< Deuteronomy 3 >
1 Lẹ́yìn èyí ní a yípadà tí a sì kọrí sí ọ̀nà tí ó lọ sí Baṣani, Ogu ọba Baṣani àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ ṣígun wá pàdé wa ní Edrei.
Så tok vi på en annen kant og drog op på veien til Basan; da drog Og, kongen i Basan, og hele hans folk ut mot oss til strid, til Edre'i.
2 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀. Kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
Og Herren sa til mig: Frykt ikke for ham! For jeg har gitt ham og hele hans folk og hans land i din hånd, og du skal gjøre med ham som du gjorde med Sihon, amorittenes konge, som bodde i Hesbon.
3 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wa fi Ogu ọba Baṣani àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lé wa lọ́wọ́. A kọlù wọ́n títí kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè.
Så gav Herren vår Gud også Og, kongen i Basan, og hele hans folk i vår hånd; og vi slo ham så vi ikke lot nogen bli tilbake eller slippe unda.
4 Ní ìgbà náà ní a gba gbogbo àwọn ìlú rẹ̀. Kò sí ọ̀kankan tí a kò gbà nínú àwọn ọgọta ìlú tí wọ́n ní, gbogbo agbègbè Argobu, lábẹ́ ìjọba Ogu ní Baṣani.
Og vi inntok dengang alle hans byer; der var ikke en by uten at vi tok den fra dem, seksti byer, hele Argob-landet, Ogs rike i Basan.
5 Gbogbo ìlú wọ̀nyí ní a mọ odi gíga yíká pẹ̀lú àwọn ìlẹ̀kùn àti irin. Ọ̀pọ̀ àwọn ìlú kéékèèké tí a kò mọ odi yíká sì tún wà pẹ̀lú.
Alle disse var faste byer med høie murer, dobbelte porter og bommer, foruten en stor mengde landsbyer.
6 Gbogbo wọn ni a parun pátápátá gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Sihoni ọba Heṣboni, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátápátá: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.
Og vi slo dem med bann, som vi hadde gjort med Sihon, kongen i Hesbon; hver by slo vi med bann, menn, kvinner og barn.
7 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú wọn, fún ara wa.
Men alt feet og hærfanget fra byene tok vi til bytte.
8 Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jordani láti odò Arnoni, títí dé orí òkè Hermoni lọ́wọ́ àwọn ọba Amori méjèèjì wọ̀nyí.
Således tok vi dengang landet fra begge amoritterkongene på denne side av Jordan, fra Arnon-åen like til fjellet Hermon -
9 (Àwọn ará Sidoni ń pe Hermoni ní Sirioni. Àwọn Amori sì ń pè é ní Seniri).
sidonierne kaller Hermon Sirjon, og amorittene kaller det Senir -
10 Gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gileadi, àti gbogbo Baṣani, títí dé Saleka, àti Edrei, ìlú àwọn ọba Ogu ní ilẹ̀ Baṣani.
alle byene på sletten og hele Gilead og hele Basan like til byene Salka og Edre'i i Ogs rike i Basan;
11 (Ogu tí í ṣe ọba Baṣani nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Refaimu. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rabba ti àwọn Ammoni.)
for Og, kongen i Basan, var den siste som var tilbake av refa'ittene; hans seng, som er av jern, står, som alle vet, i ammonitterbyen Rabba; den er ni alen lang og fire alen bred, alnen regnet efter lengden av en manns underarm.
12 Nínú àwọn ilẹ̀ tí a gbà ní ìgbà náà, mo fún àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, ní ilẹ̀ tí ó wà ní àríwá Aroeri níbi odò Arnoni, pọ̀ mọ́ ìdajì ilẹ̀ òkè Gileadi pẹ̀lú gbogbo ìlú wọn.
Dette land inntok vi dengang: Bygdene fra Aroer, som ligger ved Arnon-åen, og halvdelen av Gileadfjellene med byene der gav jeg til rubenittene og gadittene,
13 Gbogbo ìyókù Gileadi àti gbogbo Baṣani, ní ilẹ̀ ọba Ogu ni mo fún ìdajì ẹ̀yà Manase. (Gbogbo agbègbè Argobu ni Baṣani tí a mọ̀ sí ilẹ̀ àwọn ará Refaimu.
og resten av Gilead og hele Basan, Ogs rike, gav jeg til den halve Manasse stamme, hele Argob-landet, hele Basan; det er det som kalles refa'ittenes land.
14 Jairi ọ̀kan nínú àwọn ìran Manase gba gbogbo agbègbè Argobu títí dé ààlà àwọn ará Geṣuri àti àwọn ará Maakati; a sọ ibẹ̀ ní orúkọ rẹ̀ torí èyí ni Baṣani fi ń jẹ́ Hafoti-Jairi títí di òní.)
Ja'ir, Manasses sønn, inntok hele Argob-landet like til gesurittenes og ma'akatittenes landemerker, og dette land - Basan-landet - kalte han efter sitt eget navn Ja'irs byer, og så har det hett til denne dag.
15 Mo sì fi Gileadi fún Makiri,
Og til Makir gav jeg Gilead.
16 ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Reubeni àti ọmọ Gadi ni mo fún ní ilẹ̀ láti Gileadi lọ dé odò Arnoni (àárín odò náà sì jẹ́ ààlà) títí ó fi dé odò Jabbok. Èyí tí i ṣe ààlà àwọn ará Ammoni.
