< Deuteronomy 32 >

1 Fetísílẹ̀, ẹ̀yin ọ̀run, èmi yóò sọ̀rọ̀; ẹ gbọ́, ìwọ ayé, ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Ta thikĩrĩria, wee igũrũ, ngũhe ũhoro; o na we thĩ-rĩ, ta igua ciugo cia kanua gakwa.
2 Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò, kí àwọn ọ̀rọ̀ mi máa sọ̀kalẹ̀ bí ìrì, bí òjò wíníwíní sára ewéko tuntun, bí ọ̀wààrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.
Reke ũrutani wakwa uure ta mbura, nacio ciugo ciakwa igwe ta ime, ituĩke ta rũthuthuũ rũkiurĩra nyeki ya mũmerano, o na ĩtuĩke ta mbura nyingĩ ĩkiurĩra mĩmera mĩĩthĩ.
3 Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa. Ẹyin títóbi Ọlọ́run wa!
Nĩngũhunjia ũhoro wa Rĩĩtwa rĩa Jehova. Hĩ, kĩgoocei ũnene wa Ngai witũ!
4 Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé, gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo. Ọlọ́run olóòtítọ́ tí kò ṣe àṣìṣe kan, Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.
We nĩwe Rwaro rwa Ihiga, mawĩra make nĩ makinyanĩru, nacio njĩra ciake ciothe nĩ cia kĩhooto. Nĩ Ngai mwĩhokeku na ndahĩtagia, nĩ mũrũngĩrĩru, na nĩ wa kĩhooto.
5 Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀; fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apá kan tí ó sì dorí kodò.
Nĩmethaahĩtie harĩ we; ũndũ wa thoni nĩ atĩ ti ciana ciake rĩngĩ, no nĩ rũciaro rũremi na rwaganu.
6 Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn? Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín, tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?
Ũũ nĩguo mũngĩrĩha wega wa Jehova, inyuĩ andũ aya akĩĩgu na mwagĩte ũũgĩ? Githĩ tiwe Ithe wanyu, o we Mũmbi wanyu, ũrĩa wamũmbire na agĩtũma mwĩhaande wega?
7 Rántí ìgbà láéláé; wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá. Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ, àwọn àgbàgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.
Ririkana matukũ ma tene; wĩciirie ũhoro wa njiaro iria ihĩtũkĩte. Ũria thoguo na nĩegũkwĩra, O na athuuri anyu na nĩmegũgũtaarĩria.
8 Nígbà tí Ọ̀gá-ògo fi ogún àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn, ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Israẹli.
Rĩrĩa Ũrĩa-ũrĩ-Igũrũ-Mũno aaheire ndũrĩrĩ igai rĩacio, rĩrĩa aagayanirie iruka ciothe cia andũ, nĩekĩrĩire andũ othe mĩhaka, kũringana na mũigana wa ariũ a Isiraeli.
9 Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀, Jakọbu ni ìpín ìní i rẹ̀.
Nĩ gũkorwo igai rĩa Jehova nĩ andũ ake, Jakubu nĩwe igai rĩake rĩrĩa eegaĩire.
10 Ní aginjù ni ó ti rí i, ní aginjù níbi tí ẹranko kò sí. Ó yíká, ó sì tọ́jú rẹ̀, ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.
Aamuonire arĩ kũndũ werũ-inĩ, werũ ũtarĩ kĩndũ, ũgambagwo nĩ nyamũ. Nake akĩmũgitĩra na akĩmũmenyerera; aamũrangagĩra o ta kĩũma kĩa riitho rĩake,
11 Bí idì ti í ru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ń rábàbà sórí ọmọ rẹ̀, tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sì gbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.
o ta ũrĩa nderi yarahũraga tũcui twayo gĩtara-inĩ kĩayo, ĩkareera igũrũ rĩa tũcui twayo, ĩtambũrũkĩtie mathagu mayo nĩguo ituoe, na ĩgatũkuua mathagu-inĩ mayo.
12 Olúwa ṣamọ̀nà; kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.
Jehova o we wiki nĩwe wamũtongoririe; gũtiarĩ ngai ngʼeni yarĩ hamwe nake.
13 Ó mú gun ibi gíga ayé ó sì fi èso oko bọ́ ọ. Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá, àti òróró láti inú akọ òkúta wá.
