< Deuteronomy 29 >

1 Èyí ni àwọn ìpinnu májẹ̀mú tí Olúwa pàṣẹ fún Mose láti ṣe pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní Moabu, ní àfikún májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú u wọn ní Horebu.
Tɵwǝndikilǝr Pǝrwǝrdigar Israillar bilǝn ǝⱨdǝ baƣlax üqün Moab zeminida Musaƣa tapiliƣan sɵzlǝrdur. Bu ǝⱨdǝ Pǝrwǝrdigar ular bilǝn Ⱨorǝbdǝ ⱪilƣan ǝⱨdidin baxⱪa bir ǝⱨdǝ idi.
2 Mose pàṣẹ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì wí fún wọn wí pé, ojú rẹ ti rí gbogbo ohun tí Olúwa ti ṣe ní Ejibiti sí Farao àti, sí gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀ àti sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
Musa pütkül Israilni qaⱪirip ularƣa mundaⱪ dedi: «Silǝr Pǝrwǝrdigarning Misir zeminida Pirǝwngǝ, uning barliⱪ hizmǝtkarliri wǝ zeminning ⱨǝmmǝ yeridǝ kɵz aldinglarda nemǝ ix ⱪilƣinini kɵrdünglar,
3 Pẹ̀lú ojú ara rẹ ni ìwọ rí àwọn ìdánwò ńlá náà, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá.
yǝni xu qong apǝtlǝr bilǝn uluƣ mɵjizilik alamǝt wǝ karamǝtlǝrni ɵz kɵzünglar bilǝn kɵrdünglar.
4 Ṣùgbọ́n títí di àsìkò yìí Olúwa kò fi ọkàn ìmòye tàbí ojú tí ó ń rí tàbí etí tí ó n gbọ́ fún ọ.
Lekin Pǝrwǝrdigar silǝrgǝ bügüngiqǝ qüxǝngüdǝk kɵngül, kɵrgüdǝk kɵz wǝ angliƣudǝk ⱪulaⱪ bǝrmidi.
5 Nígbà ogójì ọdún tí mò ń tọ́ yín ṣọ́nà ní aginjù, aṣọ ọ̀ rẹ kò gbó tàbí bàtà ẹsẹ̀ rẹ.
Mǝn ⱪiriⱪ yil silǝrni bayawanda yetǝklǝp yürdüm; xu waⱪitlarda üstünglardiki kiyimliringlar konirimidi, putunglardiki kǝxinglarmu konirap kǝtmidi.
6 O kò jẹ oúnjẹ tàbí mu wáìnì kankan tàbí rú ohun mímu mìíràn. Mo ṣe èyí kí o lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Huda Ɵzining silǝrning Pǝrwǝrdigar Hudayinglar ikǝnlikini bilsun dǝp, silǝrgǝ yeyixkǝ nan, iqixkǝ xarab yaki küqlük iqimlik nesip ⱪilmidi.
7 Nígbà tí o dé ibí yìí, Sihoni ọba Heṣboni àti Ogu ọba Baṣani jáde wá láti bá ọ jà, ṣùgbọ́n a ṣẹ́gun wọn.
Silǝr bu jayƣa yetip kǝlgininglarda Ⱨǝxbonning padixaⱨi Siⱨon bilǝn Baxanning padixaⱨi Og biz bilǝn jǝng ⱪilƣili qiⱪti; ǝmma biz ularni urup mǝƣlup ⱪilduⱪ;
8 A gba ilẹ̀ wọn a sì fi fún àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase bí ogún.
biz ularning zeminlirini elip Rubǝnlǝr bilǝn Gadlar wǝ Manassǝⱨning yerim ⱪǝbilisigǝ miras ⱪilip bǝrduk.
9 Nítorí náà, ẹ pa májẹ̀mú yìí mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n, kí ẹ̀yin kí ó lè máa rí ire nínú gbogbo ohun tí o bá ń ṣe.
Əmdi silǝr ⱨǝmmǝ ixliringlarda rawaj tepix üqün bu ǝⱨdining sɵzlirini tutup, ularƣa ǝmǝl ⱪilinglar.
