< Deuteronomy 28 >

1 Bí ìwọ bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní kíkún kí o sì kíyèsára láti tẹ̀lé gbogbo ohun tí ó pàṣẹ tí mo fi fún ọ lónìí, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé ọ lékè ju gbogbo orílẹ̀-èdè ayé lọ.
“Eğer Tanrınız RAB'bin sözünü iyice dinler ve bugün size ilettiğim bütün buyruklarına uyarsanız, Tanrınız RAB sizi yeryüzündeki bütün uluslardan üstün kılacaktır.
2 Gbogbo ìbùkún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ bí o bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Tanrınız RAB'bin sözünü dinlerseniz, şu bereketler üzerinize gelecek ve sizinle olacak:
3 Ìbùkún ni fún ọ ni ìlú, ìbùkún ni fún ọ ní oko.
“Kentte de tarlada da kutsanacaksınız.
4 Ìbùkún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, àti irú ohun ọ̀sìn rẹ àti ìbísí i màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
“Rahminizin meyvesi kutsanacak. Toprağınızın ürünü, hayvanlarınızın dölü –sığırlarınızın buzağıları, sürülerinizin kuzuları– bereketli olacak.
5 Ìbùkún ni fún agbọ̀n rẹ àti fún ọpọ́n ipò ìyẹ̀fun rẹ.
“Sepetiniz ve hamur tekneniz bereketli olacak.
6 Ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá wọlé, ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
“İçeri girdiğinizde de dışarı çıktığınızda da kutsanacaksınız.
7 Olúwa yóò gbà fún ọ pé gbogbo ọ̀tá tí ó dìde sí ọ yóò bì ṣubú níwájú rẹ. Wọn yóò tọ̀ ọ́ wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n wọn yóò sá fún ọ ní ọ̀nà méje.
“RAB size saldıran düşmanlarınızı önünüzde bozguna uğratacak. Onlar size bir yoldan saldıracak, ama önünüzden yedi yoldan kaçacaklar.
8 Olúwa yóò rán ìbùkún sí ọ àti sí ohun gbogbo tí o bá dáwọ́ rẹ lé. Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún un fún ọ nínú ilẹ̀ tí ó ń fi fún ọ.
“RAB'bin buyruğuyla ambarlarınız dolu olacak. El attığınız her işte RAB sizi kutsayacak. Tanrınız RAB size vereceği ülkede sizi kutsayacak.
9 Olúwa yóò fi ọ́ múlẹ̀ bí ènìyàn mímọ́, bí ó ti ṣe ìlérí fún ọ lórí ìbúra, bí o bá pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ mọ́ tí o sì ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
“Tanrınız RAB'bin buyruklarına uyar, O'nun yollarında yürürseniz, RAB size içtiği ant uyarınca sizi kendisi için kutsal bir halk olarak koruyacaktır.
10 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ayé yóò rí i pé a pè ọ́ ní orúkọ Olúwa, wọn yóò sì bẹ̀rù rẹ.
Yeryüzündeki bütün uluslar RAB'be ait olduğunuzu görecek, sizden korkacaklar.
11 Olúwa yóò fi àlàáfíà fún ọ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́, fún ọmọ inú rẹ, irú ohun ọ̀sìn rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá rẹ láti fún ọ.
RAB atalarınıza ant içerek size söz verdiği ülkede bolluk içinde yaşamanızı sağlayacak: Rahminizin meyvesi kutsanacak; hayvanlarınızın yavruları, toprağınızın ürünü verimli olacak.
12 Olúwa yóò ṣí ọ̀run sílẹ̀, ìṣúra rere rẹ̀ fún ọ, láti rọ òjò sórí ilẹ̀ rẹ ní àsìkò rẹ àti láti bùkún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ. Ìwọ yóò yá ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n ìwọ kò ní í yá lọ́wọ́ ẹnìkankan.
RAB ülkenize yağmuru zamanında yağdırmak ve bütün emeğinizi verimli kılmak için göklerdeki zengin hazinesini açacak. Birçok ulusa ödünç vereceksiniz; siz ödünç almayacaksınız.
13 Olúwa yóò fi ọ́ ṣe orí, ìwọ kì yóò sì jẹ́ ìrù. Bí o bá fi etí sílẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ tí mo fi fún ọ kí o sì máa rọra tẹ̀lé wọn, ìwọ yóò máa wà lókè, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò wà ní ìsàlẹ̀ láé.
