< Deuteronomy 29 >

1 Èyí ni àwọn ìpinnu májẹ̀mú tí Olúwa pàṣẹ fún Mose láti ṣe pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní Moabu, ní àfikún májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú u wọn ní Horebu.
TUHAN memberikan semua hukum dan penjelasan tadi kepada Musa ketika umat Israel masih berkemah di wilayah Moab. Hal-hal itu menjelaskan perjanjian dengan TUHAN yang sudah ditetapkan di gunung Sinai.
2 Mose pàṣẹ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì wí fún wọn wí pé, ojú rẹ ti rí gbogbo ohun tí Olúwa ti ṣe ní Ejibiti sí Farao àti, sí gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀ àti sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
Musa memanggil semua orang Israel dan berkata kepada mereka, “Di Mesir, kalian sudah menyaksikan semua yang TUHAN lakukan terhadap raja Mesir, para pejabatnya, dan seluruh rakyatnya.
3 Pẹ̀lú ojú ara rẹ ni ìwọ rí àwọn ìdánwò ńlá náà, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá.
Dengan matamu sendiri, kalian sudah melihat berbagai bencana dan keajaiban yang TUHAN lakukan.
4 Ṣùgbọ́n títí di àsìkò yìí Olúwa kò fi ọkàn ìmòye tàbí ojú tí ó ń rí tàbí etí tí ó n gbọ́ fún ọ.
Tetapi sampai hari ini, TUHAN belum membuka pikiranmu agar mengerti makna dari semua yang sudah kalian alami.
5 Nígbà ogójì ọdún tí mò ń tọ́ yín ṣọ́nà ní aginjù, aṣọ ọ̀ rẹ kò gbó tàbí bàtà ẹsẹ̀ rẹ.
TUHAN sudah memberi tahu kalian, ‘Selama empat puluh tahun Aku memimpin kalian melewati padang belantara, pakaian dan alas kaki yang kalian pakai tidak menjadi usang.
6 O kò jẹ oúnjẹ tàbí mu wáìnì kankan tàbí rú ohun mímu mìíràn. Mo ṣe èyí kí o lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Selama itu, kalian juga tidak makan roti, minum anggur, ataupun menikmati bir, tetapi Aku menyediakan segala sesuatu yang kalian perlukan. Demikianlah Aku membuktikan bahwa Akulah TUHAN Allahmu.’”
7 Nígbà tí o dé ibí yìí, Sihoni ọba Heṣboni àti Ogu ọba Baṣani jáde wá láti bá ọ jà, ṣùgbọ́n a ṣẹ́gun wọn.
Selanjutnya kata Musa, “Ketika kita sampai di tempat ini, Raja Sihon dari Hesbon dan Raja Og dari Basan menyerang kita, tetapi kita mengalahkan mereka.
8 A gba ilẹ̀ wọn a sì fi fún àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase bí ogún.
Kita merebut negeri mereka dan membagikannya kepada suku Ruben, suku Gad, dan separuh suku Manasye sebagai milik pusaka mereka.
9 Nítorí náà, ẹ pa májẹ̀mú yìí mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n, kí ẹ̀yin kí ó lè máa rí ire nínú gbogbo ohun tí o bá ń ṣe.
“Karena itu taatilah semua ketentuan perjanjian kita dengan TUHAN, supaya Dia memberkati segala usahamu.
10 Gbogbo yín ń dúró lónìí yìí níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ: àwọn olórí yín, àwọn ẹ̀yà yín, àwọn àgbàgbà yín àti àwọn ìjòyè yín, àní gbogbo àwọn ọkùnrin mìíràn ní Israẹli,
Hari ini, kalian semua— termasuk para pemimpin suku, tua-tua, perwira, dan semua laki-laki Israel— berdiri di hadapan TUHAN Allah kita.
11 pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọ̀ rẹ àti ìyàwó ò rẹ àti àwọn àjèjì tí wọ́n ń gbé ní àgọ́ ọ̀ rẹ, tí ó ké pópòpó igi rẹ, tí ó sì gbé omi rẹ.
Hadir juga bersama kita anak-anak dan istri-istri kalian, juga semua pendatang yang tinggal di antara kita, yang bekerja memotong kayu dan menimba air.
