< Deuteronomy 3 >

1 Lẹ́yìn èyí ní a yípadà tí a sì kọrí sí ọ̀nà tí ó lọ sí Baṣani, Ogu ọba Baṣani àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ ṣígun wá pàdé wa ní Edrei.
Puis nous nous tournâmes, et nous montâmes par le chemin de Basan. Og, roi de Basan, sortit contre nous, lui et tout son peuple, pour nous combattre à Édréi.
2 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀. Kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
Yahvé me dit: « Ne le crains pas, car je l'ai livré entre tes mains, avec tout son peuple et son pays. Tu lui feras ce que tu as fait à Sihon, roi des Amoréens, qui habitait à Heshbon. »
3 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wa fi Ogu ọba Baṣani àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lé wa lọ́wọ́. A kọlù wọ́n títí kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè.
Et Yahvé, notre Dieu, livra aussi entre nos mains Og, roi de Basan, et tout son peuple. Nous le frappâmes jusqu'à ce qu'il ne lui restât plus personne.
4 Ní ìgbà náà ní a gba gbogbo àwọn ìlú rẹ̀. Kò sí ọ̀kankan tí a kò gbà nínú àwọn ọgọta ìlú tí wọ́n ní, gbogbo agbègbè Argobu, lábẹ́ ìjọba Ogu ní Baṣani.
Nous avons pris toutes ses villes à cette époque. Il n'y eut pas une ville que nous n'ayons prise: soixante villes, toute la région d'Argob, le royaume d'Og en Basan.
5 Gbogbo ìlú wọ̀nyí ní a mọ odi gíga yíká pẹ̀lú àwọn ìlẹ̀kùn àti irin. Ọ̀pọ̀ àwọn ìlú kéékèèké tí a kò mọ odi yíká sì tún wà pẹ̀lú.
Toutes ces villes étaient fortifiées par de hautes murailles, des portes et des barres, sans compter les nombreux villages sans murailles.
6 Gbogbo wọn ni a parun pátápátá gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Sihoni ọba Heṣboni, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátápátá: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.
Nous les détruisîmes par interdit, comme nous l'avions fait à Sihon, roi de Heshbon, en dévastant par interdit toutes les villes habitées, avec les femmes et les petits enfants.
7 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú wọn, fún ara wa.
Mais nous prîmes pour nous tout le bétail et le butin des villes.
8 Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jordani láti odò Arnoni, títí dé orí òkè Hermoni lọ́wọ́ àwọn ọba Amori méjèèjì wọ̀nyí.
En ce temps-là, nous prîmes le pays de la main des deux rois des Amoréens qui étaient au-delà du Jourdain, depuis le val de l'Arnon jusqu'au mont Hermon.
9 (Àwọn ará Sidoni ń pe Hermoni ní Sirioni. Àwọn Amori sì ń pè é ní Seniri).
(Les Sidoniens appellent Hermon Sirion, et les Amoréens l'appellent Senir.)
10 Gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gileadi, àti gbogbo Baṣani, títí dé Saleka, àti Edrei, ìlú àwọn ọba Ogu ní ilẹ̀ Baṣani.
Nous prîmes toutes les villes de la plaine, tout Galaad et tout Basan, jusqu'à Salca et Édréi, villes du royaume d'Og en Basan.
11 (Ogu tí í ṣe ọba Baṣani nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Refaimu. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rabba ti àwọn Ammoni.)
(Car il ne restait qu'Og, roi de Basan, du reste des Rephaïm. Voici, son sommier était un sommier de fer. N'est-ce pas à Rabba, chez les enfants d'Ammon? Sa longueur était de neuf coudées, et sa largeur de quatre coudées, selon la coudée d'un homme).
12 Nínú àwọn ilẹ̀ tí a gbà ní ìgbà náà, mo fún àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, ní ilẹ̀ tí ó wà ní àríwá Aroeri níbi odò Arnoni, pọ̀ mọ́ ìdajì ilẹ̀ òkè Gileadi pẹ̀lú gbogbo ìlú wọn.
En ce temps-là, nous prîmes possession de ce pays: depuis Arœr, qui est près du torrent de l'Arnon, et la moitié de la montagne de Galaad, avec ses villes, je les donnai aux Rubénites et aux Gadites;
13 Gbogbo ìyókù Gileadi àti gbogbo Baṣani, ní ilẹ̀ ọba Ogu ni mo fún ìdajì ẹ̀yà Manase. (Gbogbo agbègbè Argobu ni Baṣani tí a mọ̀ sí ilẹ̀ àwọn ará Refaimu.
et le reste de Galaad, et tout Basan, le royaume d'Og, je les donnai à la demi-tribu de Manassé, toute la région d'Argob, tout Basan. (On appelle ce territoire le pays des Rephaïm.
14 Jairi ọ̀kan nínú àwọn ìran Manase gba gbogbo agbègbè Argobu títí dé ààlà àwọn ará Geṣuri àti àwọn ará Maakati; a sọ ibẹ̀ ní orúkọ rẹ̀ torí èyí ni Baṣani fi ń jẹ́ Hafoti-Jairi títí di òní.)
Jaïr, fils de Manassé, prit toute la région d'Argob, jusqu'à la frontière des Gueschuriens et des Maacathiens, et il leur donna le nom de Basan, d'après son propre nom, Havvoth Jaïr, jusqu'à ce jour).
15 Mo sì fi Gileadi fún Makiri,
Je donnai Galaad à Makir.
16 ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Reubeni àti ọmọ Gadi ni mo fún ní ilẹ̀ láti Gileadi lọ dé odò Arnoni (àárín odò náà sì jẹ́ ààlà) títí ó fi dé odò Jabbok. Èyí tí i ṣe ààlà àwọn ará Ammoni.
