< Deuteronomy 32 >

1 Fetísílẹ̀, ẹ̀yin ọ̀run, èmi yóò sọ̀rọ̀; ẹ gbọ́, ìwọ ayé, ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
«ای آسمان گوش بگیر تا بگویم، و ای زمین سخنان مرا بشنو!
2 Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò, kí àwọn ọ̀rọ̀ mi máa sọ̀kalẹ̀ bí ìrì, bí òjò wíníwíní sára ewéko tuntun, bí ọ̀wààrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.
تعلیم من مثل باران خواهد بارید و مانند شبنم بر زمین خواهد نشست. کلام من مثل قطره‌های باران بر سبزهٔ تازه، و مانند نم‌نم باران بر گیاهان فرو خواهد ریخت.
3 Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa. Ẹyin títóbi Ọlọ́run wa!
نام خداوند را ستایش خواهم کرد، و قوم او عظمت وی را وصف خواهند نمود.
4 Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé, gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo. Ọlọ́run olóòtítọ́ tí kò ṣe àṣìṣe kan, Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.
خداوند همچون صخره‌ای است و اعمالش کامل و عادل، اوست خدای امین و دادگر، از گناه مبرا و با انصاف.
5 Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀; fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apá kan tí ó sì dorí kodò.
«قوم او فاسد شده، باعث ننگ او گشته‌اند، آنها دیگر فرزندان او نیستند، بلکه قومی هستند کجرو و نافرمان.
6 Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn? Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín, tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?
ای قوم احمق و نادان! آیا اینچنین از خدوند خود قدردانی می‌کنی؟ آیا او پدر و خالق تو نیست؟ آیا او نبود که تو را به وجود آورد؟
7 Rántí ìgbà láéláé; wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá. Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ, àwọn àgbàgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.
«روزهای گذشته را به یاد آر، از پدران خود بپرس تابه تو بگویند، از مشایخ سؤال کن تا به تو جواب دهند.
8 Nígbà tí Ọ̀gá-ògo fi ogún àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn, ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Israẹli.
آنگاه که خدای متعال، زمین را میان قومها تقسیم کرد، آنگاه که انسانها را منتشر ساخت، او مرزهای آنها را تعیین نمود، برحسب تعداد بنی‌اسرائیل.
9 Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀, Jakọbu ni ìpín ìní i rẹ̀.
«زیرا قوم اسرائیل متعلق به خداوندند؛ و یعقوب میراث خاص اوست.
10 Ní aginjù ni ó ti rí i, ní aginjù níbi tí ẹranko kò sí. Ó yíká, ó sì tọ́jú rẹ̀, ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.
او اسرائیل را در بیابان خشک و سوزان یافت، او را در برگرفت و از او مراقبت کرد، و مانند مردمک چشم خود از او محافظت نمود،
11 Bí idì ti í ru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ń rábàbà sórí ọmọ rẹ̀, tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sì gbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.
درست مانند عقابی که جوجه‌هایش را به پرواز درمی‌آورد، و بالهای خود را می‌گشاید تا آنها را بگیرد و با خود ببرد.
12 Olúwa ṣamọ̀nà; kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.
او قوم خود را خودش رهبری نمود و هیچ خدای دیگری با وی نبود.
13 Ó mú gun ibi gíga ayé ó sì fi èso oko bọ́ ọ. Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá, àti òróró láti inú akọ òkúta wá.
خداوند به آنها کوهستانهای حاصلخیز بخشید تا از محصول آنها سیر شوند. او به ایشان عسل از میان صخره، و روغن از میان سنگ خارا داد.
14 Pẹ̀lú u wàràǹkàṣì àti wàrà àgùntàn àti ti àgbò ẹran àti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, pẹ̀lú àgbò irú u ti Baṣani tí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èso àjàrà, àní àti wáìnì.
بهترین گاوان و گوسفندان را به آنان بخشید تا از آنها شیر و کرهٔ فراوان به دست آورند. قوچهای فربه باشان و بزها، عالیترین گندمها و مرغوبترین شرابها را به آنها عطا فرمود.
15 Jeṣuruni sanra tán ó sì tàpá; ìwọ sanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán. O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọ o sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.
«اما یِشورون سیر شده، یاغی گشت، فربه و تنومند و چاق شده، خدایی را که او را آفریده بود ترک نمود، و”صخرهٔ نجاتِ“خود را به فراموشی سپرد.
