< Deuteronomy 30 >

1 Nígbà tí gbogbo ìbùkún àti ègún wọ̀nyí tí mo ti gbé kalẹ̀ síwájú u yín bá wá sórí i yín àti tí o bá mú wọn sí àyà rẹ níbikíbi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá tú ọ ká sí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
Om du nu, när allt detta kommer över dig -- välsignelsen och förbannelsen som jag har förelagt dig -- om du lägger detta på hjärtat bland alla de folk till vilka HERREN, din Gud, då har drivit dig bort,
2 àti nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ bá yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì gbọ́rọ̀ sí pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un yín lónìí.
och du så vänder åter till HERREN, din Gud, och hör hans röst, du med dina barn, av allt ditt hjärta och av all din själ, i alla stycken såsom jag i dag bjuder dig,
3 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ohun ìní rẹ bọ̀ sípò yóò sì ṣàánú fún ọ, yóò sì tún ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè níbi tí ó ti fọ́n yín ká sí.
då skall HERREN, din Gud, åter upprätta dig och förbarma sig över dig; HERREN, din Gud, skall då åter församla dig från alla folk bland vilka han har förstrött dig.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti lé ẹni rẹ kan sí ilẹ̀ tí ó jìnnà jù lábẹ́ ọ̀run, láti ibẹ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò ṣà yín jọ yóò sì tún mú u yín padà.
Om ock dina fördrivna vore vid himmelens ända, skulle HERREN, din Gud, församla dig därifrån och hämta dig därifrån.
5 Yóò mú ọ wá sí ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn baba yín, ìwọ yóò sì mú ìní níbẹ̀. Olúwa yóò mú ọ wà ní àlàáfíà kíkún, yóò mú ọ pọ̀ sí i ju àwọn baba yín lọ.
Och HERREN, din Gud, skall låta dig komma in i det land som dina fäder hava haft till besittning; och du skall taga det i besittning, och han skall göra dig gott och skall föröka dig mer än han har gjort med dina fäder.
6 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò kọ ọkàn rẹ ní ilà àti ọkàn àwọn ọmọ yín, nítorí kí o lè fẹ́ ẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, àti ayé rẹ.
Och HERREN, din Gud. skall omskära ditt hjärta och dina efterkommandes hjärtan, så att du skall älska HERREN, din Gud, av allt ditt hjärta och av all din själ, för att du må leva.
7 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú gbogbo ègún yín wá sórí àwọn ọ̀tá à rẹ tí wọ́n kórìíra àti tí wọ́n ṣe inúnibíni rẹ.
Och HERREN, din Gud, skall lägga alla dessa förbannelser på dina fiender och på dem som hata och förfölja dig.
8 Ìwọ yóò tún gbọ́rọ̀ sí Olúwa àti tẹ̀lé gbogbo àṣẹ rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí.
Och du skall åter höra HERRENS röst och göra efter alla hans bud, som jag i dag giver dig.
9 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ọ ṣe rere nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ, àti nínú gbogbo ọmọ inú rẹ, agbo ẹran ọ̀sìn rẹ àti èso ilẹ̀ rẹ. Olúwa yóò tún mú inú dídùn sínú rẹ yóò sì mú ọ ṣe déédé, gẹ́gẹ́ bí ó ti fi inú dídùn sínú àwọn baba rẹ.
Och HERREN, din Gud, skall giva dig överflöd och lycka i alla dina händers verk, i ditt livs frukt och i din boskaps frukt och i din marks frukt. Ty såsom HERREN fröjdade sig över dina fäder, skall han då åter fröjda sig över dig och göra dig gott,
10 Bí o bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́ àti àṣẹ tí a kọ sínú ìwé òfin yìí kí o sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.
när du hör HERRENS, din Guds, röst, så att du håller hans bud och stadgar, det som är skrivet i denna lagbok, och när du vänder åter till HERREN, din Gud, av allt ditt hjärta och av all din själ.
