< Deuteronomy 30 >
1 Nígbà tí gbogbo ìbùkún àti ègún wọ̀nyí tí mo ti gbé kalẹ̀ síwájú u yín bá wá sórí i yín àti tí o bá mú wọn sí àyà rẹ níbikíbi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá tú ọ ká sí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
Inton umay kadakayo amin dagitoy a banbanag, dagiti bendision ken dagiti lunod nga inkabilko iti sangoananyo, ket no lagipenyo dagitoy kadagiti amin a dadduma a nasion a nangiturongan ni Yahweh a Diosyo kadakayo,
2 àti nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ bá yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì gbọ́rọ̀ sí pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un yín lónìí.
ken inton agsublikayo kenni Yahweh a Diosyo ken agtulnogkayo iti timekna, surotenyo amin dagiti ibilbilinko kadakayo ita nga aldaw— dakayo ken dagiti annakyo — iti isu-amin a pusoyo ken iti isu-amin a kararuayo,
3 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ohun ìní rẹ bọ̀ sípò yóò sì ṣàánú fún ọ, yóò sì tún ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè níbi tí ó ti fọ́n yín ká sí.
ket ibabawinto ni Yahweh ti pannakaibaludyo ken maasi isuna kadakayo; agsublinto isuna ken ummongennakayonto manipud kadagiti amin a tattao a nangiwarasan ni Yahweh a Diosyo kadakayo.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti lé ẹni rẹ kan sí ilẹ̀ tí ó jìnnà jù lábẹ́ ọ̀run, láti ibẹ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò ṣà yín jọ yóò sì tún mú u yín padà.
No aniaman kadagiti napapanaw a tattaoyo ket addada iti kaadayoan a luglugar iti langit, ummongennakayonto ni Yahweh a Diosyo manipud sadiay, ken iyegnakayonto manipud sadiay.
5 Yóò mú ọ wá sí ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn baba yín, ìwọ yóò sì mú ìní níbẹ̀. Olúwa yóò mú ọ wà ní àlàáfíà kíkún, yóò mú ọ pọ̀ sí i ju àwọn baba yín lọ.
Ipannakayonto ni Yahweh a Diosyo iti daga a natagikua dagiti kapuonanyo, ket tagikuaenyonto manen daytoy; naimbagto isuna kadakayo ken ad-adda a paadoennakayonto ngem iti inaramidna kadagiti kapuonanyo.
6 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò kọ ọkàn rẹ ní ilà àti ọkàn àwọn ọmọ yín, nítorí kí o lè fẹ́ ẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, àti ayé rẹ.
Kugitento ni Yahweh a Diosyo ta pusoyo ken ti puso dagiti kaputotanyo, tapno ayatenyo ni Yahweh a Diosyo iti isu-amin a pusoyo ken iti isu-amin a kararuayo, tapno agbiagkayo.
7 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú gbogbo ègún yín wá sórí àwọn ọ̀tá à rẹ tí wọ́n kórìíra àti tí wọ́n ṣe inúnibíni rẹ.
Ikabilto ni Yahweh a Diosyo amin dagitoy a lunod kadagiti kabusoryo ken kadagiti manggurgura kadakayo, ken dagiti nangidaddadanes kadakayo.
8 Ìwọ yóò tún gbọ́rọ̀ sí Olúwa àti tẹ̀lé gbogbo àṣẹ rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí.
Agsubli ken agtulnogkayonto iti timek ni Yahweh, ken aramidenyonto amin a bilbilinna nga ibilbilinko kadakayo ita nga aldaw.
9 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ọ ṣe rere nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ, àti nínú gbogbo ọmọ inú rẹ, agbo ẹran ọ̀sìn rẹ àti èso ilẹ̀ rẹ. Olúwa yóò tún mú inú dídùn sínú rẹ yóò sì mú ọ ṣe déédé, gẹ́gẹ́ bí ó ti fi inú dídùn sínú àwọn baba rẹ.
Parang-ayennakayonto ni Yahweh a Diosyo iti amin nga aramidyo, iti bunga ti bagiyo, iti bunga dagiti ay-ayupyo, ken iti bunga ti dagayo, para iti panagrang-ay; ta agrag-onto manen ni Yahweh kadakayo gapu iti panagrang-ay, kas ti panagrag-ona kadagiti ammayo.
10 Bí o bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́ àti àṣẹ tí a kọ sínú ìwé òfin yìí kí o sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.
Aramidennanto daytoy no agtulnogkayo iti timek ni Yahweh a Diosyo, tapno salimetmetanyo dagiti bilbilin ken alagadenna a naisurat iti daytoy a libro ti linteg, no agsublikayo kenni Yahweh a Diosyo iti isu-amin a pusoyo ken iti isu-amin a kararuayo.