16 Wọ́n sì fi òrìṣà mú un jowú, ohun ìríra ni wọ́n fi mú un bínú.
آنها با بت‌پرستی قبیح خود، خشم و غیرت خداوند را برانگیختند.
17 Wọ́n rú ẹbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí, ọlọ́run tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ farahàn láìpẹ́, ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.
به بتها که خدا نبودند قربانی تقدیم کردند به خدایان جدیدی که پدرانشان هرگز آنها را نشناخته بودند، خدایانی که بنی‌اسرائیل آنها را پرستش نکرده بودند.
18 Ìwọ kò rántí àpáta, tí ó bí ọ; o sì gbàgbé Ọlọ́run tí ó dá ọ.
آنها خدایی را که”صخره“شان بود و ایشان را به وجود آورده بود، فراموش کردند.
19 Olúwa sì rí èyí ó sì kọ̀ wọ́n, nítorí tí ó ti bínú nítorí ìwà ìmúnibínú àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ.
«وقتی خداوند دید که پسران و دخترانش چه می‌کنند، خشمگین شده از آنان بیزار گشت.
20 Ó sì wí pé, “Èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò lára wọn, èmi yóò sì wò ó bí ìgbẹ̀yìn in wọn yóò ti rí; nítorí wọ́n jẹ́ ìran alágídí, àwọn ọmọ tí kò sí ìgbàgbọ́ nínú wọn.
او فرمود:”آنها را ترک می‌کنم تا هر چه می‌خواهد بر سرشان بیاید، زیرا آنها قومی یاغی و خیانتکار هستند.
21 Wọ́n fi mí jowú nípa ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run, wọ́n sì fi ohun asán an wọn mú mi bínú. Èmi yóò mú wọn kún fún ìlara láti ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe ènìyàn; èmi yóò sì mú wọn bínú láti ọ̀dọ̀ aṣiwèrè orílẹ̀-èdè.
آنها با پرستش خدایان بیگانه و باطل، خشم و غیرت مرا برانگیختند، من نیز آنها را با قومهای بیگانه و باطل به خشم و غیرت می‌آورم.
22 Nítorí pé iná kan ràn nínú ìbínú mi, yóò sì jó dé ipò ikú ní ìsàlẹ̀. Yóò sì run ayé àti ìkórè e rẹ̀ yóò sì tiná bọ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá. (Sheol h7585)
خشم من افروخته شده، زمین و محصولش را خواهد سوزانید، و تا اعماق زمین فرو رفته، بنیاد کوهها را به آتش خواهد کشید. (Sheol h7585)
23 “Èmi yóò kó àwọn ohun búburú lé wọn lórí èmi ó sì na ọfà mi tán sí wọn lára.
بلایا بر سر ایشان خواهم آورد و تمام تیرهای خود را به سوی ایشان پرتاب خواهم کرد.
24 Èmi yóò mú wọn gbẹ, ooru gbígbóná àti ìparun kíkorò ni a ó fi run wọ́n. Pẹ̀lú oró ohun tí ń rákò nínú erùpẹ̀.
آنها را با گرسنگی و تب سوزان و مرض کشنده از پای در خواهم آورد. جانوران وحشی را به جان آنها خواهم انداخت و مارهای سمی را خواهم فرستاد تا ایشان را بگزند.
25 Idà ní òde, àti ẹ̀rù nínú ìyẹ̀wù, ni yóò run ọmọkùnrin àti wúńdíá. Ọmọ ẹnu ọmú àti arúgbó eléwú irun pẹ̀lú.
در بیرون، شمشیرِ دشمنان، کشتار خواهد کرد و در درون خانه‌ها وحشت حکمفرما خواهد بود. مردان و زنان جوان، کودکان و پیران، همگی نابود خواهند شد.
26 Mo ní èmi yóò tú wọn ká èmi yóò sì mú ìrántí i wọn dà kúrò nínú àwọn ènìyàn,
می‌خواستم آنها را به کلی هلاک کنم، به طوری که یاد آنها نیز از خاطرها محو گردد،
27 nítorí bí mo ti bẹ̀rù ìbínú ọ̀tá, kí àwọn ọ̀tá a wọn kí ó má ba à wí pé, ‘Ọwọ́ wa lékè ni; kì í sì í ṣe Olúwa ni ó ṣe gbogbo èyí.’”
