< Deuteronomy 33 >

1 Èyí ni ìbùkún tí Mose ènìyàn Ọlọ́run bùkún fún àwọn ọmọ Israẹli kí ó tó kú.
Voici la bénédiction par laquelle Moïse, homme de Dieu, a béni les enfants d'Israël avant sa mort.
2 Ó sì wí pé, “Olúwa ti Sinai wá, ó sì yọ sí wọn láti Seiri wá ó sì tàn án jáde láti òkè Parani wá. Ó ti ọ̀dọ̀ ẹgbẹgbàarùn-ún àwọn mímọ́ wá láti ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni òfin kan a mú bí iná ti jáde fún wọn wá.
Il dit, « Yahvé est venu du Sinaï, et s'est élevé de Seir jusqu'à eux. Il brillait du mont Paran. Il est issu des dix mille saints. A sa droite, il y avait une loi ardente pour eux.
3 Nítòótọ́, ó fẹ́ràn àwọn ènìyàn an rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ wà ní ọwọ́ rẹ̀. Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti foríbalẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti ń gba ọ̀rọ̀,
Oui, il aime le peuple. Tous ses saints sont dans votre main. Ils se sont assis à vos pieds. Chacun reçoit vos paroles.
4 òfin tí Mose fi fún wa, ìní ti ìjọ ènìyàn Jakọbu.
Moïse nous a donné une loi, un héritage pour l'assemblée de Jacob.
5 Òun ni ọba lórí Jeṣuruni ní ìgbà tí olórí àwọn ènìyàn péjọpọ̀, pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Il était roi à Jeshurun, quand les chefs du peuple étaient réunis, toutes les tribus d'Israël réunies.
6 “Jẹ́ kí Reubeni yè kí ó má ṣe kú, tàbí kí ènìyàn rẹ mọ níwọ̀n.”
« Que Ruben vive et ne meure pas; Et que ses hommes ne soient pas trop nombreux. »
7 Èyí ni ohun tí ó sọ nípa Juda: “Olúwa gbọ́ ohùn Juda kí o sì mú tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ wá. Kí ọwọ́ rẹ̀ kí ó tó fún un, kí ó sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀!”
Ceci est pour Juda. Il a dit, « Écoute, Yahvé, la voix de Juda. Amenez-le à son peuple. Avec ses mains, il s'est battu pour lui-même. Tu seras un secours contre ses adversaires. »
8 Ní ti Lefi ó wí pé, “Jẹ́ kí Tumimu àti Urimu rẹ kí ó wà pẹ̀lú ẹni mímọ́ rẹ. Ẹni tí ó dánwò ní Massa, ìwọ bá jà ní omi Meriba.
À propos de Lévi, il a dit, « Ton Thummim et ton Urim sont avec ton pieux, que vous avez prouvé à Massah, avec qui tu t'es disputé aux eaux de Meribah.
9 Ó wí fún baba àti ìyá rẹ pé, ‘Èmi kò buyì fún wọn.’ Kò mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, tàbí mọ àwọn ọmọ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó dúró lórí ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
Il dit de son père et de sa mère: « Je ne l'ai pas vu ». Il n'a pas reconnu ses frères, et il ne connaissait pas non plus ses propres enfants; car ils ont observé ta parole, et garde ton alliance.
10 Ó kọ́ Jakọbu ní ìdájọ́ rẹ̀ àti Israẹli ní òfin rẹ̀. Ó mú tùràrí wá síwájú rẹ̀ àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ẹbọ sísun sórí i pẹpẹ rẹ̀.
Ils enseigneront à Jacob tes ordonnances, et Israël ta loi. Ils mettront de l'encens devant toi, et un holocauste entier sur ton autel.
11 Bùsi ohun ìní rẹ̀, Olúwa, kí o sì tẹ́wọ́gbà iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀. Lu ẹgbẹ́ àwọn tí ó dìde sí i; àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, kí wọn kí ó má ṣe dìde mọ́.”
Yahvé, bénis ses compétences. Acceptez l'œuvre de ses mains. Frappez les hanches de ceux qui se dressent contre lui, de ceux qui le haïssent, afin qu'ils ne ressuscitent pas. »
12 Ní ti Benjamini ó wí pé, “Jẹ́ kí olùfẹ́ Olúwa máa gbé ní àlàáfíà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun a máa bò ó ní gbogbo ọjọ́, ẹni tí Olúwa fẹ́ràn yóò máa sinmi láàrín èjìká rẹ̀.”
A propos de Benjamin, il dit, « Le bien-aimé de Yahvé habitera en sécurité auprès de lui. Il le couvre toute la journée. Il habite entre ses épaules. »
13 Ní ti Josẹfu ó wí pé, “Kí Olúwa bùkún ilẹ̀ rẹ, fún ohun iyebíye láti ọ̀run pẹ̀lú ìrì àti ibú tí ó ń bẹ níṣàlẹ̀;
A propos de Joseph, il dit, « Son pays est béni par Yahvé, pour les choses précieuses des cieux, pour la rosée, pour le profond qui s'étend en dessous,
14 àti fún èso iyebíye tí ọ̀run mú wá àti ti ohun iyebíye tí ń dàgbà ní oṣooṣù;
pour les choses précieuses des fruits du soleil, pour les choses précieuses que la lune peut rapporter,
15 pẹ̀lú ohun pàtàkì òkè ńlá ìgbàanì àti fún ohun iyebíye ìgbà ayérayé;
pour les meilleures choses des anciennes montagnes, pour les choses précieuses des collines éternelles,
16 Pẹ̀lú ohun iyebíye ayé àti ẹ̀kún un rẹ̀ àti fún ìfẹ́ ẹni tí ó ń gbé inú igbó. Jẹ́ kí gbogbo èyí sinmi lé orí Josẹfu, lórí àtàrí ẹni tí ó yàtọ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀.
pour les biens précieux de la terre et sa plénitude, la bonne volonté de celui qui vivait dans la brousse. Que cela tombe sur la tête de Joseph, sur la couronne de la tête de celui qui a été séparé de ses frères.