Atũmire ahaice kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru bũrũri-inĩ, na akĩmũhũũnia na matunda ma mĩgũnda. Nĩamũheire ũũkĩ uumĩte ihiga-inĩ, na akĩmũhe maguta moimĩte ihiga-inĩ rĩa nyaigĩ;
14 Pẹ̀lú u wàràǹkàṣì àti wàrà àgùntàn àti ti àgbò ẹran àti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, pẹ̀lú àgbò irú u ti Baṣani tí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èso àjàrà, àní àti wáìnì.
akĩmũhe ngorono na iria kuuma ndũũru-inĩ cia ngʼombe, na cia mbũri na tũtũrũme tũnoru. o na mbũri na ndũrũme iria njega mũno cia Bashani, na ngano ĩrĩa njega mũno. Nĩwanyuire thakame ĩrĩ mũhũyũ ya thabibũ, nĩyo ndibei yacio.
15 Jeṣuruni sanra tán ó sì tàpá; ìwọ sanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán. O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọ o sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.
Jeshuruni nake aanorire, agĩikia haati; aahũũnire, agĩtunguha, na agĩkenga mwĩrĩ. Agĩgĩtigana na Ngai ũrĩa wamũmbire, na akĩrega Rwaro rwa Ihiga, o ruo Mũhonokia wake.
16 Wọ́n sì fi òrìṣà mú un jowú, ohun ìríra ni wọ́n fi mú un bínú.
Nĩmatũmire aigue ũiru nĩ ũndũ wa ngai icio ciao ngʼeni, na makĩmũrakaria na mĩhianano yao ĩrĩ magigi.
17 Wọ́n rú ẹbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí, ọlọ́run tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ farahàn láìpẹ́, ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.
Nĩmarutĩire ndaimono magongona, iria itarĩ Ngai: ngai iria matooĩ, ngai iria cieyumĩrĩtie o ica-ikuhĩ, ngai iria iteetigĩrĩtwo nĩ maithe manyu.
18 Ìwọ kò rántí àpáta, tí ó bí ọ; o sì gbàgbé Ọlọ́run tí ó dá ọ.
Nĩwatiganĩirie Rwaro rwa Ihiga, rũrĩa rwagũciarire; ũkĩriganĩrwo nĩ Mũrungu ũrĩa wagũciarire.
19 Olúwa sì rí èyí ó sì kọ̀ wọ́n, nítorí tí ó ti bínú nítorí ìwà ìmúnibínú àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ.
Jehova nĩonire ũndũ ũcio nake akĩmarega nĩ ũndũ nĩarakarĩtio nĩ ariũ ake na airĩtu ake.
20 Ó sì wí pé, “Èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò lára wọn, èmi yóò sì wò ó bí ìgbẹ̀yìn in wọn yóò ti rí; nítorí wọ́n jẹ́ ìran alágídí, àwọn ọmọ tí kò sí ìgbàgbọ́ nínú wọn.
Nake akiuga atĩrĩ, “Nĩngũmahitha ũthiũ wakwa, nyone ũrĩa marigĩrĩrio mao magaakorwo matariĩ; nĩgũkorwo nĩ rũciaro rũremi, ciana itaangĩĩhokeka.
21 Wọ́n fi mí jowú nípa ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run, wọ́n sì fi ohun asán an wọn mú mi bínú. Èmi yóò mú wọn kún fún ìlara láti ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe ènìyàn; èmi yóò sì mú wọn bínú láti ọ̀dọ̀ aṣiwèrè orílẹ̀-èdè.
Manjiguithirie ũiru nĩ ũndũ wa ngai itarĩ bata, na makĩndakaria na ngai ciao itarĩ kĩene. Ngaamaiguithia ũiru na rũrĩrĩ hatarĩ; ngaatũma marakario nĩ rũrĩrĩ rũtarĩ na ũmenyo.
