< Deuteronomy 30 >
1 Nígbà tí gbogbo ìbùkún àti ègún wọ̀nyí tí mo ti gbé kalẹ̀ síwájú u yín bá wá sórí i yín àti tí o bá mú wọn sí àyà rẹ níbikíbi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá tú ọ ká sí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
Musa melanjutkan pengajarannya kepada umat Israel, “Pada masa mendatang, kalian semua dan keturunanmu akan mengalami semua berkat TUHAN Allahmu yang sudah saya sampaikan. Ketika kalian menjauh dari TUHAN, kamu sekalian akan mengalami semua kutukan yang sudah saya sampaikan juga. Namun, di negeri bangsa asing ke mana TUHAN mencerai-beraikan kalian nanti, kalian akan teringat kepada semua yang tertulis dalam kitab Taurat ini.
2 àti nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ bá yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì gbọ́rọ̀ sí pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un yín lónìí.
Apabila besok kamu dan keturunanmu berbalik kepada TUHAN dengan segenap hati dan dengan segenap nafas hidupmu mematuhi perintah-Nya yang saya sampaikan hari ini,
3 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ohun ìní rẹ bọ̀ sípò yóò sì ṣàánú fún ọ, yóò sì tún ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè níbi tí ó ti fọ́n yín ká sí.
maka TUHAN Allah akan berbelas kasihan dan membebaskan kalian dari penawanan. Dia juga akan mengumpulkan kalian kembali dari negeri bangsa-bangsa lain itu.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti lé ẹni rẹ kan sí ilẹ̀ tí ó jìnnà jù lábẹ́ ọ̀run, láti ibẹ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò ṣà yín jọ yóò sì tún mú u yín padà.
Sekalipun kalian dibuang ke ujung bumi, Dia tetap akan membawamu kembali.
5 Yóò mú ọ wá sí ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn baba yín, ìwọ yóò sì mú ìní níbẹ̀. Olúwa yóò mú ọ wà ní àlàáfíà kíkún, yóò mú ọ pọ̀ sí i ju àwọn baba yín lọ.
TUHAN Allah akan membawa kalian pulang ke negeri nenek moyang kalian, dan kalian akan kembali menduduki negeri Israel. Dia akan membuat keturunan kalian menjadi lebih makmur dan lebih banyak daripada jumlah nenek moyang kalian.
6 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò kọ ọkàn rẹ ní ilà àti ọkàn àwọn ọmọ yín, nítorí kí o lè fẹ́ ẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, àti ayé rẹ.
TUHAN akan mengubah hatimu dan seluruh keturunanmu sehingga setiap orang sungguh-sungguh mengasihi Dia dengan segenap hati, supaya kalian dapat terus hidup di negeri ini.
7 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú gbogbo ègún yín wá sórí àwọn ọ̀tá à rẹ tí wọ́n kórìíra àti tí wọ́n ṣe inúnibíni rẹ.
Lalu TUHAN akan menimpakan semua kutuk tersebut kepada musuh-musuh yang membenci dan menindas kalian.
8 Ìwọ yóò tún gbọ́rọ̀ sí Olúwa àti tẹ̀lé gbogbo àṣẹ rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí.
Sedangkan kalian akan berbalik kepada TUHAN, menjadi taat kembali, dan melakukan semua perintah TUHAN yang saya sampaikan hari ini.
9 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ọ ṣe rere nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ, àti nínú gbogbo ọmọ inú rẹ, agbo ẹran ọ̀sìn rẹ àti èso ilẹ̀ rẹ. Olúwa yóò tún mú inú dídùn sínú rẹ yóò sì mú ọ ṣe déédé, gẹ́gẹ́ bí ó ti fi inú dídùn sínú àwọn baba rẹ.
Kemudian Dia akan membuat kalian berhasil dalam semua pekerjaanmu. Dia akan memberkatimu dengan banyak anak, banyak ternak, dan hasil panen yang melimpah, karena Dia ingin membuat kalian makmur, sama seperti Dia senang memberkati nenek moyangmu.
10 Bí o bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́ àti àṣẹ tí a kọ sínú ìwé òfin yìí kí o sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.
Tetapi untuk menerima semua berkat itu, kalian harus kembali kepada-Nya dengan segenap hatimu dan sungguh-sungguh menaati semua perintah dan ketetapan-Nya yang tertulis dalam kitab Taurat ini.”
11 Nítorí àṣẹ yìí tí mo pa fún ọ lónìí, kò ṣòro jù fún ọ, bẹ́ẹ̀ ni kò kọjá agbára rẹ.
“Seluruh perintah yang saya sampaikan kepada kalian hari ini tidak terlalu sulit untuk kalian lakukan dan tidak di luar pemahamanmu.
