< Deuteronomy 32 >

1 Fetísílẹ̀, ẹ̀yin ọ̀run, èmi yóò sọ̀rọ̀; ẹ gbọ́, ìwọ ayé, ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
«Ⱪulaⱪ selinglar, ǝy asmanlar, mǝn sɵzlǝy; Aƣzimning sɵzlirini angla, i yǝr-zemin!
2 Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò, kí àwọn ọ̀rọ̀ mi máa sọ̀kalẹ̀ bí ìrì, bí òjò wíníwíní sára ewéko tuntun, bí ọ̀wààrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.
Tǝlimim bolsa yamƣurdǝk yaƣidu, Sɵzlirim xǝbnǝmdǝk tamidu, Yumran ot-qɵp üstigǝ qüxkǝn sim-sim yamƣurdǝk, Kɵkzarliⱪning üstigǝ qüxkǝn hasiyǝtlik yamƣurdǝk bolidu.
3 Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa. Ẹyin títóbi Ọlọ́run wa!
Qünki mǝn Pǝrwǝrdigarning namini bayan ⱪilimǝn; Əmdi Hudayimizni uluƣ dǝp jakarlanglar!
4 Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé, gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo. Ọlọ́run olóòtítọ́ tí kò ṣe àṣìṣe kan, Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.
U ⱪoram taxtur, Uning ǝmǝlliri mukǝmmǝldur; Uning barliⱪ yolliri ⱨǝⱪⱪaniydur. U naⱨǝⱪliⱪi yoⱪ, wapadar bir Huda, Adil wǝ diyanǝtliktur.
5 Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀; fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apá kan tí ó sì dorí kodò.
Əmma [Ɵz hǝlⱪi] uningƣa buzuⱪluⱪ ⱪildi; Ularning ⱪilmixliri Uning Ɵz baliliriningkidǝk bolmidi — mana bu ularning ǝyibidur! Ular ǝgri wǝ iplas bir nǝsildur!
6 Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn? Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín, tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?
Əy ǝhmǝⱪ wǝ nadan hǝlⱪ, Pǝrwǝrdigarning yahxiliⱪini xundaⱪ yanduramsǝn? U seni bǝdǝl tɵlǝp ⱨɵr ⱪilƣan atang ǝmǝsmu? U seni yaritip, seni tikligǝn ǝmǝsmu?
7 Rántí ìgbà láéláé; wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá. Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ, àwọn àgbàgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.
Ɵtkǝn künlǝrni esinggǝ alƣin, Dǝwrdin-dǝwrgiqǝ ɵtkǝn yillarni oyliƣin; Atangdin sora, u sanga dǝp beridu; Aⱪsaⱪalliringƣa soal ⱪoy, ular seni hǝwǝrlǝndüridu.
8 Nígbà tí Ọ̀gá-ògo fi ogún àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn, ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Israẹli.
Ⱨǝmmidin aliy bolƣuqi ǝllǝrning ülüxini ularƣa ülǝxtürgǝndǝ, Adǝm’atining pǝrzǝntlirini bir-biridin bɵlginidǝ, U hǝlⱪlǝrning qegrilirini Israil balilirining saniƣa ⱪarap bekitkǝn.
9 Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀, Jakọbu ni ìpín ìní i rẹ̀.
Qünki Pǝrwǝrdigarning nesiwisi bolsa uningƣa has bolƣan hǝlⱪidur; Yaⱪup huddi qǝk taxlinip qiⱪⱪandǝk, Uning mirasidur.
10 Ní aginjù ni ó ti rí i, ní aginjù níbi tí ẹranko kò sí. Ó yíká, ó sì tọ́jú rẹ̀, ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.
U uni qɵl bir zeminda, Xamal ⱨuwlaydiƣan dǝⱨxǝtlik bir bayawanda uni tapti; Uni orap ǝtrapida ⱪoƣdap turdi, Uni kɵz ⱪariquⱪidǝk saⱪlidi;
11 Bí idì ti í ru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ń rábàbà sórí ọmọ rẹ̀, tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sì gbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.