22 Nítorí pé iná kan ràn nínú ìbínú mi, yóò sì jó dé ipò ikú ní ìsàlẹ̀. Yóò sì run ayé àti ìkórè e rẹ̀ yóò sì tiná bọ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá. (Sheol h7585)
Nĩ gũkorwo mwaki nĩwakĩtio nĩ mangʼũrĩ makwa, ũrĩa wakanaga ũgakinya mũhuro wa kwa ngoma. Nĩũkaniina thĩ na magetha mayo, na ũmundie itina cia irĩma mwaki. (Sheol h7585)
23 “Èmi yóò kó àwọn ohun búburú lé wọn lórí èmi ó sì na ọfà mi tán sí wọn lára.
“Nĩngamombĩrĩra mĩtino na mĩguĩ yakwa ndĩmĩhũthĩre ngĩmahũũra nayo.
24 Èmi yóò mú wọn gbẹ, ooru gbígbóná àti ìparun kíkorò ni a ó fi run wọ́n. Pẹ̀lú oró ohun tí ń rákò nínú erùpẹ̀.
Nĩngamarehithĩria ngʼaragu ya kũmahinyaria, ndĩmarehithĩrie gĩthĩĩna gĩa kũmaniina na mũthiro wa kũmooraga; Ngaamarehithĩria nyamũ cia gĩthaka irĩ magego moogĩ, ndĩmarehithĩrie ũrũrũ wa nduĩra iria inyororokaga rũkũngũ-inĩ.
25 Idà ní òde, àti ẹ̀rù nínú ìyẹ̀wù, ni yóò run ọmọkùnrin àti wúńdíá. Ọmọ ẹnu ọmú àti arúgbó eléwú irun pẹ̀lú.
Rũhiũ rwa njora nĩrũkaniina ciana ciao njĩra-inĩ ya itũũra; kĩmako gĩkaamaiyũra marĩ kwao mĩciĩ. Aanake na airĩtu nĩmagathira, o hamwe na ngenge, na andũ arĩa marĩ na mbuĩ.
26 Mo ní èmi yóò tú wọn ká èmi yóò sì mú ìrántí i wọn dà kúrò nínú àwọn ènìyàn,
Ndoigire nĩngamaharagania, na tharie kũririkanwo kwao kuuma kũrĩ andũ,
27 nítorí bí mo ti bẹ̀rù ìbínú ọ̀tá, kí àwọn ọ̀tá a wọn kí ó má ba à wí pé, ‘Ọwọ́ wa lékè ni; kì í sì í ṣe Olúwa ni ó ṣe gbogbo èyí.’”
no nĩndetigĩrire kĩnyararo gĩa thũ, nĩguo mũmuku ndakaage gũtaũkĩrwo, oige atĩrĩ, ‘Guoko gwitũ nĩgũtooranĩtie; Jehova tiwe wĩkĩte ũũ wothe.’”
28 Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí òye nínú wọn.
Nĩ rũrĩrĩ rũteciiragia, matirĩ na gũkũũrana thĩinĩ wao.
29 Bí ó ṣe pé wọ́n gbọ́n, kí òye yìí sì yé wọn kí wọn ro bí ìgbẹ̀yìn wọn yóò ti rí!
Naarĩ korwo maarĩ oogĩ mahote kũmenya ũguo na makũũrane ũrĩa ũhoro wao wa kũrigĩrĩria ũgaakorwo ũtariĩ!
30 Báwo ni ẹnìkan ṣe lè lé ẹgbẹ̀rún, tàbí tí ẹni méjì sì lè lé ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sá, bí kò ṣe pé àpáta wọn ti tà wọ́n, bí kò ṣe pé Olúwa wọn ti fi wọ́n tọrẹ?
Mũndũ ũmwe angĩhota atĩa gũtengʼeria andũ ngiri, kana andũ eerĩ matũme andũ ngiri ikũmi moore, tiga makorirwo meendetio nĩ Rwaro rwa Ihiga, tiga Jehova akorirwo amatiganĩirie?
31 Nítorí pé àpáta wọn kò dàbí àpáta wa, àní àwọn ọ̀tá wa tìkára wọn ń ṣe onídàájọ́.
Nĩ gũkorwo ihiga rĩao rĩtihaana ta Rwaro rwa Ihiga riitũ, o ta ũrĩa o na thũ ciitũ ciũĩ.