RAB sizi kuyruk değil baş yapacak. Eğer bugün size ilettiğim Tanrınız RAB'bin buyruklarını dinler, onlara iyice uyarsanız, altta değil, her zaman üstte olacaksınız.
14 Má ṣe yà sọ́tùn tàbí sósì kúrò, nínú èyíkéyìí àwọn àṣẹ tí mo fi fún ọ ní òní yìí, kí o má ṣe tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti máa sìn wọ́n.
Bugün size ilettiğim buyrukların dışına çıkmayacak, başka ilahların ardınca gitmeyecek, onlara tapmayacaksınız.”
15 Ṣùgbọ́n bí o kò bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì rọra máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí, gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ.
“Ama Tanrınız RAB'bin sözünü dinlemez, bugün size ilettiğim buyrukların, kuralların hepsine uymazsanız, şu lanetler üzerinize gelecek ve size ulaşacak:
16 Ègún ni fún ọ ní ìlú, ègún ni fún ọ ní oko.
“Kentte de tarlada da lanetli olacaksınız.
17 Ègún ni fún agbọ̀n rẹ àti ọpọ́n ìpo-fúláwà rẹ.
“Sepetiniz ve hamur tekneniz lanetli olacak.
18 Ègún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, ìbísí màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
“Rahminizin meyvesi, toprağınızın ürünü, sığırlarınızın buzağıları, sürülerinizin kuzuları lanetli olacak.
19 Ègún ni fún ọ nígbà tí o bá wọlé ègún sì ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
“İçeri girdiğinizde lanetli olacaksınız; dışarı çıktığınızda da lanetli olacaksınız.
20 Olúwa yóò rán ègún sórí rẹ, rúdurùdu àti ìfibú nínú gbogbo ohun tí o bá dáwọ́ rẹ lé, títí ìwọ yóò fi parun àti wá sí ìparun lójijì nítorí búburú tí o ti ṣe ní kíkọ̀ mi sílẹ̀.
“RAB'be sırt çevirmekle yaptığınız kötülükler yüzünden el attığınız her işte O sizi lanete uğratacak, şaşkına çevirecek, paylayacak. Sonunda üzerinize yıkım gelecek ve çabucak yok olacaksınız.
21 Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn bá ọ jà títí tí yóò fi pa ọ́ run kúrò ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
RAB, mülk edinmek için gideceğiniz ülkede sizi yok edinceye dek salgın hastalıkla cezalandıracak.
22 Olúwa yóò kọlù ọ́ pẹ̀lú ààrùn ìgbẹ́, pẹ̀lú ibà àti àìsàn wíwú, pẹ̀lú ìjóni ńlá àti idà, pẹ̀lú ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù tí yóò yọ ọ́ lẹ́nu títí ìwọ yóò fi parun.
Veremle, sıtmayla, iltihapla, yakıcı sıcaklıkla, kuraklıkla, samyeliyle, küfle cezalandıracak. Siz yok oluncaya dek bunlar sizi kovalayacak.
23 Ojú ọ̀run tí ó wà lórí rẹ yóò jẹ́ idẹ, ilẹ̀ tí ń bẹ níṣàlẹ̀ rẹ yóò sì jẹ́ irin.
Başınızın üstündeki gök tunç, ayağınızın altındaki yer demir olacak.
24 Olúwa yóò yí òjò ilẹ̀ rẹ sí eruku àti ẹ̀tù; láti ọ̀run ni yóò ti máa sọ̀kalẹ̀ sí ọ, títí tí ìwọ yóò fi run.
RAB siz yok oluncaya dek gökten yağmur yerine ülkenize toz ve kum yağdıracak.
25 Olúwa yóò fi ọ́ gégùn ún láti ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá rẹ. Ìwọ yóò tọ̀ wọ́n wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá fún wọn ní ọ̀nà méje, ìwọ yóò sì padà di ohun ìbẹ̀rù fún gbogbo ìjọba lórí ayé.
“RAB sizi düşmanlarınızın önünde bozguna uğratacak. Onlara bir yoldan saldıracak, ama önlerinden yedi yoldan kaçacaksınız. Yeryüzündeki bütün uluslar için dehşet verici bir örnek olacaksınız.
26 Òkú rẹ yóò jẹ́ oúnjẹ fún gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko ayé, àti pé kò ní sí ẹnikẹ́ni tí yóò lé wọn kúrò.
