< Deuteronomy 30 >

1 Nígbà tí gbogbo ìbùkún àti ègún wọ̀nyí tí mo ti gbé kalẹ̀ síwájú u yín bá wá sórí i yín àti tí o bá mú wọn sí àyà rẹ níbikíbi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá tú ọ ká sí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
We shundaq boliduki, bu barliq ishlar, yeni men séning aldingda qoyghan bu beriket bilen lenet béshinggha chüshkinide, Perwerdigar Xudaying séni heydiwetken ellerning arisida turup bularni ésingge élip köngül bölüp,
2 àti nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ bá yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì gbọ́rọ̀ sí pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un yín lónìí.
özüng we baliliring Perwerdigar Xudayingning yénigha yénip Uning awazigha qulaq sélip, men bügün sanga emr qilghan barliq ishlargha pütün qelbing we pütün jéning bilen itaet qilsang,
3 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ohun ìní rẹ bọ̀ sípò yóò sì ṣàánú fún ọ, yóò sì tún ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè níbi tí ó ti fọ́n yín ká sí.
shu chaghda Perwerdigar Xudaying séni sürgünlüktin qayturup, sanga ichini aghritip, Perwerdigar Xudaying Özi heydiwetken ellerdin yighip kélidu.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti lé ẹni rẹ kan sí ilẹ̀ tí ó jìnnà jù lábẹ́ ọ̀run, láti ibẹ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò ṣà yín jọ yóò sì tún mú u yín padà.
Gerche aranglardin hetta asmanlarning chétigichimu heydilip ketkenler bolsimu, Perwerdigar Xudaying séni shu yerdin yighip jem qilip kélidu.
5 Yóò mú ọ wá sí ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn baba yín, ìwọ yóò sì mú ìní níbẹ̀. Olúwa yóò mú ọ wà ní àlàáfíà kíkún, yóò mú ọ pọ̀ sí i ju àwọn baba yín lọ.
Perwerdigar Xudaying séni ata-bowiliringning teweliki bolghan zémin’gha keltüridu we sen uni igileysen; U sanga yaxshiliq qilip ata-bowiliringning sanidin ziyade köp qilidu;
6 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò kọ ọkàn rẹ ní ilà àti ọkàn àwọn ọmọ yín, nítorí kí o lè fẹ́ ẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, àti ayé rẹ.
Perwerdigar Xudayingni pütün qelbing, pütün jéning bilen söyüshke Perwerdigar Xudaying qelbingni we nesilliringning qelbini xetne qilidu; shuning bilen siler hayat yashaysiler.
7 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú gbogbo ègún yín wá sórí àwọn ọ̀tá à rẹ tí wọ́n kórìíra àti tí wọ́n ṣe inúnibíni rẹ.
Shundaqla Perwerdigar Xudayinglar bu hemme lenetlerni düshmenliringlarning üstige, silerge nepretlinidighanlarning üstige, silerge ziyankeshlik qilghanlarning üstige chüshüridu.
8 Ìwọ yóò tún gbọ́rọ̀ sí Olúwa àti tẹ̀lé gbogbo àṣẹ rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí.
Siler bolsanglar yénip kélip Perwerdigar Xudayinglarning awazigha qulaq sélip, men bügün silerge tapilighan hemme emrlirige emel qilisiler.
9 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ọ ṣe rere nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ, àti nínú gbogbo ọmọ inú rẹ, agbo ẹran ọ̀sìn rẹ àti èso ilẹ̀ rẹ. Olúwa yóò tún mú inú dídùn sínú rẹ yóò sì mú ọ ṣe déédé, gẹ́gẹ́ bí ó ti fi inú dídùn sínú àwọn baba rẹ.
Shundaq qilsanglar, Perwerdigar Xudayinglar qolliringlarning hemme ishida, bedininglarning méwisini, charpay malliringlarning méwisini we yéringning méwisinimu awutup silerni zor yashnitidu. Chünki Perwerdigar silerning ata-bowiliringlargha yaxshiliq qilishtin söyün’gendek, silerge yaxshiliq qilishtin söyünidu.
10 Bí o bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́ àti àṣẹ tí a kọ sínú ìwé òfin yìí kí o sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.
Siler Perwerdigar Xudayinglarning awazigha qulaq sélip, bu qanun kitabida pütülgen emrler bilen belgilimilerni tutup, pütün qelbinglar, pütün jéninglar bilen Perwerdigar Xudayinglarning teripige burulsanglarla, shundaq bolidu.
