< Deuteronomy 30 >

1 Nígbà tí gbogbo ìbùkún àti ègún wọ̀nyí tí mo ti gbé kalẹ̀ síwájú u yín bá wá sórí i yín àti tí o bá mú wọn sí àyà rẹ níbikíbi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá tú ọ ká sí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
هنگامی که تمام این برکت‌ها و لعنتها اتفاق بیفتد و شما در میان قومهای بیگانه‌ای که خداوند، خدایتان شما را به آنجا رانده است سخنان مرا به یاد بیاورید
2 àti nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ bá yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì gbọ́rọ̀ sí pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un yín lónìí.
و به سوی خداوند، خدایتان بازگشت نمایید و شما و فرزندانتان با تمامی دل فرامینی را که امروز به شما دادم اطاعت کنید،
3 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ohun ìní rẹ bọ̀ sípò yóò sì ṣàánú fún ọ, yóò sì tún ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè níbi tí ó ti fọ́n yín ká sí.
آنگاه خداوند، خدایتان شما را از اسارت نجات خواهد داد. او بر شما ترحم خواهد کرد و شما را از بین تمام قومهایی که شما را در آنها پراکنده کرده است جمع خواهد نمود.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti lé ẹni rẹ kan sí ilẹ̀ tí ó jìnnà jù lábẹ́ ọ̀run, láti ibẹ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò ṣà yín jọ yóò sì tún mú u yín padà.
اگر در دورترین نقاط دنیا هم باشید او شما را جمع می‌کند
5 Yóò mú ọ wá sí ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn baba yín, ìwọ yóò sì mú ìní níbẹ̀. Olúwa yóò mú ọ wà ní àlàáfíà kíkún, yóò mú ọ pọ̀ sí i ju àwọn baba yín lọ.
و به سرزمین نیاکانتان باز می‌گرداند تا دوباره مالک آن شوید. او شما را کامیابتر و پرشمارتر از نیاکانتان خواهد ساخت.
6 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò kọ ọkàn rẹ ní ilà àti ọkàn àwọn ọmọ yín, nítorí kí o lè fẹ́ ẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, àti ayé rẹ.
او دلهای شما و فرزندانتان را پاک خواهد کرد تا خداوند، خدایتان را با تمامی دل و جان دوست بدارید و در آن سرزمین زنده بمانید.
7 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú gbogbo ègún yín wá sórí àwọn ọ̀tá à rẹ tí wọ́n kórìíra àti tí wọ́n ṣe inúnibíni rẹ.
یهوه خدایتان همه این لعنت‌ها را متوجه دشمنانتان و کسانی که به شما آزار می‌رسانند خواهد کرد.
8 Ìwọ yóò tún gbọ́rọ̀ sí Olúwa àti tẹ̀lé gbogbo àṣẹ rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí.
پس شما باز از خداوند اطاعت خواهید کرد و همه فرمانهایش را که من امروز به شما می‌دهم نگاه خواهید داشت.
9 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ọ ṣe rere nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ, àti nínú gbogbo ọmọ inú rẹ, agbo ẹran ọ̀sìn rẹ àti èso ilẹ̀ rẹ. Olúwa yóò tún mú inú dídùn sínú rẹ yóò sì mú ọ ṣe déédé, gẹ́gẹ́ bí ó ti fi inú dídùn sínú àwọn baba rẹ.
یهوه خدایتان شما را در تمام کارهایتان برکت خواهد داد و به شما فرزندان بسیار و گله و محصول فراوان عطا خواهد کرد، چون خداوند بار دیگر از شما راضی خواهد شد، همچنانکه از پدران شما راضی بود.
10 Bí o bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́ àti àṣẹ tí a kọ sínú ìwé òfin yìí kí o sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.
اگر به صدای یهوه خدایتان گوش فرا دهید و از فرمانها و فرایض او که در این کتاب شریعت نوشته شده، اطاعت کنید و با تمامی دل و جان به سوی یهوه خدایتان بازگردید، او از شما خشنود خواهد بود.
11 Nítorí àṣẹ yìí tí mo pa fún ọ lónìí, kò ṣòro jù fún ọ, bẹ́ẹ̀ ni kò kọjá agbára rẹ.
اطاعت از این فرمان که من امروز به شما می‌دهم، خارج از توانایی و دور از دسترس شما نیست.
