< Deuteronomy 30 >

1 Nígbà tí gbogbo ìbùkún àti ègún wọ̀nyí tí mo ti gbé kalẹ̀ síwájú u yín bá wá sórí i yín àti tí o bá mú wọn sí àyà rẹ níbikíbi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá tú ọ ká sí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
Když pak přijdou na tě všecka slova tato, požehnání i zlořečenství, kterážť jsem předložil, a rozpomeneš se v srdci svém, kdež bys koli byl mezi národy, do kterýchž by tě rozehnal Hospodin Bůh tvůj,
2 àti nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ bá yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì gbọ́rọ̀ sí pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un yín lónìí.
A obrátě se k Hospodinu Bohu svému, poslouchal bys hlasu jeho ve všem, jakž já přikazuji tobě dnes, ty i synové tvoji, z celého srdce svého a ze vší duše své:
3 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ohun ìní rẹ bọ̀ sípò yóò sì ṣàánú fún ọ, yóò sì tún ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè níbi tí ó ti fọ́n yín ká sí.
Tehdy přivede zase Hospodin Bůh tvůj zajaté tvé a smiluje se nad tebou, a obrátě se, shromáždí tě ze všech národů, mezi něž rozptýlil tě Hospodin Bůh tvůj.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti lé ẹni rẹ kan sí ilẹ̀ tí ó jìnnà jù lábẹ́ ọ̀run, láti ibẹ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò ṣà yín jọ yóò sì tún mú u yín padà.
Byť pak někdo z tvých i na konec světa zahnán byl, odtud zase shromáždí tě Hospodin Bůh tvůj, a odtud půjme tě,
5 Yóò mú ọ wá sí ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn baba yín, ìwọ yóò sì mú ìní níbẹ̀. Olúwa yóò mú ọ wà ní àlàáfíà kíkún, yóò mú ọ pọ̀ sí i ju àwọn baba yín lọ.
A uvede tě zase Hospodin Bůh tvůj do země, kterouž dědičně vládli otcové tvoji, a opanuješ ji, a dobřeť učiní a rozmnoží tě více nežli otce tvé.
6 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò kọ ọkàn rẹ ní ilà àti ọkàn àwọn ọmọ yín, nítorí kí o lè fẹ́ ẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, àti ayé rẹ.
A obřeže Hospodin Bůh tvůj srdce tvé a srdce semene tvého, abys miloval Hospodina Boha svého z celého srdce svého, a ze vší duše své, abys živ byl.
7 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú gbogbo ègún yín wá sórí àwọn ọ̀tá à rẹ tí wọ́n kórìíra àti tí wọ́n ṣe inúnibíni rẹ.
Všecka pak zlořečenství tato obrátí Hospodin Bůh tvůj na nepřátely tvé a na ty, jenž v nenávisti měli tebe, a protivili se tobě.
8 Ìwọ yóò tún gbọ́rọ̀ sí Olúwa àti tẹ̀lé gbogbo àṣẹ rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí.
Ty tedy obrátě se, když poslouchati budeš hlasu Hospodina Boha svého, a činiti všecka přikázaní jeho, kteráž já tobě dnes přikazuji:
9 Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ọ ṣe rere nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ, àti nínú gbogbo ọmọ inú rẹ, agbo ẹran ọ̀sìn rẹ àti èso ilẹ̀ rẹ. Olúwa yóò tún mú inú dídùn sínú rẹ yóò sì mú ọ ṣe déédé, gẹ́gẹ́ bí ó ti fi inú dídùn sínú àwọn baba rẹ.
Dáť Hospodin Bůh tvůj prospěch při všem díle rukou tvých, v plodu života tvého i v plodu dobytka tvého, a v úrodách země tvé, tobě k dobrému. Nebo zase veseliti se bude Hospodin z tebe, dobře čině tobě, jakož veselil se z otců tvých,
10 Bí o bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́ àti àṣẹ tí a kọ sínú ìwé òfin yìí kí o sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.
Jestliže bys však poslouchal hlasu Hospodina Boha svého, a ostříhal přikázaní jeho a ustanovení jeho, napsaných v knize zákona tohoto, když bys se obrátil k Hospodinu Bohu svému celým srdcem svým a celou duší svou.
