< Deuteronomy 33 >
1 Èyí ni ìbùkún tí Mose ènìyàn Ọlọ́run bùkún fún àwọn ọmọ Israẹli kí ó tó kú.
A toć jest błogosławieństwo, którem błogosławił Mojżesz, mąż Boży, synom Izraelskim przed śmiercią swoją.
2 Ó sì wí pé, “Olúwa ti Sinai wá, ó sì yọ sí wọn láti Seiri wá ó sì tàn án jáde láti òkè Parani wá. Ó ti ọ̀dọ̀ ẹgbẹgbàarùn-ún àwọn mímọ́ wá láti ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni òfin kan a mú bí iná ti jáde fún wọn wá.
I rzekł: Pan z Synaj przyszedł, i pojawił się im z Seiru, objaśnił się z góry Faran, a przyszedł z dziesięcioma tysiącami świętych; z prawicy jego zakon ognisty dany im.
3 Nítòótọ́, ó fẹ́ràn àwọn ènìyàn an rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ wà ní ọwọ́ rẹ̀. Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti foríbalẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti ń gba ọ̀rọ̀,
Zaiste on miłuje lud; wszyscy święci jego są w rękach twych, i oni skupili się do nogi twej, aby co pojęli z słów twoich.
4 òfin tí Mose fi fún wa, ìní ti ìjọ ènìyàn Jakọbu.
Zakon podał nam Mojżesz, dziedzictwo zebraniu Jakóbowemu.
5 Òun ni ọba lórí Jeṣuruni ní ìgbà tí olórí àwọn ènìyàn péjọpọ̀, pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Bo był królem w Izraelu, gdy się zgromadzili przedniejsi z ludu, także pokolenia Izraelskie.
6 “Jẹ́ kí Reubeni yè kí ó má ṣe kú, tàbí kí ènìyàn rẹ mọ níwọ̀n.”
Niech żyje Ruben, a nie umiera; a niech będzie mężów jego poczet.
7 Èyí ni ohun tí ó sọ nípa Juda: “Olúwa gbọ́ ohùn Juda kí o sì mú tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ wá. Kí ọwọ́ rẹ̀ kí ó tó fún un, kí ó sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀!”
Potem też błogosławił Judzie, i rzekł: Wysłuchaj Panie głos Judy, a do ludu jego wprowadź go; ręka jego będzie walczyła zań, a ty go ratować będziesz przeciw nieprzyjaciołom jego.
8 Ní ti Lefi ó wí pé, “Jẹ́ kí Tumimu àti Urimu rẹ kí ó wà pẹ̀lú ẹni mímọ́ rẹ. Ẹni tí ó dánwò ní Massa, ìwọ bá jà ní omi Meriba.
A do Lewiego rzekł: Tummim twoje, i Urim twoje było przy mężu świętym twoim, któregoś kusił w Massa, i z którymeś miał spór u wód Meryba.
9 Ó wí fún baba àti ìyá rẹ pé, ‘Èmi kò buyì fún wọn.’ Kò mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, tàbí mọ àwọn ọmọ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó dúró lórí ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
Tenci to jest, który rzekł ojcu swemu, i matce swej: Nie oglądam się na was: i braci swych nie znał, i o synach swych nie wiedział; albowiem oni strzegą słów twych, i przymierze twoje zachowują.
10 Ó kọ́ Jakọbu ní ìdájọ́ rẹ̀ àti Israẹli ní òfin rẹ̀. Ó mú tùràrí wá síwájú rẹ̀ àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ẹbọ sísun sórí i pẹpẹ rẹ̀.
Będą uczyć sądów twoich Jakóba, a zakonu twego Izraela; kłaść będą kadzenie pod nozdrza twoje, a całopalenie na ołtarz twój.
11 Bùsi ohun ìní rẹ̀, Olúwa, kí o sì tẹ́wọ́gbà iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀. Lu ẹgbẹ́ àwọn tí ó dìde sí i; àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, kí wọn kí ó má ṣe dìde mọ́.”
