< Deuteronomy 33 >

1 Èyí ni ìbùkún tí Mose ènìyàn Ọlọ́run bùkún fún àwọn ọmọ Israẹli kí ó tó kú.
Tanrı adamı Musa, ölümünden önce İsrailliler'i kutsadı.
2 Ó sì wí pé, “Olúwa ti Sinai wá, ó sì yọ sí wọn láti Seiri wá ó sì tàn án jáde láti òkè Parani wá. Ó ti ọ̀dọ̀ ẹgbẹgbàarùn-ún àwọn mímọ́ wá láti ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni òfin kan a mú bí iná ti jáde fún wọn wá.
Şöyle dedi: “RAB Sina Dağı'ndan geldi, Halkına Seir'den doğdu Ve Paran Dağı'ndan parladı. On binlerce kutsalıyla birlikte geldi, Sağ elinde halkı için alev alev yanan ateş vardı.
3 Nítòótọ́, ó fẹ́ràn àwọn ènìyàn an rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ wà ní ọwọ́ rẹ̀. Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti foríbalẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti ń gba ọ̀rọ̀,
Ya RAB, halkları gerçekten seversin, Bütün kutsallar elinin altındadır. Ayaklarına kapanır, Sözlerini dinlerler.
4 òfin tí Mose fi fún wa, ìní ti ìjọ ènìyàn Jakọbu.
Yakup'un topluluğuna miras olarak, Musa bize yasayı verdi.
5 Òun ni ọba lórí Jeṣuruni ní ìgbà tí olórí àwọn ènìyàn péjọpọ̀, pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
İsrail'in oymaklarıyla Halkın önderleri bir araya geldiğinde RAB Yeşurun'un kralı oldu.
6 “Jẹ́ kí Reubeni yè kí ó má ṣe kú, tàbí kí ènìyàn rẹ mọ níwọ̀n.”
“Ruben yaşasın, ölmesin, Halkının sayısı az olmasın.”
7 Èyí ni ohun tí ó sọ nípa Juda: “Olúwa gbọ́ ohùn Juda kí o sì mú tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ wá. Kí ọwọ́ rẹ̀ kí ó tó fún un, kí ó sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀!”
Musa Yahuda için de şunları söyledi: “Ya RAB, Yahuda'nın yakarışını duy Ve onu kendi halkına getir. Kendisi için elleriyle savaştı. Düşmanlarına karşı ona yardımcı ol.”
8 Ní ti Lefi ó wí pé, “Jẹ́ kí Tumimu àti Urimu rẹ kí ó wà pẹ̀lú ẹni mímọ́ rẹ. Ẹni tí ó dánwò ní Massa, ìwọ bá jà ní omi Meriba.
Levi için de şöyle dedi: “Ya RAB, senin Tummim'in ve Urim'in Sadık kulun içindir. Onu Massa'da denedin, Meriva sularında onunla tartıştın.
9 Ó wí fún baba àti ìyá rẹ pé, ‘Èmi kò buyì fún wọn.’ Kò mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, tàbí mọ àwọn ọmọ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó dúró lórí ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
O annesi ve babası için, ‘Onları saymıyorum’ dedi. Kardeşlerini tanımadı, Çocuklarını bilmedi. Ama senin sözünü tuttu Ve antlaşmana bağlı kaldı.
10 Ó kọ́ Jakọbu ní ìdájọ́ rẹ̀ àti Israẹli ní òfin rẹ̀. Ó mú tùràrí wá síwájú rẹ̀ àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ẹbọ sísun sórí i pẹpẹ rẹ̀.
İlkelerini Yakup soyuna, Yasanı İsrail'e öğretecekler. Senin önünde buhur, Sunağında tümüyle yakmalık sunular sunacaklar.
11 Bùsi ohun ìní rẹ̀, Olúwa, kí o sì tẹ́wọ́gbà iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀. Lu ẹgbẹ́ àwọn tí ó dìde sí i; àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, kí wọn kí ó má ṣe dìde mọ́.”
