< Deuteronomy 30 >
1 Nígbà tí gbogbo ìbùkún àti ègún wọ̀nyí tí mo ti gbé kalẹ̀ síwájú u yín bá wá sórí i yín àti tí o bá mú wọn sí àyà rẹ níbikíbi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá tú ọ ká sí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
Acontecerá, quando todas estas coisas vierem sobre você, a bênção e a maldição, que coloquei diante de você, e você as chamará à mente entre todas as nações para onde Yahweh seu Deus o conduziu,
2 àti nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ bá yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì gbọ́rọ̀ sí pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un yín lónìí.
e retornará a Yahweh seu Deus e obedecerá a sua voz de acordo com tudo o que eu lhe ordeno hoje, você e seus filhos, com todo seu coração e com toda sua alma,
3 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ohun ìní rẹ bọ̀ sípò yóò sì ṣàánú fún ọ, yóò sì tún ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè níbi tí ó ti fọ́n yín ká sí.
que então Javé seu Deus os libertará do cativeiro, terá compaixão de vocês, e retornará e os reunirá de todos os povos onde Javé seu Deus os espalhou.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti lé ẹni rẹ kan sí ilẹ̀ tí ó jìnnà jù lábẹ́ ọ̀run, láti ibẹ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò ṣà yín jọ yóò sì tún mú u yín padà.
Se seus párias estão nos confins do céu, de lá Yahweh seu Deus os reunirá, e de lá ele os trará de volta.
5 Yóò mú ọ wá sí ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn baba yín, ìwọ yóò sì mú ìní níbẹ̀. Olúwa yóò mú ọ wà ní àlàáfíà kíkún, yóò mú ọ pọ̀ sí i ju àwọn baba yín lọ.
Javé, vosso Deus, vos trará para a terra que vossos pais possuíam, e vós a possuireis. Ele fará bem a vocês e aumentará o número de vocês mais do que o de seus pais.
6 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò kọ ọkàn rẹ ní ilà àti ọkàn àwọn ọmọ yín, nítorí kí o lè fẹ́ ẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, àti ayé rẹ.
Javé seu Deus circuncidará seu coração e o coração de sua prole, para amar a Javé seu Deus com todo seu coração e com toda sua alma, para que você possa viver.
7 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú gbogbo ègún yín wá sórí àwọn ọ̀tá à rẹ tí wọ́n kórìíra àti tí wọ́n ṣe inúnibíni rẹ.
Yahweh teu Deus colocará todas estas maldições sobre teus inimigos e sobre aqueles que te odeiam, que te perseguiram.
8 Ìwọ yóò tún gbọ́rọ̀ sí Olúwa àti tẹ̀lé gbogbo àṣẹ rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí.
Você voltará e obedecerá à voz de Javé, e cumprirá todos os seus mandamentos que eu lhe ordeno hoje.
9 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ọ ṣe rere nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ, àti nínú gbogbo ọmọ inú rẹ, agbo ẹran ọ̀sìn rẹ àti èso ilẹ̀ rẹ. Olúwa yóò tún mú inú dídùn sínú rẹ yóò sì mú ọ ṣe déédé, gẹ́gẹ́ bí ó ti fi inú dídùn sínú àwọn baba rẹ.
Javé, vosso Deus, vos fará prosperar em todo o trabalho de vossa mão, no fruto de vosso corpo, no fruto de vosso gado e no fruto de vossa terra, para sempre; pois Javé voltará a alegrar-se por vós para sempre, assim como alegrar-se-á por vossos pais,
10 Bí o bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́ àti àṣẹ tí a kọ sínú ìwé òfin yìí kí o sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.
se obedecerdes à voz de Javé, vosso Deus, para guardar seus mandamentos e seus estatutos que estão escritos neste livro da lei, se vos voltardes para Javé, vosso Deus, de todo o vosso coração e de toda a vossa alma.
