< Deuteronomy 32 >

1 Fetísílẹ̀, ẹ̀yin ọ̀run, èmi yóò sọ̀rọ̀; ẹ gbọ́, ìwọ ayé, ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Monyɛ aso, mo ɔsoro na mɛkasa; tie, wo asase, nsɛm a efi mʼanom.
2 Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò, kí àwọn ọ̀rọ̀ mi máa sọ̀kalẹ̀ bí ìrì, bí òjò wíníwíní sára ewéko tuntun, bí ọ̀wààrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.
Ma me nkyerɛkyerɛ ntɔ sɛ osu; na me nsɛm nsian sɛ obosu, sɛ osu a ɛpete gu sare foforo so, sɛ osu mmoroso wɔ afifide foforo so.
3 Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa. Ẹyin títóbi Ọlọ́run wa!
Mɛbɔ Awurade din. O, monkamfo yɛn Nyankopɔn kɛseyɛ!
4 Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé, gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo. Ọlọ́run olóòtítọ́ tí kò ṣe àṣìṣe kan, Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.
Ɔne Ɔbotan no, ne nnwuma so nni, na nʼakwan nyinaa ye. Onyankopɔn nokwafo a ɔnyɛ mfomso, Ɔtreneeni ne ɔnokwafo ne no.
5 Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀; fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apá kan tí ó sì dorí kodò.
Porɔwee adidi wɔn mu na wɔnyɛ ne mma; wɔyɛ awo ntoatoaso akɔntɔnkyefo aniwufo.
6 Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn? Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín, tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?
Saa ne ɔkwan a ɛsɛ sɛ mofa so tua Awurade ka ni ana, mo nkwaseafo ne adwenharefo? Ɛnyɛ ɔno ne mo Agya, mo yɛfo no? Ɛnyɛ ɔno na ɔbɔɔ mo na ɔmaa mo nnyinaso?
7 Rántí ìgbà láéláé; wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá. Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ, àwọn àgbàgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.
Monkae tete nna; munnwen tete awo ntoatoaso no ho. Mummisa mo agya na ɔbɛkyerɛ mo. Mummisa mo mpanyimfo na wɔbɛkyerɛ mo ase.
8 Nígbà tí Ọ̀gá-ògo fi ogún àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn, ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Israẹli.
Bere a Ɔsorosoroni no maa amanaman no agyapade, na ɔkyekyɛɛ adesamma nyinaa mu no, ɔtotoo ahye maa nnipa no sɛnea Israelmma no dodow te.
9 Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀, Jakọbu ni ìpín ìní i rẹ̀.
Efisɛ Israelfo yɛ Awurade kyɛfa; Yakob yɛ nʼagyapade wɔde maa no.
10 Ní aginjù ni ó ti rí i, ní aginjù níbi tí ẹranko kò sí. Ó yíká, ó sì tọ́jú rẹ̀, ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.
Ohuu no wɔ sare asase so, asase kesee a hwee nni so so. Ɔde no sie hwɛɛ ne so; ɔbɔɔ ne ho ban sɛ nʼaniwa kurutiayisi,
11 Bí idì ti í ru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ń rábàbà sórí ọmọ rẹ̀, tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sì gbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.
sɛ ɔkɔre a ɔhwanyan ne berebuw mu na ɔbɔ mfamfia fa ne mma ho, na ɔtrɛw ne ntaban mu buma no, soaa no kɔɔ no.
12 Olúwa ṣamọ̀nà; kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.
Awurade nkutoo na ɔkyerɛɛ no kwan; na ananafo nyame biara nka ne ho.
13 Ó mú gun ibi gíga ayé ó sì fi èso oko bọ́ ọ. Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá, àti òróró láti inú akọ òkúta wá.
Ɔma no nantew faa asase no nkoko so; na ɔde mfuw so nnuaba bɔɔ no akɔnhama; Ɔde ɔbotan mu wo ne ngo a efi abohemaa mu,
14 Pẹ̀lú u wàràǹkàṣì àti wàrà àgùntàn àti ti àgbò ẹran àti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, pẹ̀lú àgbò irú u ti Baṣani tí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èso àjàrà, àní àti wáìnì.
nyɛmmoa mu nufusu ne srade, nguamma ne mmirekyi a wɔadɔ srade, Basan adwennini a wɔpaw ne atoko muhumuhu siesiee no. Monom nsa papa a efi bobe mu.
15 Jeṣuruni sanra tán ó sì tàpá; ìwọ sanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán. O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọ o sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.
