< Deuteronomy 31 >

1 Nígbà náà ni Mose jáde tí ó sì sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí gbogbo Israẹli pé,
Och Mose gick åstad och talade följande till hela Israel;
2 “Mo jẹ́ ọmọ ọgọ́fà ọdún báyìí àti pé èmi kò ni lè darí i yín mọ́. Olúwa ti sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò ní kọjá Jordani.’
han sade till dem: "Jag är nu ett hundra tjugu år gammal; jag kan icke mer vara ledare och anförare, och HERREN har sagt till mig: 'Du skall icke komma över denna Jordan.'
3 Olúwa Ọlọ́run rẹ fúnra rẹ̀ ni yóò rékọjá fún ọ. Yóò pa àwọn orílẹ̀-èdè yìí run níwájú rẹ, ìwọ yóò sì mú ìní ilẹ̀ wọn, Joṣua náà yóò rékọjá fún ọ, bí Olúwa ti sọ.
Men HERREN, din Gud, går framför dig; han skall förgöra dessa folk för dig, och du skall fördriva dem, och Josua skall anföra dig, såsom HERREN har sagt.
4 Olúwa yóò sì ṣe fún wọn ohun tí ó ti ṣe sí Sihoni àti sí Ogu ọba Amori, tí ó parun pẹ̀lú ilẹ̀ ẹ wọn.
Och HERREN skall göra med dem såsom han gjorde med Sihon och Og, amoréernas konungar. vilka han lät förgås, och såsom han gjorde med deras land.
5 Olúwa yóò fi wọ́n fún ọ, kí o sì ṣe sí wọn gbogbo èyí tí mo ti pàṣẹ fún ọ.
HERREN skall giva dem i edert våld, och I skolen göra med dem alldeles såsom jag har bjudit eder.
6 Jẹ́ alágbára kí o sì ní ìgboyà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí jáyà nítorí i wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń lọ pẹ̀lú rẹ, Òun kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
Varen frimodiga och oförfärade, frukten icke och varen icke förskräckta för dem; ty HERREN, din Gud, går själv med dig; han skall icke lämna dig eller övergiva dig."
7 Nígbà náà ni Mose pe Joṣua ó sì wí fún un níwájú gbogbo Israẹli pé, “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí o ní láti lọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fún wọn, kí o sì pín ilẹ̀ náà láàrín wọn bí ogún wọn.
Och Mose kallade Josua till sig och sade till honom inför hela Israel: "Var frimodig och oförfärad; ty du skall med detta folk gå in i det land som HERREN med ed har lovat deras fäder att giva dem; och du skall utskifta det åt dem såsom arv.
8 Olúwa fúnra rẹ̀ ń lọ níwájú rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ; kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Má ṣe bẹ̀rù má sì ṣe fòyà.”
Och HERREN är den som går framför dig, han skall vara med dig, han skall icke lämna dig eller övergiva dig; du må icke frukta och icke vara förfärad."
9 Nígbà náà ni Mose kọ òfin yìí kalẹ̀ ó sì fi fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, tí ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti fún gbogbo àwọn àgbàgbà ní Israẹli.
Och Mose skrev upp denna lag och gav den åt prästerna, Levi söner, som buro HERRENS förbundsark, och åt alla de äldste i Israel.
10 Nígbà náà ni Mose pàṣẹ fún wọn, “Ní òpin ọdún méje méje, ní àkókò ọdún ìdásílẹ̀, nígbà àjọ àwọn àgọ́.
Och Mose bjöd dem och sade: "Vid slutet av vart sjunde år, när friåret är inne, vid lövhyddohögtiden,
11 Nígbà tí gbogbo Israẹli bá wá láti fi ara hàn níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ibi tí yóò yàn, ìwọ yóò ka òfin yìí níwájú wọn sí etí ìgbọ́ wọn.
då hela Israel kommer för att träda fram inför HERRENS, din Guds, ansikte, på den plats som han utväljer, då skall du läsa upp denna lag inför hela Israel, så att de höra den.
12 Pe àwọn ènìyàn jọ àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àti àwọn àjèjì tí ń gbé àwọn ìlú u yín kí wọn lè fetí sí i kí wọn sì lè kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ kí wọn sì rọra tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí.