10 Gbogbo yín ń dúró lónìí yìí níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ: àwọn olórí yín, àwọn ẹ̀yà yín, àwọn àgbàgbà yín àti àwọn ìjòyè yín, àní gbogbo àwọn ọkùnrin mìíràn ní Israẹli,
Bügün ⱨǝmminglar — kǝbilǝ baxliⱪliringlar, aⱪsⱪalliringlar, ǝmǝldarliringlar, xuningdǝk Israilning ⱨǝmmǝ ǝrliri,
11 pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọ̀ rẹ àti ìyàwó ò rẹ àti àwọn àjèjì tí wọ́n ń gbé ní àgọ́ ọ̀ rẹ, tí ó ké pópòpó igi rẹ, tí ó sì gbé omi rẹ.
kiqik baliliringlar, ayalliringlar, qedirgaⱨinglarda turuwatⱪan musapirlar, xundaⱪla otun kǝsküqiliringlar wǝ su toxuƣuqiliringlarmu, ⱨǝmminglar Pǝrwǝrdigarning aldida ⱨazir turuwatisilǝr;
12 O dúró níhìn-ín yìí kí o lè wọ inú májẹ̀mú pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, májẹ̀mú tí Olúwa ń ṣe pẹ̀lú rẹ lónìí yìí àti tí òun dè pẹ̀lú ìbúra,
mǝⱪsǝt xuki, Pǝrwǝrdigar Hudayinglarning ǝⱨdisigǝ, yǝni Pǝrwǝrdigar Hudayinglar bügün silǝrgǝ bǝrgǝn ⱪǝsimi bilǝn baƣliƣan ǝⱨdigǝ dahil boluxunglar üqündur,
13 láti jẹ́wọ́ rẹ lónìí yìí bí ènìyàn an rẹ̀, pé kí ó lè jẹ́ Ọlọ́run rẹ bí ó ti ṣèlérí àti bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba à rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
Wǝ xuning bilǝn tǝng U silǝrni bügün Ɵzigǝ has bir hǝlⱪ ⱪilip silǝrgǝ wǝdǝ ⱪilƣinidǝk, ata-bowiliringlarƣa, yǝni Ibraⱨim, Isⱨaⱪ wǝ Yaⱪupⱪa ⱪilƣan ⱪǝsimi boyiqǝ ɵzi silǝrgǝ Huda boluxtur.
14 Èmi ń ṣe májẹ̀mú yìí, pẹ̀lú ìbúra rẹ̀, kì í ṣe fún ìwọ nìkan
Lekin mǝn bu ǝⱨdǝ wǝ ⱪǝsǝmni yalƣuz silǝr bilǝnla ǝmǝs,
15 tí ó dúró níbí pẹ̀lú wa lónìí níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ṣùgbọ́n àti fún gbogbo àwọn tí kò sí níbí lónìí.
bǝlki bügün biz bilǝn bu yǝrdǝ Pǝrwǝrdigar Hudayimizning aldida turuwatⱪanlar, xundaⱪla bügün bu yǝrdǝ biz bilǝn birgǝ bolmiƣan kixilǝrning ⱨǝmmisi bilǝnmu tüzüximǝn.
16 Ìwọ fúnra à rẹ mọ bí a ṣe gbé ní Ejibiti àti bí a ṣe kọjá láàrín àwọn orílẹ̀-èdè nílẹ̀ ibí yìí.
(qünki silǝr bizning Misir zeminida ⱪandaⱪ turƣanliⱪimiz wǝ sǝpirimizdǝ ǝllǝrning otturisidin ⱪandaⱪ ɵtüp kǝlginimizni obdan bilisilǝr;
17 Ìwọ rí láàrín wọn ìríra wọn, àwọn ère àti àwọn òrìṣà igi àti ti òkúta, ti fàdákà àti ti wúrà.
Silǝr ularning arisidiki yirginqlik nǝrsilǝrni, ularning arisidiki yaƣaq, tax, altun wǝ kümüxtin yasalƣan butlarni kɵrdünglar).
