< Deuteronomy 32 >

1 Fetísílẹ̀, ẹ̀yin ọ̀run, èmi yóò sọ̀rọ̀; ẹ gbọ́, ìwọ ayé, ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Ņemiet vērā, debesis, jo es runāšu, un zeme lai dzird manas mutes vārdus.
2 Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò, kí àwọn ọ̀rọ̀ mi máa sọ̀kalẹ̀ bí ìrì, bí òjò wíníwíní sára ewéko tuntun, bí ọ̀wààrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.
Mana mācība lai līst kā lietus, un mana valoda lai pil kā rasa, kā lietutiņš uz zaļumu, un kā lāses uz zāli
3 Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa. Ẹyin títóbi Ọlọ́run wa!
Jo es slavēšu Tā Kunga vārdu; dodiet godu mūsu Dievam.
4 Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé, gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo. Ọlọ́run olóòtítọ́ tí kò ṣe àṣìṣe kan, Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.
Viņš ir tas akmens kalns, Viņa darbs ir pilnīgs, jo visi Viņa ceļi ir tiesa; Dievs ir patiesība un bez viltus, Viņš ir taisns un patiesīgs.
5 Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀; fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apá kan tí ó sì dorí kodò.
Pret Viņu tie apgrēkojušies; tie nav Viņa bērni, bet sev par kaunu, nikna un netikla cilts.
6 Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn? Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín, tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?
Vai jūs Tam Kungam tā atmaksājiet, tu ģeķīga un negudra tauta? Vai Viņš nav tavs tēvs, kam tu piederi, kas tevi radījis un sataisījis?
7 Rántí ìgbà láéláé; wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá. Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ, àwọn àgbàgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.
Piemini tās senās dienas, ņemiet vērā tos gadus no radu radiem, vaicā savam tēvam, tas tev to stāstīs, saviem vecajiem, tie tev to sacīs.
8 Nígbà tí Ọ̀gá-ògo fi ogún àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn, ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Israẹli.
Kad tas visuaugstais tautām deva viņu daļas un šķīra cilvēku bērnus, tad Viņš tautām cēla robežas pēc Israēla bērnu skaita.
9 Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀, Jakọbu ni ìpín ìní i rẹ̀.
Jo Tā Kunga daļa ir Viņa ļaudis, Jēkabs ir Viņa īpaša mantība.
10 Ní aginjù ni ó ti rí i, ní aginjù níbi tí ẹranko kò sí. Ó yíká, ó sì tọ́jú rẹ̀, ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.
Viņš to atrada tuksneša zemē, briesmīgā kaukšanas postažā, Viņš to pasargāja, kā Savu acs raugu.
11 Bí idì ti í ru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ń rábàbà sórí ọmọ rẹ̀, tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sì gbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.
Kā ērglis savu perēkli vedina un lidinājās pār saviem bērniem, izplāta savus spārnus un tos uzņem un tos nes uz saviem spārniem,
12 Olúwa ṣamọ̀nà; kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.
Tā Tas Kungs vien tos vadīja, un sveša dieva nebija ar viņu.
13 Ó mú gun ibi gíga ayé ó sì fi èso oko bọ́ ọ. Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá, àti òróró láti inú akọ òkúta wá.
Viņš to spēcīgi vadīja pār zemes augstumiem, to ēdināja ar tīruma augļiem un to zīdināja ar medu no klints un ar eļļu no cieta akmens.
14 Pẹ̀lú u wàràǹkàṣì àti wàrà àgùntàn àti ti àgbò ẹran àti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, pẹ̀lú àgbò irú u ti Baṣani tí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èso àjàrà, àní àti wáìnì.
Sviestu no govīm, un pienu no avīm, līdz ar jēru taukiem, un Basanas aunus un āžus ar taukām īkstīm, tīrus treknus kviešus un vīnogu sulu, - vīna ogu asinis tu dzēri, vīnu.
15 Jeṣuruni sanra tán ó sì tàpá; ìwọ sanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán. O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọ o sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.
Kad nu Ješuruns (t.i. Israēls) palika trekns, tad viņš spēra, - tu paliki trekns un tukls un resns, - tad viņš atstāja Dievu, savu Radītāju, un nicināja savas pestīšanas akmens kalnu.
