< Deuteronomy 31 >

1 Nígbà náà ni Mose jáde tí ó sì sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí gbogbo Israẹli pé,
Przyszedłszy tedy Mojżesz, opowiedział te słowa wszystkiemu Izraelowi,
2 “Mo jẹ́ ọmọ ọgọ́fà ọdún báyìí àti pé èmi kò ni lè darí i yín mọ́. Olúwa ti sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò ní kọjá Jordani.’
I rzekł do nich: Sto i dwadzieścia lat jest mi dziś; nie mogę więcej wychodzić i wchodzić; a też mi Pan powiedział: Nie przejdziesz za ten Jordan.
3 Olúwa Ọlọ́run rẹ fúnra rẹ̀ ni yóò rékọjá fún ọ. Yóò pa àwọn orílẹ̀-èdè yìí run níwájú rẹ, ìwọ yóò sì mú ìní ilẹ̀ wọn, Joṣua náà yóò rékọjá fún ọ, bí Olúwa ti sọ.
Pan, Bóg twój sam pójdzie przed tobą; on wytraci narody te przed tobą, i posiędziesz je: Jozue, ten pójdzie przed tobą, jako powiedział Pan.
4 Olúwa yóò sì ṣe fún wọn ohun tí ó ti ṣe sí Sihoni àti sí Ogu ọba Amori, tí ó parun pẹ̀lú ilẹ̀ ẹ wọn.
I uczyni im Pan, jako uczynił Sehonowi, i Ogowi, królom Amorejskim, i ziemi ich, które wygładził.
5 Olúwa yóò fi wọ́n fún ọ, kí o sì ṣe sí wọn gbogbo èyí tí mo ti pàṣẹ fún ọ.
A gdy je wam Pan poda, tedy im uczynicie według każdego przykazania, jakom wam przykazał.
6 Jẹ́ alágbára kí o sì ní ìgboyà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí jáyà nítorí i wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń lọ pẹ̀lú rẹ, Òun kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
Zmacniajcież się, a mężnie sobie poczynajcie, nie bójcie się, ani się lękajcie twarzy ich; albowiem Pan, Bóg twój, on idzie z tobą, nie odstąpi cię, ani cię opuści.
7 Nígbà náà ni Mose pe Joṣua ó sì wí fún un níwájú gbogbo Israẹli pé, “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí o ní láti lọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fún wọn, kí o sì pín ilẹ̀ náà láàrín wọn bí ogún wọn.
Tedy przyzwawszy Mojżesz Jozuego, rzekł do niego przed oczyma wszystkiego Izraela: Zmocnij się, a mężnie sobie poczynaj; bo ty wnijdziesz z ludem tym do ziemi, o którą przysiągł Pan ojcom ich, że im ją da, a ty im ją w dziedzictwo podzielisz.
8 Olúwa fúnra rẹ̀ ń lọ níwájú rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ; kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Má ṣe bẹ̀rù má sì ṣe fòyà.”
A Pan on pójdzie przed tobą, on będzie z tobą, nie odstąpi cię, ani cię opuści; nie bójże się, ani się lękaj.
9 Nígbà náà ni Mose kọ òfin yìí kalẹ̀ ó sì fi fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, tí ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti fún gbogbo àwọn àgbàgbà ní Israẹli.
Tedy napisał Mojżesz ten zakon i oddał go kapłanom, synom Lewiego, którzy nosili skrzynię przymierza Pańskiego, i wszystkim starszym Izraelskim.
10 Nígbà náà ni Mose pàṣẹ fún wọn, “Ní òpin ọdún méje méje, ní àkókò ọdún ìdásílẹ̀, nígbà àjọ àwọn àgọ́.
Przytem rozkazał im Mojżesz, mówiąc: Na początku każdego siódmego roku, w pewny czas roku odpuszczania, w święto Kuczek;
11 Nígbà tí gbogbo Israẹli bá wá láti fi ara hàn níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ibi tí yóò yàn, ìwọ yóò ka òfin yìí níwájú wọn sí etí ìgbọ́ wọn.
Gdy się zejdzie wszystek Izrael, aby się pokazał przed Panem, Bogiem twoim, na miejscu, które sobie obierze, obwołasz ten zakon przed wszystkim Izraelem w uszach ich;
12 Pe àwọn ènìyàn jọ àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àti àwọn àjèjì tí ń gbé àwọn ìlú u yín kí wọn lè fetí sí i kí wọn sì lè kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ kí wọn sì rọra tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí.
A zgromadzisz lud, męże, i niewiasty, i dziatki, i przychodnie twoje, którzy są w bramach twoich, aby słuchali, i aby się uczyli, i bali Pana, Boga waszego, i przestrzegali, aby czynili wszystkie słowa zakonu tego.