Huddi bürküt ɵz qanggisini tǝwritip, Balilirining üstidǝ pǝrwaz ⱪilip, Ⱪanatlirini yeyip ularni pǝylirining üstigǝ elip kɵtürginidǝk,
12 Olúwa ṣamọ̀nà; kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.
Pǝrwǝrdigarmu uningƣa xundaⱪ yalƣuz yetǝkqilik ⱪildi; Ⱨeqⱪandaⱪ yat ilaⱨ uning bilǝn billǝ ǝmǝs idi.
13 Ó mú gun ibi gíga ayé ó sì fi èso oko bọ́ ọ. Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá, àti òróró láti inú akọ òkúta wá.
U uni yǝr yüzining egiz jayliriƣa mindürdi, Wǝ u etizliⱪning mǝⱨsulatidin yedi, U uningƣa ⱪiya taxtin ⱨǝsǝl xoritip, Qaⱪmaⱪ texidin zǝytun meyi xoratti;
14 Pẹ̀lú u wàràǹkàṣì àti wàrà àgùntàn àti ti àgbò ẹran àti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, pẹ̀lú àgbò irú u ti Baṣani tí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èso àjàrà, àní àti wáìnì.
Sanga kala ⱪaymiⱪi bilǝn ⱪoy sütini iqküzüp, Ⱪozilarning yeƣini, Baxandiki ⱪoqⱪarlar wǝ tekilǝrning gɵxini yegüzüp, Esil buƣdayning esil danliridin yegüzdi, Sǝn bolsang üzüm ⱪeni bolƣan sap xarabni iqting.
15 Jeṣuruni sanra tán ó sì tàpá; ìwọ sanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán. O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọ o sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.
Lekin Yǝxurun sǝmrip tǝpkǝk bolup ⱪaldi; Bǝrⱨǝⱪ, sǝn sǝmrip kǝtting, Bordilip kǝtting, Toyunup kǝtting! U ɵzini yaratⱪan Tǝngrini taxlap, Ɵz nijatining Ⱪoram Texini kɵzgǝ ilmidi.
16 Wọ́n sì fi òrìṣà mú un jowú, ohun ìríra ni wọ́n fi mú un bínú.
Ular bolsa yat ilaⱨlarƣa ǝgixip Uning wapasizliⱪⱪa bolƣan ⱨǝsitini ⱪozƣidi, Yirginqlik ixlar bilǝn Uning ƣǝzipini kǝltürdi.
17 Wọ́n rú ẹbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí, ọlọ́run tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ farahàn láìpẹ́, ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.
Ular Igǝ-Tǝngrisi ǝmǝs jinlarƣa, Ɵzi bilmǝydiƣan ilaⱨlarƣa, Ata-bowilirimu ⱪorⱪmaydiƣan, Yengi pǝyda bolup ⱪalƣan ilaⱨlarƣa ⱪurbanliⱪ ⱪildi.
18 Ìwọ kò rántí àpáta, tí ó bí ọ; o sì gbàgbé Ọlọ́run tí ó dá ọ.
Sǝn ɵzüngni tɵrǝldürgǝn Ⱪoram Taxni kɵnglüngdin qiⱪarding, Seni apiridǝ ⱪilƣan Tǝngrini untudung.
19 Olúwa sì rí èyí ó sì kọ̀ wọ́n, nítorí tí ó ti bínú nítorí ìwà ìmúnibínú àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ.
Pǝrwǝrdigar buni kɵrüp, Oƣul-ⱪizlirining Uning aqqiⱪini kǝltürginidin, ulardin bizar bolup mundaⱪ dedi: —
20 Ó sì wí pé, “Èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò lára wọn, èmi yóò sì wò ó bí ìgbẹ̀yìn in wọn yóò ti rí; nítorí wọ́n jẹ́ ìran alágídí, àwọn ọmọ tí kò sí ìgbàgbọ́ nínú wọn.
