< Deuteronomy 29 >

1 Èyí ni àwọn ìpinnu májẹ̀mú tí Olúwa pàṣẹ fún Mose láti ṣe pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní Moabu, ní àfikún májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú u wọn ní Horebu.
Dagitoy dagiti sasao nga imbilin ni Yahweh kenni Moises nga ibagana kadagiti tattao ti Israel idiay daga ti Moab, dagiti sasao a nainayon iti tulag nga inaramidna kadakuada idiay Horeb.
2 Mose pàṣẹ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì wí fún wọn wí pé, ojú rẹ ti rí gbogbo ohun tí Olúwa ti ṣe ní Ejibiti sí Farao àti, sí gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀ àti sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
Inayaban ni Moises dagiti amin nga Israelita ket kinunana kadakuada. “Nakitayo amin a banag nga inaramid ni Yahweh iti sangoanan dagiti matayo idiay daga ti Egipto kenni Paraon, kadagiti amin nga adipenna, ken kadagiti amin a dagana—
3 Pẹ̀lú ojú ara rẹ ni ìwọ rí àwọn ìdánwò ńlá náà, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá.
dagiti napalalo a panagsagaba a nakita dagiti matayo, dagiti pagilasinan, ken dagitoy kasta unay a nakakaskasdaaw.
4 Ṣùgbọ́n títí di àsìkò yìí Olúwa kò fi ọkàn ìmòye tàbí ojú tí ó ń rí tàbí etí tí ó n gbọ́ fún ọ.
Ngem agingga ita, saannakayo nga inikkan ni Yahweh ti puso a mangammo, mata a mangkita, wenno lapayag a mangdengngeg.
5 Nígbà ogójì ọdún tí mò ń tọ́ yín ṣọ́nà ní aginjù, aṣọ ọ̀ rẹ kò gbó tàbí bàtà ẹsẹ̀ rẹ.
Indalankayo iti las-ud iti 40 a tawen idiay let-ang, saan a dimmaan dagiti kawesyo ken saan a dimmaan dagiti sandalyasyo kadagiti sakayo.
6 O kò jẹ oúnjẹ tàbí mu wáìnì kankan tàbí rú ohun mímu mìíràn. Mo ṣe èyí kí o lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Saankayo a nangan ti aniaman a tinapay wenno imminum ti aniaman nga arak wenno naingel a mainum, tapno maamoanyo a Siak ni Yahweh a Diosyo.
7 Nígbà tí o dé ibí yìí, Sihoni ọba Heṣboni àti Ogu ọba Baṣani jáde wá láti bá ọ jà, ṣùgbọ́n a ṣẹ́gun wọn.
Idi dimtengkayo ditoy a disso, rimmuar ni Sehon nga ari ti Hesbon ken ni Og nga ari ti Basan a manggubat kadatayo ket kinabiltayo ida.
8 A gba ilẹ̀ wọn a sì fi fún àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase bí ogún.
Innalatayo ti dagada ken intedtayo a kas tawid kadagiti Rubenitas, kadagiti Gaditas, ken ti kaguddua ti tribu ni Manases.
9 Nítorí náà, ẹ pa májẹ̀mú yìí mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n, kí ẹ̀yin kí ó lè máa rí ire nínú gbogbo ohun tí o bá ń ṣe.
Salimetmetanyo ngarud dagiti sasao daytoy a tulag ken aramidenyo dagitoy, tapno rumang-aykayo iti amin nga aramidenyo.
10 Gbogbo yín ń dúró lónìí yìí níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ: àwọn olórí yín, àwọn ẹ̀yà yín, àwọn àgbàgbà yín àti àwọn ìjòyè yín, àní gbogbo àwọn ọkùnrin mìíràn ní Israẹli,
Agtakderkayo amin ita, iti sangoanan ni Yahweh a Diosyo; dagiti papanguloenyo, dagiti tribuyo, dagiti panglakayenyo, ken dagiti opisialesyo— dagiti amin a lallaki ti Israel,
11 pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọ̀ rẹ àti ìyàwó ò rẹ àti àwọn àjèjì tí wọ́n ń gbé ní àgọ́ ọ̀ rẹ, tí ó ké pópòpó igi rẹ, tí ó sì gbé omi rẹ.
dagiti ubbingyo, dagiti assawayo, ken iti gangganaet a kaduayo iti kampoyo, manipud kadagiti agpukpukan kadagiti kayoyo agpapan kadagiti agsaksakdo iti danumyo.
