< Deuteronomy 29 >

1 Èyí ni àwọn ìpinnu májẹ̀mú tí Olúwa pàṣẹ fún Mose láti ṣe pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní Moabu, ní àfikún májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú u wọn ní Horebu.
To su riječi Saveza što ga propisa Jahve Mojsiju da ga sklopi s Izraelcima u zemlji moapskoj, povrh Saveza što ga je s njima sklopio na Horebu.
2 Mose pàṣẹ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì wí fún wọn wí pé, ojú rẹ ti rí gbogbo ohun tí Olúwa ti ṣe ní Ejibiti sí Farao àti, sí gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀ àti sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
Mojsije sazva sav Izrael pa im reče: “Vidjeli ste na rođene oči sve što je Jahve učinio u zemlji egipatskoj faraonu, svim službenicima njegovim i svoj zemlji njegovoj:
3 Pẹ̀lú ojú ara rẹ ni ìwọ rí àwọn ìdánwò ńlá náà, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá.
velike kušnje što su ih vidjele tvoje oči, silne znakove i čudesa!
4 Ṣùgbọ́n títí di àsìkò yìí Olúwa kò fi ọkàn ìmòye tàbí ojú tí ó ń rí tàbí etí tí ó n gbọ́ fún ọ.
Ali vam ne dade Jahve do danas razuma da shvatite, očiju da vidite ni ušiju da čujete.
5 Nígbà ogójì ọdún tí mò ń tọ́ yín ṣọ́nà ní aginjù, aṣọ ọ̀ rẹ kò gbó tàbí bàtà ẹsẹ̀ rẹ.
Vodio sam vas pustinjom četrdeset godina; odjeća se na vama nije izderala niti su se sandale na vašim nogama raskidale.
6 O kò jẹ oúnjẹ tàbí mu wáìnì kankan tàbí rú ohun mímu mìíràn. Mo ṣe èyí kí o lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Kruha niste jeli; vina ni drugoga opojnog pića niste pili, da biste znali da sam ja Jahve, Bog vaš.
7 Nígbà tí o dé ibí yìí, Sihoni ọba Heṣboni àti Ogu ọba Baṣani jáde wá láti bá ọ jà, ṣùgbọ́n a ṣẹ́gun wọn.
Kad stigoste na novo mjesto, Sihon, kralj hešbonski, i Og, kralj bašanski, iziđoše pred nas u boj, ali smo ih potukli.
8 A gba ilẹ̀ wọn a sì fi fún àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase bí ogún.
Zauzeli smo njihovu zemlju te je predali u baštinu Rubenovcima, Gadovcima i polovini plemena Manašeova.
9 Nítorí náà, ẹ pa májẹ̀mú yìí mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n, kí ẹ̀yin kí ó lè máa rí ire nínú gbogbo ohun tí o bá ń ṣe.
Držite i vršite riječi ovog Saveza da uspijevate u svemu što poduzmete.
10 Gbogbo yín ń dúró lónìí yìí níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ: àwọn olórí yín, àwọn ẹ̀yà yín, àwọn àgbàgbà yín àti àwọn ìjòyè yín, àní gbogbo àwọn ọkùnrin mìíràn ní Israẹli,
Danas stojite svi pred Jahvom, Bogom svojim: vaši plemenski glavari, vaše starješine i vaši nadglednici, svi muževi Izraela,
11 pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọ̀ rẹ àti ìyàwó ò rẹ àti àwọn àjèjì tí wọ́n ń gbé ní àgọ́ ọ̀ rẹ, tí ó ké pópòpó igi rẹ, tí ó sì gbé omi rẹ.
