< Deuteronomy 29 >
1 Èyí ni àwọn ìpinnu májẹ̀mú tí Olúwa pàṣẹ fún Mose láti ṣe pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní Moabu, ní àfikún májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú u wọn ní Horebu.
Ово су речи завета који заповеди Господ Мојсију да учини са синовима Израиљевим у земљи моавској, осим завета који је учинио с њима на Хориву.
2 Mose pàṣẹ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì wí fún wọn wí pé, ojú rẹ ti rí gbogbo ohun tí Olúwa ti ṣe ní Ejibiti sí Farao àti, sí gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀ àti sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
И сазва Мојсије све синове Израиљеве и рече им: Видели сте све што учини Господ на ваше очи у земљи мисирској Фараону и свим слугама његовим и свој земљи његовој,
3 Pẹ̀lú ojú ara rẹ ni ìwọ rí àwọn ìdánwò ńlá náà, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá.
Кушања велика, која видеше очи твоје, оне знаке и чудеса велика.
4 Ṣùgbọ́n títí di àsìkò yìí Olúwa kò fi ọkàn ìmòye tàbí ojú tí ó ń rí tàbí etí tí ó n gbọ́ fún ọ.
Али вам не даде Господ срце, да разумете, ни очи, да видите, и уши да чујете до овог дана.
5 Nígbà ogójì ọdún tí mò ń tọ́ yín ṣọ́nà ní aginjù, aṣọ ọ̀ rẹ kò gbó tàbí bàtà ẹsẹ̀ rẹ.
И водих вас четрдесет година по пустињи; не оветшаше хаљине ваше на вама, нити обућа твоја оветша на ногама твојим.
6 O kò jẹ oúnjẹ tàbí mu wáìnì kankan tàbí rú ohun mímu mìíràn. Mo ṣe èyí kí o lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Хлеба не једосте, ни писте вино и силовито пиће, да бисте познали да сам ја Господ Бог ваш.
7 Nígbà tí o dé ibí yìí, Sihoni ọba Heṣboni àti Ogu ọba Baṣani jáde wá láti bá ọ jà, ṣùgbọ́n a ṣẹ́gun wọn.
И кад дођосте на ово место, изиђе Сион, цар есевонски и Ог, цар васански пред нас у бој; и побисмо их.
8 A gba ilẹ̀ wọn a sì fi fún àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase bí ogún.
И узесмо земљу њихову, и дадосмо је у наследство племену Рувимовом и племену Гадовом и половини племена Манасијиног.
9 Nítorí náà, ẹ pa májẹ̀mú yìí mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n, kí ẹ̀yin kí ó lè máa rí ire nínú gbogbo ohun tí o bá ń ṣe.
Зато држите речи овог завета и творите их, да бисте напредовали у свему што радите.
10 Gbogbo yín ń dúró lónìí yìí níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ: àwọn olórí yín, àwọn ẹ̀yà yín, àwọn àgbàgbà yín àti àwọn ìjòyè yín, àní gbogbo àwọn ọkùnrin mìíràn ní Israẹli,
Ви стојите данас сви пред Господом Богом својим, главари од племена ваших, старешине ваше и управитељи ваши, сви људи Израиљци,
11 pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọ̀ rẹ àti ìyàwó ò rẹ àti àwọn àjèjì tí wọ́n ń gbé ní àgọ́ ọ̀ rẹ, tí ó ké pópòpó igi rẹ, tí ó sì gbé omi rẹ.
Деца ваша, жене ваше, и дошљак који је у вашем логору, и онај који ти дрва сече, и онај који ти воду носи.
12 O dúró níhìn-ín yìí kí o lè wọ inú májẹ̀mú pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, májẹ̀mú tí Olúwa ń ṣe pẹ̀lú rẹ lónìí yìí àti tí òun dè pẹ̀lú ìbúra,
Да пристанеш на завет Господа Бога свог и на клетву Његову, коју учини с тобом данас Господ Бог твој,
13 láti jẹ́wọ́ rẹ lónìí yìí bí ènìyàn an rẹ̀, pé kí ó lè jẹ́ Ọlọ́run rẹ bí ó ti ṣèlérí àti bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba à rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
Да те данас постави себи за народ и да ти Он буде Бог, као што ти је рекао и као што се заклео оцима твојим, Авраму, Исаку и Јакову.
14 Èmi ń ṣe májẹ̀mú yìí, pẹ̀lú ìbúra rẹ̀, kì í ṣe fún ìwọ nìkan
И не с вама самима чиним овај завет и ову клетву;
15 tí ó dúró níbí pẹ̀lú wa lónìí níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ṣùgbọ́n àti fún gbogbo àwọn tí kò sí níbí lónìí.
Него са сваким који данас стоји овде с нама пред Господом Богом нашим, и са сваким који није данас овде с нама.
16 Ìwọ fúnra à rẹ mọ bí a ṣe gbé ní Ejibiti àti bí a ṣe kọjá láàrín àwọn orílẹ̀-èdè nílẹ̀ ibí yìí.
Јер ви знате како смо живели у земљи мисирској, и како смо прошли кроз народе кроз које смо прошли.
17 Ìwọ rí láàrín wọn ìríra wọn, àwọn ère àti àwọn òrìṣà igi àti ti òkúta, ti fàdákà àti ti wúrà.
И видели сте гадове њихове и идоле њихове од дрвета и од камена, од сребра и од злата, који су код њих.
