< Deuteronomy 29 >

1 Èyí ni àwọn ìpinnu májẹ̀mú tí Olúwa pàṣẹ fún Mose láti ṣe pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní Moabu, ní àfikún májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú u wọn ní Horebu.
To są słowa przymierza, które PAN nakazał Mojżeszowi zawrzeć z synami Izraela w ziemi Moabu, oprócz przymierza, które zawarł z nimi na Horebie.
2 Mose pàṣẹ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì wí fún wọn wí pé, ojú rẹ ti rí gbogbo ohun tí Olúwa ti ṣe ní Ejibiti sí Farao àti, sí gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀ àti sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
I Mojżesz zwołał cały Izrael, i przemówił do nich: Widzieliście wszystko, co PAN uczynił na waszych oczach w ziemi Egiptu faraonowi, wszystkim jego sługom i całej jego ziemi:
3 Pẹ̀lú ojú ara rẹ ni ìwọ rí àwọn ìdánwò ńlá náà, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá.
Te wielkie próby, które widziały twoje oczy, znaki i wielkie cuda.
4 Ṣùgbọ́n títí di àsìkò yìí Olúwa kò fi ọkàn ìmòye tàbí ojú tí ó ń rí tàbí etí tí ó n gbọ́ fún ọ.
Ale PAN nie dał wam serca do zrozumienia ani oczu do patrzenia, ani uszu do słuchania aż do dziś.
5 Nígbà ogójì ọdún tí mò ń tọ́ yín ṣọ́nà ní aginjù, aṣọ ọ̀ rẹ kò gbó tàbí bàtà ẹsẹ̀ rẹ.
I prowadziłem was przez czterdzieści lat po pustyni. Wasze szaty nie zniszczyły się na was i wasze obuwie na waszych nogach się nie zużyło.
6 O kò jẹ oúnjẹ tàbí mu wáìnì kankan tàbí rú ohun mímu mìíràn. Mo ṣe èyí kí o lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Nie jedliście chleba, nie piliście wina i mocnego napoju, abyście poznali, że ja jestem PAN, wasz Bóg.
7 Nígbà tí o dé ibí yìí, Sihoni ọba Heṣboni àti Ogu ọba Baṣani jáde wá láti bá ọ jà, ṣùgbọ́n a ṣẹ́gun wọn.
A gdy przyszliście na to miejsce, Sichon, król Cheszbonu, i Og, król Baszanu, wyruszyli przeciwko nam do walki, i pobiliśmy ich.
8 A gba ilẹ̀ wọn a sì fi fún àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase bí ogún.
I wzięliśmy ich ziemię, i daliśmy ją jako dziedzictwo Rubenitom, Gadytom i połowie pokolenia Manassesa.
9 Nítorí náà, ẹ pa májẹ̀mú yìí mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n, kí ẹ̀yin kí ó lè máa rí ire nínú gbogbo ohun tí o bá ń ṣe.
Przestrzegajcie więc słów tego przymierza i wypełniajcie je, aby się wam szczęśliwie powodziło we wszystkim, co będziecie czynić.
10 Gbogbo yín ń dúró lónìí yìí níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ: àwọn olórí yín, àwọn ẹ̀yà yín, àwọn àgbàgbà yín àti àwọn ìjòyè yín, àní gbogbo àwọn ọkùnrin mìíràn ní Israẹli,
Stoicie dziś wszyscy przed PANEM, swoim Bogiem: naczelnicy waszych pokoleń, wasi starsi, wasi przełożeni, wszyscy mężczyźni Izraela;
11 pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọ̀ rẹ àti ìyàwó ò rẹ àti àwọn àjèjì tí wọ́n ń gbé ní àgọ́ ọ̀ rẹ, tí ó ké pópòpó igi rẹ, tí ó sì gbé omi rẹ.
