< Deuteronomy 29 >

1 Èyí ni àwọn ìpinnu májẹ̀mú tí Olúwa pàṣẹ fún Mose láti ṣe pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní Moabu, ní àfikún májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú u wọn ní Horebu.
Telles sont les paroles de l'alliance que Yahvé ordonna à Moïse de conclure avec les enfants d'Israël au pays de Moab, en complément de l'alliance qu'il avait conclue avec eux à Horeb.
2 Mose pàṣẹ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì wí fún wọn wí pé, ojú rẹ ti rí gbogbo ohun tí Olúwa ti ṣe ní Ejibiti sí Farao àti, sí gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀ àti sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
Moïse appela tout Israël, et leur dit: Vos yeux ont vu tout ce que Yahvé a fait au pays d'Égypte à Pharaon, à tous ses serviteurs et à tout son pays,
3 Pẹ̀lú ojú ara rẹ ni ìwọ rí àwọn ìdánwò ńlá náà, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá.
les grandes épreuves que vos yeux ont vues, les signes et ces grands prodiges.
4 Ṣùgbọ́n títí di àsìkò yìí Olúwa kò fi ọkàn ìmòye tàbí ojú tí ó ń rí tàbí etí tí ó n gbọ́ fún ọ.
Mais Yahvé ne vous a pas donné, jusqu'à ce jour, un cœur pour connaître, des yeux pour voir et des oreilles pour entendre.
5 Nígbà ogójì ọdún tí mò ń tọ́ yín ṣọ́nà ní aginjù, aṣọ ọ̀ rẹ kò gbó tàbí bàtà ẹsẹ̀ rẹ.
Je vous ai conduits pendant quarante ans dans le désert. Vos vêtements n'ont pas vieilli sur vous, et vos sandales n'ont pas vieilli à vos pieds.
6 O kò jẹ oúnjẹ tàbí mu wáìnì kankan tàbí rú ohun mímu mìíràn. Mo ṣe èyí kí o lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Vous n'avez pas mangé de pain, et vous n'avez pas bu de vin ni de boisson forte, afin que vous sachiez que je suis Yahvé votre Dieu.
7 Nígbà tí o dé ibí yìí, Sihoni ọba Heṣboni àti Ogu ọba Baṣani jáde wá láti bá ọ jà, ṣùgbọ́n a ṣẹ́gun wọn.
Lorsque vous êtes arrivés dans ce lieu, Sihon, roi de Hesbon, et Og, roi de Basan, sont sortis contre nous pour nous combattre, et nous les avons battus.
8 A gba ilẹ̀ wọn a sì fi fún àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase bí ogún.
Nous avons pris leur pays et l'avons donné en héritage aux Rubénites, aux Gadites et à la demi-tribu des Manassites.
9 Nítorí náà, ẹ pa májẹ̀mú yìí mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n, kí ẹ̀yin kí ó lè máa rí ire nínú gbogbo ohun tí o bá ń ṣe.
Gardez donc les paroles de cette alliance et mettez-les en pratique, afin de prospérer dans tout ce que vous ferez.
10 Gbogbo yín ń dúró lónìí yìí níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ: àwọn olórí yín, àwọn ẹ̀yà yín, àwọn àgbàgbà yín àti àwọn ìjòyè yín, àní gbogbo àwọn ọkùnrin mìíràn ní Israẹli,
Vous vous tenez tous aujourd'hui devant l'Éternel, votre Dieu: vos chefs, vos tribus, vos anciens et vos officiers, tous les hommes d'Israël,
11 pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọ̀ rẹ àti ìyàwó ò rẹ àti àwọn àjèjì tí wọ́n ń gbé ní àgọ́ ọ̀ rẹ, tí ó ké pópòpó igi rẹ, tí ó sì gbé omi rẹ.