11 Nítorí àṣẹ yìí tí mo pa fún ọ lónìí, kò ṣòro jù fún ọ, bẹ́ẹ̀ ni kò kọjá agbára rẹ.
Nebo přikázaní toto, kteréž přikazuji tobě dnes, není skryté před tebou, ani vzdálené od tebe.
12 Kò sí ní ọ̀run, tí ìwọ kò bá fi wí pé, “Ta ni yóò gòkè lọ sí ọ̀run fún wa, tí yóò sì mú wa fún wa, kí àwa lè gbọ́, kí a sì le ṣe é?”
Není na nebi, abys řekl: Kdo nám vstoupí do nebe, aby vezma, přinesl a oznámil je nám, abychom je plnili?
13 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ìhà kejì Òkun, tí ìwọ ìbá fi wí pé, “Ta ni yóò rékọjá òkun lọ fún wa, tí yóò sì mú un wá fún wa, kí àwa lè gbọ́ ọ, kí a si le ṣe é?”
Ani za mořem jest, abys řekl: Kdo se nám přeplaví za moře, aby je přinesl a oznámil nám, abychom plnili je?
14 Kì í ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ náà súnmọ́ tòsí rẹ, ó wà ní ẹnu rẹ àti ní ọkàn rẹ kí ìwọ lè máa ṣe é.
Ale velmi blízko tebe jest slovo, v ústech tvých a v srdci tvém, abys činil to:
15 Wò ó mo gbé kalẹ̀ síwájú u yín lónìí, ìyè àti àlàáfíà, ikú àti ìparun.
(Hle, předložil jsem tobě dnes život a dobré, smrt i zlé),
16 Ní èyí tí mo pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, láti máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ àti láti máa pa àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè yè, kí ó sì máa bí sí i, kí Olúwa Ọlọ́run lè bù si fún ọ ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ìwọ ń lọ láti gbà á.
Což já přikazuji tobě dnes, abys miloval Hospodina Boha svého, chodě po cestách jeho a ostříhaje přikázaní jeho, ustanovení a soudů jeho, abys živ jsa, rozmnožen byl, a požehnal tobě Hospodin Bůh tvůj v zemi, do kteréž jdeš, abys ji dědičně obdržel.
17 Ṣùgbọ́n tí ọkàn an yín bá yí padà tí ìwọ kò sì ṣe ìgbọ́ràn, àti bí o bá fà, lọ láti foríbalẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn àti sìn wọ́n,
Pakli se odvrátí srdce tvé, a nebudeš poslouchati, ale přiveden jsa k tomu, klaněti se budeš bohům cizím a jim sloužiti:
18 èmi ń sọ fún un yín lónìí yìí pé ìwọ yóò parun láìsí àní àní. O kò ní í gbé pẹ́ ní ilẹ̀ tí ìwọ ń kọjá Jordani láti gbà àti láti ní.
Ohlašuji vám dnes, že jistotně zahynete, aniž prodlíte dnů svých v zemi, do kteréž se přes Jordán béřeš, abys ji dědičně obdržel.
19 Èmi pe ọ̀run àti ilẹ̀ láti jẹ́rìí tì yín ní òní pé, èmi fi ìyè àti ikú, ìbùkún àti ègún síwájú rẹ: nítorí náà yan ìyè, kí ìwọ kí ó lè yè, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ,
Osvědčuji proti tobě dnes nebem a zemí, žeť jsem život i smrt předložil, požehnání i zlořečenství; vyvoliž sobě tedy život, abys živ byl ty i símě tvé,
20 kí ìwọ kí ó le máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, fetísílẹ̀ sí ohùn un rẹ̀, kí o sì dúró ṣinṣin nínú rẹ̀. Nítorí Olúwa ni ìyè rẹ, yóò sì fún ọ ní ọdún púpọ̀ ní ilẹ̀ tí ó ti búra láti fi fún àwọn baba rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
A miloval Hospodina Boha svého, poslouchaje hlasu jeho a přídrže se jeho, (nebo on jest život tvůj, a dlouhost dnů tvých), abys bydlil v zemi, kterouž s přísahou zaslíbil Hospodin otcům tvým Abrahamovi, Izákovi a Jákobovi, že jim ji dá.

< Deuteronomy 30 >