18 Rí i dájú pé kò sí ọkùnrin tàbí obìnrin, ìdílé tàbí ẹ̀yà láàrín yín lónìí tí ọkàn an rẹ̀ yóò yí kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa láti lọ àti láti sin àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè náà; rí i dájú pé kò sí gbòǹgbò tí ó ń mú irú èso kíkan bẹ́ẹ̀ jáde láàrín yín.
Нека не буде међу вама човека ни жене ни породице ни племена, коме би се срце одвратило данас од Господа Бога нашег, да иде да служи боговима оних народа; нека не буде међу вама корена на коме би растао отров или пелен.
19 Nígbà tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá gbọ́ ìbúra yìí, kí ó gbàdúrà ìbùkún sórí ara rẹ̀ nígbà náà ni kí ó ronú, “Èmi yóò wà ní àlàáfíà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fi àáké kọ́rí nípa lílọ nínú ọ̀nà ti ara à mi.” Èyí yóò mú àjálù wá sórí ilẹ̀ tútù àti sórí ilẹ̀ gbígbẹ bákan náà
И чувши речи ове клетве да се не похвали у срцу свом говорећи: Бићу миран ако идем за оним што у срцу свом смислим, додајући пијанство жеђи.
20 Olúwa kì yóò ní ìfẹ́ sí àti dáríjì í; ìbínú àti ìtara rẹ̀ yóò jó ọkùnrin náà. Gbogbo àwọn ègún tí a kọ sínú ìwé yìí yóò wá sórí i rẹ̀, Olúwa yóò sì yọ orúkọ rẹ̀ kúrò lábẹ́ ọ̀run.
Неће Господ опростити таквоме, него ће се онда распалити гнев Господњи и ревност Његова на таквог човека, и пашће на њ сва клетва која је написана у овој књизи, и истребиће Господ име његово под небом.
21 Olúwa yóò sì yọ òun nìkan kúrò nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli fún àjálù, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ègún májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé òfin yìí.
И одлучиће га Господ на зло од свих племена Израиљевих по свим клетвама завета написаног у књизи овог закона.
22 Àwọn ọmọ rẹ tí ó tẹ̀lé ìran rẹ lẹ́yìn àti àwọn àjèjì tí ó wá láti ilẹ̀ jíjìn yóò rí wàhálà tí ó wá sórí ilẹ̀ àti àwọn ààrùn pẹ̀lú tí Olúwa mú bá ọ.
Тада ће говорити потоњи нараштај, синови ваши који настану иза вас, и дошљак који дође из далеке земље, кад виде зла у земљи овој и болести, које ће Господ пустити на њу,
23 Gbogbo ilẹ̀ náà yóò di imí-oòrùn, àti iyọ̀, àti ìjóná tí a kò lè fi ọkàn sí, tàbí tí kò lè so èso tàbí tí koríko kò lè hù nínú u rẹ̀, yóò dàbí ìbìṣubú Sodomu àti Gomorra, Adma àti Seboimu, tí Olúwa bì ṣubú nínú ìbínú rẹ̀, àti ìkáàánú rẹ̀.
Земљу ову опаљену сумпором и сољу, где се не сеје нити шта ниче нити на њој расте каква биљка, као где је пропао Содом и Гомор, Адама и Севојим, које затре Господ у гневу свом и у јарости својој,
24 Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò béèrè pé, “Kí ló dé tí Olúwa fi ṣe èyí sí ilẹ̀ yìí? Kí ni a lè mọ ooru ìbínú ńlá yìí sí?”
Говориће сви народи: Зашто учини ово Господ од ове земље? Каква је то жестина великог гнева?
25 Ìdáhùn yóò sì jẹ́ báyìí: “Nítorí tí ènìyàn yìí kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀, májẹ̀mú tí ó ti bá wọn dá nígbà tí ó mú wọn jáde wá láti Ejibiti.
И одговараће се: Јер оставише завет Господа Бога отаца својих, који учини с њима кад их изведе из земље мисирске.
26 Wọ́n lọ wọ́n sì sin ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún wọn, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀, ọlọ́run tí kò fi fún wọn.
Јер идоше и служише другим боговима и поклањаше им се, боговима којих не знаше и који им ништа не дадоше.
27 Nígbà náà ni ìbínú Olúwa ru sí ilẹ̀ wọn, dé bi pé ó mú gbogbo ègún tí a kọ sínú ìwé yìí wá sórí i rẹ̀.
Зато се Господ разгневи на ту земљу, и пусти на њу сва проклетства написана у овој књизи.
28 Ní ìbínú àti ní ìkáàánú, àti ní ìrunú ńlá, Olúwa sì fà wọ́n tu kúrò ní ilẹ̀ wọn, ó sì lé wọn lọ sí ilẹ̀ mìíràn, bí ó ti rí ní òní yìí.”
И истреби их Господ Бог из земље њихове у гневу и јарости и љутини великој, и избаци их у другу земљу, као што се види данас.
29 Ohun ìkọ̀kọ̀ jẹ́ ti Olúwa Ọlọ́run wa, ṣùgbọ́n ohun tí a fihàn jẹ́ ti wa àti ti àwọn ọmọ wa títí láé, kí a lè tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
Шта је тајно оно је Господа Бога нашег, а јавно је наше и синова наших довека, да бисмо извршавали све речи овог закона.