12 O dúró níhìn-ín yìí kí o lè wọ inú májẹ̀mú pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, májẹ̀mú tí Olúwa ń ṣe pẹ̀lú rẹ lónìí yìí àti tí òun dè pẹ̀lú ìbúra,
Kalian berkumpul di sini untuk menyatakan bersedia menerima semua ketentuan dalam perjanjian yang TUHAN Allah sahkan dengan kita hari ini.
13 láti jẹ́wọ́ rẹ lónìí yìí bí ènìyàn an rẹ̀, pé kí ó lè jẹ́ Ọlọ́run rẹ bí ó ti ṣèlérí àti bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba à rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
Dengan mengikat perjanjian ini, kita diteguhkan sebagai umat-Nya, dan kita mengakui bahwa TUHAN adalah Allah kita. Dengan demikian, kita menggenapi yang sudah TUHAN katakan kepada kita dan perjanjian yang Dia sahkan dengan nenek moyang kita Abraham, Isak, dan Yakub.
14 Èmi ń ṣe májẹ̀mú yìí, pẹ̀lú ìbúra rẹ̀, kì í ṣe fún ìwọ nìkan
TUHAN mengikat perjanjian ini bukan hanya dengan kita saja
15 tí ó dúró níbí pẹ̀lú wa lónìí níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ṣùgbọ́n àti fún gbogbo àwọn tí kò sí níbí lónìí.
yang sekarang hadir di hadapan-Nya, tetapi juga dengan keturunan kita di masa yang akan datang.
16 Ìwọ fúnra à rẹ mọ bí a ṣe gbé ní Ejibiti àti bí a ṣe kọjá láàrín àwọn orílẹ̀-èdè nílẹ̀ ibí yìí.
“Kalian semua tahu bagaimana dulu bangsa kita tinggal di Mesir dan kemudian berjalan melewati wilayah bangsa-bangsa lain.
17 Ìwọ rí láàrín wọn ìríra wọn, àwọn ère àti àwọn òrìṣà igi àti ti òkúta, ti fàdákà àti ti wúrà.
Kalian juga sudah melihat patung-patung berhala mereka yang terbuat dari kayu, batu, perak, dan emas. Semua itu sangat menjijikan.
18 Rí i dájú pé kò sí ọkùnrin tàbí obìnrin, ìdílé tàbí ẹ̀yà láàrín yín lónìí tí ọkàn an rẹ̀ yóò yí kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa láti lọ àti láti sin àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè náà; rí i dájú pé kò sí gbòǹgbò tí ó ń mú irú èso kíkan bẹ́ẹ̀ jáde láàrín yín.
Pastikan jangan sampai ada di antara kalian, baik laki-laki, perempuan, keluarga, maupun suku, yang meninggalkan TUHAN dengan menyembah dewa-dewa bangsa lain. Orang-orang yang berbuat demikian dapat menjadi pengaruh buruk di antara kalian, seperti tanaman beracun yang meracuni orang-orang sehingga banyak yang tertular oleh kejahatannya.
19 Nígbà tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá gbọ́ ìbúra yìí, kí ó gbàdúrà ìbùkún sórí ara rẹ̀ nígbà náà ni kí ó ronú, “Èmi yóò wà ní àlàáfíà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fi àáké kọ́rí nípa lílọ nínú ọ̀nà ti ara à mi.” Èyí yóò mú àjálù wá sórí ilẹ̀ tútù àti sórí ilẹ̀ gbígbẹ bákan náà
“Apabila ada orang bebal di antara kalian yang mendengar ketentuan perjanjian ini dan berkata dalam hatinya, ‘Aku akan selamat meskipun hidup sesuka hatiku sendiri,’ maka hal itu akan mendatangkan bencana atas kalian semua, yang jahat maupun yang baik.
20 Olúwa kì yóò ní ìfẹ́ sí àti dáríjì í; ìbínú àti ìtara rẹ̀ yóò jó ọkùnrin náà. Gbogbo àwọn ègún tí a kọ sínú ìwé yìí yóò wá sórí i rẹ̀, Olúwa yóò sì yọ orúkọ rẹ̀ kúrò lábẹ́ ọ̀run.
TUHAN tidak akan bersedia mengampuni orang bebal seperti itu. TUHAN akan memisahkan orang itu dari antara suku-suku Israel, lalu mengobarkan cemburu dan amarah-Nya ke atas orang itu seperti api yang membakar habis. Semua kutuk perjanjian yang tertulis dalam kitab Taurat ini akan menimpa dia dan keturunannya, sampai TUHAN melenyapkan mereka.