«Mǝn ulardin yüzümni yoxurimǝn, Ularning aⱪiwitini kɵrüp baⱪay; Qünki ular iplas bir nǝsildur, Ⱪǝlbidǝ wapadarliⱪi yoⱪ balilardur.
21 Wọ́n fi mí jowú nípa ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run, wọ́n sì fi ohun asán an wọn mú mi bínú. Èmi yóò mú wọn kún fún ìlara láti ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe ènìyàn; èmi yóò sì mú wọn bínú láti ọ̀dọ̀ aṣiwèrè orílẹ̀-èdè.
Igǝ-tǝngrisi ǝmǝslǝr bilǝn ⱨǝsitimni kǝltürdi, Ərzimǝs mǝbudliri bilǝn ⱪǝⱨrimni ⱪozƣidi; Xunga «ⱨeq hǝlⱪ ǝmǝs» bolƣan bir hǝlⱪ arⱪiliⱪ ularning ⱨǝsitini ⱪozƣaymǝn, Nadan bir ǝl arⱪiliⱪ ularning aqqiⱪini kǝltürimǝn.
22 Nítorí pé iná kan ràn nínú ìbínú mi, yóò sì jó dé ipò ikú ní ìsàlẹ̀. Yóò sì run ayé àti ìkórè e rẹ̀ yóò sì tiná bọ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá. (Sheol h7585)
Qünki Mening ƣǝzipimdin bir ot tutaxti; U tǝⱨtisaraning tegigiqǝ kɵyüp baridu, U yǝr bilǝn uning mǝⱨsulatini yǝp ketidu, Wǝ taƣlarning ullirinimu tutaxturidu. (Sheol h7585)
23 “Èmi yóò kó àwọn ohun búburú lé wọn lórí èmi ó sì na ọfà mi tán sí wọn lára.
Mǝn ularning üstigǝ balayi’apǝtlǝrni dɵwilǝymǝn; Ya-oⱪlirimni birni ⱪoymay ularƣa atimǝn.
24 Èmi yóò mú wọn gbẹ, ooru gbígbóná àti ìparun kíkorò ni a ó fi run wọ́n. Pẹ̀lú oró ohun tí ń rákò nínú erùpẹ̀.
Ular aqarqiliⱪtin yegilǝp ketidu, Tomuz issiⱪ wǝ wabaning nǝxtǝrliri tǝripidin yǝp ketilidu; Ularƣa ⱪarxi yirtⱪuq ⱨaywanlarning qixlirini, Topida ɵmiligüqilǝrning zǝⱨirini ǝwǝtimǝn.
25 Idà ní òde, àti ẹ̀rù nínú ìyẹ̀wù, ni yóò run ọmọkùnrin àti wúńdíá. Ọmọ ẹnu ọmú àti arúgbó eléwú irun pẹ̀lú.
Taxⱪirida ⱪiliq ularni musibǝtkǝ salidu, Iqkiridǝ wǝⱨimǝ basidu; U yigit bilǝn ⱪizni, Əmqǝktiki bala bilǝn aⱪ qaqliⱪni ⱨǝmmisini yoⱪitidu.
26 Mo ní èmi yóò tú wọn ká èmi yóò sì mú ìrántí i wọn dà kúrò nínú àwọn ènìyàn,
Mǝn: «Ularni qepiwetimǝn, Insanlarning arisidin ularning namini ɵqürimǝn» — dǝyttim,
27 nítorí bí mo ti bẹ̀rù ìbínú ọ̀tá, kí àwọn ọ̀tá a wọn kí ó má ba à wí pé, ‘Ọwọ́ wa lékè ni; kì í sì í ṣe Olúwa ni ó ṣe gbogbo èyí.’”