Ya RAB, onları el attıkları her işte kutsa, Yaptıklarından hoşnut ol. Ona karşı ayaklananların Ve ondan nefret edenlerin belini kır, Bir daha ayağa kalkmasınlar!”
12 Ní ti Benjamini ó wí pé, “Jẹ́ kí olùfẹ́ Olúwa máa gbé ní àlàáfíà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun a máa bò ó ní gbogbo ọjọ́, ẹni tí Olúwa fẹ́ràn yóò máa sinmi láàrín èjìká rẹ̀.”
Benyamin için de şöyle dedi: “RAB'bin sevgilisi, O'nun yanında güvenlikte yaşasın; RAB bütün gün onu korur, O da RAB'bin kucağında oturur.”
13 Ní ti Josẹfu ó wí pé, “Kí Olúwa bùkún ilẹ̀ rẹ, fún ohun iyebíye láti ọ̀run pẹ̀lú ìrì àti ibú tí ó ń bẹ níṣàlẹ̀;
Yusuf için de şöyle dedi: “RAB onun ülkesini Gökten yağan değerli çiyle Ve yeraltındaki derin su kaynaklarıyla kutsasın.
14 àti fún èso iyebíye tí ọ̀run mú wá àti ti ohun iyebíye tí ń dàgbà ní oṣooṣù;
Ülkesi güneş altında yetişen ürünlerin en iyisiyle, Her ay yetişen en iyi meyvelerle,
15 pẹ̀lú ohun pàtàkì òkè ńlá ìgbàanì àti fún ohun iyebíye ìgbà ayérayé;
Yaşlı dağların en seçkin armağanlarıyla, Kalıcı tepelerin bolluğuyla,
16 Pẹ̀lú ohun iyebíye ayé àti ẹ̀kún un rẹ̀ àti fún ìfẹ́ ẹni tí ó ń gbé inú igbó. Jẹ́ kí gbogbo èyí sinmi lé orí Josẹfu, lórí àtàrí ẹni tí ó yàtọ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀.
Yerin en değerli ürünü ve doluluğuyla, Çalıda oturanın lütfuyla bereketli olsun. Yusuf'un başı üzerine, Kardeşlerinden ayrı olanın başı üzerine bereket yağsın.
17 Ní ọláńlá ó dàbí àkọ́bí akọ màlúù; ìwo rẹ̀, ìwo àgbáǹréré ni. Pẹ̀lú wọn ni yóò fi ti àwọn orílẹ̀-èdè, pàápàá títí dé òpin ayé. Àwọn sì ni ẹgbẹẹgbàárùn mẹ́wàá Efraimu, àwọn sì ni ẹgbẹẹgbẹ̀rún Manase.”
İlk doğan bir boğa kadar Görkemlidir o; Boynuzları yaban öküzünün boynuzları gibidir. Bu boynuzlarla ulusları, Yeryüzünün dört bucağındaki ulusları yaralayacak. İşte böyledir Efrayim'in on binleri, İşte bunlardır Manaşşe'nin binleri.”
18 Ní ti Sebuluni ó wí pé, “Yọ̀ Sebuluni, ní ti ìjáde lọ rẹ, àti ìwọ Isakari, nínú àgọ́ rẹ.
Zevulun için de şöyle dedi: “Ey Zevulun, sevinç duy yola çıkışınla, Ve sen, İssakar, çadırlarında sevin!
19 Wọn yóò pe àwọn ènìyàn sórí òkè àti níbẹ̀ wọn yóò rú ẹbọ òdodo, wọn yóò mu nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òkun, nínú ìṣúra tí ó pamọ́ nínú iyanrìn.”
Ulusları dağa çağıracak, Orada doğruluk kurbanları kesecekler. Denizlerin bolluğuyla Ve kumlarda saklı hazinelerle doyacaklar.”
20 Ní ti Gadi ó wí pé, “Ìbùkún ni ẹni tí ó mú Gadi gbilẹ̀! Gadi ń gbé níbẹ̀ bí kìnnìún, ó sì fa apá ya, àní àtàrí.
Gad için de şöyle dedi: “Gad'ın sınırını genişleten kutsansın; Gad orada kol ve baş parçalayan Bir aslan gibi oturuyor.