18 Rí i dájú pé kò sí ọkùnrin tàbí obìnrin, ìdílé tàbí ẹ̀yà láàrín yín lónìí tí ọkàn an rẹ̀ yóò yí kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa láti lọ àti láti sin àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè náà; rí i dájú pé kò sí gbòǹgbò tí ó ń mú irú èso kíkan bẹ́ẹ̀ jáde láàrín yín.
Əⱨdining mǝⱪsiti bolsa, silǝrning aranglardiki ⱨǝrbir ǝr, ⱨǝrbir ayal, ⱨǝrbir ailǝ wǝ ⱨǝrbir ⱪǝbililiringlardin bügün kɵngli Pǝrwǝrdigar Hudayimizdin yenip, xu ǝllǝrning ilaⱨlirining ⱪulluⱪiƣa kirip ketidiƣan ⱨeq kixi bolmisun, xundaⱪla aranglarda ɵt süyi wǝ ǝmǝn qiⱪiridiƣan yiltiz pǝyda bolup ⱪalmisun üqündur.
19 Nígbà tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá gbọ́ ìbúra yìí, kí ó gbàdúrà ìbùkún sórí ara rẹ̀ nígbà náà ni kí ó ronú, “Èmi yóò wà ní àlàáfíà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fi àáké kọ́rí nípa lílọ nínú ọ̀nà ti ara à mi.” Èyí yóò mú àjálù wá sórí ilẹ̀ tútù àti sórí ilẹ̀ gbígbẹ bákan náà
Dǝrwǝⱪǝ xundaⱪ boliduki, xu lǝnǝt sɵzlirini angliƣanda ɵz kɵnglidǝ ɵz-ɵzini bǝht-bǝrikǝtlik sanap: «Mǝn ⱪanqǝ baxbaxtaⱪliⱪ bilǝn mangsammu, tinq-amanliⱪta turiwerimǝn», degüqi xundaⱪ bir kixi bolidu; nǝtijidǝ, nǝm yǝrmu qangⱪaⱪ yǝrgǝ ohxaxla wǝyran ⱪilinidu.
20 Olúwa kì yóò ní ìfẹ́ sí àti dáríjì í; ìbínú àti ìtara rẹ̀ yóò jó ọkùnrin náà. Gbogbo àwọn ègún tí a kọ sínú ìwé yìí yóò wá sórí i rẹ̀, Olúwa yóò sì yọ orúkọ rẹ̀ kúrò lábẹ́ ọ̀run.
Pǝrwǝrdigar mundaⱪ kixini ǝpu ⱪilmaydu, bǝlki Pǝrwǝrdigarning ƣǝzipi bilǝn otluⱪ ⱪǝⱨri tütündǝk xu kixigǝ qüxidu; bu kitabta pütülgǝn ⱨǝmmǝ lǝnǝtlǝr uning bexiƣa qüxidu; Pǝrwǝrdigar uning ismini asmanning tegidin ɵqüridu.
21 Olúwa yóò sì yọ òun nìkan kúrò nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli fún àjálù, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ègún májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé òfin yìí.
Pǝrwǝrdigar bu ⱪanun kitabida pütülgǝn ǝⱨdining ⱨǝmmǝ lǝnǝtliri boyiqǝ Israilning barliⱪ ⱪǝbililiridin uni ayrip qiⱪip, apǝtkǝ muptila ⱪilidu.
22 Àwọn ọmọ rẹ tí ó tẹ̀lé ìran rẹ lẹ́yìn àti àwọn àjèjì tí ó wá láti ilẹ̀ jíjìn yóò rí wàhálà tí ó wá sórí ilẹ̀ àti àwọn ààrùn pẹ̀lú tí Olúwa mú bá ọ.