Ölüleriniz bütün kuşlara, yabanıl hayvanlara yem olacak; onları korkutup kaçıran kimse olmayacak.
27 Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú oówo, Ejibiti àti pẹ̀lú kókó, ojú egbò kíkẹ̀ àti ìhúnra.
RAB sizi iyileşemeyeceğiniz Mısır çıbanıyla, urlarla, kaşıntıyla, uyuzla vuracak.
28 Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú ìsínwín, ojú fífọ́ àti rúdurùdu àyà.
RAB sizi delilikle, körlükle, şaşkınlıkla cezalandıracak.
29 Ní ọ̀sán gangan ìwọ yóò fi ọwọ́ tálẹ̀ kiri bí ọkùnrin afọ́jú nínú òkùnkùn ìwọ kì yóò ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí o bá ń ṣe, ojoojúmọ́ ni wọn yóò máa ni ọ́ lára àti jà ọ́ ní olè, tí kò sì ní í sí ẹnìkan láti gbà ọ́.
Öğle vakti körlerin karanlıkta el yordamıyla yürüdüğü gibi yürüyeceksiniz. Yaptığınız her şeyde başarısız olacak, sürekli sıkıştırılacak, yağmalanacaksınız. Sizi kurtaran olmayacak.
30 Ìwọ yóò gba ògo láti fẹ́ obìnrin kan ṣùgbọ́n ẹlòmíràn yóò gbà á yóò sì tẹ́ ẹ́ ní ògo. Ìwọ yóò kọ́ ilé, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò gbé ibẹ̀. Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kò tilẹ̀ ní gbádùn èso rẹ.
“Bir kızla nişanlanacaksınız, ama başka biri onunla yatacak. Ev yapacak ama içinde oturmayacaksınız. Bağ dikecek ama üzümünü toplamayacaksınız.
31 Màlúù rẹ yóò di pípa níwájú rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò jẹ nǹkan kan nínú rẹ̀. Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ yóò sì di mímú pẹ̀lú agbára kúrò lọ́dọ̀ rẹ, a kì yóò sì da padà. Àgùntàn rẹ yóò di mímú fún àwọn ọ̀tá rẹ, ẹnìkankan kò sì ní gbà á.
Öküzünüz gözünüzün önünde kesilecek ama etini yemeyeceksiniz. Eşeğiniz zorla sizden alınacak, geri getirilmeyecek. Davarlarınız düşmanlarınıza verilecek. Sizi kurtaran olmayacak.
32 Àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ yóò di mímú fún àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, ìwọ yóò sì fi ojú rẹ ṣọ́nà dúró dè wọ́n láti ọjọ́ dé ọjọ́, ìwọ yóò sì jẹ́ aláìlágbára láti gbé ọwọ́.
Oğullarınız, kızlarınız gözlerinizin önünde başka bir ulusa verilecek. Her gün onları gözlemekten gözlerinizin gücü tükenecek. Elinizden bir şey gelmeyecek.
33 Èso ilẹ̀ rẹ àti gbogbo iṣẹ́ làálàá rẹ ni orílẹ̀-èdè mìíràn tí ìwọ kò mọ̀ yóò sì jẹ, ìwọ yóò jẹ́ kìkì ẹni ìnilára àti ẹni ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
Tanımadığınız bir halk toprağınızın ürününü ve bütün emeğinizi yiyecek. Sürekli sıkıştırılacak, ezileceksiniz.
34 Ìran tí ojú rẹ yóò rí, yóò sọ ọ́ di òmùgọ̀.
Gözlerinizle gördükleriniz sizi çıldırtacak.
35 Olúwa yóò lu eékún àti ẹsẹ̀ rẹ pẹ̀lú oówo dídùn tí kò le san tán láti àtẹ̀lé méjèèjì rẹ lọ sí òkè orí rẹ.
RAB dizlerinizi, bacaklarınızı tepeden tırnağa iyileşmeyen ağrılı çıbanlarla vuracak.
36 Olúwa yóò lé ọ àti ọba tí ó yàn lórí rẹ lọ sí orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ tàbí ti àwọn baba rẹ kò mọ̀. Ibẹ̀ ni ìwọ̀ yóò sì sin ọlọ́run mìíràn, ọlọ́run igi àti òkúta.
“RAB sizi ve başınıza atayacağınız kralı sizin de atalarınızın da bilmediği bir ulusa sürecek. Orada ağaçtan, taştan yapılmış başka ilahlara tapacaksınız.