Församla då folket, män, kvinnor och barn, och främlingarna som äro hos dig inom dina portar, på det att de må höra och lära, och på det att de må frukta HERREN, eder Gud, och hålla och göra efter alla denna lags ord;
13 Àwọn ọmọ wọn tí wọn kò mọ òfin yìí, gbọdọ̀ gbọ́ kí wọn sì kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ níwọ̀n ìgbà tí o tí ń gbé ní ilẹ̀ tí ò ń kọjá la Jordani lọ láti ni.”
och på det att deras barn, som då ännu icke känna den, må höra den och lära den, så att de frukta HERREN, eder Gud. Detta skolen I göra, så länge I leven i det land dit I nu dragen över Jordan, för att taga det i besittning.
14 Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọjọ́ ikú rẹ ti súnmọ́ etílé báyìí. Pe Joṣua kí ẹ sì fi ara yín hàn nínú àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti fi àṣẹ fún un.” Nígbà náà ni Mose àti Joṣua wá, wọ́n sì fi ara wọn hàn níbi àgọ́ àjọ.
Och HERREN sade till Mose: "Se, tiden närmar sig att du skall dö. Kalla till dig Josua, och inställen eder därefter i uppenbarelsetältet, så vill jag insätta honom i hans ämbete." Och Mose gick åstad med Josua, och de inställde sig i uppenbarelsetältet.
15 Nígbà náà ni Olúwa farahàn níbi àgọ́ ní ọ̀wọ́ àwọsánmọ̀, àwọsánmọ̀ náà sì dúró sókè ẹnu-ọ̀nà àgọ́.
Då visade sig HERREN i tältet i en molnstod, och molnstoden blev stående vid ingången till tältet.
16 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ìwọ ń lọ sinmi pẹ̀lú àwọn baba à rẹ, àwọn wọ̀nyí yóò sì ṣe àgbèrè ara wọn sí ọlọ́run àjèjì ilẹ̀ tí wọn ń wọ̀ lọ láìpẹ́. Wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀ wọn yóò sì da májẹ̀mú tí mo bá wọn dá.
Och HERREN sade till Mose: "Se, när du vilar hos dina fäder, skall detta folk stå upp och i trolös avfällighet löpa efter främmande gudar, som dyrkas i det land dit de nu komma, och de skola övergiva mig och bryta det förbund som jag har slutit med dem.
17 Ní ọjọ́ náà ni èmi yóò bínú sí wọn èmi yóò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀; èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò fún wọn, wọn yóò sì parun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àjálù àti ìṣòro yóò wá sórí wọn, àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò béèrè pé, ‘Ǹjẹ́ ìpọ́njú wọ̀nyí kò wá sórí i wa nítorí Ọlọ́run wa kò sí pẹ̀lú u wa?’
Och min vrede skall då upptändas mot dem, och jag skall övergiva dem och fördölja mitt ansikte för dem, och de skola förgöras, och mycken olycka och nöd skall träffa dem; och då skola de säga: 'Förvisso är det därför att vår Gud icke är ibland oss som dessa olyckor hava träffat oss.'
18 Èmi yóò sì pa ojú mi mọ́ dájúdájú ní ọjọ́ náà nítorí i gbogbo ìwà búburú wọn ní yíyípadà sí ọlọ́run mìíràn.
Men jag skall på den tiden alldeles fördölja mitt ansikte, för allt det ondas skull som de hava gjort, i det att de hava vänt sig till andra gudar.
19 “Ní báyìí kọ ọ́ kalẹ̀ fúnra à rẹ orin yìí kí o sì kọ ọ́ sí Israẹli kí o sì jẹ́ kí wọn kọ ọ́ kí ó lè jẹ́ ẹ̀rí ì mi sí wọn.
Så tecknen nu upp åt eder följande sång. Och du skall lära Israels barn den och lägga den i deras mun. Och så skall denna sång vara mig ett vittne mot Israels barn.
20 Nígbà tí mo ti mú wọn wá sí ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, ilẹ̀ tí mo ti ṣe ìlérí ní ìbúra fún àwọn baba ńlá wọn, àti nígbà tí wọ́n bá jẹ, tí ó sì tẹ́ wọn lọ́rùn, tí wọ́n sì gbilẹ̀, wọn yóò yí padà sí ọlọ́run mìíràn wọn yóò sì sìn wọ́n, wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀, wọn yóò sì da májẹ̀mú mi.
Ty jag skall låta dem komma in i det land som jag med ed har lovat åt deras fäder, ett land som flyter av mjölk och honung, och de skola äta och bliva mätta och feta; men de skola då vända sig till andra gudar och tjäna dem och förakta mig och bryta mitt förbund.
