< Deuteronomy 31 >

1 Nígbà náà ni Mose jáde tí ó sì sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí gbogbo Israẹli pé,
Nake Musa akiumagara agĩthiĩ akĩarĩria andũ othe a Isiraeli na ciugo ici akĩmeera atĩrĩ,
2 “Mo jẹ́ ọmọ ọgọ́fà ọdún báyìí àti pé èmi kò ni lè darí i yín mọ́. Olúwa ti sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò ní kọjá Jordani.’
“Rĩu ndĩ na ũkũrũ wa mĩaka igana na mĩrongo ĩĩrĩ, na ndingĩhota kũmũtongoria rĩngĩ. Jehova nĩanjĩĩrĩte atĩrĩ, ‘Wee ndũkũringa Rũũĩ rwa Jorodani.’
3 Olúwa Ọlọ́run rẹ fúnra rẹ̀ ni yóò rékọjá fún ọ. Yóò pa àwọn orílẹ̀-èdè yìí run níwájú rẹ, ìwọ yóò sì mú ìní ilẹ̀ wọn, Joṣua náà yóò rékọjá fún ọ, bí Olúwa ti sọ.
Jehova Ngai wanyu we mwene nĩakaringa arĩ mbere yanyu. Nĩakaniina ndũrĩrĩ icio mbere yanyu na inyuĩ nĩmũkegwatĩra bũrũri wacio. Joshua o nake nĩakaringa arĩ mbere yanyu ta ũrĩa Jehova oigire.
4 Olúwa yóò sì ṣe fún wọn ohun tí ó ti ṣe sí Sihoni àti sí Ogu ọba Amori, tí ó parun pẹ̀lú ilẹ̀ ẹ wọn.
Nake Jehova nĩakameka o ta ũrĩa eekire Sihoni na Ogu, athamaki a Aamori, arĩa aaniinire hamwe na bũrũri wao.
5 Olúwa yóò fi wọ́n fún ọ, kí o sì ṣe sí wọn gbogbo èyí tí mo ti pàṣẹ fún ọ.
Jehova nĩakamaneana kũrĩ inyuĩ, na inyuĩ no nginya mũkaameeka ũrĩa wothe ndĩmwathĩte.
6 Jẹ́ alágbára kí o sì ní ìgboyà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí jáyà nítorí i wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń lọ pẹ̀lú rẹ, Òun kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
Gĩai na hinya na mũũmĩrĩrie. Mũtigetigĩre kana mũmake nĩ ũndũ wao, nĩgũkorwo Jehova Ngai wanyu nĩ egũthiĩ hamwe na inyuĩ; ndakamũtiga kana amũtirike.”
7 Nígbà náà ni Mose pe Joṣua ó sì wí fún un níwájú gbogbo Israẹli pé, “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí o ní láti lọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fún wọn, kí o sì pín ilẹ̀ náà láàrín wọn bí ogún wọn.
Nake Musa agĩĩta Joshua, akĩmwĩra arĩ mbere ya andũ othe a Isiraeli atĩrĩ, “Gĩa na hinya, nĩgũkorwo no nginya ũthiĩ na andũ aya bũrũri-inĩ ũrĩa Jehova eehĩtire kũrĩ maithe mao ma tene atĩ nĩakamahe, nawe no nginya ũkaaũgayania gatagatĩ-inĩ kao, ũtuĩke igai rĩao.
8 Olúwa fúnra rẹ̀ ń lọ níwájú rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ; kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Má ṣe bẹ̀rù má sì ṣe fòyà.”
Jehova mwene nĩegũthiĩ mbere yaku na nĩarĩkoragwo hamwe na we; ndarĩ hĩndĩ agaagũtiga kana agũtirike. Ndũkanetigĩre, o na kana ũkue ngoro.”
9 Nígbà náà ni Mose kọ òfin yìí kalẹ̀ ó sì fi fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, tí ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti fún gbogbo àwọn àgbàgbà ní Israẹli.
Nĩ ũndũ ũcio Musa akĩandĩka watho ũcio, agĩcooka akĩũnengera athĩnjĩri-Ngai, ariũ a Lawi, arĩa maakuĩte ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova, o na akĩũnengera athuuri othe a Isiraeli.