Je donnai aux Rubénites et aux Gadites, depuis Galaad jusqu'au torrent de l'Arnon, le milieu du torrent, et sa limite, jusqu'au fleuve Jabbok, qui est la limite des fils d'Ammon.
17 Pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah pẹ̀lú, àti Jordani gẹ́gẹ́ bí òpin ilẹ̀ rẹ̀, láti Kinnereti lọ títí dé Òkun pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah, àní Òkun Iyọ̀, ní ìsàlẹ̀ àwọn orísun Pisga ní ìhà ìlà-oòrùn.
La plaine, le Jourdain et sa limite, depuis Kinnéreth jusqu'à la mer de la plaine, la mer Salée, sous les pentes du Pisga, à l'orient.
18 Mo pàṣẹ fún un yín ní ìgbà náà pé, “Olúwa Ọlọ́run yín ti fi ilẹ̀ yìí fún un yín láti ní i. Ṣùgbọ́n, gbogbo àwọn ọkùnrin yín tí ó lera tí wọ́n sì ti dira ogun, gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín: ará Israẹli.
En ce temps-là, je vous ai donné cet ordre: « Yahvé ton Dieu t'a donné ce pays pour que tu en prennes possession. Vous tous, hommes de valeur, vous passerez armés devant vos frères, les enfants d'Israël.
19 Àwọn ẹ̀yà a yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ohun ọ̀sìn in yín (mo mọ̀ pé ẹ ti ní ohun ọ̀sìn púpọ̀) lè dúró ní àwọn ìlú tí mo fi fún un yín,
Mais vos femmes, vos petits enfants et vos troupeaux (je sais que vous avez beaucoup de bétail) habiteront dans les villes que je vous ai données,
20 títí di ìgbà tí Olúwa yóò fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi bí ó ti fún un yín, àti ìgbà tí àwọn náà yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún wọn ní ìhà kejì Jordani. Nígbà náà ni ọ̀kọ̀ọ̀kan yín tó lè padà lọ sí ìní rẹ̀ tí mo fún un.”
jusqu'à ce que l'Éternel donne du repos à vos frères, comme à vous, et qu'ils possèdent aussi le pays que l'Éternel, votre Dieu, leur donne au-delà du Jourdain. Alors vous retournerez chacun dans sa propriété, que je vous ai donnée. »
21 Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún Joṣua pé, “Ìwọ tí fi ojú rẹ rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ṣe sí àwọn ọba méjèèjì wọ̀nyí. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò ṣe sí àwọn ilẹ̀ ọba tí ẹ̀yin n lọ.
En ce temps-là, je donnai cet ordre à Josué: « Tes yeux ont vu tout ce que Yahvé ton Dieu a fait à ces deux rois. C'est ainsi que Yahvé fera à tous les royaumes où tu passeras.
22 Ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, Olúwa Ọlọ́run yín tìkára rẹ̀ ni yóò jà fún un yín.”
Tu ne les craindras pas, car Yahvé ton Dieu combat lui-même pour toi. »
23 Nígbà náà ni mo bẹ Olúwa wí pé,
En ce temps-là, je suppliai Yahvé, en disant:
24 “Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí bẹ̀rẹ̀ sí fi títóbi rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ han ìránṣẹ́ rẹ. Ọlọ́run wo ló tó bẹ́ẹ̀ láyé àti lọ́run tí ó lè ṣe àwọn iṣẹ́ agbára ńlá tí o ti ṣe?
« Seigneur Yahvé, tu as commencé à montrer à ton serviteur ta grandeur et ta main puissante. Car quel dieu y a-t-il dans les cieux et sur la terre qui puisse faire des œuvres comme les tiennes, et des actes de puissance comme les tiens?
25 Jẹ́ kí n kọjá lọ wo ilẹ̀ rere ti ìkọjá Jordani, ilẹ̀ òkè dídára nì àti Lebanoni.”
Je t'en prie, laisse-moi aller voir le bon pays qui est au-delà du Jourdain, cette belle montagne et le Liban. »
26 Ṣùgbọ́n torí i tiyín, Olúwa Ọlọ́run bínú sí mi kò sì gbọ́ tèmi. Olúwa sọ wí pé, “Ó tó gẹ́ẹ́, ìwọ kò gbọdọ̀ sọ ohunkóhun lórí ọ̀rọ̀ yìí sí mi mọ́.
Mais Yahvé s'est mis en colère contre moi à cause de vous, et il ne m'a pas écouté. L'Éternel m'a dit: « C'est assez! Ne me parle plus de cette affaire.
27 Gòkè lọ sí orí òkè Pisga, sì wò yíká ìwọ̀-oòrùn, ìlà-oòrùn, àríwá àti gúúsù. Fi ojú ara rẹ wo ilẹ̀ náà níwọ̀n bí ìwọ kò tí ní kọjá Jordani yìí.
Monte au sommet du Pisga, et lève tes yeux vers l'ouest, le nord, le sud et l'est, et regarde de tes yeux, car tu ne passeras pas ce Jourdain.
28 Ṣùgbọ́n yan Joṣua, kí o sì gbà á níyànjú, mú un lọ́kàn le, torí pé òun ni yóò síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọjá, yóò sì jẹ́ kí wọn jogún ilẹ̀ náà tí ìwọ yóò rí.”
Mais commandez à Josué, encouragez-le et fortifiez-le, car il passera devant ce peuple, et il lui fera hériter le pays que vous verrez. »
29 Báyìí ni a dúró ní àfonífojì ní ẹ̀bá Beti-Peori.
Nous restâmes donc dans la vallée, près de Beth Peor.

< Deuteronomy 3 >