37 Ìwọ yóò di ẹni ìyanu, àti ẹni òwe, àti ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ nínú gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò darí rẹ sí.
RAB'bin sizi süreceği bütün uluslar başınıza gelenlerden dehşete düşecek; sizi aşağılayacak, sizinle eğlenecekler.
38 Ìwọ yóò gbin irúgbìn púpọ̀ ṣùgbọ́n ìwọ yóò kórè kékeré, nítorí eṣú yóò jẹ ẹ́ run.
“Çok tohum ekecek, ama az toplayacaksınız. Çünkü ürününüzü çekirge yiyecek.
39 Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà púpọ̀ ìwọ yóò sì ro wọ́n ṣùgbọ́n kò ní mú wáìnì náà tàbí kó àwọn èso jọ, nítorí kòkòrò yóò jẹ wọ́n run.
Bağlar dikecek, bakımını yapacak, ama şarap içmeyecek, üzüm toplamayacaksınız. Onları kurt yiyecek.
40 Ìwọ yóò ní igi olifi jákèjádò ilẹ̀ rẹ ṣùgbọ́n ìwọ kò ní lo òróró náà, nítorí olifi náà yóò rẹ̀ dànù.
Ülkenizin her yerinde zeytinlikleriniz olacak, ama zeytinyağı sürünmeyeceksiniz. Zeytin ağaçlarınız ürününü yere dökecek.
41 Ìwọ yóò ní àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin ṣùgbọ́n ìwọ kò nípa wọ́n mọ́, nítorí wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
Oğullarınız, kızlarınız olacak, ama sizinle kalmayacaklar, sürgüne gönderilecekler.
42 Ọ̀wọ́ eṣú yóò gba gbogbo àwọn igi rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ.
Bütün ağaçlarınızı, toprağınızın ürününü çekirgeler yiyecek.
43 Àjèjì tí ń gbé láàrín rẹ yóò gbé sókè gíga jù ọ́ lọ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò máa di ìrẹ̀sílẹ̀.
“Aranızdaki yabancılar yükseldikçe yükselecek, sizse alçaldıkça alçalacaksınız.
44 Yóò yà ọ́, ṣùgbọ́n o kì yóò yà á, òun ni yóò jẹ́ orí, ìwọ yóò jẹ́ ìrù.
O sana ödünç verecek, ama sen ona ödünç vermeyeceksin. O baş, sen kuyruk olacaksın.
45 Gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ, wọn yóò lé ọ wọn yóò sì bá ọ títí tí ìwọ yóò fi parun, nítorí ìwọ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ kò sì kíyèsi àṣẹ àti òfin tí ó fi fún ọ.
“Bütün bu lanetler başınıza yağacak. Yok oluncaya dek sizi kovalayacak ve size erişecek. Çünkü Tanrınız RAB'bin sözünü dinlemediniz, size verdiği buyrukları, kuralları yerine getirmediniz.
46 Wọn yóò jẹ́ àmì àti ìyanu fún ọ àti fún irú-ọmọ rẹ títí láé.
Bu lanetler siz ve soyunuz için sonsuza dek bir belirti, şaşılası bir olay olarak kalacak.
47 Nítorí ìwọ kò sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ní ayọ̀ àti inú dídùn ní àkókò àlàáfíà.
Madem bolluk zamanında Tanrınız RAB'be sevinçle, hoşnutlukla kulluk etmediniz,
48 Nítorí náà nínú ebi àti òǹgbẹ, nínú ìhòhò àti àìní búburú, ìwọ yóò sin àwọn ọ̀tá à rẹ tí Olúwa rán sí ọ. Yóò sì fi àjàgà irin bọ̀ ọ́ ní ọrùn, títí yóò fi run ọ́.
RAB'bin üzerinize göndereceği düşmanlara kölelik edeceksiniz. Aç, susuz, çıplak kalacaksınız; her şeye gereksinim duyacaksınız. RAB sizi yok edinceye dek boynunuza demir boyunduruk vuracak.
49 Olúwa yóò mú àwọn orílẹ̀-èdè wá sí ọ láti ọ̀nà jíjìn, bí òpin ayé, bí idì ti ń bẹ́ láti orí òkè sílẹ̀, orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò gbọ́ èdè wọn.
“RAB uzaktan, dünyanın öbür ucundan bir ulusu –dilini bilmediğiniz bir ulusu, yaşlılara saygı, küçüklere sevgi beslemeyen acımasız bir ulusu– birden çullanan bir kartal gibi başınıza getirecek.