djeca vaša, žene vaše i došljak koji je u tvome taboru - od onoga koji ti siječe drva do onoga koji ti nosi vodu -
12 O dúró níhìn-ín yìí kí o lè wọ inú májẹ̀mú pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, májẹ̀mú tí Olúwa ń ṣe pẹ̀lú rẹ lónìí yìí àti tí òun dè pẹ̀lú ìbúra,
da stupite u Savez s Jahvom, Bogom svojim, u Savez zakletvom potvrđen, što ga Jahve, Bog tvoj, danas s tobom sklapa
13 láti jẹ́wọ́ rẹ lónìí yìí bí ènìyàn an rẹ̀, pé kí ó lè jẹ́ Ọlọ́run rẹ bí ó ti ṣèlérí àti bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba à rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
da danas od tebe učini svoj narod i da ti on bude Bog, kako ti je rekao i kako se zakleo tvojim ocima: Abrahamu, Izaku i Jakovu.
14 Èmi ń ṣe májẹ̀mú yìí, pẹ̀lú ìbúra rẹ̀, kì í ṣe fún ìwọ nìkan
I ne sklapam danas ovaj Savez sa zakletvom samo s vama
15 tí ó dúró níbí pẹ̀lú wa lónìí níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ṣùgbọ́n àti fún gbogbo àwọn tí kò sí níbí lónìí.
nego i sa svakim koji danas stoji ovdje s nama pred Jahvom, Bogom našim, i sa svakim koji danas nije ovdje s nama.
16 Ìwọ fúnra à rẹ mọ bí a ṣe gbé ní Ejibiti àti bí a ṣe kọjá láàrín àwọn orílẹ̀-èdè nílẹ̀ ibí yìí.
Sami znate kako smo boravili u zemlji egipatskoj i kako smo prošli posred naroda kroz koje ste morali proći.
17 Ìwọ rí láàrín wọn ìríra wọn, àwọn ère àti àwọn òrìṣà igi àti ti òkúta, ti fàdákà àti ti wúrà.
Vidjeli ste njihove rugobe, njihove kumire od drveta i kamena, srebra i zlata što ih imaju.
18 Rí i dájú pé kò sí ọkùnrin tàbí obìnrin, ìdílé tàbí ẹ̀yà láàrín yín lónìí tí ọkàn an rẹ̀ yóò yí kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa láti lọ àti láti sin àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè náà; rí i dájú pé kò sí gbòǹgbò tí ó ń mú irú èso kíkan bẹ́ẹ̀ jáde láàrín yín.
Neka ne bude među vama čovjeka ni žene, roda ni plemena kojemu bi se srce danas odvratilo od Jahve, Boga našega, pa da ide iskazivati štovanje bogovima onih naroda. Neka ne bude među vama korijena koji rađa otrovom i pelinom.
19 Nígbà tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá gbọ́ ìbúra yìí, kí ó gbàdúrà ìbùkún sórí ara rẹ̀ nígbà náà ni kí ó ronú, “Èmi yóò wà ní àlàáfíà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fi àáké kọ́rí nípa lílọ nínú ọ̀nà ti ara à mi.” Èyí yóò mú àjálù wá sórí ilẹ̀ tútù àti sórí ilẹ̀ gbígbẹ bákan náà
Neka se nitko, čuvši riječi ovog prokletstva, ne nada blagoslovu kazujući u svome srcu: 'Bit će mi dobro ako poživim i po prohtjevima srca svoga. Nek' povodanj utaži žeđ!'
20 Olúwa kì yóò ní ìfẹ́ sí àti dáríjì í; ìbínú àti ìtara rẹ̀ yóò jó ọkùnrin náà. Gbogbo àwọn ègún tí a kọ sínú ìwé yìí yóò wá sórí i rẹ̀, Olúwa yóò sì yọ orúkọ rẹ̀ kúrò lábẹ́ ọ̀run.
Takvome neće Jahve nikad oprostiti, nego će se gnjev i ljubomornost Jahvina izliti na tog čovjeka, tako da će se sve prokletstvo zapisano u ovoj knjizi na nj oboriti te će Jahve izbrisati ime njegovo pod nebom.
