< Deuteronomy 3 >
1 Lẹ́yìn èyí ní a yípadà tí a sì kọrí sí ọ̀nà tí ó lọ sí Baṣani, Ogu ọba Baṣani àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ ṣígun wá pàdé wa ní Edrei.
"Sitten me käännyimme toisaalle ja kuljimme Baasanin tietä. Silloin lähti Oog, Baasanin kuningas, hän ja kaikki hänen sotaväkensä, Edreihin taistelemaan meitä vastaan.
2 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀. Kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
Mutta Herra sanoi minulle: 'Älä pelkää häntä, sillä minä annan sinun käsiisi hänet ja kaiken hänen kansansa ja hänen maansa. Tee hänelle, niinkuin teit Siihonille, amorilaisten kuninkaalle, joka asui Hesbonissa.'
3 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wa fi Ogu ọba Baṣani àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lé wa lọ́wọ́. A kọlù wọ́n títí kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè.
Ja niin Herra, meidän Jumalamme, antoi meidän käsiimme myöskin Oogin, Baasanin kuninkaan, ja kaiken hänen sotaväkensä, ja me voitimme hänet, päästämättä pakoon ainoatakaan.
4 Ní ìgbà náà ní a gba gbogbo àwọn ìlú rẹ̀. Kò sí ọ̀kankan tí a kò gbà nínú àwọn ọgọta ìlú tí wọ́n ní, gbogbo agbègbè Argobu, lábẹ́ ìjọba Ogu ní Baṣani.
Ja me valloitimme silloin kaikki hänen kaupunkinsa-ei ollut ainoatakaan kaupunkia, jota emme olisi heiltä ottaneet-kuusikymmentä kaupunkia, koko Argobin seudun, Oogin valtakunnan Baasanissa,
5 Gbogbo ìlú wọ̀nyí ní a mọ odi gíga yíká pẹ̀lú àwọn ìlẹ̀kùn àti irin. Ọ̀pọ̀ àwọn ìlú kéékèèké tí a kò mọ odi yíká sì tún wà pẹ̀lú.
kaikki nämä kaupungit korkeilla muureilla, porteilla ja salvoilla varustettuja, ja sen lisäksi vielä suuren joukon linnoittamattomia pikkukaupunkeja.
6 Gbogbo wọn ni a parun pátápátá gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Sihoni ọba Heṣboni, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátápátá: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.
Ja me vihimme ne tuhon omiksi, niinkuin olimme tehneet Siihonille, Hesbonin kuninkaalle; me vihimme tuhon omiksi jokaisessa kaupungissa miehet, naiset ja lapset.
7 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú wọn, fún ara wa.
Mutta kaiken karjan ynnä saaliin kaupungeista me ryöstimme itsellemme.
8 Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jordani láti odò Arnoni, títí dé orí òkè Hermoni lọ́wọ́ àwọn ọba Amori méjèèjì wọ̀nyí.
Niin me otimme silloin kahdelta amorilaisten kuninkaalta, jotka hallitsivat tuolla puolella Jordanin, heidän maansa Arnon-joesta aina Hermonin vuoreen asti-
9 (Àwọn ará Sidoni ń pe Hermoni ní Sirioni. Àwọn Amori sì ń pè é ní Seniri).
siidonilaiset kutsuvat Hermonia Sirjoniksi, mutta amorilaiset kutsuvat sitä Seniriksi-
10 Gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gileadi, àti gbogbo Baṣani, títí dé Saleka, àti Edrei, ìlú àwọn ọba Ogu ní ilẹ̀ Baṣani.
kaikki ylätasangon kaupungit ja koko Gileadin ja koko Baasanin aina Salkaan ja Edreihin, Baasanissa oleviin Oogin valtakunnan kaupunkeihin, saakka.
11 (Ogu tí í ṣe ọba Baṣani nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Refaimu. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rabba ti àwọn Ammoni.)
Sillä Baasanin kuningas Oog oli yksin enää jäljellä viimeisistä refalaisista. Hänen basaltista tehty ruumisarkkunsa on vieläkin ammonilaisten kaupungissa Rabbassa; se on yhdeksää kyynärää pitkä ja neljää kyynärää leveä, mitattuna tavallisella kyynärämitalla.