21 Àti nígbà tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpọ́njú àti ìṣòro bá wá sórí i wọn, orin yìí yóò jẹ́ ẹ̀rí sí wọn, nítorí kò ní di ìgbàgbé fún àwọn ọmọ wọn. Mo mọ̀ ohun tí wọ́n ní inú dídùn sí láti ṣe, pàápàá kí èmi tó mú wọn wá sí ilẹ̀ tí mo ṣe ìlérí fún wọn lórí ìbúra.”
Och när då mycken olycka och nöd träffar dem, skall denna sång avlägga sitt vittnesbörd inför dem; ty den skall icke förgätas och försvinna ur deras avkomlingars mun. Jag vet ju med vilka tankar de umgås redan nu, innan jag har låtit dem komma in i det land som jag med ed lovade dem."
22 Nígbà náà ni Mose kọ orin yìí kalẹ̀ ní ọjọ́ náà ó sì kọ ọ́ sí Israẹli.
Så tecknade då Mose upp sången på den dagen och lät Israels barn lära den.
23 Olúwa sì fún Joṣua ọmọ Nuni ní àṣẹ yìí: “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí ìwọ yóò mú Israẹli wá sí ilẹ̀ tí mo ṣèlérí fún wọn lórí ìbúra, èmi fúnra à mi yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.”
Och han insatte Josua, Nuns son, i hans ämbete och sade: "Var frimodig och oförfärad; ty du skall föra Israels barn in i det land som jag med ed har lovat åt dem, och jag skall vara med dig."
24 Lẹ́yìn ìgbà tí Mose ti parí i kíkọ ọ̀rọ̀ òfin yìí sínú ìwé láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin,
Då nu Mose hade fullständigt tecknat upp denna lags ord i en bok,
25 ó sì fi àṣẹ yìí fún àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa:
bjöd han leviterna som buro HERRENS förbundsark och sade:
26 “Gba ìwé òfin yìí kí o sì fi sí ẹ̀gbẹ́ àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Níbẹ̀ ni yóò wà bí ẹ̀rí sí ọ.
"Tagen denna lagbok och läggen den vid sidan av HERRENS, eder Guds, förbundsark, så att den ligger där till ett vittne mot dig.
27 Nítorí mo mọ irú ọlọ̀tẹ̀ àti ọlọ́rùn líle tí ẹ jẹ́. Bí o bá ṣe ọlọ̀tẹ̀ sí Olúwa nígbà tí mo pàpà wà láyé pẹ̀lú yín, báwo ní ẹ ó ti ṣe ọlọ̀tẹ̀ tó nígbà tí mo bá kú tán!
Ty jag känner din gensträvighet och hårdnackenhet. Se, ännu medan jag har levat kvar bland eder, haven I varit gensträviga mot HERREN; huru mycket mer skolen I ej då bliva det efter min död!
28 Ẹ péjọpọ̀ síwájú mi gbogbo àgbà ẹ̀yà yín àti àwọn aláṣẹ yín, kí èmi lè sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí etí ìgbọ́ ọ́ wọn.
Församlen nu till mig alla de äldste i edra stammar, så ock edra tillsyningsmän, för att jag må inför dem tala dessa ord och taga himmel och jord till vittnen mot dem.
29 Nítorí tí mo mọ̀ pé lẹ́yìn ikú mi, ó dájú pé ìwọ yóò padà di ìbàjẹ́ pátápátá, ẹ ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ní ọjọ́ tó ń bọ̀, ìpọ́njú yóò sọ̀kalẹ̀ sórí i yín nítorí ẹ̀yin yóò ṣe búburú níwájú Olúwa ẹ ó sì mú u bínú nípa ohun tí ọwọ́ yín ti ṣe.”
Ty jag vet att I efter min död skolen taga eder till, vad fördärvligt är, och vika av ifrån den väg som jag har bjudit eder gå; därför skall olycka träffa eder i kommande dagar, när I gören vad ont är i HERRENS ögon, så att I förtörnen honom genom edra händers verk."
30 Mose sì ka ọ̀rọ̀ inú orin yìí láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin sí etí ìgbọ́ ọ gbogbo ìjọ Israẹli:
Och Mose föredrog inför Israels hela församling följande sång från början till slutet.

< Deuteronomy 31 >