12 Kò sí ní ọ̀run, tí ìwọ kò bá fi wí pé, “Ta ni yóò gòkè lọ sí ọ̀run fún wa, tí yóò sì mú wa fún wa, kí àwa lè gbọ́, kí a sì le ṣe é?”
چون این فرمان در آسمان نیست که بگویید: «چه کسی به آسمان بالا خواهد رفت و آن را پایین خواهد آورد تا آن را بشنویم و اطاعت کنیم؟»
13 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ìhà kejì Òkun, tí ìwọ ìbá fi wí pé, “Ta ni yóò rékọjá òkun lọ fún wa, tí yóò sì mú un wá fún wa, kí àwa lè gbọ́ ọ, kí a si le ṣe é?”
و نه در ماورای دریاهاست که بگویید: «چه کسی می‌تواند به آن سوی دریاها برود و آن را برای ما بیاورد تا آن را بشنویم و اطاعت کنیم؟»
14 Kì í ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ náà súnmọ́ tòsí rẹ, ó wà ní ẹnu rẹ àti ní ọkàn rẹ kí ìwọ lè máa ṣe é.
این کلام به شما بسیار نزدیک است؛ آن در دهان و در دل شماست تا بتوانید آن را به جا آورید.
15 Wò ó mo gbé kalẹ̀ síwájú u yín lónìí, ìyè àti àlàáfíà, ikú àti ìparun.
حال گوش کنید، من امروز مرگ و زندگی، بدی و خوبی را در برابر شما قرار داده‌ام تا یکی را برگزینید.
16 Ní èyí tí mo pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, láti máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ àti láti máa pa àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè yè, kí ó sì máa bí sí i, kí Olúwa Ọlọ́run lè bù si fún ọ ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ìwọ ń lọ láti gbà á.
من امروز به شما دستور داده‌ام که یهوه خدایتان را دوست داشته در راه او گام بردارید و فرمانها و فرایض و قوانین او را نگاه دارید تا زنده مانده، قومی بزرگ بشوید و یهوه خدایتان به شما در سرزمینی که تصرف خواهید کرد، برکت بدهد.
17 Ṣùgbọ́n tí ọkàn an yín bá yí padà tí ìwọ kò sì ṣe ìgbọ́ràn, àti bí o bá fà, lọ láti foríbalẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn àti sìn wọ́n,
ولی اگر گوش ندهید و اطاعت نکنید و به دنبال خدایان دیگر بروید و آنها را بپرستید،
18 èmi ń sọ fún un yín lónìí yìí pé ìwọ yóò parun láìsí àní àní. O kò ní í gbé pẹ́ ní ilẹ̀ tí ìwọ ń kọjá Jordani láti gbà àti láti ní.
در این صورت همین امروز به شما اعلام می‌کنم که بدون شک نابود خواهید شد و در سرزمینی که از رود اردن گذر می‌کنید تا آن را تصرف کنید، عمری طولانی نخواهید داشت.
19 Èmi pe ọ̀run àti ilẹ̀ láti jẹ́rìí tì yín ní òní pé, èmi fi ìyè àti ikú, ìbùkún àti ègún síwájú rẹ: nítorí náà yan ìyè, kí ìwọ kí ó lè yè, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ,
زمین و آسمان را شاهد می‌گیرم که امروز زندگی و مرگ، برکت و لعنت را در برابر شما قرار داده‌ام. زندگی را انتخاب کنید تا شما و فرزندانتان زنده بمانید.
20 kí ìwọ kí ó le máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, fetísílẹ̀ sí ohùn un rẹ̀, kí o sì dúró ṣinṣin nínú rẹ̀. Nítorí Olúwa ni ìyè rẹ, yóò sì fún ọ ní ọdún púpọ̀ ní ilẹ̀ tí ó ti búra láti fi fún àwọn baba rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
خداوند، خدایتان را دوست داشته، از او اطاعت کنید و به او بچسبید، زیرا او زندگی شماست و به شما و فرزندانتان در سرزمینی که با سوگند به پدرانتان ابراهیم و اسحاق و یعقوب وعده داده است، عمری طولانی عطا خواهد فرمود.

< Deuteronomy 30 >