11 Nítorí àṣẹ yìí tí mo pa fún ọ lónìí, kò ṣòro jù fún ọ, bẹ́ẹ̀ ni kò kọjá agbára rẹ.
Ty det bud som jag i dag giver dig är dig icke för svårt och är icke långt borta.
12 Kò sí ní ọ̀run, tí ìwọ kò bá fi wí pé, “Ta ni yóò gòkè lọ sí ọ̀run fún wa, tí yóò sì mú wa fún wa, kí àwa lè gbọ́, kí a sì le ṣe é?”
Det är icke i himmelen, så att du skulle behöva säga: "Vem vill för oss fara upp till himmelen och hämta det åt oss och låta oss höra det, så att vi kunna göra därefter?"
13 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ìhà kejì Òkun, tí ìwọ ìbá fi wí pé, “Ta ni yóò rékọjá òkun lọ fún wa, tí yóò sì mú un wá fún wa, kí àwa lè gbọ́ ọ, kí a si le ṣe é?”
Det är icke heller på andra sidan havet, så att du skulle behöva säga: "Vem vill för oss fara över till andra sidan havet och hämta det åt oss och låta oss höra det, så att vi kunna göra därefter?"
14 Kì í ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ náà súnmọ́ tòsí rẹ, ó wà ní ẹnu rẹ àti ní ọkàn rẹ kí ìwọ lè máa ṣe é.
Nej, ordet är dig mycket nära, i din mun och i ditt hjärta, så att du kan göra därefter.
15 Wò ó mo gbé kalẹ̀ síwájú u yín lónìí, ìyè àti àlàáfíà, ikú àti ìparun.
Se, jag förelägger dig i dag livet och vad gott är, döden och vad ont är,
16 Ní èyí tí mo pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, láti máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ àti láti máa pa àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè yè, kí ó sì máa bí sí i, kí Olúwa Ọlọ́run lè bù si fún ọ ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ìwọ ń lọ láti gbà á.
då jag nu i dag bjuder dig att älska HERREN, din Gud, att vandra på hans vägar och hålla hans bud och stadgar och rätter, för att du må leva och föröka dig, och för att HERREN, din Gud, må välsigna dig i det land dit du nu kommer, för att taga det i besittning.
17 Ṣùgbọ́n tí ọkàn an yín bá yí padà tí ìwọ kò sì ṣe ìgbọ́ràn, àti bí o bá fà, lọ láti foríbalẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn àti sìn wọ́n,
Men om ditt hjärta vänder sig bort och du icke vill höra, om du låter förföra dig, så att du tillbeder andra gudar och tjänar dem,
18 èmi ń sọ fún un yín lónìí yìí pé ìwọ yóò parun láìsí àní àní. O kò ní í gbé pẹ́ ní ilẹ̀ tí ìwọ ń kọjá Jordani láti gbà àti láti ní.
så förkunnar jag eder i dag att I förvisso skolen förgås. I skolen då icke länge leva i det land dit du nu drager över Jordan, för att komma och taga det i besittning.
19 Èmi pe ọ̀run àti ilẹ̀ láti jẹ́rìí tì yín ní òní pé, èmi fi ìyè àti ikú, ìbùkún àti ègún síwájú rẹ: nítorí náà yan ìyè, kí ìwọ kí ó lè yè, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ,
Jag tager i dag himmel och jord till vittnen mot eder, att jag har förelagt dig liv och död, välsignelse och förbannelse, Så må du då välja livet, för att du och dina efterkommande mån leva,
20 kí ìwọ kí ó le máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, fetísílẹ̀ sí ohùn un rẹ̀, kí o sì dúró ṣinṣin nínú rẹ̀. Nítorí Olúwa ni ìyè rẹ, yóò sì fún ọ ní ọdún púpọ̀ ní ilẹ̀ tí ó ti búra láti fi fún àwọn baba rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
i det att du älskar HERREN, din Gud, och hör hans röst och håller dig till honom; ty detta betyder för dig liv och lång levnad, så att du får bo i det land som HERREN med ed har lovat dina fäder, Abraham, Isak och Jakob, att giva dem.

< Deuteronomy 30 >