< Deuteronomy 33 >
1 Èyí ni ìbùkún tí Mose ènìyàn Ọlọ́run bùkún fún àwọn ọmọ Israẹli kí ó tó kú.
Ez pedig az áldás, a melylyel megáldá Mózes, az Istennek embere, Izráel fiait az ő halála előtt.
2 Ó sì wí pé, “Olúwa ti Sinai wá, ó sì yọ sí wọn láti Seiri wá ó sì tàn án jáde láti òkè Parani wá. Ó ti ọ̀dọ̀ ẹgbẹgbàarùn-ún àwọn mímọ́ wá láti ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni òfin kan a mú bí iná ti jáde fún wọn wá.
Monda ugyanis: Az Úr a Sinai hegyről jött, és Szeirből támadt fel nékik; Párán hegyéről ragyogott elő, tízezer szent közül jelent meg, jobbja felől tüzes törvény vala számukra.
3 Nítòótọ́, ó fẹ́ràn àwọn ènìyàn an rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ wà ní ọwọ́ rẹ̀. Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti foríbalẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti ń gba ọ̀rọ̀,
Bizony szereti ő a népeket! Mind kezednél vannak az ő szentjei, oda szegődnek, a te lábaidhoz, és hallgatják a te beszédeidet.
4 òfin tí Mose fi fún wa, ìní ti ìjọ ènìyàn Jakọbu.
Törvényt parancsolt nékünk Mózes, örökségül Jákób községének.
5 Òun ni ọba lórí Jeṣuruni ní ìgbà tí olórí àwọn ènìyàn péjọpọ̀, pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
És király lőn Jesurunban, mikor összegyűltek a népnek fejei, és együtt voltak Izráel törzsei.
6 “Jẹ́ kí Reubeni yè kí ó má ṣe kú, tàbí kí ènìyàn rẹ mọ níwọ̀n.”
Éljen Rúben és meg ne haljon; és száma legyen embereinek.
7 Èyí ni ohun tí ó sọ nípa Juda: “Olúwa gbọ́ ohùn Juda kí o sì mú tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ wá. Kí ọwọ́ rẹ̀ kí ó tó fún un, kí ó sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀!”
Ez pedig a Júda áldása; és monda: Hallgasd meg Uram a Júda szavát, és vidd be őt az ő népéhez. Az ő keze elégséges legyen néki, de légy segítsége az ő szorongatói ellen.
8 Ní ti Lefi ó wí pé, “Jẹ́ kí Tumimu àti Urimu rẹ kí ó wà pẹ̀lú ẹni mímọ́ rẹ. Ẹni tí ó dánwò ní Massa, ìwọ bá jà ní omi Meriba.
Léviről pedig monda: A te Thummimod és Urimod a te kegyes férfiadé, a kit megkísértél Masszában, a kivel perbe szálltál Mériba vizeinél.
9 Ó wí fún baba àti ìyá rẹ pé, ‘Èmi kò buyì fún wọn.’ Kò mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, tàbí mọ àwọn ọmọ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó dúró lórí ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
A ki azt mondta az ő atyjáról és anyjáról: Nem láttam őt; és az ő atyjafiait nem ismerte, fiaival sem gondolt; mert megtartották a te beszédedet, és ragaszkodtak szövetségedhez.
10 Ó kọ́ Jakọbu ní ìdájọ́ rẹ̀ àti Israẹli ní òfin rẹ̀. Ó mú tùràrí wá síwájú rẹ̀ àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ẹbọ sísun sórí i pẹpẹ rẹ̀.
Tanítják a te végzéseidre Jákóbot, és a te törvényedre Izráelt; füstölőt tesznek a te orczád elé, és égőáldozatot a te oltárodra.
11 Bùsi ohun ìní rẹ̀, Olúwa, kí o sì tẹ́wọ́gbà iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀. Lu ẹgbẹ́ àwọn tí ó dìde sí i; àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, kí wọn kí ó má ṣe dìde mọ́.”
Áldd meg Uram az ő erejét, és az ő kezének munkája legyen kedves előtted! Törd meg derekukat a reá támadóknak és az ő gyűlölőinek, hogy fel ne kelhessenek!
12 Ní ti Benjamini ó wí pé, “Jẹ́ kí olùfẹ́ Olúwa máa gbé ní àlàáfíà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun a máa bò ó ní gbogbo ọjọ́, ẹni tí Olúwa fẹ́ràn yóò máa sinmi láàrín èjìká rẹ̀.”
Benjáminról monda: Az Úrnak kedveltje! Bátorságban lakozik mellette, fedezi őt minden időben, és az ő vállai között lakik.
13 Ní ti Josẹfu ó wí pé, “Kí Olúwa bùkún ilẹ̀ rẹ, fún ohun iyebíye láti ọ̀run pẹ̀lú ìrì àti ibú tí ó ń bẹ níṣàlẹ̀;
Józsefről pedig monda: Áldott az Úrtól az ő földe az égnek kincseivel, a harmattal és az alant elterülő mélységes vizekkel;
14 àti fún èso iyebíye tí ọ̀run mú wá àti ti ohun iyebíye tí ń dàgbà ní oṣooṣù;
A nap érlelte drága terméssel, és a hold sarjasztotta drágaságokkal;
15 pẹ̀lú ohun pàtàkì òkè ńlá ìgbàanì àti fún ohun iyebíye ìgbà ayérayé;
És az ős hegyek javaival, és az örök halmok drágaságaival;
16 Pẹ̀lú ohun iyebíye ayé àti ẹ̀kún un rẹ̀ àti fún ìfẹ́ ẹni tí ó ń gbé inú igbó. Jẹ́ kí gbogbo èyí sinmi lé orí Josẹfu, lórí àtàrí ẹni tí ó yàtọ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀.