Wasze dzieci, wasze żony i przybysz, który [mieszka] w twoim obozie; od tego, który rąbie drwa, po tego, który czerpie wodę;
12 O dúró níhìn-ín yìí kí o lè wọ inú májẹ̀mú pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, májẹ̀mú tí Olúwa ń ṣe pẹ̀lú rẹ lónìí yìí àti tí òun dè pẹ̀lú ìbúra,
Aby wejść w przymierze z PANEM, swoim Bogiem, i w jego przysięgę, którą PAN, twój Bóg, zawiera dziś z tobą;
13 láti jẹ́wọ́ rẹ lónìí yìí bí ènìyàn an rẹ̀, pé kí ó lè jẹ́ Ọlọ́run rẹ bí ó ti ṣèlérí àti bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba à rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
Aby cię dziś ustanowić dla siebie ludem i żeby on sam był dla ciebie Bogiem, tak jak ci powiedział i tak jak poprzysiągł twoim ojcom: Abrahamowi, Izaakowi i Jakubowi.
14 Èmi ń ṣe májẹ̀mú yìí, pẹ̀lú ìbúra rẹ̀, kì í ṣe fún ìwọ nìkan
Nie tylko z wami zawieram to przymierze i tę przysięgę;
15 tí ó dúró níbí pẹ̀lú wa lónìí níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ṣùgbọ́n àti fún gbogbo àwọn tí kò sí níbí lónìí.
Lecz z każdym, kto dziś stoi tu z nami przed PANEM, naszym Bogiem, i z każdym, kogo tu dziś z nami nie ma.
16 Ìwọ fúnra à rẹ mọ bí a ṣe gbé ní Ejibiti àti bí a ṣe kọjá láàrín àwọn orílẹ̀-èdè nílẹ̀ ibí yìí.
Wy bowiem wiecie, jak mieszkaliśmy w ziemi Egiptu i jak przechodziliśmy wśród narodów, które minęliśmy;
17 Ìwọ rí láàrín wọn ìríra wọn, àwọn ère àti àwọn òrìṣà igi àti ti òkúta, ti fàdákà àti ti wúrà.
I widzieliście ich obrzydliwości i posągi z drewna i kamienia, ze srebra i złota, które są u nich.
18 Rí i dájú pé kò sí ọkùnrin tàbí obìnrin, ìdílé tàbí ẹ̀yà láàrín yín lónìí tí ọkàn an rẹ̀ yóò yí kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa láti lọ àti láti sin àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè náà; rí i dájú pé kò sí gbòǹgbò tí ó ń mú irú èso kíkan bẹ́ẹ̀ jáde láàrín yín.
Niech nie będzie wśród was mężczyzny ani kobiety, ani rodziny, ani pokolenia, których serce odwróciłoby się dziś od PANA, naszego Boga, by iść i służyć bogom tych narodów i żeby nie było wśród was korzenia wydającego żółć i piołun;
19 Nígbà tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá gbọ́ ìbúra yìí, kí ó gbàdúrà ìbùkún sórí ara rẹ̀ nígbà náà ni kí ó ronú, “Èmi yóò wà ní àlàáfíà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fi àáké kọ́rí nípa lílọ nínú ọ̀nà ti ara à mi.” Èyí yóò mú àjálù wá sórí ilẹ̀ tútù àti sórí ilẹ̀ gbígbẹ bákan náà
Który gdy usłyszy słowa tego przekleństwa, pobłogosławi sobie w sercu, mówiąc: Będę miał pokój, chociaż będę postępował według zdania mego serca, dodając pijaństwo do pragnienia.
20 Olúwa kì yóò ní ìfẹ́ sí àti dáríjì í; ìbínú àti ìtara rẹ̀ yóò jó ọkùnrin náà. Gbogbo àwọn ègún tí a kọ sínú ìwé yìí yóò wá sórí i rẹ̀, Olúwa yóò sì yọ orúkọ rẹ̀ kúrò lábẹ́ ọ̀run.
PAN nie zechce mu przebaczyć, lecz zapali się gniew PANA i jego zazdrość przeciwko temu człowiekowi, spadną na niego wszystkie przekleństwa, które są zapisane w tej księdze, i PAN wymaże jego imię spod nieba.
