< Deuteronomy 29 >
1 Èyí ni àwọn ìpinnu májẹ̀mú tí Olúwa pàṣẹ fún Mose láti ṣe pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní Moabu, ní àfikún májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú u wọn ní Horebu.
Det er den Pagts Ord, som HERREN bød Moses at slutte med Israelitterne i Moabs Land foruden den Pagt, han havde sluttet med dem ved Horeb.
2 Mose pàṣẹ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì wí fún wọn wí pé, ojú rẹ ti rí gbogbo ohun tí Olúwa ti ṣe ní Ejibiti sí Farao àti, sí gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀ àti sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
Og Moses kaldte hele Israel sammen og sagde til dem: I har set alt, hvad HERREN i Ægypten for eders Øjne gjorde ved Farao og alle hans Tjenere og hele hans Land,
3 Pẹ̀lú ojú ara rẹ ni ìwọ rí àwọn ìdánwò ńlá náà, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá.
de store Prøvelser, I så med egne Øjne, disse store Tegn og Undere.
4 Ṣùgbọ́n títí di àsìkò yìí Olúwa kò fi ọkàn ìmòye tàbí ojú tí ó ń rí tàbí etí tí ó n gbọ́ fún ọ.
Men hidindtil har HERREN ikke givet eder Hjerte til at forstå med eller Øjne til at se med eller Ører til at høre med.
5 Nígbà ogójì ọdún tí mò ń tọ́ yín ṣọ́nà ní aginjù, aṣọ ọ̀ rẹ kò gbó tàbí bàtà ẹsẹ̀ rẹ.
I fyrretyve År har jeg ført eder om i Ørkenen; eders Klæder blev ikke slidt af Kroppen på eder, og dine Sko blev ikke slidt af Fødderne på dig;
6 O kò jẹ oúnjẹ tàbí mu wáìnì kankan tàbí rú ohun mímu mìíràn. Mo ṣe èyí kí o lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Brød fik I ikke at spise, og Vin og stærk Drik fik I ikke at drikke, for at I skulde kende, at jeg er HERREN eders Gud.
7 Nígbà tí o dé ibí yìí, Sihoni ọba Heṣboni àti Ogu ọba Baṣani jáde wá láti bá ọ jà, ṣùgbọ́n a ṣẹ́gun wọn.
Og da I kom til Stedet her, drog Kong Sihon af Hesjbon og Kong Og af Basan ud til Kamp imod os, men vi slog dem
8 A gba ilẹ̀ wọn a sì fi fún àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase bí ogún.
og erobrede deres Land og gav Rubeniterne og Gaditerne og Manasses halve Stamme det til Arvelod.
9 Nítorí náà, ẹ pa májẹ̀mú yìí mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n, kí ẹ̀yin kí ó lè máa rí ire nínú gbogbo ohun tí o bá ń ṣe.
Tag derfor Vare på denne Pagts Ord og gør efter dem, for at I kan få Lykke til al eders Gerning.
10 Gbogbo yín ń dúró lónìí yìí níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ: àwọn olórí yín, àwọn ẹ̀yà yín, àwọn àgbàgbà yín àti àwọn ìjòyè yín, àní gbogbo àwọn ọkùnrin mìíràn ní Israẹli,
I står i Dag alle for HERREN eders Guds Åsyn, eders Stammeoverhoveder, Dommere, Ældste og Tilsynsmænd, hver Mand i Israel,
11 pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọ̀ rẹ àti ìyàwó ò rẹ àti àwọn àjèjì tí wọ́n ń gbé ní àgọ́ ọ̀ rẹ, tí ó ké pópòpó igi rẹ, tí ó sì gbé omi rẹ.