Błogosławże, Panie, mocy jego, a sprawy rąk jego przyjmij wdzięcznie; zetrzyj biodra nieprzyjaciół jego, i tych którzy go nienawidzą, aby powstać nie mogli.
12 Ní ti Benjamini ó wí pé, “Jẹ́ kí olùfẹ́ Olúwa máa gbé ní àlàáfíà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun a máa bò ó ní gbogbo ọjọ́, ẹni tí Olúwa fẹ́ràn yóò máa sinmi láàrín èjìká rẹ̀.”
A do Benjamina rzekł: Ten jest najmilszy Panu; będzie mieszkał przy nim bezpiecznie; bronić go będzie na każdy dzień, a między ramiony jego przebywać będzie.
13 Ní ti Josẹfu ó wí pé, “Kí Olúwa bùkún ilẹ̀ rẹ, fún ohun iyebíye láti ọ̀run pẹ̀lú ìrì àti ibú tí ó ń bẹ níṣàlẹ̀;
Do Józefa też rzekł: Błogosławiona od Pana ziemia jego z najlepszych rzeczy niebieskich, z rosy, i z źródeł z ziemi wynikających.
14 àti fún èso iyebíye tí ọ̀run mú wá àti ti ohun iyebíye tí ń dàgbà ní oṣooṣù;
I dla rozkosznych urodzajów słonecznych, także dla rozkosznych dostałych urodzajów miesięcznych;
15 pẹ̀lú ohun pàtàkì òkè ńlá ìgbàanì àti fún ohun iyebíye ìgbà ayérayé;
I dla rozkosznych gór starodawnych, i dla rozkosznych pagórków wiecznych;
16 Pẹ̀lú ohun iyebíye ayé àti ẹ̀kún un rẹ̀ àti fún ìfẹ́ ẹni tí ó ń gbé inú igbó. Jẹ́ kí gbogbo èyí sinmi lé orí Josẹfu, lórí àtàrí ẹni tí ó yàtọ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀.
Także dla rozkosznych owoców ziemi, i obfitości jej, a dla życzliwości mieszkającego w krzu. Niech to błogosławieństwo przyjdzie na głowę Józefowę, i na wierzch głowy Nazarejczyka między bracią jego.
17 Ní ọláńlá ó dàbí àkọ́bí akọ màlúù; ìwo rẹ̀, ìwo àgbáǹréré ni. Pẹ̀lú wọn ni yóò fi ti àwọn orílẹ̀-èdè, pàápàá títí dé òpin ayé. Àwọn sì ni ẹgbẹẹgbàárùn mẹ́wàá Efraimu, àwọn sì ni ẹgbẹẹgbẹ̀rún Manase.”
Jako pierworodnego wołu ozdoba jego, a jako rogi jednorożcowe rogi jego, temi narody zbodzie na porząd aż do ostatnich granic ziemi; a teć są dziesięć tysięcy Efraimitów, a te tysiące Manasesytów.
18 Ní ti Sebuluni ó wí pé, “Yọ̀ Sebuluni, ní ti ìjáde lọ rẹ, àti ìwọ Isakari, nínú àgọ́ rẹ.
A do Zabulona rzekł: Wesel się Zabulon w wyjściu swem, a ty Isaschar w namiotach twoich.
19 Wọn yóò pe àwọn ènìyàn sórí òkè àti níbẹ̀ wọn yóò rú ẹbọ òdodo, wọn yóò mu nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òkun, nínú ìṣúra tí ó pamọ́ nínú iyanrìn.”
Ludu na górę przyzowią; tam ofiarować będą ofiary sprawiedliwości, ponieważ obfitość morską ssać będą, i zakryte skarby piasku.