21 Olúwa yóò sì yọ òun nìkan kúrò nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli fún àjálù, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ègún májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé òfin yìí.
Prema svim prokletstvima ovog Saveza, zapisanima u knjizi ovoga Zakona, Jahve će ga odstraniti, na njegovu propast, od svih plemena izraelskih.
22 Àwọn ọmọ rẹ tí ó tẹ̀lé ìran rẹ lẹ́yìn àti àwọn àjèjì tí ó wá láti ilẹ̀ jíjìn yóò rí wàhálà tí ó wá sórí ilẹ̀ àti àwọn ààrùn pẹ̀lú tí Olúwa mú bá ọ.
Kasniji naraštaj, sinovi vaši poslije vas, i stranci koji dođu iz daleke zemlje, kad vide zla ove zemlje i bolesti što će ih Jahve pustiti na nju, reći će:
23 Gbogbo ilẹ̀ náà yóò di imí-oòrùn, àti iyọ̀, àti ìjóná tí a kò lè fi ọkàn sí, tàbí tí kò lè so èso tàbí tí koríko kò lè hù nínú u rẹ̀, yóò dàbí ìbìṣubú Sodomu àti Gomorra, Adma àti Seboimu, tí Olúwa bì ṣubú nínú ìbínú rẹ̀, àti ìkáàánú rẹ̀.
'Sva je zemlja njegova samo sumpor i sol; niti se što sije niti što klija; nikakva travka na njoj ne raste; jednaka je srušenoj Sodomi i Gomori, Admi i Sebojimu, što ih Jahve sruši u svojoj ljutini i gnjevu.'
24 Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò béèrè pé, “Kí ló dé tí Olúwa fi ṣe èyí sí ilẹ̀ yìí? Kí ni a lè mọ ooru ìbínú ńlá yìí sí?”
I svi će narodi pitati: 'Zašto učini Jahve ovako ovoj zemlji? Kakva je morala biti žestina toga silnoga gnjeva?'
25 Ìdáhùn yóò sì jẹ́ báyìí: “Nítorí tí ènìyàn yìí kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀, májẹ̀mú tí ó ti bá wọn dá nígbà tí ó mú wọn jáde wá láti Ejibiti.
Onda će im se reći: 'Jer su ostavili Savez što ga je Jahve, Bog otaca njihovih, bio sklopio s njima kad ih je izveo iz zemlje egipatske;
26 Wọ́n lọ wọ́n sì sin ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún wọn, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀, ọlọ́run tí kò fi fún wọn.
i jer su otišli da iskazuju štovanje drugim bogovima i njima se klanjali, bogovima kojih nisu poznavali i kojih im on nije odredio.
27 Nígbà náà ni ìbínú Olúwa ru sí ilẹ̀ wọn, dé bi pé ó mú gbogbo ègún tí a kọ sínú ìwé yìí wá sórí i rẹ̀.
Zato se Jahvin gnjev izlio na ovu zemlju i palo na nju sve prokletstvo zapisano u ovoj knjizi.
28 Ní ìbínú àti ní ìkáàánú, àti ní ìrunú ńlá, Olúwa sì fà wọ́n tu kúrò ní ilẹ̀ wọn, ó sì lé wọn lọ sí ilẹ̀ mìíràn, bí ó ti rí ní òní yìí.”
Jahve ih je iščupao iz njihove zemlje u ljutini, srdžbi i velikom gnjevu te ih bacio u drugu zemlju. Tako je i danas.'
29 Ohun ìkọ̀kọ̀ jẹ́ ti Olúwa Ọlọ́run wa, ṣùgbọ́n ohun tí a fihàn jẹ́ ti wa àti ti àwọn ọmọ wa títí láé, kí a lè tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
Što je sakriveno, pripada Jahvi, Bogu našemu, a objava nama i sinovima našim zauvijek da vršimo sve riječi ovoga Zakona.

< Deuteronomy 29 >