11 Nítorí àṣẹ yìí tí mo pa fún ọ lónìí, kò ṣòro jù fún ọ, bẹ́ẹ̀ ni kò kọjá agbára rẹ.
Pois este mandamento que eu lhe ordeno hoje não é muito difícil para você ou muito distante.
12 Kò sí ní ọ̀run, tí ìwọ kò bá fi wí pé, “Ta ni yóò gòkè lọ sí ọ̀run fún wa, tí yóò sì mú wa fún wa, kí àwa lè gbọ́, kí a sì le ṣe é?”
Não é no céu que você deve dizer: “Quem subirá por nós ao céu, trazê-lo até nós e proclamá-lo, para que o façamos”?
13 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ìhà kejì Òkun, tí ìwọ ìbá fi wí pé, “Ta ni yóò rékọjá òkun lọ fún wa, tí yóò sì mú un wá fún wa, kí àwa lè gbọ́ ọ, kí a si le ṣe é?”
Também não é além do mar, que você deva dizer: “Quem irá por nós, para o mar, trazê-lo até nós e proclamá-lo, para que o façamos”?
14 Kì í ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ náà súnmọ́ tòsí rẹ, ó wà ní ẹnu rẹ àti ní ọkàn rẹ kí ìwọ lè máa ṣe é.
Mas a palavra está muito perto de você, em sua boca e em seu coração, para que você possa fazê-lo.
15 Wò ó mo gbé kalẹ̀ síwájú u yín lónìí, ìyè àti àlàáfíà, ikú àti ìparun.
Eis que hoje vos propus a vida e a prosperidade, a morte e o mal.
16 Ní èyí tí mo pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, láti máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ àti láti máa pa àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè yè, kí ó sì máa bí sí i, kí Olúwa Ọlọ́run lè bù si fún ọ ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ìwọ ń lọ láti gbà á.
Pois eu vos ordeno hoje que ameis a Javé vosso Deus, que andeis nos seus caminhos e guardeis seus mandamentos, seus estatutos e suas ordenanças, para que vivais e vos multipliqueis, e para que Javé vosso Deus vos abençoe na terra onde entrardes para possuí-la.
17 Ṣùgbọ́n tí ọkàn an yín bá yí padà tí ìwọ kò sì ṣe ìgbọ́ràn, àti bí o bá fà, lọ láti foríbalẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn àti sìn wọ́n,
Mas se seu coração se desviar e você não ouvir, mas for atraído e adorar outros deuses, e os servir,
18 èmi ń sọ fún un yín lónìí yìí pé ìwọ yóò parun láìsí àní àní. O kò ní í gbé pẹ́ ní ilẹ̀ tí ìwọ ń kọjá Jordani láti gbà àti láti ní.
declaro-lhe hoje que você certamente perecerá. Não prolongareis vossos dias na terra onde passareis o Jordão para entrardes para possuí-la.
19 Èmi pe ọ̀run àti ilẹ̀ láti jẹ́rìí tì yín ní òní pé, èmi fi ìyè àti ikú, ìbùkún àti ègún síwájú rẹ: nítorí náà yan ìyè, kí ìwọ kí ó lè yè, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ,
Chamo hoje o céu e a terra para testemunhar contra vocês que coloquei diante de vocês a vida e a morte, a bênção e a maldição. Portanto, escolhe a vida, para que vivas, tu e teus descendentes,
20 kí ìwọ kí ó le máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, fetísílẹ̀ sí ohùn un rẹ̀, kí o sì dúró ṣinṣin nínú rẹ̀. Nítorí Olúwa ni ìyè rẹ, yóò sì fún ọ ní ọdún púpọ̀ ní ilẹ̀ tí ó ti búra láti fi fún àwọn baba rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
para amar a Javé teu Deus, para obedecer à sua voz e para se apegar a ele; pois ele é tua vida, e a duração de teus dias, para que habites na terra que Javé jurou a teus pais, a Abraão, a Isaac, e a Jacó, dar-lhes.