10 Nígbà náà ni Mose pàṣẹ fún wọn, “Ní òpin ọdún méje méje, ní àkókò ọdún ìdásílẹ̀, nígbà àjọ àwọn àgọ́.
Ningĩ Musa akĩmaatha akĩmeera atĩrĩ, “O mũthia-inĩ wa mĩaka mũgwanja, mwaka-inĩ ũrĩa ũtuĩtwo wa kũrekanĩra mathiirĩ, hĩndĩ ya Gĩathĩ gĩa Ithũnũ-rĩ,
11 Nígbà tí gbogbo Israẹli bá wá láti fi ara hàn níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ibi tí yóò yàn, ìwọ yóò ka òfin yìí níwájú wọn sí etí ìgbọ́ wọn.
nĩrĩo andũ othe a Isiraeli mariumagĩra mbere ya Jehova Ngai wanyu handũ harĩa we mwene agaathuura, nĩmũrĩmathomagĩra watho ũyũ mũrĩ mbere yao makĩiguaga.
12 Pe àwọn ènìyàn jọ àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àti àwọn àjèjì tí ń gbé àwọn ìlú u yín kí wọn lè fetí sí i kí wọn sì lè kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ kí wọn sì rọra tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí.
Cookanagĩrĩria andũ othe hamwe: arũme, na andũ-a-nja, na ciana, na andũ a kũngĩ arĩa matũũraga matũũra-inĩ manyu, nĩgeetha mathikĩrĩrie na merute gwĩtigĩra Jehova Ngai wanyu, na marũmagĩrĩre ciugo cia watho ũyũ.
13 Àwọn ọmọ wọn tí wọn kò mọ òfin yìí, gbọdọ̀ gbọ́ kí wọn sì kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ níwọ̀n ìgbà tí o tí ń gbé ní ilẹ̀ tí ò ń kọjá la Jordani lọ láti ni.”
Ciana ciao iria itooĩ watho ũyũ, no nginya ciũigue, na ciĩrute gwĩtigĩra Jehova Ngai wanyu rĩrĩa rĩothe mũgũtũũra bũrũri ũcio mũraringa Rũũĩ rwa Jorodani mũthiĩ mũkawĩgwatĩre.”
14 Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọjọ́ ikú rẹ ti súnmọ́ etílé báyìí. Pe Joṣua kí ẹ sì fi ara yín hàn nínú àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti fi àṣẹ fún un.” Nígbà náà ni Mose àti Joṣua wá, wọ́n sì fi ara wọn hàn níbi àgọ́ àjọ.
Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Atĩrĩrĩ, mũthenya wa gũkua gwaku ũrĩ hakuhĩ. Ĩta Joshua mũũke nake na mũrũgame Hema-inĩ-ya-Gũtũnganwo, nĩho ngũnengerera Joshua wĩra.” Nĩ ũndũ ũcio Musa na Joshua magĩũka makĩrũgama Hema-inĩ-ya-Gũtũnganwo.
15 Nígbà náà ni Olúwa farahàn níbi àgọ́ ní ọ̀wọ́ àwọsánmọ̀, àwọsánmọ̀ náà sì dúró sókè ẹnu-ọ̀nà àgọ́.
Hĩndĩ ĩyo Jehova akiumĩra Hema-inĩ ĩyo arĩ thĩinĩ wa gĩtugĩ gĩa itu, narĩo itu rĩu rĩkĩrũgama itoonyero-inĩ rĩa Hema.
16 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ìwọ ń lọ sinmi pẹ̀lú àwọn baba à rẹ, àwọn wọ̀nyí yóò sì ṣe àgbèrè ara wọn sí ọlọ́run àjèjì ilẹ̀ tí wọn ń wọ̀ lọ láìpẹ́. Wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀ wọn yóò sì da májẹ̀mú tí mo bá wọn dá.
Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Wee nĩũkũhurũka hamwe na maithe maku, nao andũ aya ihinda rĩtarĩ kũraihu nĩmekũhũũra ũmaraya na ngai cia kũngĩ cia bũrũri ũrĩa mũratoonya. Nĩmakandirika na mathũkie kĩrĩkanĩro kĩrĩa ndaathondekete nao.