A földnek drágaságaival és bőségével. A csipkebokorban lakozónak jó kedve szálljon Józsefnek fejére, az ő atyjafiai közül kiválasztottnak koponyájára!
17 Ní ọláńlá ó dàbí àkọ́bí akọ màlúù; ìwo rẹ̀, ìwo àgbáǹréré ni. Pẹ̀lú wọn ni yóò fi ti àwọn orílẹ̀-èdè, pàápàá títí dé òpin ayé. Àwọn sì ni ẹgbẹẹgbàárùn mẹ́wàá Efraimu, àwọn sì ni ẹgbẹẹgbẹ̀rún Manase.”
Tehenének első fajzása dicsőségére van; szarvai bivalyszarvak; népeket öklel azokkal mindenfelé a földnek széléig. És ezek Efraim tízezrei és Manassé ezrei.
18 Ní ti Sebuluni ó wí pé, “Yọ̀ Sebuluni, ní ti ìjáde lọ rẹ, àti ìwọ Isakari, nínú àgọ́ rẹ.
És Zebulonról monda: Örvendj Zebulon a te kimentedben, és te Izsakhár a te sátraidban.
19 Wọn yóò pe àwọn ènìyàn sórí òkè àti níbẹ̀ wọn yóò rú ẹbọ òdodo, wọn yóò mu nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òkun, nínú ìṣúra tí ó pamọ́ nínú iyanrìn.”
Népeket hívogatnak a hegyre, igaz áldozattal áldoznak ott; mert a tengerek bőségét szopják, és a fövénynek rejtett kincseit.
20 Ní ti Gadi ó wí pé, “Ìbùkún ni ẹni tí ó mú Gadi gbilẹ̀! Gadi ń gbé níbẹ̀ bí kìnnìún, ó sì fa apá ya, àní àtàrí.
És Gádról monda: Áldott az, a ki kiterjeszti Gádot! Mint nőstény oroszlán, úgy lakik, és szétszaggat kart és koponyát.
21 Ó sì yan ilẹ̀ tí ó dára jù fún ara rẹ̀; ìpín olórí ni a sì fi fún un. Nígbà tí ó rí tí gbogbo àwọn ènìyàn péjọ, ó mú òdodo Olúwa ṣẹ, àti ìdájọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli.”
Az elejét nézte ki magának, mert ott volt elrejtve a törvényadó osztályrésze. De elméne a népnek fejedelmeivel, az Úrnak igazságát cselekedte, és az ő végzését Izráellel együtt.
22 Ní ti Dani ó wí pé, “Ọmọ kìnnìún ni Dani, tí ń fò láti Baṣani wá.”
És Dánról monda: Dán oroszlánnak kölyke, a mely Básánból szökik ki.
23 Ní ti Naftali ó wí pé, “Ìwọ Naftali, kún fún ojúrere Ọlọ́run àti ìbùkún Olúwa; yóò jogún ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gúúsù.”
És Nafthaliról monda: Ó Nafthali, a ki az Úrnak jó kedvével bővölködöl és áldásával vagy teljes! Vedd birtokba a tengert és a délt.
24 Ní ti Aṣeri ó wí pé, “Ìbùkún ọmọ ni ti Aṣeri; jẹ́ kí ó rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kí ó sì ri ẹsẹ̀ rẹ̀ sínú òróró.
És Áserről monda: Áldott a többi fiak felett Áser! Legyen az ő atyjafiai előtt kedves, és áztassa lábát olajban.
25 Bàtà rẹ̀ yóò jẹ́ irin àti idẹ, agbára rẹ̀ yóò sì rí bí ọjọ́ rẹ̀.
Vas és réz legyenek a te záraid; és élteden át tartson erőd.
26 “Kò sí ẹlòmíràn bí Ọlọ́run Jeṣuruni, ẹni tí ń gun ọ̀run fún ìrànlọ́wọ́ rẹ àti ní ojú ọ̀run nínú ọláńlá rẹ̀.
Nincs olyan, mint a Jesurun Istene! Az egeken száguld segítségedre, és fenségében a felhőkön.
27 Ọlọ́run ayérayé ni ibi ìsádi rẹ, àti ní ìsàlẹ̀ ni apá ayérayé wà. Yóò lé àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ, ó sì wí pé, ‘Ẹ máa parun!’
Hajlék az örökkévaló Isten, alant vannak örökkévaló karjai; elűzi előled az ellenséget, és ezt mondja: Pusztítsd!
28 Israẹli nìkan yóò jókòó ní àlàáfíà, orísun Jakọbu nìkan ní ilẹ̀ ọkà àti ti ọtí wáìnì, níbi tí ọ̀run ti ń sẹ ìrì sílẹ̀.
És bátorságban lakozik Izráel, egymaga lesz Jákób forrása a gabona és a bor földén, és az ő egei harmatot csepegnek.
29 Ìbùkún ni fún ọ, Israẹli, ta ni ó dàbí rẹ, ẹni tí a gbàlà láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Òun ni asà àti ìrànwọ́ rẹ̀ àti idà ọláńlá rẹ̀. Àwọn ọ̀tá rẹ yóò tẹríba fún ọ, ìwọ yóò sì tẹ ibi gíga wọn mọ́lẹ̀.”
Boldog vagy Izráel! Kicsoda olyan mint te? Nép, a kit az Úr véd, a te segítségednek pajzsa, és a ki a te dicsőségednek fegyvere! Hízelegnek majd néked a te ellenségeid, és te azoknak magaslatait taposod.