20 Ní ti Gadi ó wí pé, “Ìbùkún ni ẹni tí ó mú Gadi gbilẹ̀! Gadi ń gbé níbẹ̀ bí kìnnìún, ó sì fa apá ya, àní àtàrí.
A do Gada rzekł: Błogosławiony, który rozmnaża Gada! jako lew mieszkać będzie, a porwie ramię i głowę;
21 Ó sì yan ilẹ̀ tí ó dára jù fún ara rẹ̀; ìpín olórí ni a sì fi fún un. Nígbà tí ó rí tí gbogbo àwọn ènìyàn péjọ, ó mú òdodo Olúwa ṣẹ, àti ìdájọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli.”
Który sobie upatrzył na początku mieszkanie, a iż tam o dziale swoim przez zakonodawcę ubezpieczony jest; przetoż pójdzie z książęty ludu, sprawiedliwość Pańską wykona, i sądy jego z Izraelem.
22 Ní ti Dani ó wí pé, “Ọmọ kìnnìún ni Dani, tí ń fò láti Baṣani wá.”
A do Dana rzekł: Dan jako szczenię lwie wyskakujące z Basan.
23 Ní ti Naftali ó wí pé, “Ìwọ Naftali, kún fún ojúrere Ọlọ́run àti ìbùkún Olúwa; yóò jogún ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gúúsù.”
A do Neftalima rzekł: Neftali, nasycony przyjaźni i pełny błogosławieństwa Pańskiego, zachód i południe opanujesz.
24 Ní ti Aṣeri ó wí pé, “Ìbùkún ọmọ ni ti Aṣeri; jẹ́ kí ó rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kí ó sì ri ẹsẹ̀ rẹ̀ sínú òróró.
A do Asera rzekł: Błogosławiony nad inne syny Aser, będzie przyjemny braciom swoim, i omoczy w oliwie nogę swoję.
25 Bàtà rẹ̀ yóò jẹ́ irin àti idẹ, agbára rẹ̀ yóò sì rí bí ọjọ́ rẹ̀.
Żelazo i miedź pod obuwiem twojem; i póki będą trwać dni twoje, słynąć będzie moc twoja.
26 “Kò sí ẹlòmíràn bí Ọlọ́run Jeṣuruni, ẹni tí ń gun ọ̀run fún ìrànlọ́wọ́ rẹ àti ní ojú ọ̀run nínú ọláńlá rẹ̀.
Nie masz tak prawego, jako Bóg, który jeździ po niebie ku ratunku twemu, i w wielmożności swej na obłokach.
27 Ọlọ́run ayérayé ni ibi ìsádi rẹ, àti ní ìsàlẹ̀ ni apá ayérayé wà. Yóò lé àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ, ó sì wí pé, ‘Ẹ máa parun!’
Mieszkaniem twojem Bóg wieczny, a ze spodku ramiona wieczności. Ten wyrzuci przed tobą nieprzyjaciela, a rzeczeć: Wytrać go;
28 Israẹli nìkan yóò jókòó ní àlàáfíà, orísun Jakọbu nìkan ní ilẹ̀ ọkà àti ti ọtí wáìnì, níbi tí ọ̀run ti ń sẹ ìrì sílẹ̀.
Aby mieszkał Izrael bezpiecznie sam, źródło Jakóbowe, w ziemi zboża i wina, którego też niebiosa kropić będą rosą.
29 Ìbùkún ni fún ọ, Israẹli, ta ni ó dàbí rẹ, ẹni tí a gbàlà láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Òun ni asà àti ìrànwọ́ rẹ̀ àti idà ọláńlá rẹ̀. Àwọn ọ̀tá rẹ yóò tẹríba fún ọ, ìwọ yóò sì tẹ ibi gíga wọn mọ́lẹ̀.”
Błogosławionyś ty, Izraelu! Któż podobny tobie? ludu zachowany przez Pana, który jest tarczą ratunku twego, a mieczem zacności twojej. Przeto obłudnieć się poddadzą nieprzyjaciele twoi, a ty wyniosłość ich deptać będziesz.