< Deuteronomy 30 >

1 Nígbà tí gbogbo ìbùkún àti ègún wọ̀nyí tí mo ti gbé kalẹ̀ síwájú u yín bá wá sórí i yín àti tí o bá mú wọn sí àyà rẹ níbikíbi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá tú ọ ká sí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
And it will be that they will come on you all the things these the blessing and the curse which I have set before you and you will bring [them] back to heart your in all the nations where he has banished you Yahweh God your there towards.
2 àti nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ bá yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì gbọ́rọ̀ sí pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un yín lónìí.
And you will turn back to Yahweh God your and you will listen to voice his according to all that I [am] commanding you this day you and children your with all heart your and with all being your.
3 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ohun ìní rẹ bọ̀ sípò yóò sì ṣàánú fún ọ, yóò sì tún ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè níbi tí ó ti fọ́n yín ká sí.
And he will turn back Yahweh God your captivity your and he will have compassion on you and he will return and he will gather you from all the peoples where he has scattered you Yahweh God your there towards.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti lé ẹni rẹ kan sí ilẹ̀ tí ó jìnnà jù lábẹ́ ọ̀run, láti ibẹ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò ṣà yín jọ yóò sì tún mú u yín padà.
If he will be banished [one] your at [the] end of the heavens from there he will gather you Yahweh God your and from there he will bring you.
5 Yóò mú ọ wá sí ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn baba yín, ìwọ yóò sì mú ìní níbẹ̀. Olúwa yóò mú ọ wà ní àlàáfíà kíkún, yóò mú ọ pọ̀ sí i ju àwọn baba yín lọ.
And he will bring you Yahweh God your to the land which they took possession of ancestors your and you will take possession of it and he will do good to you and he will make great you more than ancestors your.
6 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò kọ ọkàn rẹ ní ilà àti ọkàn àwọn ọmọ yín, nítorí kí o lè fẹ́ ẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, àti ayé rẹ.
And he will circumcise Yahweh God your heart your and [the] heart of offspring your to love Yahweh God your with all heart your and with all being your for [the] sake of life your.
7 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú gbogbo ègún yín wá sórí àwọn ọ̀tá à rẹ tí wọ́n kórìíra àti tí wọ́n ṣe inúnibíni rẹ.
And he will put Yahweh God your all the oaths these on enemies your and on [those who] hate you who they have persecuted you.
8 Ìwọ yóò tún gbọ́rọ̀ sí Olúwa àti tẹ̀lé gbogbo àṣẹ rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí.
And you you will turn and you will listen to [the] voice of Yahweh and you will do all commandments his which I [am] commanding you this day.
9 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ọ ṣe rere nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ, àti nínú gbogbo ọmọ inú rẹ, agbo ẹran ọ̀sìn rẹ àti èso ilẹ̀ rẹ. Olúwa yóò tún mú inú dídùn sínú rẹ yóò sì mú ọ ṣe déédé, gẹ́gẹ́ bí ó ti fi inú dídùn sínú àwọn baba rẹ.
And he will make abound you Yahweh God your in all - [the] work of hand your in [the] fruit of womb your and in [the] fruit of livestock your and in [the] fruit of ground your to good for - he will turn Yahweh to rejoice on you for good just as he rejoiced on ancestors your.
10 Bí o bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́ àti àṣẹ tí a kọ sínú ìwé òfin yìí kí o sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.
If you will listen to [the] voice of Yahweh God your to keep commandments his and statutes his that is written in [the] book of the law this if you will return to Yahweh God your with all heart your and with all being your.
11 Nítorí àṣẹ yìí tí mo pa fún ọ lónìí, kò ṣòro jù fún ọ, bẹ́ẹ̀ ni kò kọjá agbára rẹ.
For the commandment this which I [am] commanding you this day not [is too] difficult it for you and not [is] far away it.
12 Kò sí ní ọ̀run, tí ìwọ kò bá fi wí pé, “Ta ni yóò gòkè lọ sí ọ̀run fún wa, tí yóò sì mú wa fún wa, kí àwa lè gbọ́, kí a sì le ṣe é?”
Not [is] in the heavens it to say who? will he go up for us the heavens towards so he may fetch it for us so he may make hear us it so we may do it.
13 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ìhà kejì Òkun, tí ìwọ ìbá fi wí pé, “Ta ni yóò rékọjá òkun lọ fún wa, tí yóò sì mú un wá fún wa, kí àwa lè gbọ́ ọ, kí a si le ṣe é?”
And not [is] from [the] other side of the sea it to say who? will he pass over for us to [the] other side of the sea so he may fetch it for us so he may make hear us it so we may do it.
14 Kì í ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ náà súnmọ́ tòsí rẹ, ó wà ní ẹnu rẹ àti ní ọkàn rẹ kí ìwọ lè máa ṣe é.
For [is] near to you the word very in mouth your and in heart your to do it.
15 Wò ó mo gbé kalẹ̀ síwájú u yín lónìí, ìyè àti àlàáfíà, ikú àti ìparun.
See I set before you this day life and good and death and evil.
16 Ní èyí tí mo pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, láti máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ àti láti máa pa àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè yè, kí ó sì máa bí sí i, kí Olúwa Ọlọ́run lè bù si fún ọ ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ìwọ ń lọ láti gbà á.
(If you will listen to [the] commandments of Yahweh God your *X*) which I [am] commanding you this day to love Yahweh God your to walk in ways his and to keep commandments his and statutes his and judgments his and you will live and you will increase and he will bless you Yahweh God your in the land where you [are] about to go there towards to take possession of it.
17 Ṣùgbọ́n tí ọkàn an yín bá yí padà tí ìwọ kò sì ṣe ìgbọ́ràn, àti bí o bá fà, lọ láti foríbalẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn àti sìn wọ́n,
And if it will turn away heart your and not you will listen and you will be drawn aside and you will bow down to gods other and you will serve them.
18 èmi ń sọ fún un yín lónìí yìí pé ìwọ yóò parun láìsí àní àní. O kò ní í gbé pẹ́ ní ilẹ̀ tí ìwọ ń kọjá Jordani láti gbà àti láti ní.
I tell to you this day that certainly you will perish! not you will prolong! days on the land where you [are] about to pass over the Jordan to go there towards to take possession of it.
19 Èmi pe ọ̀run àti ilẹ̀ láti jẹ́rìí tì yín ní òní pé, èmi fi ìyè àti ikú, ìbùkún àti ègún síwájú rẹ: nítorí náà yan ìyè, kí ìwọ kí ó lè yè, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ,
I call as witnesses against you this day the heavens and the earth life and death I have set before you blessing and curse and you will choose life so that you may live you and offspring your.
20 kí ìwọ kí ó le máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, fetísílẹ̀ sí ohùn un rẹ̀, kí o sì dúró ṣinṣin nínú rẹ̀. Nítorí Olúwa ni ìyè rẹ, yóò sì fún ọ ní ọdún púpọ̀ ní ilẹ̀ tí ó ti búra láti fi fún àwọn baba rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
By loving Yahweh God your by listening to voice his and by cleaving to him for he [is] life your and [the] length of days your to dwell on the land which he swore Yahweh to ancestors your to Abraham to Isaac and to Jacob to give to them.

< Deuteronomy 30 >