eders Småbørn og Hustruer og de fremmede, der opholder sig i din Lejr, både dine Brændehuggere og Vandbærere,
12 O dúró níhìn-ín yìí kí o lè wọ inú májẹ̀mú pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, májẹ̀mú tí Olúwa ń ṣe pẹ̀lú rẹ lónìí yìí àti tí òun dè pẹ̀lú ìbúra,
for at indtræde i HERREN din Guds Pagt og det Edsforbund, HERREN din Gud. i Dag slutter med dig,
13 láti jẹ́wọ́ rẹ lónìí yìí bí ènìyàn an rẹ̀, pé kí ó lè jẹ́ Ọlọ́run rẹ bí ó ti ṣèlérí àti bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba à rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
for at han i dag kan gøre dig til sit Folk, så han bliver din Gud, som han lovede dig og tilsvor dine Fædre, Abraham, Isak og Jakob.
14 Èmi ń ṣe májẹ̀mú yìí, pẹ̀lú ìbúra rẹ̀, kì í ṣe fún ìwọ nìkan
Og ikke med eder alene slutter jeg denne Pagt og dette Edsforbund,
15 tí ó dúró níbí pẹ̀lú wa lónìí níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ṣùgbọ́n àti fún gbogbo àwọn tí kò sí níbí lónìí.
men både med dem, der i Dag står her hos os for HERREN vor Guds Åsyn, og med dem, der i Dag ikke er til Stede hos os her.
16 Ìwọ fúnra à rẹ mọ bí a ṣe gbé ní Ejibiti àti bí a ṣe kọjá láàrín àwọn orílẹ̀-èdè nílẹ̀ ibí yìí.
Thi I ved jo selv, at vi boede i Ægypten, og at vi drog igennem de forskellige Folkeslags Lande,
17 Ìwọ rí láàrín wọn ìríra wọn, àwọn ère àti àwọn òrìṣà igi àti ti òkúta, ti fàdákà àti ti wúrà.
og I så deres væmmelige Guder og de Afgudsbilleder af Træ og Sten, af Sølv og Guld, som de har.
18 Rí i dájú pé kò sí ọkùnrin tàbí obìnrin, ìdílé tàbí ẹ̀yà láàrín yín lónìí tí ọkàn an rẹ̀ yóò yí kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa láti lọ àti láti sin àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè náà; rí i dájú pé kò sí gbòǹgbò tí ó ń mú irú èso kíkan bẹ́ẹ̀ jáde láàrín yín.
Så lad der da ikke iblandt eder findes nogen Mand eller Kvinde, Slægt eller Stamme, hvis Hjerte i Dag vender sig bort fra HERREN vor Gud, så de går hen og dyrker disse Folks Guder; lad der ikke iblandt eder nådes nogen Rod, hvoraf Gift og Malurt vokser op,
19 Nígbà tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá gbọ́ ìbúra yìí, kí ó gbàdúrà ìbùkún sórí ara rẹ̀ nígbà náà ni kí ó ronú, “Èmi yóò wà ní àlàáfíà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fi àáké kọ́rí nípa lílọ nínú ọ̀nà ti ara à mi.” Èyí yóò mú àjálù wá sórí ilẹ̀ tútù àti sórí ilẹ̀ gbígbẹ bákan náà
så at han, når han hører dette Edsforbunds Ord, i sit Hjerte lover sig selv alt godt og tænker: "Det skal nok gå mig vel, selv om jeg vandrer med genstridigt Hjerte!" Thi så vil han ødelægge både frodigt og tørt.
20 Olúwa kì yóò ní ìfẹ́ sí àti dáríjì í; ìbínú àti ìtara rẹ̀ yóò jó ọkùnrin náà. Gbogbo àwọn ègún tí a kọ sínú ìwé yìí yóò wá sórí i rẹ̀, Olúwa yóò sì yọ orúkọ rẹ̀ kúrò lábẹ́ ọ̀run.
HERREN vil ikke tilgive den Mand, nej, hans Vrede og Nidkærhed skal blusse op mod sådan en Mand, og al den Forbandelse, der er optegnet i denne Bog, vil lægge sig på ham, og HERREN vil udslette hans Navn under Himmelen!
