< Deuteronomy 28 >

1 Bí ìwọ bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní kíkún kí o sì kíyèsára láti tẹ̀lé gbogbo ohun tí ó pàṣẹ tí mo fi fún ọ lónìí, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé ọ lékè ju gbogbo orílẹ̀-èdè ayé lọ.
Şi se va întâmpla, dacă vei da ascultare cu atenţie vocii DOMNULUI Dumnezeul tău, luând seama să împlineşti toate poruncile lui, pe care ţi le poruncesc astăzi, că DOMNUL Dumnezeul tău te va înălţa mai presus de toate naţiunile pământului,
2 Gbogbo ìbùkún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ bí o bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Şi toate aceste binecuvântări vor veni peste tine şi te vor ajunge, dacă vei da ascultare vocii DOMNULUI Dumnezeul tău.
3 Ìbùkún ni fún ọ ni ìlú, ìbùkún ni fún ọ ní oko.
Binecuvântat vei fi în cetate şi binecuvântat vei fi în câmp.
4 Ìbùkún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, àti irú ohun ọ̀sìn rẹ àti ìbísí i màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
Binecuvântat va fi rodul trupului tău şi rodul pământului tău şi rodul vitelor tale, fătul vacilor tale şi turmele oilor tale.
5 Ìbùkún ni fún agbọ̀n rẹ àti fún ọpọ́n ipò ìyẹ̀fun rẹ.
Binecuvântat va fi coşul tău şi covata ta.
6 Ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá wọlé, ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
Binecuvântat vei fi când intri şi binecuvântat vei fi când ieşi.
7 Olúwa yóò gbà fún ọ pé gbogbo ọ̀tá tí ó dìde sí ọ yóò bì ṣubú níwájú rẹ. Wọn yóò tọ̀ ọ́ wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n wọn yóò sá fún ọ ní ọ̀nà méje.
DOMNUL va face pe duşmanii tăi, care se ridică împotriva ta, să fie bătuţi înaintea feţei tale; ei vor ieşi împotriva ta pe o cale şi vor fugi dinaintea ta pe şapte căi.
8 Olúwa yóò rán ìbùkún sí ọ àti sí ohun gbogbo tí o bá dáwọ́ rẹ lé. Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún un fún ọ nínú ilẹ̀ tí ó ń fi fún ọ.
DOMNUL va porunci binecuvântare asupra ta în depozitele tale şi pe tot ce îţi vei pune mâna; şi te va binecuvânta în ţara pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău.
9 Olúwa yóò fi ọ́ múlẹ̀ bí ènìyàn mímọ́, bí ó ti ṣe ìlérí fún ọ lórí ìbúra, bí o bá pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ mọ́ tí o sì ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
DOMNUL te va întemeia ca popor sfânt pentru el, precum ţi-a jurat, dacă vei păzi poruncile DOMNULUI Dumnezeul tău şi vei umbla în căile lui.
10 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ayé yóò rí i pé a pè ọ́ ní orúkọ Olúwa, wọn yóò sì bẹ̀rù rẹ.
Şi toate popoarele pământului vor vedea că eşti numit după numele DOMNULUI şi se vor teme de tine.
11 Olúwa yóò fi àlàáfíà fún ọ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́, fún ọmọ inú rẹ, irú ohun ọ̀sìn rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá rẹ láti fún ọ.
Şi DOMNUL te va face abundent în bunătăţi, în rodul trupului tău şi în rodul vitelor tale şi în rodul pământului tău, în ţara pe care DOMNUL a jurat părinţilor tăi să ţi-o dea.
12 Olúwa yóò ṣí ọ̀run sílẹ̀, ìṣúra rere rẹ̀ fún ọ, láti rọ òjò sórí ilẹ̀ rẹ ní àsìkò rẹ àti láti bùkún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ. Ìwọ yóò yá ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n ìwọ kò ní í yá lọ́wọ́ ẹnìkankan.
DOMNUL îţi va deschide tezaurul său bun, cerul să dea ploaie ţării tale la timpul ei şi să binecuvânteze toată lucrarea mâinii tale, şi vei da cu împrumut multor naţiuni, dar tu nu vei lua cu împrumut.
13 Olúwa yóò fi ọ́ ṣe orí, ìwọ kì yóò sì jẹ́ ìrù. Bí o bá fi etí sílẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ tí mo fi fún ọ kí o sì máa rọra tẹ̀lé wọn, ìwọ yóò máa wà lókè, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò wà ní ìsàlẹ̀ láé.
Şi DOMNUL te va face capul şi nu coada, şi vei fi numai deasupra şi nu vei fi dedesubt, dacă dai ascultare poruncilor DOMNULUI Dumnezeul tău, pe care ţi le poruncesc astăzi să iei seama şi să le împlineşti,
14 Má ṣe yà sọ́tùn tàbí sósì kúrò, nínú èyíkéyìí àwọn àṣẹ tí mo fi fún ọ ní òní yìí, kí o má ṣe tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti máa sìn wọ́n.
