< Deuteronomy 31 >

1 Nígbà náà ni Mose jáde tí ó sì sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí gbogbo Israẹli pé,
And so Moises yede, and spak alle these wordis to al Israel,
2 “Mo jẹ́ ọmọ ọgọ́fà ọdún báyìí àti pé èmi kò ni lè darí i yín mọ́. Olúwa ti sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò ní kọjá Jordani.’
and seide to hem, Y am to dai of an hundrid and twenti yeer, Y may no ferthere go out and go yn, moost sithen also the Lord seide to me, Thou schalt not passe this Jordan.
3 Olúwa Ọlọ́run rẹ fúnra rẹ̀ ni yóò rékọjá fún ọ. Yóò pa àwọn orílẹ̀-èdè yìí run níwájú rẹ, ìwọ yóò sì mú ìní ilẹ̀ wọn, Joṣua náà yóò rékọjá fún ọ, bí Olúwa ti sọ.
Therfor thi Lord God schal passe bifore thee; he schal do awei these folkis in thi siyt, and thou schalt welde hem; and this Josue schal go bifor thee, as the Lord spak.
4 Olúwa yóò sì ṣe fún wọn ohun tí ó ti ṣe sí Sihoni àti sí Ogu ọba Amori, tí ó parun pẹ̀lú ilẹ̀ ẹ wọn.
And the Lord schal do to hem as he dide to Seon, and Og kyng of Ammorreis, and to `the lond of hem; and he schal do hem awey.
5 Olúwa yóò fi wọ́n fún ọ, kí o sì ṣe sí wọn gbogbo èyí tí mo ti pàṣẹ fún ọ.
Therfor whanne the Lord hath bitake to you also hem, ye schulen do in lijk maner to hem, as Y comaundide to you.
6 Jẹ́ alágbára kí o sì ní ìgboyà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí jáyà nítorí i wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń lọ pẹ̀lú rẹ, Òun kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
Do ye manli, and be ye coumfortid; nyle ye drede in herte, nethir drede ye at the siyt of hem, for thi Lord God hym silf is thi ledere, and he schal not leeue, nether schal forsake thee.
7 Nígbà náà ni Mose pe Joṣua ó sì wí fún un níwájú gbogbo Israẹli pé, “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí o ní láti lọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fún wọn, kí o sì pín ilẹ̀ náà láàrín wọn bí ogún wọn.
And Moyses clepid Josue, and seide to hym bifor al the multitude of the sones of Israel, Be thou coumfortid, and be thou strong; for thou schalt lede this puple in to the lond which the Lord swoor that he schal yyue to `the fadris of hem; and thou schalt departe it bi lot.
8 Olúwa fúnra rẹ̀ ń lọ níwájú rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ; kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Má ṣe bẹ̀rù má sì ṣe fòyà.”
And the Lord hym silf whiche is youre ledere, schal be with thee, he schal not leeue, nether schal forsake thee; nyle thou drede, nether drede thou in herte.
9 Nígbà náà ni Mose kọ òfin yìí kalẹ̀ ó sì fi fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, tí ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti fún gbogbo àwọn àgbàgbà ní Israẹli.
Therfor Moyses wroot this lawe, and bitook it to the preestis, sones of Leuy, that baren the arke of the bond of pees of the Lord, and to alle the eldere men of Israel.
10 Nígbà náà ni Mose pàṣẹ fún wọn, “Ní òpin ọdún méje méje, ní àkókò ọdún ìdásílẹ̀, nígbà àjọ àwọn àgọ́.
And Moyses comaundide to hem, and seide, Aftir seuen yeer, in the yeer of remyssioun, in the solempnete of tabernaclis,
11 Nígbà tí gbogbo Israẹli bá wá láti fi ara hàn níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ibi tí yóò yàn, ìwọ yóò ka òfin yìí níwájú wọn sí etí ìgbọ́ wọn.
whanne alle men of Israel schulen come togidere, that thei appere in the siyt of her Lord God, in the place `which the Lord chees, thou schalt rede the wordis of this lawe bifor al Israel,
12 Pe àwọn ènìyàn jọ àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àti àwọn àjèjì tí ń gbé àwọn ìlú u yín kí wọn lè fetí sí i kí wọn sì lè kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ kí wọn sì rọra tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí.
while thei heren, and while al the puple is gaderid to gidere, as wel to men, as to wymmen, to litle children, and comelyngis that ben with ynne thi yatis; that thei here, and lerne, and drede youre Lord God, and kepe and fille alle the wordis of this lawe;
13 Àwọn ọmọ wọn tí wọn kò mọ òfin yìí, gbọdọ̀ gbọ́ kí wọn sì kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ níwọ̀n ìgbà tí o tí ń gbé ní ilẹ̀ tí ò ń kọjá la Jordani lọ láti ni.”
also that the sones of hem, that now knowen not, moun here, and that thei drede her Lord God in alle daies in whiche thei lyuen in the lond to whiche ye schulen go to gete, whanne Jordan is passid.