Yeshurun dɔɔ srade na onyaa ahoɔden; aduan ma wɔyɛɛ duru, yɛɛ pemee. Wɔtoo Onyankopɔn a ɔbɔɔ wɔn no asaworam; wɔpoo wɔn Nkwagye Botan no.
16 Wọ́n sì fi òrìṣà mú un jowú, ohun ìríra ni wọ́n fi mú un bínú.
Wɔma ɔtwee ninkunu wɔ wɔn ananafo anyame no ho na wɔde wɔn abosom a okyi no hyɛɛ no abufuw.
17 Wọ́n rú ẹbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí, ọlọ́run tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ farahàn láìpẹ́, ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.
Wɔbɔɔ afɔre maa atoro anyame a wɔnyɛ Onyankopɔn, anyame a na wonnim wɔn, anyame a wɔbaa nnansa yi ara, anyame a na mo agyanom nsuro wɔn.
18 Ìwọ kò rántí àpáta, tí ó bí ọ; o sì gbàgbé Ọlọ́run tí ó dá ọ.
Mopaa Ɔbotan a ɔyɛɛ mo agya no. Mo werɛ fii Onyankopɔn a ɔwoo mo no.
19 Olúwa sì rí èyí ó sì kọ̀ wọ́n, nítorí tí ó ti bínú nítorí ìwà ìmúnibínú àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ.
Awurade huu eyi na ɔpoo wɔn efisɛ ne mmabarima ne ne mmabea hyɛɛ no abufuw.
20 Ó sì wí pé, “Èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò lára wọn, èmi yóò sì wò ó bí ìgbẹ̀yìn in wọn yóò ti rí; nítorí wọ́n jẹ́ ìran alágídí, àwọn ọmọ tí kò sí ìgbàgbọ́ nínú wọn.
Ɔkae se, “Mede mʼanim behintaw wɔn na wɔahu sɛnea wɔn awiei bɛyɛ Efisɛ, wɔyɛ awo ntoatoaso akɔntɔnkyefo; mma a wonni nokware.
21 Wọ́n fi mí jowú nípa ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run, wọ́n sì fi ohun asán an wọn mú mi bínú. Èmi yóò mú wọn kún fún ìlara láti ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe ènìyàn; èmi yóò sì mú wọn bínú láti ọ̀dọ̀ aṣiwèrè orílẹ̀-èdè.
Wɔde nea ɛnyɛ Onyame ahyɛ me ninkutwe na wɔde wɔn ahoni ahuhuw no ahyɛ me abufuw. Mɛma wɔn ani abere nnipa a wɔnyɛ me nkurɔfo. Mɛma ɔman a wonni ntease no ahyɛ wɔn abufuw.
22 Nítorí pé iná kan ràn nínú ìbínú mi, yóò sì jó dé ipò ikú ní ìsàlẹ̀. Yóò sì run ayé àti ìkórè e rẹ̀ yóò sì tiná bọ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá. (Sheol h7585)
Efisɛ mʼabufuwhyew befita ogya mu, nea ɛhyew kɔka awufo a wɔwɔ asase ase no. Ɛbɛsɛe asase ne so nnɔbae na ɛpaapae mmepɔw fapem. (Sheol h7585)
23 “Èmi yóò kó àwọn ohun búburú lé wọn lórí èmi ó sì na ọfà mi tán sí wọn lára.
“Mɛhɔre amanehunu ahorow no siw wɔ wɔn so na matow me bɛmma awowɔ wɔn.
24 Èmi yóò mú wọn gbẹ, ooru gbígbóná àti ìparun kíkorò ni a ó fi run wọ́n. Pẹ̀lú oró ohun tí ń rákò nínú erùpẹ̀.
Mede ɔkɔm kɛse, atiridiinini ne owuyare a ɛsɛe ade; mɛsoma nkekammoa se aba wɔn so; nhurutoa a wɔtow si wɔ mfutuma mu no ano bɔre.
25 Idà ní òde, àti ẹ̀rù nínú ìyẹ̀wù, ni yóò run ọmọkùnrin àti wúńdíá. Ọmọ ẹnu ọmú àti arúgbó eléwú irun pẹ̀lú.
Afoa bɛma wɔahwere wɔn mma wɔ abɔnten so; wɔn afi mu, ehu bɛtɔ wɔn so. Mmerante ne mmabaa, mmofra ne nkwakoraa ase bɛhyew.
26 Mo ní èmi yóò tú wọn ká èmi yóò sì mú ìrántí i wọn dà kúrò nínú àwọn ènìyàn,
Mekae se mɛbɔ wɔn ahwete na mapepa wɔn din afi nnipa adwene mu.