12 Kò sí ní ọ̀run, tí ìwọ kò bá fi wí pé, “Ta ni yóò gòkè lọ sí ọ̀run fún wa, tí yóò sì mú wa fún wa, kí àwa lè gbọ́, kí a sì le ṣe é?”
Perintah-perintah TUHAN itu tidak disimpan di surga sehingga kalian harus bertanya, ‘Siapakah yang bisa naik ke sana untuk mengambilkannya bagi kita, supaya kita bisa mendengar dan melakukannya?’
13 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ìhà kejì Òkun, tí ìwọ ìbá fi wí pé, “Ta ni yóò rékọjá òkun lọ fún wa, tí yóò sì mú un wá fún wa, kí àwa lè gbọ́ ọ, kí a si le ṣe é?”
Perintah-perintah itu juga tidak disimpan di seberang laut sehingga kalian harus bertanya, ‘Siapakah yang bisa menyeberangi laut besar itu untuk mengambilkannya bagi kita, supaya kita bisa mendengar dan melakukannya?’
14 Kì í ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ náà súnmọ́ tòsí rẹ, ó wà ní ẹnu rẹ àti ní ọkàn rẹ kí ìwọ lè máa ṣe é.
Sesungguhnya perintah TUHAN sangat dekat denganmu! Kalian sudah mengetahuinya dan bisa membicarakannya dengan sesamamu. Jadi, sekarang hanya tinggal melakukannya saja.
15 Wò ó mo gbé kalẹ̀ síwájú u yín lónìí, ìyè àti àlàáfíà, ikú àti ìparun.
“Perhatikanlah! Hari ini saya mengajukan dua pilihan kepada kamu sekalian: Hidup dengan sejahtera, atau ditimpa kesialan sampai mati.
16 Ní èyí tí mo pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, láti máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ àti láti máa pa àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè yè, kí ó sì máa bí sí i, kí Olúwa Ọlọ́run lè bù si fún ọ ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ìwọ ń lọ láti gbà á.
Kasihilah TUHAN Allahmu, hiduplah menurut kehendak-Nya, dan taatilah perintah, ketetapan, serta peraturan-Nya. Dengan demikian, bangsa kita akan tetap hidup serta bertambah besar, dan TUHAN Allah akan memberkati kalian di negeri yang sebentar lagi kalian duduki.
17 Ṣùgbọ́n tí ọkàn an yín bá yí padà tí ìwọ kò sì ṣe ìgbọ́ràn, àti bí o bá fà, lọ láti foríbalẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn àti sìn wọ́n,
“Namun, jika hatimu berpaling dari TUHAN dan kamu menolak mendengarkan Dia, malahan terpikat untuk menyembah dewa-dewa,
18 èmi ń sọ fún un yín lónìí yìí pé ìwọ yóò parun láìsí àní àní. O kò ní í gbé pẹ́ ní ilẹ̀ tí ìwọ ń kọjá Jordani láti gbà àti láti ní.
saya memperingatkanmu hari ini: Kamu pasti akan binasa! Kamu tidak akan hidup lama di negeri di seberang sungai Yordan itu.
19 Èmi pe ọ̀run àti ilẹ̀ láti jẹ́rìí tì yín ní òní pé, èmi fi ìyè àti ikú, ìbùkún àti ègún síwájú rẹ: nítorí náà yan ìyè, kí ìwọ kí ó lè yè, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ,
“Jadi, hari ini saya sudah memberi dua pilihan kepada kamu sekalian, yakni hidup dengan berkat TUHAN, atau mengalami kutuk-Nya sampai mati. Biarlah langit dan bumi menjadi saksi atas pilihanmu! Demi kebaikanmu sendiri dan keturunanmu, pilihlah hidup!
20 kí ìwọ kí ó le máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, fetísílẹ̀ sí ohùn un rẹ̀, kí o sì dúró ṣinṣin nínú rẹ̀. Nítorí Olúwa ni ìyè rẹ, yóò sì fún ọ ní ọdún púpọ̀ ní ilẹ̀ tí ó ti búra láti fi fún àwọn baba rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
Kasihilah TUHAN Allah kita, taatilah Dia, dan berpeganglah erat kepada-Nya selalu. Seharusnya begitulah cara hidupmu! Jika kamu mengasihi Dia dan taat kepada-Nya, kamu dan keturunanmu akan tinggal selamanya di negeri yang TUHAN janjikan untuk diberikan kepada nenek moyang kita Abraham, Isak, dan Yakub.”