50 Orílẹ̀-èdè tí ó rorò tí kò ní ojúrere fún àgbà tàbí àánú fún ọmọdé.
51 Wọn yóò jẹ ohun ọ̀sìn rẹ run àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ títí tí ìwọ yóò fi parun. Wọn kì yóò fi hóró irúgbìn kan fún ọ, wáìnì tuntun tàbí òróró, tàbí agbo ẹran màlúù rẹ kankan tàbí ọ̀wọ́ ẹran àgùntàn rẹ títí ìwọ yóò fi run.
Siz yok oluncaya dek hayvanlarınızın yavrularını, toprağınızın ürününü yiyip bitirecekler. Size ne tahıl, ne şarap, ne zeytinyağı, ne sığırlarınızın buzağılarını, ne de sürülerinizin kuzularını bırakacaklar; ta ki, siz ortadan kalkıncaya dek.
52 Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ títí tí odi ìdáàbòbò gíga yẹn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé yóò fi wó lulẹ̀. Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ jákèjádò ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ.
Güvendiğiniz yüksek, dayanıklı surlar yerle bir oluncaya dek ülkenizdeki bütün kentlerde sizi kuşatacaklar. Tanrınız RAB'bin size verdiği ülkedeki bütün kentleri kuşatacaklar.
53 Ìwọ ó sì jẹ èso ọmọ inú rẹ̀, ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti ti àwọn ọmọ rẹ obìnrin tí Olúwa Ọlọ́run ti fi fún ọ; nínú ìdótì náà àti nínú ìhámọ́ náà tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò há ọ mọ́.
“Kuşatma sırasında düşmanınızın vereceği sıkıntıdan rahminizin meyvesini, Tanrınız RAB'bin size verdiği oğulların, kızların etini yiyeceksiniz.
54 Ọkùnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, ojú rẹ̀ yóò korò sí arákùnrin rẹ̀ àti sí aya oókan àyà rẹ̀, àti sí ìyókù ọmọ rẹ̀ tí òun jẹ kù.
Aranızdaki en yumuşak, en duyarlı adam bile öz kardeşine, sevdiği karısına, sağ kalan çocuklarına acımayacak;
55 Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fún ẹnikẹ́ni nínú ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ̀ tí ó ń jẹ, nítorí kò sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún un nínú ìdótì náà àti ìhámọ́, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ gbogbo.
yediği çocuklarının etini onların hiçbiriyle paylaşmayacak. Çünkü düşmanın kuşatma sırasında sizi sıkıştırması yüzünden kentlerinizde hiç yiyecek kalmayacak.
56 Obìnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, tí kò jẹ́ dáṣà láti fi àtẹ́lẹsẹ̀ ẹ rẹ̀ kan ilẹ̀ nítorí ìkẹ́ra àti ìwà ẹlẹgẹ́, ojú u rẹ̀ yóò korò sí ọkọ oókan àyà rẹ̀, àti sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ rẹ̀ obìnrin,
Aranızda en yumuşak, en duyarlı kadın –yumuşaklığından ve duyarlılığından ayağının tabanını yere basmak istemeyen kadın– bile sevdiği kocasından, öz oğlundan, kızından, plasentayı ve doğuracağı çocukları esirgeyecek. Çünkü kuşatma sırasında düşmanın kentlerinizde size vereceği sıkıntıdan, yokluktan onları gizlice yiyecek.
57 àti sí ọmọ rẹ̀ tí ó ti agbede-méjì ẹsẹ̀ rẹ̀ jáde, àti sí àwọn ọmọ rẹ̀ tí yóò bí. Nítorí òun ó jẹ wọ́n ní ìkọ̀kọ̀, nítorí àìní ohunkóhun nínú ìdótì àti ìhámọ́ náà, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ.
58 Bí ìwọ kò bá rọra tẹ̀lé gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí, tí a kọ sínú ìwé yìí, tí ìwọ kò sì bu ọlá fún ògo yìí àti orúkọ dáradára: orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ,
“Bu kitapta yazılı yasanın bütün sözlerine uymaz, Tanrınız RAB'bin yüce ve heybetli adından korkmazsanız,
59 Olúwa yóò sọ ìyọnu rẹ di ìyanu, àti ìyọnu irú-ọmọ ọ̀ rẹ, àní àwọn ìyọnu ńlá èyí tí yóò pẹ́, àti ààrùn búburú èyí tí yóò pẹ́.