13 Àwọn ọmọ wọn tí wọn kò mọ òfin yìí, gbọdọ̀ gbọ́ kí wọn sì kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ níwọ̀n ìgbà tí o tí ń gbé ní ilẹ̀ tí ò ń kọjá la Jordani lọ láti ni.”
Synowie też ich, którzy jeszcze nie wiedzą, niechaj słuchają, i niech się uczą bać Pana, Boga waszego, po wszystkie dni, których żyć będziecie na ziemi, do której idziecie, przeprawiwszy się przez Jordan wnijdziecie, abyście ją posiedli.
14 Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọjọ́ ikú rẹ ti súnmọ́ etílé báyìí. Pe Joṣua kí ẹ sì fi ara yín hàn nínú àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti fi àṣẹ fún un.” Nígbà náà ni Mose àti Joṣua wá, wọ́n sì fi ara wọn hàn níbi àgọ́ àjọ.
Zatem rzekł Pan do Mojżesza: Oto, przybliżyły się dni śmierci twojej; przyzówże Jozuego, a stańcie w namiocie zgromadzenia, a przykażę mu. Szedł tedy Mojżesz i Jozue, a stanęli w namiocie zgromadzenia.
15 Nígbà náà ni Olúwa farahàn níbi àgọ́ ní ọ̀wọ́ àwọsánmọ̀, àwọsánmọ̀ náà sì dúró sókè ẹnu-ọ̀nà àgọ́.
Tedy się ukazał Pan w namiocie w słupie obłokowym; i stanął on słup obłokowy nade drzwiami namiotu,
16 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ìwọ ń lọ sinmi pẹ̀lú àwọn baba à rẹ, àwọn wọ̀nyí yóò sì ṣe àgbèrè ara wọn sí ọlọ́run àjèjì ilẹ̀ tí wọn ń wọ̀ lọ láìpẹ́. Wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀ wọn yóò sì da májẹ̀mú tí mo bá wọn dá.
I rzekł Pan do Mojżesza: Oto, ty zaśniesz z ojcy twoimi; a powstawszy lud ten będzie cudzołożył, naśladując bogów cudzoziemców tej ziemi, do której wchodzi, aby mieszkał w pośrodku niej i opuści mię, i złamie przymierze moje, którem postanowił z nim.
17 Ní ọjọ́ náà ni èmi yóò bínú sí wọn èmi yóò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀; èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò fún wọn, wọn yóò sì parun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àjálù àti ìṣòro yóò wá sórí wọn, àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò béèrè pé, ‘Ǹjẹ́ ìpọ́njú wọ̀nyí kò wá sórí i wa nítorí Ọlọ́run wa kò sí pẹ̀lú u wa?’
Przetoż zapali się gniew mój przeciwko jemu onego dnia, a opuszczę je, i skryję oblicze moje przed nimi, a będzie na pożarcie, i znajdą go wiele złych rzeczy i utrapienia; i rzecze dnia onego: Azaż nie dlatego, iż Boga mego nie masz w pośrodku mnie, znalazły mię te złe rzeczy?
18 Èmi yóò sì pa ojú mi mọ́ dájúdájú ní ọjọ́ náà nítorí i gbogbo ìwà búburú wọn ní yíyípadà sí ọlọ́run mìíràn.
A Ja kryjąc skryję oblicze moje w on dzień dla wszystkiego złego, które czynili, udawszy się za bogi cudzymi.
19 “Ní báyìí kọ ọ́ kalẹ̀ fúnra à rẹ orin yìí kí o sì kọ ọ́ sí Israẹli kí o sì jẹ́ kí wọn kọ ọ́ kí ó lè jẹ́ ẹ̀rí ì mi sí wọn.
Teraz tedy napiszcie sobie tę pieśń, a naucz jej synów Izraelskich; włóż ją w usta ich, aby im była ta pieśń świadectwem przeciwko synom Izraelowym.
20 Nígbà tí mo ti mú wọn wá sí ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, ilẹ̀ tí mo ti ṣe ìlérí ní ìbúra fún àwọn baba ńlá wọn, àti nígbà tí wọ́n bá jẹ, tí ó sì tẹ́ wọn lọ́rùn, tí wọ́n sì gbilẹ̀, wọn yóò yí padà sí ọlọ́run mìíràn wọn yóò sì sìn wọ́n, wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀, wọn yóò sì da májẹ̀mú mi.