Og til rubenittene og gadittene gav jeg landet fra Gilead til Arnon-åen, til midt i åen, og landet langsmed den, og til Jabbok-åen, Ammons barns grense,
17 Pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah pẹ̀lú, àti Jordani gẹ́gẹ́ bí òpin ilẹ̀ rẹ̀, láti Kinnereti lọ títí dé Òkun pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah, àní Òkun Iyọ̀, ní ìsàlẹ̀ àwọn orísun Pisga ní ìhà ìlà-oòrùn.
og ødemarken og Jordan og landet langsmed den, fra Kinnerets sjø til Ødemarks-havet - Salthavet - nedenfor Pisga-liene, mot øst.
18 Mo pàṣẹ fún un yín ní ìgbà náà pé, “Olúwa Ọlọ́run yín ti fi ilẹ̀ yìí fún un yín láti ní i. Ṣùgbọ́n, gbogbo àwọn ọkùnrin yín tí ó lera tí wọ́n sì ti dira ogun, gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín: ará Israẹli.
Dengang bød jeg eder og sa: Herren eders Gud har gitt eder dette land til eie; væbnet skal I, alle som er krigsdyktige menn, dra frem foran eders brødre, Israels barn.
19 Àwọn ẹ̀yà a yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ohun ọ̀sìn in yín (mo mọ̀ pé ẹ ti ní ohun ọ̀sìn púpọ̀) lè dúró ní àwọn ìlú tí mo fi fún un yín,
Bare eders hustruer og barn og eders fe - jeg vet at I har meget fe - skal bli igjen i de byer jeg har gitt eder,
20 títí di ìgbà tí Olúwa yóò fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi bí ó ti fún un yín, àti ìgbà tí àwọn náà yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún wọn ní ìhà kejì Jordani. Nígbà náà ni ọ̀kọ̀ọ̀kan yín tó lè padà lọ sí ìní rẹ̀ tí mo fún un.”
inntil Herren gir eders brødre ro likesom eder, og de og har tatt det land i eie som Herren eders Gud gir dem på hin side Jordan; da kan I vende tilbake, hver til den eiendom jeg har gitt eder.
21 Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún Joṣua pé, “Ìwọ tí fi ojú rẹ rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ṣe sí àwọn ọba méjèèjì wọ̀nyí. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò ṣe sí àwọn ilẹ̀ ọba tí ẹ̀yin n lọ.
På samme tid bød jeg Josva og sa: Du har med egne øine sett alt det Herren eders Gud har gjort med disse to konger; således vil Herren gjøre med alle de riker du drar over til.
22 Ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, Olúwa Ọlọ́run yín tìkára rẹ̀ ni yóò jà fún un yín.”
I skal ikke være redde for dem; for Herren eders Gud vil selv stride for eder.
23 Nígbà náà ni mo bẹ Olúwa wí pé,
For jeg bønnfalt dengang Herren og sa:
24 “Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí bẹ̀rẹ̀ sí fi títóbi rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ han ìránṣẹ́ rẹ. Ọlọ́run wo ló tó bẹ́ẹ̀ láyé àti lọ́run tí ó lè ṣe àwọn iṣẹ́ agbára ńlá tí o ti ṣe?
Herre, Herre! Du har begynt å la din tjener se din storhet og din sterke hånd; for hvor er det en gud i himmelen og på jorden som kan gjøre sådanne gjerninger og storverk som du?
25 Jẹ́ kí n kọjá lọ wo ilẹ̀ rere ti ìkọjá Jordani, ilẹ̀ òkè dídára nì àti Lebanoni.”
La mig nu få dra over og se det gode land på hin side Jordan, dette gode fjell-land og Libanon!
26 Ṣùgbọ́n torí i tiyín, Olúwa Ọlọ́run bínú sí mi kò sì gbọ́ tèmi. Olúwa sọ wí pé, “Ó tó gẹ́ẹ́, ìwọ kò gbọdọ̀ sọ ohunkóhun lórí ọ̀rọ̀ yìí sí mi mọ́.
Men Herren var vred på mig for eders skyld, og han hørte ikke på mig, men han sa til mig: La det nu være nok, tal ikke mere til mig om dette!
27 Gòkè lọ sí orí òkè Pisga, sì wò yíká ìwọ̀-oòrùn, ìlà-oòrùn, àríwá àti gúúsù. Fi ojú ara rẹ wo ilẹ̀ náà níwọ̀n bí ìwọ kò tí ní kọjá Jordani yìí.
Gå op på Pisgas topp og løft dine øine mot vest og mot nord og mot syd og mot øst, og se vidt omkring dig! For over Jordan her skal du ikke komme.
28 Ṣùgbọ́n yan Joṣua, kí o sì gbà á níyànjú, mú un lọ́kàn le, torí pé òun ni yóò síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọjá, yóò sì jẹ́ kí wọn jogún ilẹ̀ náà tí ìwọ yóò rí.”
Og gi Josva befaling og gjør ham frimodig og sterk! For han skal føre dette folk over, og han skal gi dem til arv det land du skal skue.
29 Báyìí ni a dúró ní àfonífojì ní ẹ̀bá Beti-Peori.
Så blev vi da i dalen midt imot Bet-Peor.