16 Wọ́n sì fi òrìṣà mú un jowú, ohun ìríra ni wọ́n fi mú un bínú.
Tie Viņu tirināja caur svešiem (dieviem), caur negantībām tie Viņu apkaitināja.
17 Wọ́n rú ẹbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí, ọlọ́run tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ farahàn láìpẹ́, ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.
Tie upurēja jodiem, nedievam, dieviem, ko tie nepazina, jauniem, kas nesen cēlušies, ko jūsu tēvi nav bijušies.
18 Ìwọ kò rántí àpáta, tí ó bí ọ; o sì gbàgbé Ọlọ́run tí ó dá ọ.
To akmens kalnu, kas tevi dzemdinājis, tu atstāji, un aizmirsi Dievu, kas tevi radījis.
19 Olúwa sì rí èyí ó sì kọ̀ wọ́n, nítorí tí ó ti bínú nítorí ìwà ìmúnibínú àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ.
Kad Tas Kungs to redzēja, tad Viņš atmeta īgnumā Savus dēlus un Savas meitas,
20 Ó sì wí pé, “Èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò lára wọn, èmi yóò sì wò ó bí ìgbẹ̀yìn in wọn yóò ti rí; nítorí wọ́n jẹ́ ìran alágídí, àwọn ọmọ tí kò sí ìgbàgbọ́ nínú wọn.
Un sacīja: Es paslēpšu Savu vaigu no viņiem, Es redzēšu, kā tiem pēc klāsies, jo tie ir netikla tauta, bērni bez ticības.
21 Wọ́n fi mí jowú nípa ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run, wọ́n sì fi ohun asán an wọn mú mi bínú. Èmi yóò mú wọn kún fún ìlara láti ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe ènìyàn; èmi yóò sì mú wọn bínú láti ọ̀dọ̀ aṣiwèrè orílẹ̀-èdè.
Tie Mani tirinājuši caur nedievu, tie Mani kaitinājuši caur savām nelietībām; tad arī Es viņus tirināšu caur netautu, caur ģeķīgu tautu Es tos kaitināšu.
22 Nítorí pé iná kan ràn nínú ìbínú mi, yóò sì jó dé ipò ikú ní ìsàlẹ̀. Yóò sì run ayé àti ìkórè e rẹ̀ yóò sì tiná bọ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá. (Sheol h7585)
Jo uguns ir iededzies no Manām dusmām un degs līdz visdziļākai ellei un aprīs zemi ar viņas augļiem un iededzinās kalnu pamatus. (Sheol h7585)
23 “Èmi yóò kó àwọn ohun búburú lé wọn lórí èmi ó sì na ọfà mi tán sí wọn lára.
Es sakrāšu pār tiem ļaunumus, Savas bultas Es uz tiem izšaušu.
24 Èmi yóò mú wọn gbẹ, ooru gbígbóná àti ìparun kíkorò ni a ó fi run wọ́n. Pẹ̀lú oró ohun tí ń rákò nínú erùpẹ̀.
Badā tiem būs izģinst, mēris un rūgtas sērgas tos aprīs, Es sūtīšu zvēru zobus pret tiem un pīšļos līdēju čūsku dzeloņus.
25 Idà ní òde, àti ẹ̀rù nínú ìyẹ̀wù, ni yóò run ọmọkùnrin àti wúńdíá. Ọmọ ẹnu ọmú àti arúgbó eléwú irun pẹ̀lú.
Ārā tos postīs zobens un iekšā briesmas, kā jaunekļus, tā jaunavas, zīdāmos līdz ar sirmgalvjiem.
26 Mo ní èmi yóò tú wọn ká èmi yóò sì mú ìrántí i wọn dà kúrò nínú àwọn ènìyàn,
Es sacītu: Es tos izputināšu, Es izdeldēšu viņu piemiņu starp cilvēkiem, -
27 nítorí bí mo ti bẹ̀rù ìbínú ọ̀tá, kí àwọn ọ̀tá a wọn kí ó má ba à wí pé, ‘Ọwọ́ wa lékè ni; kì í sì í ṣe Olúwa ni ó ṣe gbogbo èyí.’”