Biraⱪ düxmǝnning mǝshirǝ ⱪilixidin ⱪorⱪtum; Israilning rǝⱪibliri bu ixni hata qüxinip: — Bu ix bizning ⱪolimizning küqlüklükidin bolƣan bolsa kerǝk, Pǝrwǝrdigar buni ⱨeq ⱪilmidi» demisun dǝp, [bu ixni ⱪilmidim].
28 Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí òye nínú wọn.
Israil nǝsiⱨǝttin mǝⱨrum bolƣan bir ǝl, Ularning ⱨeq ǝⱪil-pǝmi yoⱪtur.
29 Bí ó ṣe pé wọ́n gbọ́n, kí òye yìí sì yé wọn kí wọn ro bí ìgbẹ̀yìn wọn yóò ti rí!
Aⱨ, ular dana bolsidi! Xundaⱪ bolsa buni qüxinip, Ɵz aⱪiwiti ⱪandaⱪ bolidiƣinini oylaytti!
30 Báwo ni ẹnìkan ṣe lè lé ẹgbẹ̀rún, tàbí tí ẹni méjì sì lè lé ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sá, bí kò ṣe pé àpáta wọn ti tà wọ́n, bí kò ṣe pé Olúwa wọn ti fi wọ́n tọrẹ?
Əgǝr ularning Ⱪoram Texi ularni setiwǝtmigǝn bolsa, Pǝrwǝrdigar ularni [düxmǝnlirigǝ] taxlap bǝrmigǝn bolsa, Bir kixi ⱪandaⱪmu ming kixini ɵz aldidin ⱨǝydiyǝlǝytti?, Ikki kixi ⱪandaⱪmu on ming kixini ⱪaquralaytti?
31 Nítorí pé àpáta wọn kò dàbí àpáta wa, àní àwọn ọ̀tá wa tìkára wọn ń ṣe onídàájọ́.
Qünki baxⱪilarning ⱪoram texi bolsa bizning Ⱪoram Teximizdǝk ǝmǝstur. Buningƣa düxmǝnlirimiz ɵzliri guwaⱨliⱪ bǝrsun!
32 Igi àjàrà a wọn wá láti igi àjàrà Sodomu àti ti ìgbẹ́ ẹ Gomorra. Èso àjàrà wọn kún fún oró, ìdì wọn korò.
Qünki ularning üzüm teli Sodomning üzüm telidin, Gomorraning etizliⱪliridin qiⱪⱪandur; Üzümliri zǝⱨǝrlik üzümlǝrdur, Ularning ⱨǝrbir sapiⱪi aqqiⱪtur,
33 Ọtí wáìnì wọn ìwọ ti dragoni ni, àti oró mímú ti ejò paramọ́lẹ̀.
Xarabi bolsa ǝjdiⱨalarning zǝⱨiridur, Kobralarning ǝjǝllik zǝⱨiridur.
34 “Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́ èmi kò sì fi èdìdì dì í ní ìṣúra mi?
[Pǝrwǝrdigar]: «Bularning [ⱨǝmmisi] Meningkidǝ saⱪlaⱪliⱪ ǝmǝsmu? Ɵz hǝzinilirimdǝ mɵⱨürlǝngǝn ǝmǝsmu?
35 Ti èmi ni láti gbẹ̀san. Èmi yóò san án fún wọn ní àkókò tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yóò yọ; ọjọ́ ìdààmú wọn súnmọ́ etílé ohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”
Intiⱪam Meningkidur, Yamanliⱪni ⱪayturuxmu xundaⱪ, Bular ular putlixidiƣan waⱪitⱪiqǝ saⱪlaⱪliⱪ turidu, Qünki ularning balayi’apǝtlik küni yeⱪinlaxmaⱪta, Ularning bexiƣa qüxidiƣan ixlar bolsa tez keliwatidu.
36 Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tán tí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.