21 Olúwa yóò sì yọ òun nìkan kúrò nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli fún àjálù, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ègún májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé òfin yìí.
HERREN vil udskille ham af alle Israels Stammer og bringe Ulykke over ham i Overensstemmelse med alle de Pagtens Forbandelser, som er skrevet i denne Lovbog.
22 Àwọn ọmọ rẹ tí ó tẹ̀lé ìran rẹ lẹ́yìn àti àwọn àjèjì tí ó wá láti ilẹ̀ jíjìn yóò rí wàhálà tí ó wá sórí ilẹ̀ àti àwọn ààrùn pẹ̀lú tí Olúwa mú bá ọ.
Og når den kommende Slægt, eders Børn, der kommer efter eder. og de fremmede, der kommer langvejsfra, ser de Plager, der har ramt dette Land, og de Sygdomme, HERREN har hjemsøgt det med,
23 Gbogbo ilẹ̀ náà yóò di imí-oòrùn, àti iyọ̀, àti ìjóná tí a kò lè fi ọkàn sí, tàbí tí kò lè so èso tàbí tí koríko kò lè hù nínú u rẹ̀, yóò dàbí ìbìṣubú Sodomu àti Gomorra, Adma àti Seboimu, tí Olúwa bì ṣubú nínú ìbínú rẹ̀, àti ìkáàánú rẹ̀.
Svovl og Salt, hele Landet afsvedet, så det ikke kan tilsåes og ingen Afgrøde give, og ingen Urter kan gro deri, som dengang Sodoma og Gomorra, Adma og Zebojim blev ødelagt, da HERREN lod dem gå under i sin Vrede og Harme, da skal de spørge,
24 Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò béèrè pé, “Kí ló dé tí Olúwa fi ṣe èyí sí ilẹ̀ yìí? Kí ni a lè mọ ooru ìbínú ńlá yìí sí?”
og alle Folkeslag skal spørge: "Hvorfor har HERREN handlet således med dette Land? Hvorledes hænger det sammen med denne vældige Vredesglød?"
25 Ìdáhùn yóò sì jẹ́ báyìí: “Nítorí tí ènìyàn yìí kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀, májẹ̀mú tí ó ti bá wọn dá nígbà tí ó mú wọn jáde wá láti Ejibiti.
Så skal man svare: "Det er, fordi de sveg den Pagt, HERREN, deres Fædres Gud, havde sluttet med dem, da han førte dem ud af Ægypten,
26 Wọ́n lọ wọ́n sì sin ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún wọn, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀, ọlọ́run tí kò fi fún wọn.
og gik hen og dyrkede fremmede Guder og tilbad dem, Guder, som de ikke før havde kendt til, og som han ikke havde tildelt dem;
27 Nígbà náà ni ìbínú Olúwa ru sí ilẹ̀ wọn, dé bi pé ó mú gbogbo ègún tí a kọ sínú ìwé yìí wá sórí i rẹ̀.
derfor blussede HERRENs Vrede op imod dette Land, så han lod al den Forbandelse, som er optegnet i denne Bog, komme over det,
28 Ní ìbínú àti ní ìkáàánú, àti ní ìrunú ńlá, Olúwa sì fà wọ́n tu kúrò ní ilẹ̀ wọn, ó sì lé wọn lọ sí ilẹ̀ mìíràn, bí ó ti rí ní òní yìí.”
og derfor oprykkede han dem fra deres Land i Vrede og Harme og heftig Forbitrelse og slængte dem ud i et fremmed Land, som det nu er sket."
29 Ohun ìkọ̀kọ̀ jẹ́ ti Olúwa Ọlọ́run wa, ṣùgbọ́n ohun tí a fihàn jẹ́ ti wa àti ti àwọn ọmọ wa títí láé, kí a lè tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
De skjulte Ting er for HERREN vor Gud, men de åbenbare er for os og vore Børn evindelig, at vi må lære at handle efter alle denne Lovs Ord!