Ja Es nebītos, ka viņu ienaidnieki Mani nesadusmo, ka viņu spaidītāji nesaprazdami nesaka: mūsu roka bija augsta, un ne Tas Kungs visu to darījis.
28 Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí òye nínú wọn.
Jo tie ir ļaudis bez padoma, un saprašanas tiem nav.
29 Bí ó ṣe pé wọ́n gbọ́n, kí òye yìí sì yé wọn kí wọn ro bí ìgbẹ̀yìn wọn yóò ti rí!
Ak kaut viņi būtu gudri to saprast, un ņemtu vērā, kā tiem pēcgalā klāsies.
30 Báwo ni ẹnìkan ṣe lè lé ẹgbẹ̀rún, tàbí tí ẹni méjì sì lè lé ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sá, bí kò ṣe pé àpáta wọn ti tà wọ́n, bí kò ṣe pé Olúwa wọn ti fi wọ́n tọrẹ?
Kā viens var tūkstošus vajāt un kā divi var dzenāt desmit tūkstošus? Vai ne tāpēc, ka viņu akmens kalns tos ir pārdevis, un Tas Kungs tos ir nodevis.
31 Nítorí pé àpáta wọn kò dàbí àpáta wa, àní àwọn ọ̀tá wa tìkára wọn ń ṣe onídàájọ́.
Jo viņu akmens kalns nav kā mūsu akmens kalns, par to mūsu ienaidnieki paši ir spriedēji.
32 Igi àjàrà a wọn wá láti igi àjàrà Sodomu àti ti ìgbẹ́ ẹ Gomorra. Èso àjàrà wọn kún fún oró, ìdì wọn korò.
Jo viņu vīna koks ir no Sodomas vīna koka un no Gomoras laukiem; viņu vīna ķekari ir žults ķekari, tiem ir rūgtas ogas.
33 Ọtí wáìnì wọn ìwọ ti dragoni ni, àti oró mímú ti ejò paramọ́lẹ̀.
Viņu vīns ir pūķu siekalas un briesmīga odžu žults.
34 “Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́ èmi kò sì fi èdìdì dì í ní ìṣúra mi?
Vai tas nav pie Manis paslēpts, aizzieģelēts Manā padomā.
35 Ti èmi ni láti gbẹ̀san. Èmi yóò san án fún wọn ní àkókò tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yóò yọ; ọjọ́ ìdààmú wọn súnmọ́ etílé ohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”
Man pieder atriebšana un atmaksāšana, uz to laiku, kad viņu kāja slīdēs; jo viņu posta diena ir tuvu, un viņu liktenis nāk steigšus.
36 Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tán tí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.
Jo Tas Kungs tiesās Savus ļaudis un par Saviem kalpiem Viņš apžēlosies, kad Viņš redzēs, ka spēks ir izzudis, ka beigti mazs un liels.
37 Yóò wí pé, “Òrìṣà wọn dà báyìí, àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,
Tad Viņš sacīs: Kur ir viņu dievi, tas akmens kalns, uz ko tie cerēja?
38 ọlọ́run tí ó jẹ ọ̀rá ẹran ẹbọ wọn tí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn? Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n! Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!
Viņu upura taukus tie ēda, viņu dzeramā upura vīnu tie dzēra, - lai viņi ceļas un jums palīdz, ka jums ir patvērums.
39 “Wò ó báyìí pé, Èmi fúnra à mi, Èmi ni! Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi. Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè. Mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná, kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.
Raugāt nu, ka Es, Es tas esmu, un neviena nav, kā vien Es! Es nonāvēju un daru dzīvu, Es ievainoju un dziedināju, un glābēja nav no Manas rokas.
40 Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé, Èmi ti wà láààyè títí láé,
Jo Es paceļu pret debesīm Savu roku un saku: tik tiešām, kā Es dzīvoju mūžīgi,
41 nígbà tí mo bá pọ́n idà dídán mi àti tí mo bá sì fi ọwọ́ mi lé ìdájọ́, Èmi yóò san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá mi Èmi ó sì san fún àwọn tí ó kórìíra à mi.
Kad Es trīšu Sava zobena zibeni un Mana roka izstiepsies uz sodību, tad Es atkal atriebšos pie Saviem pretiniekiem un atmaksāšu Saviem ienaidniekiem.