14 Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọjọ́ ikú rẹ ti súnmọ́ etílé báyìí. Pe Joṣua kí ẹ sì fi ara yín hàn nínú àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti fi àṣẹ fún un.” Nígbà náà ni Mose àti Joṣua wá, wọ́n sì fi ara wọn hàn níbi àgọ́ àjọ.
And the Lord seide to Moises, Lo! the daies of thi deeth ben nyy; clepe thou Josue, and stonde ye in the tabernacle of witnessyng, that Y comaunde to hym. Therfor Moises and Josue yeden, and stooden in the tabernacle of witnessyng;
15 Nígbà náà ni Olúwa farahàn níbi àgọ́ ní ọ̀wọ́ àwọsánmọ̀, àwọsánmọ̀ náà sì dúró sókè ẹnu-ọ̀nà àgọ́.
and the Lord apperide there in a pilere of cloude, that stood in the entryng of the tabernacle.
16 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ìwọ ń lọ sinmi pẹ̀lú àwọn baba à rẹ, àwọn wọ̀nyí yóò sì ṣe àgbèrè ara wọn sí ọlọ́run àjèjì ilẹ̀ tí wọn ń wọ̀ lọ láìpẹ́. Wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀ wọn yóò sì da májẹ̀mú tí mo bá wọn dá.
And the Lord seide to Moises, Lo! thou schalt slepe with thi fadris, and this puple schal rise, and schal do fornycacioun aftir alien goddis in the lond, to which lond it schal entre, that it dwelle ther ynne; there it schal forsake me, and schal make void the boond of pees, which Y couenauntide with it.
17 Ní ọjọ́ náà ni èmi yóò bínú sí wọn èmi yóò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀; èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò fún wọn, wọn yóò sì parun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àjálù àti ìṣòro yóò wá sórí wọn, àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò béèrè pé, ‘Ǹjẹ́ ìpọ́njú wọ̀nyí kò wá sórí i wa nítorí Ọlọ́run wa kò sí pẹ̀lú u wa?’
And my strong veniaunce schal be wrooth ayens that puple in that dai, and Y schal forsake it, and Y schal hide my face fro it, and it schal be in to deuouryng; alle yuels and turmentyngis schulen fynde it, so that it seie in that dai, Verili for the Lord is not with me, these yuelis han founde me.
18 Èmi yóò sì pa ojú mi mọ́ dájúdájú ní ọjọ́ náà nítorí i gbogbo ìwà búburú wọn ní yíyípadà sí ọlọ́run mìíràn.
Forsothe Y schal hide, and schal hile `my face in that dai, for alle the yuels `whiche it dide, for it suede alien goddis.
19 “Ní báyìí kọ ọ́ kalẹ̀ fúnra à rẹ orin yìí kí o sì kọ ọ́ sí Israẹli kí o sì jẹ́ kí wọn kọ ọ́ kí ó lè jẹ́ ẹ̀rí ì mi sí wọn.
Now therfor write ye to you this song, and `teche ye the sones of Israel, that thei holde it in mynde, and synge bi mouth; and that this song be to me for a witnessyng among the sones of Israel.
20 Nígbà tí mo ti mú wọn wá sí ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, ilẹ̀ tí mo ti ṣe ìlérí ní ìbúra fún àwọn baba ńlá wọn, àti nígbà tí wọ́n bá jẹ, tí ó sì tẹ́ wọn lọ́rùn, tí wọ́n sì gbilẹ̀, wọn yóò yí padà sí ọlọ́run mìíràn wọn yóò sì sìn wọ́n, wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀, wọn yóò sì da májẹ̀mú mi.
For Y schal lede hym in to the lond, for which Y swoor to hise fadris, flowynge with mylk and hony; and whanne thei han ete, and ben fillid, and ben maad fat, thei schulen turne to alien goddis, and thei schulen serue hem; and thei schulen bacbite me, and schulen make voide my couenaunt.