21 Olúwa yóò sì yọ òun nìkan kúrò nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli fún àjálù, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ègún májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé òfin yìí.
22 Àwọn ọmọ rẹ tí ó tẹ̀lé ìran rẹ lẹ́yìn àti àwọn àjèjì tí ó wá láti ilẹ̀ jíjìn yóò rí wàhálà tí ó wá sórí ilẹ̀ àti àwọn ààrùn pẹ̀lú tí Olúwa mú bá ọ.
“Lama kelamaan, berbagai kutukan bencana dan wabah penyakit yang berulang kali ditimpakan akan berdampak. Tanah di seluruh negeri Israel akan rusak oleh belerang dan garam sehingga tidak bisa ditanami apa pun, bahkan rumput liar pun tidak bisa tumbuh. Negeri itu akan menjadi seperti kota Sodom, Gomora, Adma, dan Zeboim, yang dihancurkan TUHAN dalam murka-Nya. Lalu pengunjung dari bangsa lain bahkan sisa keturunanmu yang masih hidup
23 Gbogbo ilẹ̀ náà yóò di imí-oòrùn, àti iyọ̀, àti ìjóná tí a kò lè fi ọkàn sí, tàbí tí kò lè so èso tàbí tí koríko kò lè hù nínú u rẹ̀, yóò dàbí ìbìṣubú Sodomu àti Gomorra, Adma àti Seboimu, tí Olúwa bì ṣubú nínú ìbínú rẹ̀, àti ìkáàánú rẹ̀.
24 Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò béèrè pé, “Kí ló dé tí Olúwa fi ṣe èyí sí ilẹ̀ yìí? Kí ni a lè mọ ooru ìbínú ńlá yìí sí?”
akan bertanya, ‘Mengapa TUHAN, Allah nenek moyang mereka, berbuat demikian pada negeri ini? Apa yang membuat-Nya begitu murka?’ “Maka orang-orang akan menjawab, ‘Ini terjadi karena bangsa Israel tidak lagi hidup sesuai dengan hukum dan ketentuan perjanjian yang mereka sahkan dengan TUHAN ketika Dia membawa mereka keluar dari Mesir.
25 Ìdáhùn yóò sì jẹ́ báyìí: “Nítorí tí ènìyàn yìí kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀, májẹ̀mú tí ó ti bá wọn dá nígbà tí ó mú wọn jáde wá láti Ejibiti.
26 Wọ́n lọ wọ́n sì sin ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún wọn, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀, ọlọ́run tí kò fi fún wọn.
Mereka menyimpang dengan sujud menyembah dewa-dewa yang tidak pernah mereka kenal sebelumnya, dan yang dilarang oleh TUHAN.
27 Nígbà náà ni ìbínú Olúwa ru sí ilẹ̀ wọn, dé bi pé ó mú gbogbo ègún tí a kọ sínú ìwé yìí wá sórí i rẹ̀.
Perbuatan itulah yang membuat murka TUHAN berkobar sehingga Dia mengutuk negeri mereka, sesuai peringatan yang sudah tertulis dalam kitab ini.
28 Ní ìbínú àti ní ìkáàánú, àti ní ìrunú ńlá, Olúwa sì fà wọ́n tu kúrò ní ilẹ̀ wọn, ó sì lé wọn lọ sí ilẹ̀ mìíràn, bí ó ti rí ní òní yìí.”
Akhirnya dalam amarah-Nya, TUHAN mencabut orang Israel dari negeri mereka dan membuang mereka ke negeri lain, di mana mereka tinggal sampai hari ini.’”
29 Ohun ìkọ̀kọ̀ jẹ́ ti Olúwa Ọlọ́run wa, ṣùgbọ́n ohun tí a fihàn jẹ́ ti wa àti ti àwọn ọmọ wa títí láé, kí a lè tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
Sebagai penutup, Musa berkata, “Ada hal-hal yang TUHAN Allah rahasiakan dari kita. Namun, untuk segala hal yang sudah Dia nyatakan, kita dan keturunan kita bertanggung jawab melakukannya. Itu berarti kita harus menaati segala hukum dan ketentuan dalam kitab ini.”

< Deuteronomy 29 >