ولی فکر کردم که شاید دشمنان بگویند: «قدرت ما بود که آنها را نابود کرد نه قدرت خداوند.»“
28 Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí òye nínú wọn.
«اسرائیل قومی است نادان و بی‌فهم.
29 Bí ó ṣe pé wọ́n gbọ́n, kí òye yìí sì yé wọn kí wọn ro bí ìgbẹ̀yìn wọn yóò ti rí!
ای کاش شعور داشت و می‌فهمید که چرا شکست خورده است.
30 Báwo ni ẹnìkan ṣe lè lé ẹgbẹ̀rún, tàbí tí ẹni méjì sì lè lé ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sá, bí kò ṣe pé àpáta wọn ti tà wọ́n, bí kò ṣe pé Olúwa wọn ti fi wọ́n tọrẹ?
چرا هزار نفرشان از یک نفر، و ده هزار نفرشان از دو نفر شکست خوردند؟ زیرا”صخرهٔ“ایشان، ایشان را ترک کرده بود، خداوند ایشان را به دست دشمن تسلیم نموده بود.
31 Nítorí pé àpáta wọn kò dàbí àpáta wa, àní àwọn ọ̀tá wa tìkára wọn ń ṣe onídàájọ́.
حتی دشمنانشان نیز می‌دانند که صخره‌شان مانند صخرهٔ ما نیست.
32 Igi àjàrà a wọn wá láti igi àjàrà Sodomu àti ti ìgbẹ́ ẹ Gomorra. Èso àjàrà wọn kún fún oró, ìdì wọn korò.
دشمنان اسرائیل مانند مردم سدوم و عموره فاسدند، مثل درختانی می‌باشند که انگور تلخ و سمی به بار می‌آورند،
33 Ọtí wáìnì wọn ìwọ ti dragoni ni, àti oró mímú ti ejò paramọ́lẹ̀.
مانند شرابی هستند که از زهر مار گرفته شده باشد.
34 “Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́ èmi kò sì fi èdìdì dì í ní ìṣúra mi?
«خداوند می‌فرماید:”آنچه دشمنان کرده‌اند نزد من ذخیره شده و در خزانه‌های من مختوم گردیده است.
35 Ti èmi ni láti gbẹ̀san. Èmi yóò san án fún wọn ní àkókò tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yóò yọ; ọjọ́ ìdààmú wọn súnmọ́ etílé ohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”
من به موقع آنها را مجازات خواهم کرد. انتقام و جزا از آنِ من است. به‌زودی آنها خواهند افتاد، زیرا روز هلاکت ایشان نزدیک است.“
36 Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tán tí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.
«خداوند به داد قومش خواهد رسید و بر بندگانش شفقت خواهد فرمود، وقتی ببیند که قوت ایشان از بین رفته و برای برده و آزاد رمقی نمانده است.
37 Yóò wí pé, “Òrìṣà wọn dà báyìí, àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,
خداوند به قومش خواهد گفت:”کجا هستند خدایان شما، «صخره‌هایی» که به آنها پناه می‌بردید
38 ọlọ́run tí ó jẹ ọ̀rá ẹran ẹbọ wọn tí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn? Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n! Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!
و چربی قربانیها را به آنان می‌خوراندید و شراب برای نوشیدن به آنها تقدیم می‌کردید؟ بگذارید آنها برخیزند و به شما کمک کنند و برای شما پناهگاه باشند.
39 “Wò ó báyìí pé, Èmi fúnra à mi, Èmi ni! Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi. Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè. Mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná, kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.
بدانید که تنها من خدا هستم و خدای دیگری غیر از من نیست. می‌میرانم و زنده می‌سازم، مجروح می‌کنم و شفا می‌بخشم، و کسی نمی‌تواند از دست من برهاند.
40 Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé, Èmi ti wà láààyè títí láé,
من که تا ابد زنده هستم، دست خود را به آسمان برافراشته، اعلام می‌کنم
41 nígbà tí mo bá pọ́n idà dídán mi àti tí mo bá sì fi ọwọ́ mi lé ìdájọ́, Èmi yóò san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá mi Èmi ó sì san fún àwọn tí ó kórìíra à mi.
که شمشیر براق خود را تیز کرده، بر دشمنانم داوری خواهم نمود. از آنها انتقام خواهم گرفت و کسانی را که از من نفرت دارند مجازات خواهم کرد.