12 O dúró níhìn-ín yìí kí o lè wọ inú májẹ̀mú pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, májẹ̀mú tí Olúwa ń ṣe pẹ̀lú rẹ lónìí yìí àti tí òun dè pẹ̀lú ìbúra,
Addakayo ditoy tapno makitulagkayo kenni Yahweh a Diosyo ken iti sapata nga ar-aramiden ni Yahweh kadakayo ita nga aldaw,
13 láti jẹ́wọ́ rẹ lónìí yìí bí ènìyàn an rẹ̀, pé kí ó lè jẹ́ Ọlọ́run rẹ bí ó ti ṣèlérí àti bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba à rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
tapno aramidennakayo a tattaona ita nga aldaw, ken agbalin isuna a Dios kadakayo, kas insaona kadakayo, ken kas ti insapatana kadagiti kapuonanyo, a ni Abraham, ni Isaac, ken ni Jacob.
14 Èmi ń ṣe májẹ̀mú yìí, pẹ̀lú ìbúra rẹ̀, kì í ṣe fún ìwọ nìkan
Ken saan laeng a dakayo ti pakitulagak ken pagisapataak
15 tí ó dúró níbí pẹ̀lú wa lónìí níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ṣùgbọ́n àti fún gbogbo àwọn tí kò sí níbí lónìí.
— kadagiti amin a makipagtaktakder kadatayo ita ditoy iti sangoanan ni Yahweh a Diostayo, ngem kasta met dagiti pay awan kadatayo ditoy ita.
16 Ìwọ fúnra à rẹ mọ bí a ṣe gbé ní Ejibiti àti bí a ṣe kọjá láàrín àwọn orílẹ̀-èdè nílẹ̀ ibí yìí.
Ammoyo ti panagnaedtayo iti daga ti Egipto, ken ti idadatengtayo iti tengnga dagiti nasion a naglasatanyo.
17 Ìwọ rí láàrín wọn ìríra wọn, àwọn ère àti àwọn òrìṣà igi àti ti òkúta, ti fàdákà àti ti wúrà.
Nakitayo dagiti makarimon a banbanag kadakuada: dagiti didiosenda a kayo ken bato, pirak ken balitok, nga adda kadakuada,
18 Rí i dájú pé kò sí ọkùnrin tàbí obìnrin, ìdílé tàbí ẹ̀yà láàrín yín lónìí tí ọkàn an rẹ̀ yóò yí kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa láti lọ àti láti sin àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè náà; rí i dájú pé kò sí gbòǹgbò tí ó ń mú irú èso kíkan bẹ́ẹ̀ jáde láàrín yín.
tapno awanto koma kadakayo ti aniaman a lalaki, babai, pamilia, wenno tribo a tumallikod ti pusona ita nga aldaw manipud kenni Yahweh a Diostayo, a mapan agdayaw kadagiti dios dagitoy a nasion—tapno awan koma kadakayo ti aniaman a ramut a makasabidong ken napait a kayo,
19 Nígbà tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá gbọ́ ìbúra yìí, kí ó gbàdúrà ìbùkún sórí ara rẹ̀ nígbà náà ni kí ó ronú, “Èmi yóò wà ní àlàáfíà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fi àáké kọ́rí nípa lílọ nínú ọ̀nà ti ara à mi.” Èyí yóò mú àjálù wá sórí ilẹ̀ tútù àti sórí ilẹ̀ gbígbẹ bákan náà
tapno inton mangngeg dayta a tao dagiti sasao daytoy a lunod, saanna a bendisionan ti bagina iti pusona ket kunana, “Natalnaakto, uray no magnaak iti kinatangken ti pusok.' Daytoy ti gapuna a dadaelento ni Yahweh ti amin a tattao iti daga.
20 Olúwa kì yóò ní ìfẹ́ sí àti dáríjì í; ìbínú àti ìtara rẹ̀ yóò jó ọkùnrin náà. Gbogbo àwọn ègún tí a kọ sínú ìwé yìí yóò wá sórí i rẹ̀, Olúwa yóò sì yọ orúkọ rẹ̀ kúrò lábẹ́ ọ̀run.
Saanto a pakawanen ni Yahweh isuna, ngem ketdi, umasukto ti unget ken imon ni Yahweh maibusor iti dayta a tao, ken umay amin kenkuana dagiti amin a lunod a naisurat iti daytoy a libro, ken punasento ni Yahweh ti naganna manipud iti sirok ti langit.