21 Àti nígbà tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpọ́njú àti ìṣòro bá wá sórí i wọn, orin yìí yóò jẹ́ ẹ̀rí sí wọn, nítorí kò ní di ìgbàgbé fún àwọn ọmọ wọn. Mo mọ̀ ohun tí wọ́n ní inú dídùn sí láti ṣe, pàápàá kí èmi tó mú wọn wá sí ilẹ̀ tí mo ṣe ìlérí fún wọn lórí ìbúra.”
Aftir that many yuels and turmentyngis han founde hym, this song schal answere hym for witnessing, which song no foryetyng schal do awey fro the mouth of thi seed. For Y knowe the thouytis therof to day, what thingis it schal do, bifore that Y bringe it in to the lond which Y bihiyte to it.
22 Nígbà náà ni Mose kọ orin yìí kalẹ̀ ní ọjọ́ náà ó sì kọ ọ́ sí Israẹli.
Therfor Moises wroot the song, and tauyte the sones of Israel.
23 Olúwa sì fún Joṣua ọmọ Nuni ní àṣẹ yìí: “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí ìwọ yóò mú Israẹli wá sí ilẹ̀ tí mo ṣèlérí fún wọn lórí ìbúra, èmi fúnra à mi yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.”
And the Lord comaundide to Josue, the sone of Nun, and seide, Be thou coumfortid, and be thou strong; for thou schalt lede the sones of Israel in to the lond which Y bihiyte, and Y schal be with thee.
24 Lẹ́yìn ìgbà tí Mose ti parí i kíkọ ọ̀rọ̀ òfin yìí sínú ìwé láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin,
Therfor aftir that Moises wroot the wordis of this lawe in a book, and fillide,
25 ó sì fi àṣẹ yìí fún àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa:
he comaundide to Leuytis that baren the ark of boond of pees of the Lord,
26 “Gba ìwé òfin yìí kí o sì fi sí ẹ̀gbẹ́ àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Níbẹ̀ ni yóò wà bí ẹ̀rí sí ọ.
and seide, Take ye this book, and putte ye it in the side of the arke of boond of pees of youre Lord God, that it be there ayens thee in to witnessyng.
27 Nítorí mo mọ irú ọlọ̀tẹ̀ àti ọlọ́rùn líle tí ẹ jẹ́. Bí o bá ṣe ọlọ̀tẹ̀ sí Olúwa nígbà tí mo pàpà wà láyé pẹ̀lú yín, báwo ní ẹ ó ti ṣe ọlọ̀tẹ̀ tó nígbà tí mo bá kú tán!
For Y knowe thi stryuyng, and thin hardest nol; yit while Y lyuede and entride with you, ye diden euere stryuyngli ayens the Lord; hou myche more whanne Y schal be deed.
28 Ẹ péjọpọ̀ síwájú mi gbogbo àgbà ẹ̀yà yín àti àwọn aláṣẹ yín, kí èmi lè sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí etí ìgbọ́ ọ́ wọn.
Gadere ye to me all the grettere men in birthe, and techeris, bi youre lynagis, and Y schal speke to hem, herynge these wordis, and Y schal clepe ayens hem heuene and erthe.
29 Nítorí tí mo mọ̀ pé lẹ́yìn ikú mi, ó dájú pé ìwọ yóò padà di ìbàjẹ́ pátápátá, ẹ ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ní ọjọ́ tó ń bọ̀, ìpọ́njú yóò sọ̀kalẹ̀ sórí i yín nítorí ẹ̀yin yóò ṣe búburú níwájú Olúwa ẹ ó sì mú u bínú nípa ohun tí ọwọ́ yín ti ṣe.”
For Y knowe, that aftir my deeth ye schulen do wickidli, and schulen bowe awei soone fro the weie which Y comaundide to you; and yuels schulen come to you in the laste tyme, whanne ye `han do yuel in the siyt of the Lord, that ye terre hym to ire bi the werkis of youre hondis.
30 Mose sì ka ọ̀rọ̀ inú orin yìí láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin sí etí ìgbọ́ ọ gbogbo ìjọ Israẹli:
Therfor while al the cumpeny of the sones of Israel herde, Moises spak the wordis of this song, and fillide `til to the ende.

< Deuteronomy 31 >