< Deuteronomy 3 >
1 Lẹ́yìn èyí ní a yípadà tí a sì kọrí sí ọ̀nà tí ó lọ sí Baṣani, Ogu ọba Baṣani àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ ṣígun wá pàdé wa ní Edrei.
And we turned and we went up [the] way of Bashan and he came forth Og [the] king of Bashan to meet us he and all people his for battle Edrei.
2 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀. Kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
And he said Yahweh to me may not you fear him for in hand your I give him and all people his and land his and you will do to him just as you did to Sihon [the] king of the Amorite[s] who [was] dwelling in Heshbon.
3 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wa fi Ogu ọba Baṣani àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lé wa lọ́wọ́. A kọlù wọ́n títí kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè.
And he gave Yahweh God our in hand our also Og [the] king of Bashan and all people his and we struck down him until not he had left to him a survivor.
4 Ní ìgbà náà ní a gba gbogbo àwọn ìlú rẹ̀. Kò sí ọ̀kankan tí a kò gbà nínú àwọn ọgọta ìlú tí wọ́n ní, gbogbo agbègbè Argobu, lábẹ́ ìjọba Ogu ní Baṣani.
And we captured all cities his at the time that not it was a town which not we took from with them sixty citi[es] all [the] region of Argob [the] kingdom of Og in Bashan.
5 Gbogbo ìlú wọ̀nyí ní a mọ odi gíga yíká pẹ̀lú àwọn ìlẹ̀kùn àti irin. Ọ̀pọ̀ àwọn ìlú kéékèèké tí a kò mọ odi yíká sì tún wà pẹ̀lú.
All these [were] cities fortified wall high gates and bar[s] apart from [the] cities of the hamlet-dweller[s] many very.
6 Gbogbo wọn ni a parun pátápátá gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Sihoni ọba Heṣboni, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátápátá: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.
And we totally destroyed them just as we had done to Sihon [the] king of Heshbon we totally destroyed every city of men the women and the little one[s].
7 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú wọn, fún ara wa.
And all the livestock and [the] booty of the cities we plundered for ourselves.
8 Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jordani láti odò Arnoni, títí dé orí òkè Hermoni lọ́wọ́ àwọn ọba Amori méjèèjì wọ̀nyí.
And we took at the time that the land from [the] hand of [the] two [the] kings of the Amorite[s] who [were] on [the] other side of the Jordan from [the] wadi of Arnon to [the] mountain of Hermon.
9 (Àwọn ará Sidoni ń pe Hermoni ní Sirioni. Àwọn Amori sì ń pè é ní Seniri).
[the] Sidonians They call Hermon Sirion and the Amorite[s] they call it Senir.
10 Gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gileadi, àti gbogbo Baṣani, títí dé Saleka, àti Edrei, ìlú àwọn ọba Ogu ní ilẹ̀ Baṣani.
All - [the] cities of the plain and all Gilead and all Bashan to Salecah and Edrei [the] cities of [the] kingdom of Og in Bashan.
11 (Ogu tí í ṣe ọba Baṣani nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Refaimu. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rabba ti àwọn Ammoni.)
For only Og [the] king of Bashan he survived from [the] remnant of the Rephaites there! sarcophagus his [was] a sarcophagus of iron ¿ not [is] it in Rabbah of [the] people of Ammon [was] nine cubits length its and [was] four cubits breadth its by a cubit of a human.
12 Nínú àwọn ilẹ̀ tí a gbà ní ìgbà náà, mo fún àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, ní ilẹ̀ tí ó wà ní àríwá Aroeri níbi odò Arnoni, pọ̀ mọ́ ìdajì ilẹ̀ òkè Gileadi pẹ̀lú gbogbo ìlú wọn.
And the land this we took possession of at the time that from Aroer which [was] at [the] wadi of Arnon and [the] half of [the] hill country of Gilead and cities its I gave to the Reubenite[s] and to the Gadite[s].
13 Gbogbo ìyókù Gileadi àti gbogbo Baṣani, ní ilẹ̀ ọba Ogu ni mo fún ìdajì ẹ̀yà Manase. (Gbogbo agbègbè Argobu ni Baṣani tí a mọ̀ sí ilẹ̀ àwọn ará Refaimu.
And [the] remainder of Gilead and all Bashan [the] kingdom of Og I gave to [the] half of [the] tribe of Manasseh all [the] region of Argob to all Bashan it it was called [the] land of [the] Rephaites.
14 Jairi ọ̀kan nínú àwọn ìran Manase gba gbogbo agbègbè Argobu títí dé ààlà àwọn ará Geṣuri àti àwọn ará Maakati; a sọ ibẹ̀ ní orúkọ rẹ̀ torí èyí ni Baṣani fi ń jẹ́ Hafoti-Jairi títí di òní.)
Jair [the] son of Manasseh he took all [the] region of Argob to [the] border of the Geshurite[s] and the Maacathite[s] and he called them on own name his Bashan [the] villages of Jair until the day this.
15 Mo sì fi Gileadi fún Makiri,
And to Makir I gave Gilead.
16 ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Reubeni àti ọmọ Gadi ni mo fún ní ilẹ̀ láti Gileadi lọ dé odò Arnoni (àárín odò náà sì jẹ́ ààlà) títí ó fi dé odò Jabbok. Èyí tí i ṣe ààlà àwọn ará Ammoni.