Qünki Pǝrwǝrdigar ularning küqi tügǝp kǝtkǝnlikini, ularning [aziyip], ⱨǝtta ajiz yaki meyiplǝrningmu ⱪalmiƣinini kɵrgǝndǝ, U Ɵz hǝlⱪining üstigǝ ⱨɵküm qiⱪiridu, Ɵz bǝndilirigǝ meⱨir-xǝpⱪǝt kɵrsitidu.
37 Yóò wí pé, “Òrìṣà wọn dà báyìí, àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,
U waⱪitta U mundaⱪ dǝydu: «Ⱪeni, ularning ilaⱨliri? Ɵzigǝ tayanq ⱪilƣan ⱪoram texi ǝmdi ⱪǝyǝrdidur?
38 ọlọ́run tí ó jẹ ọ̀rá ẹran ẹbọ wọn tí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn? Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n! Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!
Ularning ɵtküzgǝn ⱪurbanliⱪlirining yeƣini yegǝn, Ularning xarab ⱨǝdiyǝliridiki xarabini iqkǝnlǝr ⱪǝyǝrgǝ kǝtti? Əmdi ular ornidin turup silǝrgǝ yardǝm berip, panaⱨinglar bolsun!
39 “Wò ó báyìí pé, Èmi fúnra à mi, Èmi ni! Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi. Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè. Mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná, kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.
Əmdi Mǝn Ɵzüm, pǝⱪǝt Mǝnla «Xu»durmǝn, Manga ⱨǝmraⱨ ⱨeqⱪandaⱪ ilaⱨning yoⱪluⱪini kɵrüp bilinglar. Mǝn ɵltürüp tirildürimǝn, Zǝhimlǝndürüp saⱪaytimǝn; Wǝ ⱨeqkim Mening ⱪolumdin ⱪutⱪuzalmaydu.
40 Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé, Èmi ti wà láààyè títí láé,
Qünki Mǝn ⱪolumni asmanlarƣa kɵtürüp: — «Əbǝdgiqǝ ⱨayatturmǝn» dǝp eytip,
41 nígbà tí mo bá pọ́n idà dídán mi àti tí mo bá sì fi ọwọ́ mi lé ìdájọ́, Èmi yóò san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá mi Èmi ó sì san fún àwọn tí ó kórìíra à mi.
Qaⱪnap turidiƣan ⱪiliqimni ittik ⱪilimǝn, Mening ⱪolum adalǝtni ⱪoral ⱪilip tutidu, Düxmǝnlirimdin intiⱪam alimǝn, Mǝndin nǝprǝtlǝngüqilǝrning ⱪilƣanlirini ularƣa yandurimǝn!
42 Èmi yóò mú ọfà mu ẹ̀jẹ̀, nígbà tí idà mi bá jẹ ẹran: ẹ̀jẹ̀ ẹni pípa àti ẹni ìgbèkùn, láti orí àwọn aṣáájú ọ̀tá.”
Mǝn ya oⱪlirimni ⱪan iqküzüp mǝst ⱪilimǝn, Mening ⱪiliqim gɵx yǝydu, Mǝn ularni ɵltürülgǝnlǝr bilǝn ǝsirlǝrning ⱪenini, Düxmǝnning sǝrdarlirining baxlirini yǝp-iqidiƣan ⱪilimǝn».
43 Ẹ yọ̀ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí òun yóò gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀; yóò sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá a rẹ̀ yóò sì ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àti ènìyàn rẹ̀.
Əy ǝllǝr, Uning hǝlⱪi bilǝn billǝ xadlininglar, Qünki U Ɵz bǝndilirining ⱪenining intiⱪamini alidu, Ɵz düxmǝnlirigǝ ⱪisas yanduridu, Ɵz zemini bilǝn hǝlⱪi üqün kǝqürüm-kafarǝt kǝltürüp beridu».
44 Mose sì wá ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí ní etí àwọn ènìyàn náà, òun, àti Hosea ọmọ Nuni.
Əmdi Musa bilǝn Nunning oƣli Yǝxua kelip bu ƣǝzǝlning barliⱪ sɵzlirini hǝlⱪning aldida oⱪup bǝrdi.
