< Deuteronomy 32 >
1 Fetísílẹ̀, ẹ̀yin ọ̀run, èmi yóò sọ̀rọ̀; ẹ gbọ́, ìwọ ayé, ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
“Listen to me, [all you who are in the] heavens, and [all you who are on the] earth, listen to what I say [MTY].
2 Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò, kí àwọn ọ̀rọ̀ mi máa sọ̀kalẹ̀ bí ìrì, bí òjò wíníwíní sára ewéko tuntun, bí ọ̀wààrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.
I wish/desire that my teaching will fall on you like rain drops or be like dew on the ground, and be like a gentle rain on the young plants, like showers on the grass.
3 Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa. Ẹyin títóbi Ọlọ́run wa!
I will praise Yahweh [MTY]. And [all you people should] tell others that our God is very great.
4 Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé, gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo. Ọlọ́run olóòtítọ́ tí kò ṣe àṣìṣe kan, Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.
He is like a rock [MET] [under which we are protected]; [everything] that he does is perfect and completely just/fair [DOU]. He always does what he says that he will do; he never does anything that is wrong.
5 Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀; fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apá kan tí ó sì dorí kodò.
“But [you Israeli people] have been very unfaithful to him; because of your sins, you no longer [deserve to] be his children. You are extremely wicked and deceitful [DOU].
6 Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn? Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín, tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?
You foolish and senseless [DOU] people, (is this the way that you should repay Yahweh [for all that he has done for you]?/this is certainly not the way that you should repay Yahweh [for all that he has done for you].) [RHQ] He is your father; he created you [RHQ]; he caused you to become a nation.
7 Rántí ìgbà láéláé; wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá. Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ, àwọn àgbàgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.
“Think about [what happened] long ago; consider what happened to your ancestors. Ask your parents, and they will inform you; ask the older people, and they will tell you.
8 Nígbà tí Ọ̀gá-ògo fi ogún àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn, ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Israẹli.
When God, who is greater than any other god, long ago divided the people into groups, he assigned to the nations their land. He determined where each people-group should live and (assigned to/chose for) each people-group a god/angel.
9 Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀, Jakọbu ni ìpín ìní i rẹ̀.
But Yahweh decided that we would be his people; he chose [us, the descendants of] Jacob, to belong to him.
10 Ní aginjù ni ó ti rí i, ní aginjù níbi tí ẹranko kò sí. Ó yíká, ó sì tọ́jú rẹ̀, ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.
“He saw [our ancestors] when they were in a desert, wandering in a land (that was desolate/where no people lived). He protected them and took care of them, as every person takes good care of his own eyes. [SIM, IDM]
11 Bí idì ti í ru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ń rábàbà sórí ọmọ rẹ̀, tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sì gbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.
[Yahweh protected his people] just like an eagle encourages its babies [to fly] and flutters over them [MET], spreading its wings and catching them [if they start to fall].
12 Olúwa ṣamọ̀nà; kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.
Yahweh was the only one who led them; no other foreign god helped him.
13 Ó mú gun ibi gíga ayé ó sì fi èso oko bọ́ ọ. Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá, àti òróró láti inú akọ òkúta wá.
“[After they entered the land that Yahweh promised to give to them], Yahweh enabled them to rule the hilly areas; they ate the crops that grew in the fields. They found honey in the rocks, and their olive trees [MTY] grew [even] in stony ground.
14 Pẹ̀lú u wàràǹkàṣì àti wàrà àgùntàn àti ti àgbò ẹran àti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, pẹ̀lú àgbò irú u ti Baṣani tí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èso àjàrà, àní àti wáìnì.
The cows gave them plenty of curds/yogurt, the goats gave them plenty of milk, they had well-fed sheep and cattle, they had very good wheat, and they made delicious wine from their grapes.
15 Jeṣuruni sanra tán ó sì tàpá; ìwọ sanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán. O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọ o sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.
“The Israeli people became rich and prosperous, but then they rebelled against God; they abandoned him, the one who created them, the one who powerfully saves them.