And to the Reubenite[s] and to the Gadite[s] I gave from Gilead and to [the] wadi of Arnon [the] middle of the wadi and a border and to Jabbok the wadi [is] [the] border of [the] people of Ammon.
17 Pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah pẹ̀lú, àti Jordani gẹ́gẹ́ bí òpin ilẹ̀ rẹ̀, láti Kinnereti lọ títí dé Òkun pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah, àní Òkun Iyọ̀, ní ìsàlẹ̀ àwọn orísun Pisga ní ìhà ìlà-oòrùn.
And the Arabah and the Jordan and a border from Kinnereth and to [the] sea of the Arabah [the] Sea of Salt under [the] slopes of Pisgah east-ward.
18 Mo pàṣẹ fún un yín ní ìgbà náà pé, “Olúwa Ọlọ́run yín ti fi ilẹ̀ yìí fún un yín láti ní i. Ṣùgbọ́n, gbogbo àwọn ọkùnrin yín tí ó lera tí wọ́n sì ti dira ogun, gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín: ará Israẹli.
And I commanded you at the time that saying Yahweh God your he has given to you the land this to take possession of it equipped you will pass over before countrymen your [the] people of Israel O all [the] sons of strength.
19 Àwọn ẹ̀yà a yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ohun ọ̀sìn in yín (mo mọ̀ pé ẹ ti ní ohun ọ̀sìn púpọ̀) lè dúró ní àwọn ìlú tí mo fi fún un yín,
Only wives your and little one[s] your and livestock your I know that livestock much [belongs] to you they will remain in cities your which I have given to you.
20 títí di ìgbà tí Olúwa yóò fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi bí ó ti fún un yín, àti ìgbà tí àwọn náà yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún wọn ní ìhà kejì Jordani. Nígbà náà ni ọ̀kọ̀ọ̀kan yín tó lè padà lọ sí ìní rẹ̀ tí mo fún un.”
Until that he will give rest Yahweh - to countrymen your like you and they will take possession of also they the land which Yahweh God your [is] about to give to them on [the] other side of the Jordan and you will return everyone to possession his which I have given to you.
21 Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún Joṣua pé, “Ìwọ tí fi ojú rẹ rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ṣe sí àwọn ọba méjèèjì wọ̀nyí. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò ṣe sí àwọn ilẹ̀ ọba tí ẹ̀yin n lọ.
And Joshua I commanded at the time that saying eyes your [are] the [ones which] have seen all that he did Yahweh God your to [the] two the kings these thus he will do Yahweh to all the kingdoms where you [are] about to pass over there.
22 Ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, Olúwa Ọlọ́run yín tìkára rẹ̀ ni yóò jà fún un yín.”
Not you must fear them for Yahweh God your he [is] the [one who] will fight for you.
23 Nígbà náà ni mo bẹ Olúwa wí pé,
And I sought favor to Yahweh at the time that saying.
24 “Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí bẹ̀rẹ̀ sí fi títóbi rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ han ìránṣẹ́ rẹ. Ọlọ́run wo ló tó bẹ́ẹ̀ láyé àti lọ́run tí ó lè ṣe àwọn iṣẹ́ agbára ńlá tí o ti ṣe?
O Lord Yahweh you you have begun to show servant your greatness your and hand your strong that who? [is] God in the heavens and on the earth who he will do like works your and like mighty deeds your.
25 Jẹ́ kí n kọjá lọ wo ilẹ̀ rere ti ìkọjá Jordani, ilẹ̀ òkè dídára nì àti Lebanoni.”
Let me pass over please so I may see the land good which [is] on [the] other side of the Jordan the hill country good this and Lebanon.
26 Ṣùgbọ́n torí i tiyín, Olúwa Ọlọ́run bínú sí mi kò sì gbọ́ tèmi. Olúwa sọ wí pé, “Ó tó gẹ́ẹ́, ìwọ kò gbọdọ̀ sọ ohunkóhun lórí ọ̀rọ̀ yìí sí mi mọ́.
And he was furious Yahweh with me on account of you and not he listened to me and he said Yahweh to me enough for you may not you repeat to speak to me again in the matter this.
27 Gòkè lọ sí orí òkè Pisga, sì wò yíká ìwọ̀-oòrùn, ìlà-oòrùn, àríwá àti gúúsù. Fi ojú ara rẹ wo ilẹ̀ náà níwọ̀n bí ìwọ kò tí ní kọjá Jordani yìí.
Go up - [the] top of Pisgah and lift up eyes your west-ward and north-ward and south-ward and east-ward and see with own eyes your that not you will pass over the Jordan this.
28 Ṣùgbọ́n yan Joṣua, kí o sì gbà á níyànjú, mú un lọ́kàn le, torí pé òun ni yóò síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọjá, yóò sì jẹ́ kí wọn jogún ilẹ̀ náà tí ìwọ yóò rí.”
And commission Joshua and encourage him and strengthen him for he he will pass over before the people this and he he will give as an inheritance them the land which you will see.
29 Báyìí ni a dúró ní àfonífojì ní ẹ̀bá Beti-Peori.
And we remained in the valley opposite to Beth Peor.