11 Nítorí àṣẹ yìí tí mo pa fún ọ lónìí, kò ṣòro jù fún ọ, bẹ́ẹ̀ ni kò kọjá agbára rẹ.
Ta saan unay a narigat kadakayo daytoy a bilin nga ibilbilinko kadakayo ita nga aldaw, wenno saan nga adayo unay daytoy kadakayo a gaw-aten.
12 Kò sí ní ọ̀run, tí ìwọ kò bá fi wí pé, “Ta ni yóò gòkè lọ sí ọ̀run fún wa, tí yóò sì mú wa fún wa, kí àwa lè gbọ́, kí a sì le ṣe é?”
Awan daytoy idiay langit, tapno rumbeng a kunaenyo, 'Siasino ti umuli idiay langit para kadatayo ken mangibaba daytoy kadatayo ken mangipangngeg kadatayo, tapno mabalintayo nga aramiden daytoy?'
13 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ìhà kejì Òkun, tí ìwọ ìbá fi wí pé, “Ta ni yóò rékọjá òkun lọ fún wa, tí yóò sì mú un wá fún wa, kí àwa lè gbọ́ ọ, kí a si le ṣe é?”
Wenno awan daytoy iti ballasiw ti baybay, tapno kasapulan nga ibagayo, 'Siasino ti bumallasiw iti baybay ken mangiyeg daytoy kadatayo ken mangipangngeg kadatayo, tapno mabalintayo nga aramiden daytoy?'
14 Kì í ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ náà súnmọ́ tòsí rẹ, ó wà ní ẹnu rẹ àti ní ọkàn rẹ kí ìwọ lè máa ṣe é.
Ngem asideg unay ti sao kadakayo, iti ngiwatyo, ken iti pusoyo, tapno mabalinyo nga aramiden daytoy.
15 Wò ó mo gbé kalẹ̀ síwájú u yín lónìí, ìyè àti àlàáfíà, ikú àti ìparun.
Kitaem, inkabilko ita nga aldaw iti sangoananyo ti biag ken imbag, patay ken dakes.
16 Ní èyí tí mo pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, láti máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ àti láti máa pa àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè yè, kí ó sì máa bí sí i, kí Olúwa Ọlọ́run lè bù si fún ọ ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ìwọ ń lọ láti gbà á.
No tungpalenyo dagiti bilbilin ni Yahweh a Diosyo, nga ibilbilinko kadakayo ita nga aldaw nga ayatenyo ni Yahweh a Diosyo, a magnakayo kadagiti wagasna, ken salimetmetanyo dagiti bilbilinna, dagiti alagadenna ken dagiti linlintegna, agbiag ken umadukayo, ket bendisionannakayo ni Yahweh a Diosyo iti daga a papananyo a tagikuaen.
17 Ṣùgbọ́n tí ọkàn an yín bá yí padà tí ìwọ kò sì ṣe ìgbọ́ràn, àti bí o bá fà, lọ láti foríbalẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn àti sìn wọ́n,
Ngem no tumallikod ti pusoyo, ken saankayo a dumngeg ngem ketdi maiyaw-awankayo ken agrukbabkayo kadagiti sabali a dios ken agdaydayawkayo kadakuada,
18 èmi ń sọ fún un yín lónìí yìí pé ìwọ yóò parun láìsí àní àní. O kò ní í gbé pẹ́ ní ilẹ̀ tí ìwọ ń kọjá Jordani láti gbà àti láti ní.
ket ibagak kadakayo ita nga aldaw nga awan dua-dua a mapukawkayo; saanyonto a mapaatiddug dagiti al-adawyo iti daga a lasatenyo ti Jordan a papananyo ken tagikuaen.
19 Èmi pe ọ̀run àti ilẹ̀ láti jẹ́rìí tì yín ní òní pé, èmi fi ìyè àti ikú, ìbùkún àti ègún síwájú rẹ: nítorí náà yan ìyè, kí ìwọ kí ó lè yè, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ,
Awagak ti langit ken daga tapno agsaksi maibusor kadakayo ita nga aldaw nga inkabilko iti sangoananyo ti biag ken patay, dagiti bendision ken dagiti lunod; pilienyo ngarud ti biag tapno agbiagkayo, dakayo ken dagiti kaputotanyo.
20 kí ìwọ kí ó le máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, fetísílẹ̀ sí ohùn un rẹ̀, kí o sì dúró ṣinṣin nínú rẹ̀. Nítorí Olúwa ni ìyè rẹ, yóò sì fún ọ ní ọdún púpọ̀ ní ilẹ̀ tí ó ti búra láti fi fún àwọn baba rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
Aramidenyo daytoy tapno ayatenyo ni Yahweh a Diosyo, tapno agtulnogkayo iti timekna, ken tapno kumpetkayo kenkuana. Ta isuna ti biagyo ken ti kaatiddug dagiti al-aldawyo; aramidenyo daytoy tapno agbiagkayo iti daga nga insapata ni Yahweh nga itedna kadagiti kapuonanyo, a ni Abraham, Isaac ken ni Jacob.”