27 nítorí bí mo ti bẹ̀rù ìbínú ọ̀tá, kí àwọn ọ̀tá a wọn kí ó má ba à wí pé, ‘Ọwọ́ wa lékè ni; kì í sì í ṣe Olúwa ni ó ṣe gbogbo èyí.’”
Nanso misuroo ɔtamfo fɛwdi, anyɛ a na ɔtamfo ante ase aka se, ‘Yɛn nsa adi nkonim; Ɛnyɛ Awurade na ɔyɛɛ eyinom nyinaa.’”
28 Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí òye nínú wọn.
Israel yɛ ɔman a wonni adwene. Obi nni wɔn mu a ɔwɔ nhumu.
29 Bí ó ṣe pé wọ́n gbọ́n, kí òye yìí sì yé wọn kí wọn ro bí ìgbẹ̀yìn wọn yóò ti rí!
Sɛ anka wɔyɛ anyansafo na wɔbɛte eyi ase, na wɔahu nea wɔn awiei bɛyɛ ɛ!
30 Báwo ni ẹnìkan ṣe lè lé ẹgbẹ̀rún, tàbí tí ẹni méjì sì lè lé ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sá, bí kò ṣe pé àpáta wọn ti tà wọ́n, bí kò ṣe pé Olúwa wọn ti fi wọ́n tọrẹ?
Ɛbɛyɛ dɛn na onipa baako ataa nnipa apem, na baanu bɛma mpem du aguan, gye sɛ wɔn Botan atɔn wɔn gye sɛ Awurade ayi wɔn ama.
31 Nítorí pé àpáta wọn kò dàbí àpáta wa, àní àwọn ọ̀tá wa tìkára wọn ń ṣe onídàájọ́.
Efisɛ wɔn botan nte sɛ yɛn Botan, sɛnea yɛn atamfo mpo gye to mu no.
32 Igi àjàrà a wọn wá láti igi àjàrà Sodomu àti ti ìgbẹ́ ẹ Gomorra. Èso àjàrà wọn kún fún oró, ìdì wọn korò.
Wɔn bobe fi Sodom bobe mu na efi Gomora mfuw mu. Awuduru ahyɛ wɔn bobe aba mma, na bɔnwoma ahyɛ wɔn kasiaw amaama.
33 Ọtí wáìnì wọn ìwọ ti dragoni ni, àti oró mímú ti ejò paramọ́lẹ̀.
Wɔn bobesa yɛ awɔ ano bɔre; aprammiri ano bɔrewerɛmfo.
34 “Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́ èmi kò sì fi èdìdì dì í ní ìṣúra mi?
“So menkoraa eyi mmoroso, na mensɔw ano wɔ mʼademude mu ana
35 Ti èmi ni láti gbẹ̀san. Èmi yóò san án fún wọn ní àkókò tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yóò yọ; ọjọ́ ìdààmú wọn súnmọ́ etílé ohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”
Mɛtɔ were; metua so ka. Wɔn nan bɛwatiri bere a ɛsɛ mu; wɔn atoyerɛnkyɛm no abɛn na wɔn sɛe taa wɔn.”
36 Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tán tí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.
Awurade bebu ne nkurɔfo atɛn na wasesa nʼadwene wɔ ne nkoa ho, bere a wahu sɛ wɔn ahoɔden asa, na ɛnkaa obiara, akoa anaa ɔdehye.
37 Yóò wí pé, “Òrìṣà wọn dà báyìí, àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,
Obebisa se, “Afei wɔn anyame no wɔ he, ɔbotan a wɔde yɛɛ wɔn guankɔbea,
38 ọlọ́run tí ó jẹ ọ̀rá ẹran ẹbọ wọn tí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn? Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n! Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!
anyame a wodii wɔn afɔrebɔde mu srade na wɔnom wɔn ɔnom afɔrebɔ mu nsa no? Ma wɔnsɔre mmɛboa mo! Ma womegye mo!
39 “Wò ó báyìí pé, Èmi fúnra à mi, Èmi ni! Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi. Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè. Mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná, kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.
“Afei, munhu sɛ, me ara me ne no! Onyame biara nni hɔ sɛ me! Me na mikum na mema nkwa: Me na mipira, na mɛkyekye, na obi rentumi nnye mfi me nsam.
40 Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé, Èmi ti wà láààyè títí láé,
Mema me nsa so kyerɛ ɔsoro de nidi sua sɛ: Sɛ mete ase daa yi,
41 nígbà tí mo bá pọ́n idà dídán mi àti tí mo bá sì fi ọwọ́ mi lé ìdájọ́, Èmi yóò san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá mi Èmi ó sì san fún àwọn tí ó kórìíra à mi.
sɛ mesew me afoa a ɛpa yerɛwyerɛw no na mifi atemmu mu so mu kuaw a, mɛtɔ mʼatamfo so were na matua wɔn a wokyi me ka.