11 Nítorí àṣẹ yìí tí mo pa fún ọ lónìí, kò ṣòro jù fún ọ, bẹ́ẹ̀ ni kò kọjá agbára rẹ.
Chünki men bügün sanga tapilighan bu emr sen üchün karamet ish emes yaki sendin yiraqmu emes.
12 Kò sí ní ọ̀run, tí ìwọ kò bá fi wí pé, “Ta ni yóò gòkè lọ sí ọ̀run fún wa, tí yóò sì mú wa fún wa, kí àwa lè gbọ́, kí a sì le ṣe é?”
Bu emr asmanning üstide emes, séning: «Bizning uninggha emel qilmiqimiz üchün kim asman’gha chiqip uni élip chüshüp bizge anglitidu?» déyishingning hajiti bolmaydu.
13 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ìhà kejì Òkun, tí ìwọ ìbá fi wí pé, “Ta ni yóò rékọjá òkun lọ fún wa, tí yóò sì mú un wá fún wa, kí àwa lè gbọ́ ọ, kí a si le ṣe é?”
We shuningdek bu emr déngizning u teripidimu emestur, séning: «Bizning uninggha emel qilmiqimiz üchün kim déngizdin ötüp, uni élip kélip bizge anglitidu» déyishingning hajiti bolmaydu.
14 Kì í ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ náà súnmọ́ tòsí rẹ, ó wà ní ẹnu rẹ àti ní ọkàn rẹ kí ìwọ lè máa ṣe é.
Chünki bu söz bolsa uninggha emel qilmiqing üchün sanga bek yéqin, yeni aghzingda we könglüngde bardur.
15 Wò ó mo gbé kalẹ̀ síwájú u yín lónìí, ìyè àti àlàáfíà, ikú àti ìparun.
Mana, men bügün aldinglarda hayat bilen yaxshiliq, ölüm bilen yamanliqni qoydum;
16 Ní èyí tí mo pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, láti máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ àti láti máa pa àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè yè, kí ó sì máa bí sí i, kí Olúwa Ọlọ́run lè bù si fún ọ ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ìwọ ń lọ láti gbà á.
chünki özüm sanga höküm bérip: — Siler Perwerdigar Xudayinglarni söyüp, Uning yollirida méngip, emrliri, belgilimiliri hem hökümlirige emel qilinglar, dep bügün silerge tapilidim; shundaq qilsanglar siler yashap awup, uni igileshke kiridighan zémin’gha barghininglarda Perwerdigar Xudayinglar silerni beriketleydu.
17 Ṣùgbọ́n tí ọkàn an yín bá yí padà tí ìwọ kò sì ṣe ìgbọ́ràn, àti bí o bá fà, lọ láti foríbalẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn àti sìn wọ́n,
Lékin eger könglüngni tetür qilip, qulaq salmay azdurulup, bashqa ilahlargha bash urup choqun’ghili tursang,
18 èmi ń sọ fún un yín lónìí yìí pé ìwọ yóò parun láìsí àní àní. O kò ní í gbé pẹ́ ní ilẹ̀ tí ìwọ ń kọjá Jordani láti gbà àti láti ní.
men shuni bügün silerge agahlandurup éytip qoyayki, siler halak bolmay qalmaysiler; siler uni igileshke Iordan deryasidin ötüp baridighan zémin’gha kirgininglarda uzun ömür körelmeysiler.
19 Èmi pe ọ̀run àti ilẹ̀ láti jẹ́rìí tì yín ní òní pé, èmi fi ìyè àti ikú, ìbùkún àti ègún síwájú rẹ: nítorí náà yan ìyè, kí ìwọ kí ó lè yè, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ,
Men bügün hayat bilen ölümni, beriket bilen lenetni aldingda qoyghinimgha asman bilen zéminni üstüngge guwah bolushqa chaqirimen; emdi özüng we nesling yashay désenglar, hayatni talliwal;
20 kí ìwọ kí ó le máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, fetísílẹ̀ sí ohùn un rẹ̀, kí o sì dúró ṣinṣin nínú rẹ̀. Nítorí Olúwa ni ìyè rẹ, yóò sì fún ọ ní ọdún púpọ̀ ní ilẹ̀ tí ó ti búra láti fi fún àwọn baba rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
Perwerdigar Xudayingni söyüp, Uning awazigha qulaq sélip, Uninggha baghlan’ghin; chünki U Özi séning hayating we ömrüngning uzunluqidur; chünki shundaq qilsang Perwerdigar ata-bowiliring bolghan Ibrahim, Ishaq we Yaqupqa: «Men silerge uni bérimen» dep qesem qilip wede qilghan zéminda turisen».

< Deuteronomy 30 >