17 Ní ọjọ́ náà ni èmi yóò bínú sí wọn èmi yóò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀; èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò fún wọn, wọn yóò sì parun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àjálù àti ìṣòro yóò wá sórí wọn, àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò béèrè pé, ‘Ǹjẹ́ ìpọ́njú wọ̀nyí kò wá sórí i wa nítorí Ọlọ́run wa kò sí pẹ̀lú u wa?’
Mũthenya ũcio nĩngamarakarĩra na ndĩmatirike; nĩngamahitha ũthiũ wakwa, nao nĩmakaniinwo. Nĩmagakorwo nĩ mĩanangĩko mĩingĩ na moritũ maingĩ, nao mũthenya ũcio nĩ makooria atĩrĩ, ‘Githĩ mĩanangĩko ĩno ndĩtũkorete nĩ ũndũ Ngai ndakoretwo hamwe na ithuĩ?’
18 Èmi yóò sì pa ojú mi mọ́ dájúdájú ní ọjọ́ náà nítorí i gbogbo ìwà búburú wọn ní yíyípadà sí ọlọ́run mìíràn.
Na hatarĩ nganja nĩngamahitha ũthiũ wakwa mũthenya ũcio, nĩ ũndũ wa waganu wao wothe wa gũcookerera ngai ingĩ.
19 “Ní báyìí kọ ọ́ kalẹ̀ fúnra à rẹ orin yìí kí o sì kọ ọ́ sí Israẹli kí o sì jẹ́ kí wọn kọ ọ́ kí ó lè jẹ́ ẹ̀rí ì mi sí wọn.
“No rĩrĩ, wĩyandĩkĩre rwĩmbo rũrũ, na ũrũrute andũ a Isiraeli, na ũreke marũine, nĩguo rũtuĩke ũira wakwa wa kũmookĩrĩra.
20 Nígbà tí mo ti mú wọn wá sí ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, ilẹ̀ tí mo ti ṣe ìlérí ní ìbúra fún àwọn baba ńlá wọn, àti nígbà tí wọ́n bá jẹ, tí ó sì tẹ́ wọn lọ́rùn, tí wọ́n sì gbilẹ̀, wọn yóò yí padà sí ọlọ́run mìíràn wọn yóò sì sìn wọ́n, wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀, wọn yóò sì da májẹ̀mú mi.
Ndaarĩkia kũmatoonyia bũrũri ũcio ũrĩ bũthi wa iria na ũũkĩ, bũrũri ũcio nderĩire maithe mao ma tene, na rĩrĩa makaarĩa na mahũũne na matheereme, nĩmakagarũrũkĩra ngai ingĩ macihooe, maamene na mathũkie kĩrĩkanĩro gĩakwa.
21 Àti nígbà tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpọ́njú àti ìṣòro bá wá sórí i wọn, orin yìí yóò jẹ́ ẹ̀rí sí wọn, nítorí kò ní di ìgbàgbé fún àwọn ọmọ wọn. Mo mọ̀ ohun tí wọ́n ní inú dídùn sí láti ṣe, pàápàá kí èmi tó mú wọn wá sí ilẹ̀ tí mo ṣe ìlérí fún wọn lórí ìbúra.”
Na rĩrĩa mĩanangĩko mĩingĩ na moritũ maingĩ makaamakora, rwĩmbo rũrũ nĩrũgatuĩka ũira wa kũmookĩrĩra, nĩ ũndũ njiaro ciao itikariganĩrwo nĩruo. Nĩnjũũĩ ũrĩa maciirĩire gwĩka, o na itarĩ ndĩramatoonyia bũrũri ũrĩa ndaamerĩire na mwĩhĩtwa.”
22 Nígbà náà ni Mose kọ orin yìí kalẹ̀ ní ọjọ́ náà ó sì kọ ọ́ sí Israẹli.
Nĩ ũndũ ũcio Musa akĩandĩka rwĩmbo rũu o mũthenya ũcio, na akĩrũruta andũ a Isiraeli.