21 Ó sì yan ilẹ̀ tí ó dára jù fún ara rẹ̀; ìpín olórí ni a sì fi fún un. Nígbà tí ó rí tí gbogbo àwọn ènìyàn péjọ, ó mú òdodo Olúwa ṣẹ, àti ìdájọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli.”
Kendine ilk toprağı seçti; Önderlik payı ona verilmiştir. Halkın önderleri bir araya geldiğinde, RAB'bin doğru isteğini Ve İsrail'e ilişkin ilkelerini, O yerine getirdi.”
22 Ní ti Dani ó wí pé, “Ọmọ kìnnìún ni Dani, tí ń fò láti Baṣani wá.”
Dan için de şöyle dedi: “Dan Başan'dan sıçrayan Aslan yavrusudur.”
23 Ní ti Naftali ó wí pé, “Ìwọ Naftali, kún fún ojúrere Ọlọ́run àti ìbùkún Olúwa; yóò jogún ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gúúsù.”
Naftali için de şöyle dedi: “Ey sen, RAB'bin lütfu ve Kutsamasıyla dolu olan Naftali! Sen batıyı ve güneyi mülk edineceksin.”
24 Ní ti Aṣeri ó wí pé, “Ìbùkún ọmọ ni ti Aṣeri; jẹ́ kí ó rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kí ó sì ri ẹsẹ̀ rẹ̀ sínú òróró.
Aşer için de şöyle dedi: “Oğullar arasında en çok kutsanan Aşer olsun, Kardeşlerinin beğenisini kazanan o olsun. Ayağını zeytinyağına batırsın.
25 Bàtà rẹ̀ yóò jẹ́ irin àti idẹ, agbára rẹ̀ yóò sì rí bí ọjọ́ rẹ̀.
Kapı sürgülerin demir ve tunç olacak Ve gücün yaşamın boyunca sürecektir.”
26 “Kò sí ẹlòmíràn bí Ọlọ́run Jeṣuruni, ẹni tí ń gun ọ̀run fún ìrànlọ́wọ́ rẹ àti ní ojú ọ̀run nínú ọláńlá rẹ̀.
“Ey Yeşurun, sana yardım için Göklere ve bulutlara görkemle binen, Tanrı'ya benzer biri yok.
27 Ọlọ́run ayérayé ni ibi ìsádi rẹ, àti ní ìsàlẹ̀ ni apá ayérayé wà. Yóò lé àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ, ó sì wí pé, ‘Ẹ máa parun!’
Sığınağın çağlar boyu var olan Tanrı'dır, Seni taşıyan O'nun yorulmaz kollarıdır. Düşmanı önünden kovacak Ve sana, ‘Onu yok et!’ diyecek.
28 Israẹli nìkan yóò jókòó ní àlàáfíà, orísun Jakọbu nìkan ní ilẹ̀ ọkà àti ti ọtí wáìnì, níbi tí ọ̀run ti ń sẹ ìrì sílẹ̀.
Böylece İsrail güvenlik içinde yaşayacak; Tahıl ve yeni şarap ülkesinde, Yakup'un pınarı güvenlikte kalacak. Gökler oraya çiy damlatacak.
29 Ìbùkún ni fún ọ, Israẹli, ta ni ó dàbí rẹ, ẹni tí a gbàlà láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Òun ni asà àti ìrànwọ́ rẹ̀ àti idà ọláńlá rẹ̀. Àwọn ọ̀tá rẹ yóò tẹríba fún ọ, ìwọ yóò sì tẹ ibi gíga wọn mọ́lẹ̀.”
Ne mutlu sana, ey İsrail! Var mı senin gibisi? Sen RAB'bin kurtardığı bir halksın. RAB seni koruyan kalkan Ve şanlı kılıcındır. Düşmanların senin önünde küçülecek Ve sen onları çiğneyeceksin.”

< Deuteronomy 33 >