32 Igi àjàrà a wọn wá láti igi àjàrà Sodomu àti ti ìgbẹ́ ẹ Gomorra. Èso àjàrà wọn kún fún oró, ìdì wọn korò.
Mũthabibũ wao uumĩte mũthabibũ-inĩ wa Sodomu, na ũkoima mĩgũnda-inĩ ya Gomora. Thabibũ ciayo ciyũrĩte thumu, nacio ikũmba ciacio ikarũra.
33 Ọtí wáìnì wọn ìwọ ti dragoni ni, àti oró mímú ti ejò paramọ́lẹ̀.
Ndibei yacio nĩ ũrũrũ wa nduĩra, o guo thumu ũrĩa mũũru mũno wa nduĩra.
34 “Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́ èmi kò sì fi èdìdì dì í ní ìṣúra mi?
“Githĩ ndikoretwo njigĩte ũndũ ũyũ wega ngaikara ndĩũmenyereire mũthiithũ-inĩ wakwa?
35 Ti èmi ni láti gbẹ̀san. Èmi yóò san án fún wọn ní àkókò tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yóò yọ; ọjọ́ ìdààmú wọn súnmọ́ etílé ohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”
Kũrĩhanĩria nĩ gwakwa; nĩ niĩ ngaarĩhanĩria. Ihinda rĩakinya, kũgũrũ kwao nĩ gũgaatenderũka; mũthenya wao wa mwanangĩko ũrĩ hakuhĩ, naguo mũtino wao ũhiũhĩte ũmakore.”
36 Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tán tí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.
Jehova nĩagaciirithia andũ ake, na aiguĩre ndungata ciake tha, rĩrĩa akoona nĩmathirĩtwo nĩ hinya, na gũtirĩ o na ũmwe wao ũtigarĩte, arĩ ngombo kana atarĩ ngombo.
37 Yóò wí pé, “Òrìṣà wọn dà báyìí, àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,
Nake nĩ akoiga atĩrĩ, “Rĩu ngai ciao ikĩrĩ ha, ihiga rĩu meehithaga harĩ rĩo,
38 ọlọ́run tí ó jẹ ọ̀rá ẹran ẹbọ wọn tí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn? Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n! Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!
ngai iria ciarĩĩaga maguta ma magongona mao, na ikanyua ndibei ya indo iria ciarutagwo cia kũnyuuo? Reke cigĩũkĩre imũteithie! Reke imũhe kĩĩgitio!
39 “Wò ó báyìí pé, Èmi fúnra à mi, Èmi ni! Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi. Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè. Mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná, kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.
“Rĩu menyai atĩ niĩ mwene nĩ niĩ Ngai! Gũtirĩ ngai ũngĩ tiga niĩ. Nĩ niĩ njũraganaga na niĩ ndũũranagia muoyo, nĩndiihanĩtie na nĩngũhonia, na gũtirĩ o na ũmwe ũngĩhonokania kuuma guoko-inĩ gwakwa.
40 Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé, Èmi ti wà láààyè títí láé,
Nguoya guoko gwakwa na igũrũ njuge atĩrĩ: O ta ũrĩa ndũũraga muoyo nginya tene,
41 nígbà tí mo bá pọ́n idà dídán mi àti tí mo bá sì fi ọwọ́ mi lé ìdájọ́, Èmi yóò san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá mi Èmi ó sì san fún àwọn tí ó kórìíra à mi.
rĩrĩa ngaanoora rũhiũ rwakwa rwa njora rũkahenia na ndĩrũnyiite na guoko gwakwa ngĩtua ciira, nĩngerĩhĩria kũrĩ thũ ciakwa, na ndĩĩrĩhĩrie kũrĩ arĩa maathũire.
42 Èmi yóò mú ọfà mu ẹ̀jẹ̀, nígbà tí idà mi bá jẹ ẹran: ẹ̀jẹ̀ ẹni pípa àti ẹni ìgbèkùn, láti orí àwọn aṣáájú ọ̀tá.”
Nĩngatũma mĩguĩ yakwa ĩnyue thakame ĩrĩĩo, Naruo rũhiũ rwakwa rwa njora rũrĩage nyama: ĩyo nĩ thakame ya arĩa moragĩtwo na arĩa matahĩtwo, na mĩtwe ya atongoria a thũ.”
43 Ẹ yọ̀ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí òun yóò gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀; yóò sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá a rẹ̀ yóò sì ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àti ènìyàn rẹ̀.