42 Èmi yóò mú ọfà mu ẹ̀jẹ̀, nígbà tí idà mi bá jẹ ẹran: ẹ̀jẹ̀ ẹni pípa àti ẹni ìgbèkùn, láti orí àwọn aṣáájú ọ̀tá.”
Mɛma me bɛmma anom mogya abow, na mʼafoa adi ɔhonam, atɔfo ne nnommumfo mogya, atamfo ntuanofo no ti.”
43 Ẹ yọ̀ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí òun yóò gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀; yóò sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá a rẹ̀ yóò sì ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àti ènìyàn rẹ̀.
Mo aman, mo ne ne nkurɔfo nni ahurusi, efisɛ ɔbɛtɔ ne nkoa mogya so were; ɔbɛtɔ were wɔ nʼatamfo so na wapata ama nʼasase ne ne nkurɔfo.
44 Mose sì wá ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí ní etí àwọn ènìyàn náà, òun, àti Hosea ọmọ Nuni.
Mose ne Nun babarima Hosea ba bɛkaa dwom yi mu nsɛm nyinaa kyerɛɛ nnipa no.
45 Nígbà tí Mose parí i kíka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí Israẹli.
Mose woroo saa dwom no mu nsɛm no kyerɛɛ Israelfo no wiee no,
46 Ó sọ fún un pé, “Ẹ gbé ọkàn an yín lé gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ láàrín yín lónìí, kí ẹ̀yin lè pàṣẹ fún àwọn ọmọ yín láti gbọ́rọ̀ àti láti ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
ɔka kaa ho se, “Momfa nsɛm a maka akyerɛ mo no nyinaa nsie mo koma mu. Monka nkyerɛ mo mma nso, sɛnea ɛbɛyɛ a wobedi saa mmara yi mu nsɛm nyinaa so pɛpɛɛpɛ.
47 Wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ asán fún ọ, ìyè e yín ni wọ́n. Nípa wọn ni ẹ̀yin yóò gbé pẹ́ lórí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ń gòkè e Jordani lọ láti gbà.”
Saa nkyerɛkyerɛ yi nyɛ nsɛm bi a wɔde rema mo kwa, ɛyɛ mo nkwa! Sɛ mudi so a, mubenyin akyɛ wɔ asase a moretwa Asubɔnten Yordan akɔfa no so.”
48 Ní ọjọ́ kan náà, Olúwa sọ fún Mose pé,
Da no ara, Awurade ka kyerɛɛ Mose se,
49 “Gòkè lọ sí Abarimu sí òkè Nebo ní Moabu, tí ó kọjú sí Jeriko, kí o sì wo ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí mo ń fi fún àwọn ọmọ Israẹli, bí ìní i wọn.
“Kɔ Moab, kɔ mmepɔw a ɛwɔ asu no apuei no so, na foro Nebo bepɔw a ɛne Yeriko di nhwɛanim no. To wʼani hwɛ Kanaan asase no, asase a mede rema Israelfo sɛ wɔn agyapade no.
50 Ní orí òkè tí ìwọ ń gùn lọ ìwọ yóò kùú níbẹ̀, kí a sì sin ọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin in rẹ Aaroni ti kú ní orí òkè Hori tí a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn an rẹ̀.
Bepɔw a woaforo no so hɔ na wobɛkɔ akɔka wʼagyanom ho, sɛnea wo nua Aaron wuu wɔ Hor bepɔw so kɔkaa nʼagyanom ho no.
51 Ìdí ni pé ẹ̀yin méjèèjì ṣẹ̀ sí mi láàrín àwọn ọmọ Israẹli ní ibi omi Meriba Kadeṣi ní aginjù Sini àti nítorí ẹ̀yin kò yà mí sí mímọ́ láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Efisɛ mo baanu dii me huammɔ wɔ Israelfo mu wɔ Meriba ne Kades asu ho wɔ Sin sare so. Moanni me kronkronyɛ ho adanse ankyerɛ Israelfo no wɔ hɔ.
52 Nítorí náà, ìwọ yóò rí ilẹ̀ náà ní ọ̀kánkán, o kì yóò wọ inú rẹ̀ ilẹ̀ ti mo ti fi fún àwọn ọmọ Israẹli.”
Ɛno nti, mubehu asase no afi akyiri, nanso morenkɔ asase a mede rema Israelfo no so.”

< Deuteronomy 32 >