RAB sizi ve soyunuzu korkunç belalarla, büyük ve sürekli belalarla, ağır, iyileşmez hastalıklarla vuracak.
60 Olúwa yóò mú gbogbo ààrùn Ejibiti tí ó mú ẹ̀rù bà ọ́ wá padà bá ọ, wọn yóò sì lẹ̀ mọ́ ọ.
Sizi ürküten Mısır'ın bütün hastalıklarını yeniden başınıza getirecek; size yapışacaklar.
61 Olúwa yóò tún mú onírúurú àìsàn àti ìpọ́njú tí a kò kọ sínú ìwé òfin yìí wá sórí rẹ, títí ìwọ yóò fi run.
Siz yok oluncaya dek RAB bu Yasa Kitabı'nda yazılmamış her türlü hastalığı ve belayı da başınıza getirecek.
62 Ìwọ tí ó dàbí àìmoye bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò ṣẹ́ku kékeré níye, nítorí tí o kò ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Gökteki yıldızlar kadar çok olan sizler, sayıca az bırakılacaksınız. Çünkü Tanrınız RAB'bin sözüne kulak vermediniz.
63 Gẹ́gẹ́ bí ó ti dùn mọ́ Olúwa nínú láti mú ọ ṣe rere àti láti pọ̀ si ní iye, bẹ́ẹ̀ ni yóò dùn mọ́ ọ nínú láti bì ọ́ ṣubú kí ó sì pa ọ́ run. Ìwọ yóò di fífà tu kúrò lórí ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
Size iyilik yapmak, sizi çoğaltmak RAB'bi nasıl sevindirdiyse, sizi yıkmak ve yok etmek de öyle sevindirecektir. Mülk edinmek için gideceğiniz ülkeden sökülüp atılacaksınız.
64 Nígbà náà ni Olúwa yóò fọ́n ọ ká láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, láti òpin kan ní ayé sí òmíràn. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò ti sin ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run igi àti ti òkúta. Èyí tí ìwọ àti àwọn baba rẹ kò mọ̀.
“RAB sizi dünyanın bir ucundan öbür ucuna, bütün halklar arasına dağıtacak. Orada sizin de atalarınızın da tanımadığı, ağaçtan ve taştan yapılmış başka ilahlara tapacaksınız.
65 Ìwọ kì yóò sinmi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà, kò sí ibi ìsinmi fún àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti fún ọ ní ọkàn ìnàngà, àárẹ̀ ojú, àti àìnírètí àyà.
Bu uluslar arasında ne esenliğiniz ne de dinlenecek bir yeriniz olacak. Orada RAB size titreyen yürekler, umutsuzluk ve bakmaktan yorulmuş gözler verecek.
66 Ìwọ yóò gbé ní ìdádúró ṣinṣin, kún fún ìbẹ̀rùbojo lọ́sàn án àti lóru, bẹ́ẹ̀ kọ́ láé ni ìwọ yóò rí i ní àrídájú wíwà láyé rẹ.
Sürekli can kaygısı içinde yaşayacaksınız. Gece gündüz dehşet içinde olacaksınız. Yaşamınızın güvenliği olmayacak.
67 Ìwọ yóò wí ní òwúrọ̀ pé, “Bí ó tilẹ̀ lè jẹ́ pé ìrọ̀lẹ́ nìkan ni!” Nítorí ẹ̀rù tí yóò gba ọkàn rẹ àti ìran tí ojú rẹ yóò máa rí.
Yüreğinizi kaplayan dehşet ve gözlerinizin gördüğü olaylar yüzünden, sabah, ‘Keşke akşam olsa!’, akşam, ‘Keşke sabah olsa!’ diyeceksiniz.
68 Olúwa yóò rán ọ padà nínú ọkọ̀ sí Ejibiti sí ìrìnàjò tí mo ní ìwọ kì yóò lọ mọ́. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò tún fi ara rẹ fún àwọn ọ̀tá à rẹ gẹ́gẹ́ bí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò rà ọ́.
Bir daha görmeyeceksiniz dediğim yoldan RAB sizi gemilerle Mısır'a geri gönderecek. Orada erkek ve kadın köle olarak kendinizi düşmanlarınıza satmaya kalkışacaksınız; ama satın alan olmayacak.”

< Deuteronomy 28 >