12 Nínú àwọn ilẹ̀ tí a gbà ní ìgbà náà, mo fún àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, ní ilẹ̀ tí ó wà ní àríwá Aroeri níbi odò Arnoni, pọ̀ mọ́ ìdajì ilẹ̀ òkè Gileadi pẹ̀lú gbogbo ìlú wọn.
Kun me silloin olimme ottaneet omaksemme tämän maan, annoin minä sen osan siitä, joka alkaa Aroerista, Arnon-joen varrelta, sekä puolet Gileadin vuoristoa kaupunkeineen ruubenilaisille ja gaadilaisille.
13 Gbogbo ìyókù Gileadi àti gbogbo Baṣani, ní ilẹ̀ ọba Ogu ni mo fún ìdajì ẹ̀yà Manase. (Gbogbo agbègbè Argobu ni Baṣani tí a mọ̀ sí ilẹ̀ àwọn ará Refaimu.
Loput Gileadista ja koko Baasanin, Oogin valtakunnan, minä annoin toiselle puolelle Manassen sukukuntaa, koko Argobin seudun; koko tätä Baasania kutsutaan refalaisten maaksi.
14 Jairi ọ̀kan nínú àwọn ìran Manase gba gbogbo agbègbè Argobu títí dé ààlà àwọn ará Geṣuri àti àwọn ará Maakati; a sọ ibẹ̀ ní orúkọ rẹ̀ torí èyí ni Baṣani fi ń jẹ́ Hafoti-Jairi títí di òní.)
Jaair, Manassen poika, valtasi koko Argobin seudun aina gesurilaisten ja maakatilaisten alueeseen saakka, ja hän kutsui nämä seudut, se on Baasanin, oman nimensä mukaan Jaairin leirikyliksi, niinkuin niitä kutsutaan vielä tänäkin päivänä.
15 Mo sì fi Gileadi fún Makiri,
Ja Maakirille minä annoin Gileadin.
16 ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Reubeni àti ọmọ Gadi ni mo fún ní ilẹ̀ láti Gileadi lọ dé odò Arnoni (àárín odò náà sì jẹ́ ààlà) títí ó fi dé odò Jabbok. Èyí tí i ṣe ààlà àwọn ará Ammoni.
Ja ruubenilaisille ja gaadilaisille minä annoin maan Gileadista aina Arnon-jokeen, jokilaakson keskikohtaan saakka, joka on rajana, ja Jabbok-jokeen saakka, joka on ammonilaisten rajana;
17 Pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah pẹ̀lú, àti Jordani gẹ́gẹ́ bí òpin ilẹ̀ rẹ̀, láti Kinnereti lọ títí dé Òkun pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah, àní Òkun Iyọ̀, ní ìsàlẹ̀ àwọn orísun Pisga ní ìhà ìlà-oòrùn.
niin myös Aromaan, Jordan rajana, Kinneretistä aina Aromaan mereen, Suolamereen, saakka, Pisgan rinteiden juurelle, itään päin.
18 Mo pàṣẹ fún un yín ní ìgbà náà pé, “Olúwa Ọlọ́run yín ti fi ilẹ̀ yìí fún un yín láti ní i. Ṣùgbọ́n, gbogbo àwọn ọkùnrin yín tí ó lera tí wọ́n sì ti dira ogun, gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín: ará Israẹli.
Ja silloin minä käskin teitä ja sanoin: 'Herra, teidän Jumalanne, on antanut teille tämän maan omaksenne. Mutta te, kaikki sotakuntoiset miehet, lähtekää asestettuina veljienne, israelilaisten, etunenässä.