23 Olúwa sì fún Joṣua ọmọ Nuni ní àṣẹ yìí: “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí ìwọ yóò mú Israẹli wá sí ilẹ̀ tí mo ṣèlérí fún wọn lórí ìbúra, èmi fúnra à mi yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.”
Jehova nĩaheire Joshua mũrũ wa Nuni rĩathani rĩrĩ: “Gĩa na hinya na ũũmĩrĩrie, nĩgũkorwo nĩwe ũgũkinyia andũ a Isiraeli bũrũri ũrĩa ndamerĩire na mwĩhĩtwa, na Niĩ mwene nĩngũkorwo ndĩ hamwe nawe.”
24 Lẹ́yìn ìgbà tí Mose ti parí i kíkọ ọ̀rọ̀ òfin yìí sínú ìwé láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin,
Thuutha wa Musa kũrĩĩkia kwandĩka ciugo cia watho ũcio ibuku-inĩ kuuma kĩambĩrĩria nginya mũthia,
25 ó sì fi àṣẹ yìí fún àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa:
nĩaheire Alawii arĩa maakuuaga ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova watho ũyũ,
26 “Gba ìwé òfin yìí kí o sì fi sí ẹ̀gbẹ́ àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Níbẹ̀ ni yóò wà bí ẹ̀rí sí ọ.
akĩmeera atĩrĩ, “Oyai Ibuku rĩĩrĩ rĩa Watho mũrĩige mwena-inĩ wa ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova Ngai wanyu. Rĩgũtũũra hau rĩrĩ ũira wa kũmũũkagĩrĩra.
27 Nítorí mo mọ irú ọlọ̀tẹ̀ àti ọlọ́rùn líle tí ẹ jẹ́. Bí o bá ṣe ọlọ̀tẹ̀ sí Olúwa nígbà tí mo pàpà wà láyé pẹ̀lú yín, báwo ní ẹ ó ti ṣe ọlọ̀tẹ̀ tó nígbà tí mo bá kú tán!
Nĩgũkorwo nĩnjũũĩ ũrĩa mũrĩ aremi na mũkoomia ngingo. Angĩkorwo mũkoretwo mũremeire Jehova ndĩ muoyo na ndĩ hamwe na inyuĩ-rĩ, mũgaakĩrĩrĩria kũrema atĩa ndakua!
28 Ẹ péjọpọ̀ síwájú mi gbogbo àgbà ẹ̀yà yín àti àwọn aláṣẹ yín, kí èmi lè sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí etí ìgbọ́ ọ́ wọn.
Cookanĩrĩriai athuuri othe a mĩhĩrĩga yanyu, na anene anyu othe mbere yakwa, nĩgeetha njarie ciugo ici makĩĩiguagĩra, na njĩte igũrũ na thĩ irute ũira wa kũmookĩrĩra.
29 Nítorí tí mo mọ̀ pé lẹ́yìn ikú mi, ó dájú pé ìwọ yóò padà di ìbàjẹ́ pátápátá, ẹ ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ní ọjọ́ tó ń bọ̀, ìpọ́njú yóò sọ̀kalẹ̀ sórí i yín nítorí ẹ̀yin yóò ṣe búburú níwájú Olúwa ẹ ó sì mú u bínú nípa ohun tí ọwọ́ yín ti ṣe.”
Nĩgũkorwo nĩnjũũĩ ndaarĩkia gũkua inyuĩ nĩ mũgethũkia biũ, na mũgarũrũke mũtige gũthiĩ na njĩra ĩrĩa ndĩmwathĩte. Matukũ marĩa magooka mwanangĩko nĩũkamũkora, nĩ ũndũ nĩmũgeeka maũndũ mooru maitho-inĩ ma Jehova, mũtũme arakario nĩ kĩrĩa mũthondekete na moko manyu.”
30 Mose sì ka ọ̀rọ̀ inú orin yìí láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin sí etí ìgbọ́ ọ gbogbo ìjọ Israẹli:
Nake Musa agĩcookera ciugo ici cia rwĩmbo rũrũ kuuma kĩambĩrĩria nginya mũthia, akĩiguagwo nĩ kĩũngano gĩothe gĩa Isiraeli:

< Deuteronomy 31 >