16 Wọ́n sì fi òrìṣà mú un jowú, ohun ìríra ni wọ́n fi mú un bínú.
So he abandoned them because they started to worship other/strange gods. Because of their worshiping disgusting idols, he became angry.
17 Wọ́n rú ẹbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí, ọlọ́run tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ farahàn láìpẹ́, ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.
They offered sacrifices to gods who were [really] demons, gods that their ancestors had never known; they offered sacrifices to gods that they had recently found out about, gods whom your ancestors had never revered.
18 Ìwọ kò rántí àpáta, tí ó bí ọ; o sì gbàgbé Ọlọ́run tí ó dá ọ.
They forgot [the true] God, the one who protects them [MET], the one who created them and caused them to live.
19 Olúwa sì rí èyí ó sì kọ̀ wọ́n, nítorí tí ó ti bínú nítorí ìwà ìmúnibínú àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ.
“When Yahweh saw that [they had abandoned him], he became angry, so he rejected [the Israeli people, who are like] his sons and daughters.
20 Ó sì wí pé, “Èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò lára wọn, èmi yóò sì wò ó bí ìgbẹ̀yìn in wọn yóò ti rí; nítorí wọ́n jẹ́ ìran alágídí, àwọn ọmọ tí kò sí ìgbàgbọ́ nínú wọn.
He said, ‘They are very wicked/stubborn people, very unfaithful; so I will no longer help them, and then I will watch and see what happens to them.
21 Wọ́n fi mí jowú nípa ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run, wọ́n sì fi ohun asán an wọn mú mi bínú. Èmi yóò mú wọn kún fún ìlara láti ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe ènìyàn; èmi yóò sì mú wọn bínú láti ọ̀dọ̀ aṣiwèrè orílẹ̀-èdè.
They made me very angry because of their worshiping idols, which are not really gods; they have caused me to be [jealous [MET] because I want them to worship only me]. So now, in order to cause them to become jealous, I will send [to attack them an army of] a nation of worthless and foolish people.
22 Nítorí pé iná kan ràn nínú ìbínú mi, yóò sì jó dé ipò ikú ní ìsàlẹ̀. Yóò sì run ayé àti ìkórè e rẹ̀ yóò sì tiná bọ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá. (Sheol )
I will be very angry, and I will destroy them like a fire that will burn on the earth and all the way down to the place where dead people are [MET]; that fire will destroy the earth and everything that grows on it, and it will even burn what is down under the mountains. (Sheol )
23 “Èmi yóò kó àwọn ohun búburú lé wọn lórí èmi ó sì na ọfà mi tán sí wọn lára.
I will cause them to experience many disasters; [they will feel as though] [MET] I am shooting all my arrows at them.
24 Èmi yóò mú wọn gbẹ, ooru gbígbóná àti ìparun kíkorò ni a ó fi run wọ́n. Pẹ̀lú oró ohun tí ń rákò nínú erùpẹ̀.
They will die because of being hungry and because of having hot fevers and because of terrible diseases; I will send wild animals to attack [MTY] them, and poisonous snakes to bite [MTY] them.
25 Idà ní òde, àti ẹ̀rù nínú ìyẹ̀wù, ni yóò run ọmọkùnrin àti wúńdíá. Ọmọ ẹnu ọmú àti arúgbó eléwú irun pẹ̀lú.
Outside [their houses, their enemies] will kill them [MTY] with swords, and in their homes, [their enemies will cause] them to be terrified. Their enemies will kill young men and young women, and they will kill infants and old people with gray hair.
26 Mo ní èmi yóò tú wọn ká èmi yóò sì mú ìrántí i wọn dà kúrò nínú àwọn ènìyàn,
I wanted to scatter the Israeli people to distant countries in order that no one would ever remember them.