vos petits enfants, vos femmes, et les étrangers qui sont au milieu de vos camps, depuis celui qui coupe votre bois jusqu'à celui qui tire votre eau,
12 O dúró níhìn-ín yìí kí o lè wọ inú májẹ̀mú pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, májẹ̀mú tí Olúwa ń ṣe pẹ̀lú rẹ lónìí yìí àti tí òun dè pẹ̀lú ìbúra,
afin que vous entriez dans l'alliance de l'Éternel, votre Dieu, et dans le serment qu'il vous fait aujourd'hui,
13 láti jẹ́wọ́ rẹ lónìí yìí bí ènìyàn an rẹ̀, pé kí ó lè jẹ́ Ọlọ́run rẹ bí ó ti ṣèlérí àti bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba à rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
afin qu'il vous établisse aujourd'hui comme son peuple et qu'il soit votre Dieu, comme il vous l'a dit et comme il l'a juré à vos pères, Abraham, Isaac et Jacob.
14 Èmi ń ṣe májẹ̀mú yìí, pẹ̀lú ìbúra rẹ̀, kì í ṣe fún ìwọ nìkan
Ce n'est pas seulement avec vous que je fais cette alliance et ce serment,
15 tí ó dúró níbí pẹ̀lú wa lónìí níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ṣùgbọ́n àti fún gbogbo àwọn tí kò sí níbí lónìí.
mais avec ceux qui se tiennent aujourd'hui avec nous devant Yahvé notre Dieu, et aussi avec ceux qui ne sont pas aujourd'hui avec nous
16 Ìwọ fúnra à rẹ mọ bí a ṣe gbé ní Ejibiti àti bí a ṣe kọjá láàrín àwọn orílẹ̀-èdè nílẹ̀ ibí yìí.
(car vous savez comment nous avons vécu dans le pays d'Égypte, et comment nous sommes passés au milieu des nations par lesquelles vous avez passé;
17 Ìwọ rí láàrín wọn ìríra wọn, àwọn ère àti àwọn òrìṣà igi àti ti òkúta, ti fàdákà àti ti wúrà.
et vous avez vu leurs abominations et leurs idoles de bois, de pierre, d'argent et d'or, qui étaient parmi elles);
18 Rí i dájú pé kò sí ọkùnrin tàbí obìnrin, ìdílé tàbí ẹ̀yà láàrín yín lónìí tí ọkàn an rẹ̀ yóò yí kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa láti lọ àti láti sin àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè náà; rí i dájú pé kò sí gbòǹgbò tí ó ń mú irú èso kíkan bẹ́ẹ̀ jáde láàrín yín.
de peur qu'il n'y ait parmi vous un homme, une femme, une famille ou une tribu dont le cœur se détourne aujourd'hui de l'Éternel, notre Dieu, pour aller servir les dieux de ces nations, de peur qu'il n'y ait parmi vous une racine qui produise un poison amer,
19 Nígbà tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá gbọ́ ìbúra yìí, kí ó gbàdúrà ìbùkún sórí ara rẹ̀ nígbà náà ni kí ó ronú, “Èmi yóò wà ní àlàáfíà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fi àáké kọ́rí nípa lílọ nínú ọ̀nà ti ara à mi.” Èyí yóò mú àjálù wá sórí ilẹ̀ tútù àti sórí ilẹ̀ gbígbẹ bákan náà
et qu'en entendant les paroles de cette malédiction, il ne se bénisse dans son cœur, en disant: « J'aurai la paix, quoique je marche dans l'obstination de mon cœur », pour détruire l'humide par le sec.
20 Olúwa kì yóò ní ìfẹ́ sí àti dáríjì í; ìbínú àti ìtara rẹ̀ yóò jó ọkùnrin náà. Gbogbo àwọn ègún tí a kọ sínú ìwé yìí yóò wá sórí i rẹ̀, Olúwa yóò sì yọ orúkọ rẹ̀ kúrò lábẹ́ ọ̀run.
L'Éternel ne lui pardonnera pas, mais alors la colère et la jalousie de l'Éternel fumeront contre cet homme, et toute la malédiction écrite dans ce livre tombera sur lui, et l'Éternel effacera son nom de dessous le ciel.