Kǝlgüsi dǝwr bolsa, yǝni silǝrdin keyin qiⱪidiƣan baliliringlar wǝ xundaⱪla yiraⱪ yurttin kǝlgǝn musapirlar Pǝrwǝrdigar xu zeminning üstigǝ ǝwǝtkǝn balayi’apǝtlǝr bilǝn kesǝllǝrni kɵridu;
23 Gbogbo ilẹ̀ náà yóò di imí-oòrùn, àti iyọ̀, àti ìjóná tí a kò lè fi ọkàn sí, tàbí tí kò lè so èso tàbí tí koríko kò lè hù nínú u rẹ̀, yóò dàbí ìbìṣubú Sodomu àti Gomorra, Adma àti Seboimu, tí Olúwa bì ṣubú nínú ìbínú rẹ̀, àti ìkáàánú rẹ̀.
Pǝrwǝrdigar ƣǝzipi wǝ ⱪǝⱨri bilǝn wǝyran ⱪilƣan Sodom, Gomorra, Admaⱨ wǝ Zǝboimlarning wǝyranqiliⱪidǝk zeminning ⱨǝmmǝ yeri günggürtlixip, xorlixip, kɵyüp kǝtkinini, teriⱪqiliⱪmu, ⱨosulmu bolmiƣinini, ot-qɵpmu ünmiginini kɵridu;
24 Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò béèrè pé, “Kí ló dé tí Olúwa fi ṣe èyí sí ilẹ̀ yìí? Kí ni a lè mọ ooru ìbínú ńlá yìí sí?”
buni kɵrgǝnlǝr, ⱨǝtta ⱨǝmmǝ ǝl-yurt: «Nemixⱪa Pǝrwǝrdigar bu zeminƣa mundaⱪ ⱪilƣandu? Nemixⱪa Uning ƣǝzipi xunqǝ ⱪattiⱪ, ǝxǝddiy bolƣandu?» dǝp soraydu;
25 Ìdáhùn yóò sì jẹ́ báyìí: “Nítorí tí ènìyàn yìí kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀, májẹ̀mú tí ó ti bá wọn dá nígbà tí ó mú wọn jáde wá láti Ejibiti.
andin ularƣa jawab berilip: «Ular ata-bowilirining Hudasi Pǝrwǝrdigarning ularni Misir zeminidin ⱪutⱪuzup qiⱪarƣinida ular bilǝn bekitkǝn ǝⱨdini taxlap,
26 Wọ́n lọ wọ́n sì sin ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún wọn, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀, ọlọ́run tí kò fi fún wọn.
berip ularning nesiwisi bolmiƣan, ɵzimu tonumiƣan ilaⱨlarning ⱪulluⱪiƣa kirip, ularƣa qoⱪunƣini üqün xundaⱪ boldi.
27 Nígbà náà ni ìbínú Olúwa ru sí ilẹ̀ wọn, dé bi pé ó mú gbogbo ègún tí a kọ sínú ìwé yìí wá sórí i rẹ̀.
Mana bu sǝwǝbtin Pǝrwǝrdigarning ƣǝzipi bu zeminƣa tutixip, bu kitabta pütülgǝn ⱨǝmmǝ lǝnǝtni uning üstigǝ kǝltürdi.
28 Ní ìbínú àti ní ìkáàánú, àti ní ìrunú ńlá, Olúwa sì fà wọ́n tu kúrò ní ilẹ̀ wọn, ó sì lé wọn lọ sí ilẹ̀ mìíràn, bí ó ti rí ní òní yìí.”
Xuning üqün Pǝrwǝrdigar ƣǝzǝp, aqqiⱪ wǝ zor ⱪǝⱨr bilǝn ularni yurtidin yulup, baxⱪa bir yurtⱪa taxlidi» — deyilidu.
29 Ohun ìkọ̀kọ̀ jẹ́ ti Olúwa Ọlọ́run wa, ṣùgbọ́n ohun tí a fihàn jẹ́ ti wa àti ti àwọn ọmọ wa títí láé, kí a lè tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
Ⱨǝrbir yoxurun sirlar bolsa Pǝrwǝrdigar Hudayimizningkidur; lekin ⱨǝrⱪandaⱪ axkarilanƣan wǝⱨiylǝr bolsa bu ⱪanunning sɵzlirigǝ ǝmǝl ⱪiliximiz üqün ǝbǝdgiqǝ biz wǝ balilirimizningkidur.

< Deuteronomy 29 >