42 Èmi yóò mú ọfà mu ẹ̀jẹ̀, nígbà tí idà mi bá jẹ ẹran: ẹ̀jẹ̀ ẹni pípa àti ẹni ìgbèkùn, láti orí àwọn aṣáájú ọ̀tá.”
تیرهایم غرق خون دشمنان خواهند شد، شمشیرم گوشت کشته‌شدگان و اسیران را خواهد درید و به خون آنها آغشته خواهد گشت، سرهای رهبران آنها پوشیده از خون خواهند شد.“
43 Ẹ yọ̀ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí òun yóò gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀; yóò sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá a rẹ̀ yóò sì ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àti ènìyàn rẹ̀.
«ای آسمانها، با او شادی کنید، و ای همهٔ فرشتگان خدا او را پرستش نمایند! ای قومها با قوم او شادی کنید، فرشتگان خدا در او تقویت یابند؛ زیرا او انتقام خون بندگانش را خواهد گرفت. او از دشمنان خود انتقام خواهد گرفت، کسانی را که از او بیزارند سزا خواهد داد، و قوم و سرزمین خود را از گناه پاک خواهد ساخت.»
44 Mose sì wá ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí ní etí àwọn ènìyàn náà, òun, àti Hosea ọmọ Nuni.
وقتی که موسی و یوشع کلمات این سرود را برای قوم اسرائیل خواندند،
45 Nígbà tí Mose parí i kíka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí Israẹli.
46 Ó sọ fún un pé, “Ẹ gbé ọkàn an yín lé gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ láàrín yín lónìí, kí ẹ̀yin lè pàṣẹ fún àwọn ọmọ yín láti gbọ́rọ̀ àti láti ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
موسی به قوم گفت: «سخنانی را که امروز به شما گفتم، در دل خود جای دهید و به فرزندان خود دستور دهید تا به دقت از تمام قوانین خدا اطاعت کنند؛
47 Wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ asán fún ọ, ìyè e yín ni wọ́n. Nípa wọn ni ẹ̀yin yóò gbé pẹ́ lórí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ń gòkè e Jordani lọ láti gbà.”
زیرا این قوانین کلماتی بی‌ارزش نیستند، بلکه حیات شما هستند. از آنها اطاعت کنید تا در سرزمینی که در آن طرف رود اردن تصرف خواهید کرد عمر طولانی داشته باشید.»
48 Ní ọjọ́ kan náà, Olúwa sọ fún Mose pé,
همان روز خداوند به موسی گفت:
49 “Gòkè lọ sí Abarimu sí òkè Nebo ní Moabu, tí ó kọjú sí Jeriko, kí o sì wo ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí mo ń fi fún àwọn ọmọ Israẹli, bí ìní i wọn.
«به کوهستان عباریم واقع در سرزمین موآب مقابل اریحا برو. در آنجا بر کوه نبو برآی و تمام سرزمین کنعان را که به قوم اسرائیل می‌دهم، ببین.
50 Ní orí òkè tí ìwọ ń gùn lọ ìwọ yóò kùú níbẹ̀, kí a sì sin ọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin in rẹ Aaroni ti kú ní orí òkè Hori tí a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn an rẹ̀.
سپس تو در آن کوه خواهی مرد و به اجداد خود خواهی پیوست همان‌طور که برادرت هارون نیز در کوه هور درگذشت و به اجداد خود پیوست،
51 Ìdí ni pé ẹ̀yin méjèèjì ṣẹ̀ sí mi láàrín àwọn ọmọ Israẹli ní ibi omi Meriba Kadeṣi ní aginjù Sini àti nítorí ẹ̀yin kò yà mí sí mímọ́ láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
زیرا هر دو شما در برابر قوم اسرائیل، کنار چشمهٔ مریبهٔ قادش واقع در بیابان صین، حرمت قدوسیت مرا نگه نداشتید.
52 Nítorí náà, ìwọ yóò rí ilẹ̀ náà ní ọ̀kánkán, o kì yóò wọ inú rẹ̀ ilẹ̀ ti mo ti fi fún àwọn ọmọ Israẹli.”
سرزمینی را که به قوم اسرائیل می‌دهم، در برابر خود، خواهی دید ولی هرگز وارد آن نخواهی شد.»

< Deuteronomy 32 >