19 Àwọn ẹ̀yà a yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ohun ọ̀sìn in yín (mo mọ̀ pé ẹ ti ní ohun ọ̀sìn púpọ̀) lè dúró ní àwọn ìlú tí mo fi fún un yín,
Ainoastaan vaimonne, lapsenne ja karjanne-sillä minä tiedän teillä olevan paljon karjaa-jääkööt kaupunkeihinne, jotka minä olen teille antanut,
20 títí di ìgbà tí Olúwa yóò fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi bí ó ti fún un yín, àti ìgbà tí àwọn náà yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún wọn ní ìhà kejì Jordani. Nígbà náà ni ọ̀kọ̀ọ̀kan yín tó lè padà lọ sí ìní rẹ̀ tí mo fún un.”
kunnes Herra suo veljienne, samoinkuin teidänkin, päästä rauhaan, kun hekin ovat ottaneet omaksensa sen maan, jonka Herra, teidän Jumalanne, antaa teille Jordanin tuolta puolelta; sitten saatte palata takaisin, kukin omistamallensa maalle, jonka minä olen teille antanut.'
21 Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún Joṣua pé, “Ìwọ tí fi ojú rẹ rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ṣe sí àwọn ọba méjèèjì wọ̀nyí. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò ṣe sí àwọn ilẹ̀ ọba tí ẹ̀yin n lọ.
Ja silloin minä käskin Joosuaa ja sanoin: 'Sinä olet omin silmin nähnyt kaiken, mitä Herra, teidän Jumalanne, on tehnyt näille kahdelle kuninkaalle. Samalla tavalla Herra on tekevä kaikille valtakunnille, joihin sinä menet.
22 Ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, Olúwa Ọlọ́run yín tìkára rẹ̀ ni yóò jà fún un yín.”
Älkää niitä peljätkö, sillä Herra, teidän Jumalanne, sotii itse teidän puolestanne.'
23 Nígbà náà ni mo bẹ Olúwa wí pé,
Ja silloin minä anoin Herralta armoa sanoen:
24 “Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí bẹ̀rẹ̀ sí fi títóbi rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ han ìránṣẹ́ rẹ. Ọlọ́run wo ló tó bẹ́ẹ̀ láyé àti lọ́run tí ó lè ṣe àwọn iṣẹ́ agbára ńlá tí o ti ṣe?
'Herra, Herra, sinä olet alkanut näyttää palvelijallesi valtasuuruuttasi ja väkevää kättäsi; sillä kuka on se jumala taivaassa tai maassa, joka voi tehdä sellaisia töitä ja niin voimallisia tekoja kuin sinä?
25 Jẹ́ kí n kọjá lọ wo ilẹ̀ rere ti ìkọjá Jordani, ilẹ̀ òkè dídára nì àti Lebanoni.”
Niin salli minun nyt mennä katsomaan sitä hyvää maata, joka on tuolla puolella Jordanin, tuota ihanaa vuoristoa ja Libanonia.'
26 Ṣùgbọ́n torí i tiyín, Olúwa Ọlọ́run bínú sí mi kò sì gbọ́ tèmi. Olúwa sọ wí pé, “Ó tó gẹ́ẹ́, ìwọ kò gbọdọ̀ sọ ohunkóhun lórí ọ̀rọ̀ yìí sí mi mọ́.
Mutta Herra oli julmistunut minuun teidän tähtenne eikä kuullut minua, vaan sanoi minulle: 'Riittää! Älä puhu minulle enempää tästä asiasta.
27 Gòkè lọ sí orí òkè Pisga, sì wò yíká ìwọ̀-oòrùn, ìlà-oòrùn, àríwá àti gúúsù. Fi ojú ara rẹ wo ilẹ̀ náà níwọ̀n bí ìwọ kò tí ní kọjá Jordani yìí.
Nouse Pisgan huipulle ja kohota katseesi länteen ja pohjoiseen, etelään ja itään ja katsele silmilläsi; sillä tämän Jordanin yli sinä et mene.
28 Ṣùgbọ́n yan Joṣua, kí o sì gbà á níyànjú, mú un lọ́kàn le, torí pé òun ni yóò síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọjá, yóò sì jẹ́ kí wọn jogún ilẹ̀ náà tí ìwọ yóò rí.”
Ja anna määräyksiä Joosualle, vahvista ja rohkaise häntä. Sillä hän menee sinne tämän kansan edellä, ja hän jakaa heille perinnöksi sen maan, jonka sinä näet.'
29 Báyìí ni a dúró ní àfonífojì ní ẹ̀bá Beti-Peori.
Ja me jäimme laaksoon, vastapäätä Beet-Peoria."