17 Ní ọláńlá ó dàbí àkọ́bí akọ màlúù; ìwo rẹ̀, ìwo àgbáǹréré ni. Pẹ̀lú wọn ni yóò fi ti àwọn orílẹ̀-èdè, pàápàá títí dé òpin ayé. Àwọn sì ni ẹgbẹẹgbàárùn mẹ́wàá Efraimu, àwọn sì ni ẹgbẹẹgbẹ̀rún Manase.”
La majesté appartient au premier-né de son troupeau. Ses cornes sont les cornes du bœuf sauvage. Avec eux, il poussera tous les peuples jusqu'aux extrémités de la terre. Ce sont les dix mille d'Ephraïm. Ce sont les milliers de Manassé. »
18 Ní ti Sebuluni ó wí pé, “Yọ̀ Sebuluni, ní ti ìjáde lọ rẹ, àti ìwọ Isakari, nínú àgọ́ rẹ.
Sur Zabulon, il dit, « Réjouis-toi, Zabulon, de ta sortie; et Issachar, dans vos tentes.
19 Wọn yóò pe àwọn ènìyàn sórí òkè àti níbẹ̀ wọn yóò rú ẹbọ òdodo, wọn yóò mu nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òkun, nínú ìṣúra tí ó pamọ́ nínú iyanrìn.”
Ils appelleront les peuples sur la montagne. Ils y offriront des sacrifices de justice, car ils puiseront dans l'abondance des mers, les trésors cachés du sable. »
20 Ní ti Gadi ó wí pé, “Ìbùkún ni ẹni tí ó mú Gadi gbilẹ̀! Gadi ń gbé níbẹ̀ bí kìnnìún, ó sì fa apá ya, àní àtàrí.
A propos de Gad, il dit, « Celui qui élargit Gad est béni. Il habite comme une lionne, et déchire le bras et la couronne de la tête.
21 Ó sì yan ilẹ̀ tí ó dára jù fún ara rẹ̀; ìpín olórí ni a sì fi fún un. Nígbà tí ó rí tí gbogbo àwọn ènìyàn péjọ, ó mú òdodo Olúwa ṣẹ, àti ìdájọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli.”
Il a fourni la première partie pour lui-même, car la part du législateur lui était réservée. Il est venu avec les têtes du peuple. Il a exécuté la justice de Yahvé, Ses ordonnances avec Israël. »
22 Ní ti Dani ó wí pé, “Ọmọ kìnnìún ni Dani, tí ń fò láti Baṣani wá.”
A propos de Dan, il dit, « Dan est un lionceau qui bondit hors de Bashan. »
23 Ní ti Naftali ó wí pé, “Ìwọ Naftali, kún fún ojúrere Ọlọ́run àti ìbùkún Olúwa; yóò jogún ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gúúsù.”
A propos de Nephtali, il dit, « Naphtali, satisfait de la faveur, plein de la bénédiction de Yahvé, Posséder l'ouest et le sud. »
24 Ní ti Aṣeri ó wí pé, “Ìbùkún ọmọ ni ti Aṣeri; jẹ́ kí ó rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kí ó sì ri ẹsẹ̀ rẹ̀ sínú òróró.
A propos d'Asher, il a dit, « Asher a la chance d'avoir des enfants. Qu'il soit accepté par ses frères. Qu'il trempe son pied dans l'huile.
25 Bàtà rẹ̀ yóò jẹ́ irin àti idẹ, agbára rẹ̀ yóò sì rí bí ọjọ́ rẹ̀.
Tes barres seront en fer et en bronze. Ta force sera à la mesure de tes jours.
26 “Kò sí ẹlòmíràn bí Ọlọ́run Jeṣuruni, ẹni tí ń gun ọ̀run fún ìrànlọ́wọ́ rẹ àti ní ojú ọ̀run nínú ọláńlá rẹ̀.
« Il n'y a personne comme Dieu, Jeshurun, qui chevauche les cieux pour vous aider, dans son excellence sur les cieux.
27 Ọlọ́run ayérayé ni ibi ìsádi rẹ, àti ní ìsàlẹ̀ ni apá ayérayé wà. Yóò lé àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ, ó sì wí pé, ‘Ẹ máa parun!’
Le Dieu éternel est ta demeure. En dessous, il y a les bras éternels. Il a chassé l'ennemi de devant vous, et a dit: « Détruisez!
28 Israẹli nìkan yóò jókòó ní àlàáfíà, orísun Jakọbu nìkan ní ilẹ̀ ọkà àti ti ọtí wáìnì, níbi tí ọ̀run ti ń sẹ ìrì sílẹ̀.
Israël habite en sécurité, la seule fontaine de Jacob, Au pays du grain et du vin nouveau. Oui, ses cieux laissent tomber la rosée.
29 Ìbùkún ni fún ọ, Israẹli, ta ni ó dàbí rẹ, ẹni tí a gbàlà láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Òun ni asà àti ìrànwọ́ rẹ̀ àti idà ọláńlá rẹ̀. Àwọn ọ̀tá rẹ yóò tẹríba fún ọ, ìwọ yóò sì tẹ ibi gíga wọn mọ́lẹ̀.”
Tu es heureux, Israël! Qui est comme vous, un peuple sauvé par Yahvé, le bouclier de ton aide, l'épée de votre excellence? Vos ennemis se soumettront à vous. Tu fouleras leurs hauts lieux. »

< Deuteronomy 33 >