45 Nígbà tí Mose parí i kíka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí Israẹli.
Andin Musa bu ⱨǝmmǝ sɵzlǝrni barliⱪ Israil aldida ahirlaxturup
46 Ó sọ fún un pé, “Ẹ gbé ọkàn an yín lé gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ láàrín yín lónìí, kí ẹ̀yin lè pàṣẹ fún àwọn ọmọ yín láti gbọ́rọ̀ àti láti ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
ularƣa sɵz ⱪilip: «Mǝn bügün otturanglarda silǝrni agaⱨlandurup guwaⱨliⱪ bǝrgǝn bu barliⱪ sɵzlǝrgǝ kɵngül bɵlünglar; silǝr bularni baliliringlarƣa tapilap: «Bu ⱪanunning ⱨǝmmǝ sɵzlirigǝ ǝmǝl ⱪilixⱪa kɵngül ⱪoyunglar» dǝp buyruxunglar kerǝk.
47 Wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ asán fún ọ, ìyè e yín ni wọ́n. Nípa wọn ni ẹ̀yin yóò gbé pẹ́ lórí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ń gòkè e Jordani lọ láti gbà.”
Qünki bu sɵz silǝrgǝ munasiwǝtsiz, ⱪuruⱪ sɵz ǝmǝs, bǝlki silǝrning ⱨayatinglardur! Silǝr u zeminni igilǝxkǝ Iordan dǝryasidin ɵtisilǝr; ɵtkǝndin keyin u zeminda bu sɵz arⱪiliⱪ uzun ɵmür kɵrisilǝr» — dedi.
48 Ní ọjọ́ kan náà, Olúwa sọ fún Mose pé,
Yǝnǝ xu küni Pǝrwǝrdigar Musaƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ dedi: —
49 “Gòkè lọ sí Abarimu sí òkè Nebo ní Moabu, tí ó kọjú sí Jeriko, kí o sì wo ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí mo ń fi fún àwọn ọmọ Israẹli, bí ìní i wọn.
Sǝn uxbu Abarim teƣiƣa, yǝni Yerihoning utturidiki, Moabning zeminidiki Nebo teƣiƣa qiⱪⱪin wǝ xu yǝrdǝ Mǝn Israillarƣa ɵz tǝwǝliki bolux üqün beridiƣan Ⱪanaan zeminini kɵrgin.
50 Ní orí òkè tí ìwọ ń gùn lọ ìwọ yóò kùú níbẹ̀, kí a sì sin ọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin in rẹ Aaroni ti kú ní orí òkè Hori tí a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn an rẹ̀.
Andin akang Ⱨarun Ⱨor teƣida ɵlüp ɵz hǝlⱪlirigǝ ⱪoxulƣandǝk, sǝnmu qiⱪidiƣan xu taƣda ɵlüp hǝlⱪliringgǝ ⱪoxulƣin;
51 Ìdí ni pé ẹ̀yin méjèèjì ṣẹ̀ sí mi láàrín àwọn ọmọ Israẹli ní ibi omi Meriba Kadeṣi ní aginjù Sini àti nítorí ẹ̀yin kò yà mí sí mímọ́ láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
qünki silǝr Zin qɵlidiki Mǝribaⱨ-Ⱪadǝxning sulirining yeniƣa barƣanda, ikkinglar Israillarning arisida Manga wapasizliⱪ kɵrsitip, Israillarning arisida Meni «muⱪǝddǝs» dǝp ⱨɵrmǝtlimidinglar.
52 Nítorí náà, ìwọ yóò rí ilẹ̀ náà ní ọ̀kánkán, o kì yóò wọ inú rẹ̀ ilẹ̀ ti mo ti fi fún àwọn ọmọ Israẹli.”
Xunga sǝn Israillarƣa beridiƣan xu zeminni udulungda kɵrisǝn, lekin uningƣa kirǝlmǝysǝn.

< Deuteronomy 32 >