21 Olúwa yóò sì yọ òun nìkan kúrò nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli fún àjálù, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ègún májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé òfin yìí.
I PAN go oddzieli ku złemu ze wszystkich pokoleń Izraela według wszystkich przekleństw przymierza zapisanych w księdze tego Prawa.
22 Àwọn ọmọ rẹ tí ó tẹ̀lé ìran rẹ lẹ́yìn àti àwọn àjèjì tí ó wá láti ilẹ̀ jíjìn yóò rí wàhálà tí ó wá sórí ilẹ̀ àti àwọn ààrùn pẹ̀lú tí Olúwa mú bá ọ.
A wasze przyszłe pokolenie, wasi synowie, którzy powstaną po was, i cudzoziemiec, który przyjdzie z dalekiej ziemi, powiedzą, gdy zobaczą plagi tej ziemi i choroby, którymi PAN ją dotknął;
23 Gbogbo ilẹ̀ náà yóò di imí-oòrùn, àti iyọ̀, àti ìjóná tí a kò lè fi ọkàn sí, tàbí tí kò lè so èso tàbí tí koríko kò lè hù nínú u rẹ̀, yóò dàbí ìbìṣubú Sodomu àti Gomorra, Adma àti Seboimu, tí Olúwa bì ṣubú nínú ìbínú rẹ̀, àti ìkáàánú rẹ̀.
Bo siarka i sól wypalą całą tę ziemię, że nie będzie obsiewana ani też nie będzie wydawać owocu i nie urośnie na niej żadna trawa jak w przypadku zniszczenia Sodomy i Gomory, Admy i Seboim, które PAN zniszczył w swoim gniewie i zapalczywości;
24 Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò béèrè pé, “Kí ló dé tí Olúwa fi ṣe èyí sí ilẹ̀ yìí? Kí ni a lè mọ ooru ìbínú ńlá yìí sí?”
A zapytają wszystkie narody: Dlaczego PAN tak postąpił z tą ziemią? Cóż to za żar tej wielkiej zapalczywości?
25 Ìdáhùn yóò sì jẹ́ báyìí: “Nítorí tí ènìyàn yìí kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀, májẹ̀mú tí ó ti bá wọn dá nígbà tí ó mú wọn jáde wá láti Ejibiti.
I odpowiedzą: Ponieważ porzucili przymierze PANA, Boga swych ojców, które zawarł z nimi, gdy ich wyprowadził z ziemi Egiptu.
26 Wọ́n lọ wọ́n sì sin ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún wọn, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀, ọlọ́run tí kò fi fún wọn.
Poszli bowiem służyć innym bogom i oddali im pokłon – bogom, których nie znali i których im nie przydzielił.
27 Nígbà náà ni ìbínú Olúwa ru sí ilẹ̀ wọn, dé bi pé ó mú gbogbo ègún tí a kọ sínú ìwé yìí wá sórí i rẹ̀.
Dlatego gniew PANA zapłonął przeciw tej ziemi, aby sprowadzić na nią wszelkie przekleństwa zapisane w tej księdze.
28 Ní ìbínú àti ní ìkáàánú, àti ní ìrunú ńlá, Olúwa sì fà wọ́n tu kúrò ní ilẹ̀ wọn, ó sì lé wọn lọ sí ilẹ̀ mìíràn, bí ó ti rí ní òní yìí.”
I PAN wykorzenił ich z ich ziemi w gniewie i zapalczywości oraz w wielkim oburzeniu i wyrzucił ich do obcej ziemi, jak to dziś [widzicie].
29 Ohun ìkọ̀kọ̀ jẹ́ ti Olúwa Ọlọ́run wa, ṣùgbọ́n ohun tí a fihàn jẹ́ ti wa àti ti àwọn ọmọ wa títí láé, kí a lè tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
Rzeczy tajemne [należą] do PANA, naszego Boga, a objawione – do nas i naszych synów na wieki, abyśmy wypełniali wszystkie słowa tego prawa.

< Deuteronomy 29 >