21 Olúwa yóò sì yọ òun nìkan kúrò nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli fún àjálù, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ègún májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé òfin yìí.
Ilasinto ni Yahweh isuna para iti didigra manipud kadagiti amin a tribo ti Israel, kas maiyannurot kadagiti amin a lunod iti tulag a naisurat iti daytoy a libro iti linteg.
22 Àwọn ọmọ rẹ tí ó tẹ̀lé ìran rẹ lẹ́yìn àti àwọn àjèjì tí ó wá láti ilẹ̀ jíjìn yóò rí wàhálà tí ó wá sórí ilẹ̀ àti àwọn ààrùn pẹ̀lú tí Olúwa mú bá ọ.
Ti sumaruno a henerasion, dagiti annakyo a tumaud a sumaruno kadakayo, ken ti gangganaet nga umay manipud ti adayo a daga, agsaodanto no makitada dagiti didigra iti daytoy a daga ken dagiti saksakit a pinangpasakit ni Yahweh iti daytoy—
23 Gbogbo ilẹ̀ náà yóò di imí-oòrùn, àti iyọ̀, àti ìjóná tí a kò lè fi ọkàn sí, tàbí tí kò lè so èso tàbí tí koríko kò lè hù nínú u rẹ̀, yóò dàbí ìbìṣubú Sodomu àti Gomorra, Adma àti Seboimu, tí Olúwa bì ṣubú nínú ìbínú rẹ̀, àti ìkáàánú rẹ̀.
ket inton makitada a nagbalin nga asufre ken mapupuoran nga asin ti entero a daga, nga awan ti aniaman a maimula wenno agbunga, nga awan ti ruot a dumakkel, kas ti pannakadadael ti Sodoma ken Gomorra, Adma ken Seboim, a dinadael ni Yahweh gapu iti unget ken pungtotna—
24 Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò béèrè pé, “Kí ló dé tí Olúwa fi ṣe èyí sí ilẹ̀ yìí? Kí ni a lè mọ ooru ìbínú ńlá yìí sí?”
ibagadanto a sangsangkamaysa agraman amin a dadduma a nasion, “Apay nga inaramid daytoy ni Yahweh iti daytoy a daga? Ania ti kaipapanan ti bara daytoy napalalo nga unget?'
25 Ìdáhùn yóò sì jẹ́ báyìí: “Nítorí tí ènìyàn yìí kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀, májẹ̀mú tí ó ti bá wọn dá nígbà tí ó mú wọn jáde wá láti Ejibiti.
Ket ibaganto dagiti tattao, “Daytoy ket gapu ta sinalungasingda ti katulaganda kenni Yahweh, ti Dios dagiti kapuonanda, nga inaramidna kadakuada idi inruarna ida manipud iti daga ti Egipto,
26 Wọ́n lọ wọ́n sì sin ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún wọn, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀, ọlọ́run tí kò fi fún wọn.
ken gapu ta napan ken nagdaydayawda kadagiti sabali a dios ken nagrukbabda kadakuada, dagiti dios a saanda nga am-ammo ken saanna nga inted kadakuada.
27 Nígbà náà ni ìbínú Olúwa ru sí ilẹ̀ wọn, dé bi pé ó mú gbogbo ègún tí a kọ sínú ìwé yìí wá sórí i rẹ̀.
Simged ngarud ti unget ni Yahweh maibusor ti daytoy a daga, tapno iyegna iti daytoy dagiti amin a lunod a naisurat iti daytoy a libro.
28 Ní ìbínú àti ní ìkáàánú, àti ní ìrunú ńlá, Olúwa sì fà wọ́n tu kúrò ní ilẹ̀ wọn, ó sì lé wọn lọ sí ilẹ̀ mìíràn, bí ó ti rí ní òní yìí.”
Pinarut ida ni Yahweh manipud iti dagada gapu iti unget, pungtot ken iti napalalo a luksaw, ken imbellengna ida iti sabali a daga agingga ita nga aldaw.'
29 Ohun ìkọ̀kọ̀ jẹ́ ti Olúwa Ọlọ́run wa, ṣùgbọ́n ohun tí a fihàn jẹ́ ti wa àti ti àwọn ọmọ wa títí láé, kí a lè tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
Kukua laeng ni Yahweh a Diostayo dagiti palimed a banbanag, ngem dagiti banbanag a naipakaammo ket kukuatayo ken dagiti kaputotantayo iti agnanayon, tapno maaramidtayo amin a sasao daytoy a linteg.

< Deuteronomy 29 >