42 Èmi yóò mú ọfà mu ẹ̀jẹ̀, nígbà tí idà mi bá jẹ ẹran: ẹ̀jẹ̀ ẹni pípa àti ẹni ìgbèkùn, láti orí àwọn aṣáájú ọ̀tá.”
Es dzirdināšu Savas bultas ar asinīm, - un Mans zobens ēdīs miesas, - ar nokauto un gūstīto asinīm, no ienaidnieku varenām galvām.
43 Ẹ yọ̀ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí òun yóò gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀; yóò sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá a rẹ̀ yóò sì ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àti ènìyàn rẹ̀.
Gavilējiet, tautas, par Viņa ļaudīm, - jo Viņš atriebj Savu kalpu asinis un atriebjas pie Saviem pretiniekiem un apžēlojās par Savu zemi un par Saviem ļaudīm. -
44 Mose sì wá ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí ní etí àwọn ènìyàn náà, òun, àti Hosea ọmọ Nuni.
Un Mozus nāca un runāja visus šīs dziesmas vārdus to ļaužu ausīs, viņš un Jozuas, Nuna dēls.
45 Nígbà tí Mose parí i kíka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí Israẹli.
Kad nu Mozus bija beidzis runāt visus šos vārdus uz visu Israēli,
46 Ó sọ fún un pé, “Ẹ gbé ọkàn an yín lé gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ láàrín yín lónìí, kí ẹ̀yin lè pàṣẹ fún àwọn ọmọ yín láti gbọ́rọ̀ àti láti ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
Tad viņš uz tiem sacīja: ņemiet pie sirds visus šos vārdus, ko es šodien jums apliecināju; tos jums būs pavēlēt saviem bērniem, ka tie tur un dara visus šīs bauslības vārdus.
47 Wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ asán fún ọ, ìyè e yín ni wọ́n. Nípa wọn ni ẹ̀yin yóò gbé pẹ́ lórí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ń gòkè e Jordani lọ láti gbà.”
Jo tas jums nav tukšs vārds, bet ir jūsu dzīvība, un caur šo vārdu jūs ilgi dzīvosiet tai zemē, ko iemantot jūs ejat pār Jardāni.
48 Ní ọjọ́ kan náà, Olúwa sọ fún Mose pé,
Un Tas Kungs runāja uz Mozu tai pašā dienā sacīdams:
49 “Gòkè lọ sí Abarimu sí òkè Nebo ní Moabu, tí ó kọjú sí Jeriko, kí o sì wo ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí mo ń fi fún àwọn ọmọ Israẹli, bí ìní i wọn.
“Kāp uz šo Abarim kalnu, tas ir Nebus kalns, Moaba zemē pret Jēriku, un skaties Kanaāna zemi, ko Es Israēla bērniem došu iemantot.
50 Ní orí òkè tí ìwọ ń gùn lọ ìwọ yóò kùú níbẹ̀, kí a sì sin ọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin in rẹ Aaroni ti kú ní orí òkè Hori tí a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn an rẹ̀.
Un tev būs mirt uz tā kalna, kur tu uzkāpsi, un tapt piepulcinātam pie saviem ļaudīm, kā Ārons, tavs brālis, nomira uz Hora kalna un tapa piepulcināts pie saviem ļaudīm;
51 Ìdí ni pé ẹ̀yin méjèèjì ṣẹ̀ sí mi láàrín àwọn ọmọ Israẹli ní ibi omi Meriba Kadeṣi ní aginjù Sini àti nítorí ẹ̀yin kò yà mí sí mímọ́ láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Tādēļ ka jūs Israēla bērnu vidū esat noziegušies pret Mani pie strīdus ūdens Kādešā, Cin tuksnesī, tāpēc ka jūs Mani neesat svētījuši Israēla bērnu vidū.
52 Nítorí náà, ìwọ yóò rí ilẹ̀ náà ní ọ̀kánkán, o kì yóò wọ inú rẹ̀ ilẹ̀ ti mo ti fi fún àwọn ọmọ Israẹli.”
Jo tu redzēsi to zemi savā priekšā, bet tur tu nenonāksi, tai zemē, ko Es došu Israēla bērniem.”

< Deuteronomy 32 >