21 Olúwa yóò sì yọ òun nìkan kúrò nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli fún àjálù, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ègún májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé òfin yìí.
Yahvé le mettra à part pour le mal, parmi toutes les tribus d'Israël, selon toutes les malédictions de l'alliance écrites dans ce livre de la loi.
22 Àwọn ọmọ rẹ tí ó tẹ̀lé ìran rẹ lẹ́yìn àti àwọn àjèjì tí ó wá láti ilẹ̀ jíjìn yóò rí wàhálà tí ó wá sórí ilẹ̀ àti àwọn ààrùn pẹ̀lú tí Olúwa mú bá ọ.
La génération à venir - tes enfants qui se lèveront après toi, et l'étranger qui viendra d'un pays lointain - dira, quand elle verra les plaies de ce pays, et les maladies dont Yahvé l'a rendu malade,
23 Gbogbo ilẹ̀ náà yóò di imí-oòrùn, àti iyọ̀, àti ìjóná tí a kò lè fi ọkàn sí, tàbí tí kò lè so èso tàbí tí koríko kò lè hù nínú u rẹ̀, yóò dàbí ìbìṣubú Sodomu àti Gomorra, Adma àti Seboimu, tí Olúwa bì ṣubú nínú ìbínú rẹ̀, àti ìkáàánú rẹ̀.
que toute sa terre n'est que soufre, sel et brûlure, qu'elle ne se sème pas, ne produit pas, et qu'il n'y pousse pas d'herbe, comme Sodome, Gomorrhe, Adma et Tseboïm, que Yahvé a détruites dans sa colère et dans sa fureur.
24 Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò béèrè pé, “Kí ló dé tí Olúwa fi ṣe èyí sí ilẹ̀ yìí? Kí ni a lè mọ ooru ìbínú ńlá yìí sí?”
Toutes les nations diront: « Pourquoi Yahvé a-t-il fait cela à ce pays? Que signifie l'ardeur de cette grande colère? »
25 Ìdáhùn yóò sì jẹ́ báyìí: “Nítorí tí ènìyàn yìí kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀, májẹ̀mú tí ó ti bá wọn dá nígbà tí ó mú wọn jáde wá láti Ejibiti.
Alors on dira: « Parce qu'ils ont abandonné l'alliance de Yahvé, le Dieu de leurs pères, qu'il avait conclue avec eux en les faisant sortir du pays d'Égypte,
26 Wọ́n lọ wọ́n sì sin ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún wọn, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀, ọlọ́run tí kò fi fún wọn.
ils sont allés servir d'autres dieux et se prosterner devant eux, des dieux qu'ils ne connaissaient pas et qu'il ne leur avait pas donnés.
27 Nígbà náà ni ìbínú Olúwa ru sí ilẹ̀ wọn, dé bi pé ó mú gbogbo ègún tí a kọ sínú ìwé yìí wá sórí i rẹ̀.
Aussi la colère de Yahvé s'enflamma-t-elle contre ce pays, pour faire venir sur lui toutes les malédictions qui sont écrites dans ce livre.
28 Ní ìbínú àti ní ìkáàánú, àti ní ìrunú ńlá, Olúwa sì fà wọ́n tu kúrò ní ilẹ̀ wọn, ó sì lé wọn lọ sí ilẹ̀ mìíràn, bí ó ti rí ní òní yìí.”
Yahvé les a déracinés de leur pays avec colère, avec fureur et avec une grande indignation, et il les a poussés dans un autre pays, comme c'est le cas aujourd'hui. »
29 Ohun ìkọ̀kọ̀ jẹ́ ti Olúwa Ọlọ́run wa, ṣùgbọ́n ohun tí a fihàn jẹ́ ti wa àti ti àwọn ọmọ wa títí láé, kí a lè tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
Les choses secrètes appartiennent à Yahvé notre Dieu; mais les choses révélées nous appartiennent, à nous et à nos enfants, pour toujours, afin que nous mettions en pratique toutes les paroles de cette loi.

< Deuteronomy 29 >