27 nítorí bí mo ti bẹ̀rù ìbínú ọ̀tá, kí àwọn ọ̀tá a wọn kí ó má ba à wí pé, ‘Ọwọ́ wa lékè ni; kì í sì í ṣe Olúwa ni ó ṣe gbogbo èyí.’”
But [if I did that], their enemies would wrongly boast that they were the ones who had [gotten rid of my people]; they would say, “We [SYN] are the ones who defeated them; it was not Yahweh who has done all these things.”’
28 Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí òye nínú wọn.
You Israelis are a nation of people who do not have any sense. None of you is wise.
29 Bí ó ṣe pé wọ́n gbọ́n, kí òye yìí sì yé wọn kí wọn ro bí ìgbẹ̀yìn wọn yóò ti rí!
If you were wise, you would understand [why you would be punished]; you would have realized what was going to happen to you.
30 Báwo ni ẹnìkan ṣe lè lé ẹgbẹ̀rún, tàbí tí ẹni méjì sì lè lé ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sá, bí kò ṣe pé àpáta wọn ti tà wọ́n, bí kò ṣe pé Olúwa wọn ti fi wọ́n tọrẹ?
[You would have realized] why 1,000 [of your soldiers] would be defeated by only one [of the enemy soldiers], and why two of your enemies would chase away 10,000 [Israeli soldiers]. [You would realize that this would happen] only if God, the one who always defended you [MET], had allowed your enemies to defeat you, because he had abandoned you.
31 Nítorí pé àpáta wọn kò dàbí àpáta wa, àní àwọn ọ̀tá wa tìkára wọn ń ṣe onídàájọ́.
Your enemies know that their gods are not powerful like Yahweh, our God, [so their gods could not have defeated us Israelis].
32 Igi àjàrà a wọn wá láti igi àjàrà Sodomu àti ti ìgbẹ́ ẹ Gomorra. Èso àjàrà wọn kún fún oró, ìdì wọn korò.
Your enemies are like [MET] grapevines planted near [the ruins of] Sodom and Gomorrah [cities]; the grapes from those vines are bitter and poisonous;
33 Ọtí wáìnì wọn ìwọ ti dragoni ni, àti oró mímú ti ejò paramọ́lẹ̀.
the wine [from those grapes] is like the poison of snakes [DOU].
34 “Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́ èmi kò sì fi èdìdì dì í ní ìṣúra mi?
[“Yahweh says], ‘I know [RHQ] [what I have planned to do to the Israeli people and to their enemies], and those plans are so secure [that it as though he locked them up] [MET].
35 Ti èmi ni láti gbẹ̀san. Èmi yóò san án fún wọn ní àkókò tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yóò yọ; ọjọ́ ìdààmú wọn súnmọ́ etílé ohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”
I am the one who will get revenge and pay those enemies back for what they have done [to my people], at the right time for them to be punished [IDM]; they will soon experience disasters, and I will punish/destroy them quickly.’
36 Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tán tí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.
“But Yahweh will see that you who are truly his people, who (are innocent/have not done things that are wrong), and he will be merciful to you. And he will see that you are helpless, and that there are very few of you, slaves or free people, who are still alive.
37 Yóò wí pé, “Òrìṣà wọn dà báyìí, àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,
Then Yahweh will ask his people, ‘Where are the gods that you thought would protect you [MET]?
38 ọlọ́run tí ó jẹ ọ̀rá ẹran ẹbọ wọn tí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn? Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n! Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!
You gave to those gods the best parts of the animals that you sacrificed, and you poured out wine for them to drink. So, they should begin to help you; they should be the ones who will protect you!
39 “Wò ó báyìí pé, Èmi fúnra à mi, Èmi ni! Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi. Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè. Mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná, kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.
“But now you will realize that I, only I, am God; there is no other god who is [a real] god. I am the one who can kill people and who can cause people to live; I can wound people, and I can heal people, and there is no one who can prevent me from doing those things.