Inyuĩ ndũrĩrĩ, kenai hamwe na andũ ake, nĩgũkorwo nĩakarĩhanĩria thakame ya ndungata ciake; acirĩhĩrie harĩ thũ ciake, na ahoroherie bũrũri wake, o na andũ ake.
44 Mose sì wá ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí ní etí àwọn ènìyàn náà, òun, àti Hosea ọmọ Nuni.
Musa nĩmookire na Joshua mũrũ wa Nuni, na makĩaria ciugo ciothe cia rwĩmbo rũrũ andũ makĩiguaga.
45 Nígbà tí Mose parí i kíka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí Israẹli.
Rĩrĩa Musa aarĩkirie kũhe andũ a Isiraeli ũhoro ũcio,
46 Ó sọ fún un pé, “Ẹ gbé ọkàn an yín lé gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ láàrín yín lónìí, kí ẹ̀yin lè pàṣẹ fún àwọn ọmọ yín láti gbọ́rọ̀ àti láti ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
akĩmeera atĩrĩ, “Ciugo ici ciothe ndaamwĩra ũmũthĩ itarĩ na itherũ, rekei ciikare ngoro-inĩ cianyu, nĩgeetha mũgaatha ciana cianyu gwathĩkĩra wega ciugo icio ciothe cia watho ũyũ.
47 Wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ asán fún ọ, ìyè e yín ni wọ́n. Nípa wọn ni ẹ̀yin yóò gbé pẹ́ lórí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ń gòkè e Jordani lọ láti gbà.”
To ciugo o ũguo harĩ inyuĩ, no nĩcio muoyo wanyu. Nĩigatũma mũtũũre matukũ maingĩ bũrũri ũrĩa mũraringa Rũũĩ rwa Jorodani mũkawĩgwatĩre.”
48 Ní ọjọ́ kan náà, Olúwa sọ fún Mose pé,
Mũthenya o ro ũcio Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
49 “Gòkè lọ sí Abarimu sí òkè Nebo ní Moabu, tí ó kọjú sí Jeriko, kí o sì wo ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí mo ń fi fún àwọn ọmọ Israẹli, bí ìní i wọn.
“Ambata, ũkinye mwambato wa Abarimu o, kũu kĩrĩma kĩa Nebo bũrũri-inĩ wa Moabi, kũngʼethanĩra na Jeriko, wĩrorere Kaanani, bũrũri ũrĩa ndĩrahe andũ a Isiraeli ũtuĩke igai rĩao.
50 Ní orí òkè tí ìwọ ń gùn lọ ìwọ yóò kùú níbẹ̀, kí a sì sin ọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin in rẹ Aaroni ti kú ní orí òkè Hori tí a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn an rẹ̀.
Kĩrĩma kĩu ũkũhaica nĩkĩo ũgaakuĩra, nawe ũcookanĩrĩrio hamwe na andũ anyu, o ta ũrĩa mũrũ wa nyũkwa Harũni aakuĩrĩire kĩrĩma-inĩ kĩa Horu, nake agĩcookanĩrĩrio hamwe na andũ arĩa manakua.
51 Ìdí ni pé ẹ̀yin méjèèjì ṣẹ̀ sí mi láàrín àwọn ọmọ Israẹli ní ibi omi Meriba Kadeṣi ní aginjù Sini àti nítorí ẹ̀yin kò yà mí sí mímọ́ láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Gĩtũmi kĩa ũguo nĩ tondũ inyuĩ eerĩ nĩmwagire kũnjĩtĩkia mũrĩ mbere ya andũ a Isiraeli o kũu maaĩ-inĩ ma Meriba Kadeshi werũ-inĩ wa Zini tondũ mũtiigana kũrũgamĩrĩra ũtheru wakwa harĩ andũ a Isiraeli.
52 Nítorí náà, ìwọ yóò rí ilẹ̀ náà ní ọ̀kánkán, o kì yóò wọ inú rẹ̀ ilẹ̀ ti mo ti fi fún àwọn ọmọ Israẹli.”
Nĩ ũndũ ũcio, nĩ ũkuona bũrũri ũcio ũrĩ o haraaya; no ndũgatoonya bũrũri ũcio ndĩrahe andũ a Isiraeli.”

< Deuteronomy 32 >