Albowiem wprowadzę go do ziemi, o którąm przysiągł ojcom jego, opływającej mlekiem i miodem; i będzie jadł, a naje się, i utyje, a obróci się do bogów cudzych, i służyć im będzie, i rozdraźnią mię, i zrzucą przymierze moje,
21 Àti nígbà tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpọ́njú àti ìṣòro bá wá sórí i wọn, orin yìí yóò jẹ́ ẹ̀rí sí wọn, nítorí kò ní di ìgbàgbé fún àwọn ọmọ wọn. Mo mọ̀ ohun tí wọ́n ní inú dídùn sí láti ṣe, pàápàá kí èmi tó mú wọn wá sí ilẹ̀ tí mo ṣe ìlérí fún wọn lórí ìbúra.”
I stanie się, gdy go znajdzie wiele złego i utrapienia, że będzie ta pieśń przed nim na świadectwo; albowiem nie przyjdzie w zapamiętanie w uściech nasienia ich, gdyż wiem myśli jego, i co on jeszcze dziś czynić będzie, pierwej niż go wprowadzę do ziemi, o którąm przysiągł.
22 Nígbà náà ni Mose kọ orin yìí kalẹ̀ ní ọjọ́ náà ó sì kọ ọ́ sí Israẹli.
I napisał Mojżesz tę pieśń onegoż dnia, i nauczył jej synów Izraelskich.
23 Olúwa sì fún Joṣua ọmọ Nuni ní àṣẹ yìí: “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí ìwọ yóò mú Israẹli wá sí ilẹ̀ tí mo ṣèlérí fún wọn lórí ìbúra, èmi fúnra à mi yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.”
Potem przykazał Jozuemu, synowi Nunowemu, i rzekł: Zmacniaj się, i mężnie sobie poczynaj; albowiem ty wprowadzisz syny Izraelskie do ziemi, o którąm im przysiągł; a Ja będę z tobą.
24 Lẹ́yìn ìgbà tí Mose ti parí i kíkọ ọ̀rọ̀ òfin yìí sínú ìwé láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin,
I stało się, gdy napisał Mojżesz słowa zakonu tego w księgi, i dokończył ich,
25 ó sì fi àṣẹ yìí fún àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa:
Rozkazał Mojżesz Lewitom, którzy nosili skrzynię przymierza Pańskiego, mówiąc:
26 “Gba ìwé òfin yìí kí o sì fi sí ẹ̀gbẹ́ àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Níbẹ̀ ni yóò wà bí ẹ̀rí sí ọ.
Weźmijcie księgi zakonu tego i włóżcie je przy stronie do skrzyni przymierza Pana, Boga waszego, aby tam były przeciwko tobie na świadectwo;
27 Nítorí mo mọ irú ọlọ̀tẹ̀ àti ọlọ́rùn líle tí ẹ jẹ́. Bí o bá ṣe ọlọ̀tẹ̀ sí Olúwa nígbà tí mo pàpà wà láyé pẹ̀lú yín, báwo ní ẹ ó ti ṣe ọlọ̀tẹ̀ tó nígbà tí mo bá kú tán!
Albowiem ja znam upór twój, i kark twój twardy; oto, póki ja jeszcze dziś żyję z wami, jesteście odpornymi Panu, jakoż daleko więcej po śmierci mojej?
28 Ẹ péjọpọ̀ síwájú mi gbogbo àgbà ẹ̀yà yín àti àwọn aláṣẹ yín, kí èmi lè sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí etí ìgbọ́ ọ́ wọn.
Zgromadźcież do mnie wszystkie starsze pokoleń waszych, i przełożone wasze, żebym mówił w uszach ich słowa te, i będę wzywał na świadectwo przeciwko nim niebo i ziemię,
29 Nítorí tí mo mọ̀ pé lẹ́yìn ikú mi, ó dájú pé ìwọ yóò padà di ìbàjẹ́ pátápátá, ẹ ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ní ọjọ́ tó ń bọ̀, ìpọ́njú yóò sọ̀kalẹ̀ sórí i yín nítorí ẹ̀yin yóò ṣe búburú níwájú Olúwa ẹ ó sì mú u bínú nípa ohun tí ọwọ́ yín ti ṣe.”
Ponieważ wiem, że po śmierci mojej popsujecie się bardzo, a ustąpicie z drogi, którąm wam rozkazał; przetoż przyjdzie na was to złe w ostatnie dni, gdy będziecie czynić złe przed oczyma Pańskiemi, draźniąc go sprawami rąk waszych.
30 Mose sì ka ọ̀rọ̀ inú orin yìí láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin sí etí ìgbọ́ ọ gbogbo ìjọ Israẹli:
I mówił Mojżesz w uszach wszystkiego zgromadzenia Izraelskiego słowa tej pieśni, aż jej dokończył.

< Deuteronomy 31 >