40 Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé, Èmi ti wà láààyè títí láé,
I raise my hand toward heaven and solemnly declare that just as sure as I live forever,
41 nígbà tí mo bá pọ́n idà dídán mi àti tí mo bá sì fi ọwọ́ mi lé ìdájọ́, Èmi yóò san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá mi Èmi ó sì san fún àwọn tí ó kórìíra à mi.
that when I sharpen my sword, as I [SYN] prepare to punish people, I will get revenge on my enemies; I will pay back those who hate me.
42 Èmi yóò mú ọfà mu ẹ̀jẹ̀, nígbà tí idà mi bá jẹ ẹran: ẹ̀jẹ̀ ẹni pípa àti ẹni ìgbèkùn, láti orí àwọn aṣáájú ọ̀tá.”
I will kill all [of my enemies] with a sword; it will be as though I had arrows that will be covered with their blood. I will kill [MTY] all those whom I capture and cut off their leaders’ heads.’
43 Ẹ yọ̀ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí òun yóò gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀; yóò sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá a rẹ̀ yóò sì ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àti ènìyàn rẹ̀.
“You people of all nations, you as well as his people should praise Yahweh, because Yahweh gets revenge on those who kill the people who serve him; and he cleanses his people’s land which has become defiled because of their sins.”
44 Mose sì wá ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí ní etí àwọn ènìyàn náà, òun, àti Hosea ọmọ Nuni.
Joshua and Moses/I recited the words of that song while the Israeli people were listening.
45 Nígbà tí Mose parí i kíka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí Israẹli.
When they/we finished reciting to the Israeli people the words of this song,
46 Ó sọ fún un pé, “Ẹ gbé ọkàn an yín lé gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ láàrín yín lónìí, kí ẹ̀yin lè pàṣẹ fún àwọn ọmọ yín láti gbọ́rọ̀ àti láti ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
Moses/I said, “Never forget all these commands that I have been giving you today. Teach these laws to your children, in order that they will faithfully obey all of them.
47 Wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ asán fún ọ, ìyè e yín ni wọ́n. Nípa wọn ni ẹ̀yin yóò gbé pẹ́ lórí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ń gòkè e Jordani lọ láti gbà.”
These instructions are very important [LIT]. If [you obey] them, you will live a long time in the land that you are about to cross the Jordan [River] to occupy.”
48 Ní ọjọ́ kan náà, Olúwa sọ fún Mose pé,
On that same day, Yahweh said to Moses/me,
49 “Gòkè lọ sí Abarimu sí òkè Nebo ní Moabu, tí ó kọjú sí Jeriko, kí o sì wo ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí mo ń fi fún àwọn ọmọ Israẹli, bí ìní i wọn.
“Go to the Abarim Mountain range [here] in the Moab region, across from Jericho. Climb Nebo Mountain, and look [toward the west] to see Canaan land, the land that I am about to give to the Israeli people.
50 Ní orí òkè tí ìwọ ń gùn lọ ìwọ yóò kùú níbẹ̀, kí a sì sin ọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin in rẹ Aaroni ti kú ní orí òkè Hori tí a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn an rẹ̀.
You will die on that mountain [EUP, DOU], like your [older] brother Aaron died on Hor Mountain.
51 Ìdí ni pé ẹ̀yin méjèèjì ṣẹ̀ sí mi láàrín àwọn ọmọ Israẹli ní ibi omi Meriba Kadeṣi ní aginjù Sini àti nítorí ẹ̀yin kò yà mí sí mímọ́ láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
You will die because both of you disobeyed me in the presence of the Israeli people, when you all were at Meribah Springs near Kadesh [town] in the Zin Desert. You did not honor and respect me in the presence of the Israeli people in the way that I deserve because I am God.
52 Nítorí náà, ìwọ yóò rí ilẹ̀ náà ní ọ̀kánkán, o kì yóò wọ inú rẹ̀ ilẹ̀ ti mo ti fi fún àwọn ọmọ Israẹli.”
[When you are on that mountain where I told you to go], you will see in the distance in front of you the land that I am about to give to the Israeli people, but you will not enter it.”