Şi să nu te abaţi nici la dreapta nici la stânga, de la niciunul dintre cuvintele pe care ţi le poruncesc astăzi, ca să mergi după alţi dumnezei să le serveşti.
15 Ṣùgbọ́n bí o kò bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì rọra máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí, gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ.
Dar se va întâmpla, dacă nu vei da ascultare vocii DOMNULUI Dumnezeul tău, ca să iei seama şi să împlineşti toate poruncile lui şi statutele lui, pe care ţi le poruncesc astăzi, că toate blestemele acestea vor veni peste tine şi te vor ajunge.
16 Ègún ni fún ọ ní ìlú, ègún ni fún ọ ní oko.
Blestemat vei fi în cetate şi blestemat în câmp.
17 Ègún ni fún agbọ̀n rẹ àti ọpọ́n ìpo-fúláwà rẹ.
Blestemat va fi coşul tău şi blestemată covata ta.
18 Ègún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, ìbísí màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
Blestemat va fi rodul trupului tău şi rodul ţării tale, fătul vacilor tale şi turmele oilor tale.
19 Ègún ni fún ọ nígbà tí o bá wọlé ègún sì ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
Blestemat vei fi când intri şi blestemat când ieşi.
20 Olúwa yóò rán ègún sórí rẹ, rúdurùdu àti ìfibú nínú gbogbo ohun tí o bá dáwọ́ rẹ lé, títí ìwọ yóò fi parun àti wá sí ìparun lójijì nítorí búburú tí o ti ṣe ní kíkọ̀ mi sílẹ̀.
DOMNUL va trimite peste tine blestem, chinuire şi mustrare, peste orice îţi vei pune mâna să faci, până când vei fi nimicit şi până când vei pieri repede, din cauza stricăciunii faptelor tale, prin care m-ai părăsit.
21 Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn bá ọ jà títí tí yóò fi pa ọ́ run kúrò ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
DOMNUL va face ciuma să se lipească de tine, până când te va nimici din ţara în care intri să o stăpâneşti.
22 Olúwa yóò kọlù ọ́ pẹ̀lú ààrùn ìgbẹ́, pẹ̀lú ibà àti àìsàn wíwú, pẹ̀lú ìjóni ńlá àti idà, pẹ̀lú ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù tí yóò yọ ọ́ lẹ́nu títí ìwọ yóò fi parun.
DOMNUL te va lovi cu mistuire şi cu febră şi cu inflamare şi cu arsură puternică şi cu sabie şi cu tăciune în grâu şi cu mană; şi ele te vor urmări până vei pieri.
23 Ojú ọ̀run tí ó wà lórí rẹ yóò jẹ́ idẹ, ilẹ̀ tí ń bẹ níṣàlẹ̀ rẹ yóò sì jẹ́ irin.
Şi cerul tău care este deasupra capului tău va fi aramă, şi pământul care este sub tine, fier.
24 Olúwa yóò yí òjò ilẹ̀ rẹ sí eruku àti ẹ̀tù; láti ọ̀run ni yóò ti máa sọ̀kalẹ̀ sí ọ, títí tí ìwọ yóò fi run.
DOMNUL va face ploaia peste ţara ta, pulbere şi praf, ele vor coborî din cer asupra ta, până când vei fi nimicit.
25 Olúwa yóò fi ọ́ gégùn ún láti ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá rẹ. Ìwọ yóò tọ̀ wọ́n wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá fún wọn ní ọ̀nà méje, ìwọ yóò sì padà di ohun ìbẹ̀rù fún gbogbo ìjọba lórí ayé.
DOMNUL va face să fii bătut înaintea duşmanilor tăi, vei ieşi împotriva lor pe o cale şi vei fugi dinaintea lor pe şapte căi şi vei fi alungat în toate împărăţiile pământului.
26 Òkú rẹ yóò jẹ́ oúnjẹ fún gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko ayé, àti pé kò ní sí ẹnikẹ́ni tí yóò lé wọn kúrò.
Şi trupul tău mort va fi hrană pentru toate păsările cerului şi fiarele pământului şi nimeni nu le va speria.
27 Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú oówo, Ejibiti àti pẹ̀lú kókó, ojú egbò kíkẹ̀ àti ìhúnra.
DOMNUL te va lovi cu ulcerele Egiptului şi cu tumori şi cu crustă şi cu pecingine, de care nu te poţi vindeca.
28 Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú ìsínwín, ojú fífọ́ àti rúdurùdu àyà.
DOMNUL te va lovi cu nebunie şi cu orbire şi cu înmărmurire a inimii,
29 Ní ọ̀sán gangan ìwọ yóò fi ọwọ́ tálẹ̀ kiri bí ọkùnrin afọ́jú nínú òkùnkùn ìwọ kì yóò ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí o bá ń ṣe, ojoojúmọ́ ni wọn yóò máa ni ọ́ lára àti jà ọ́ ní olè, tí kò sì ní í sí ẹnìkan láti gbà ọ́.
Şi vei bâjbâi în miezul zilei, precum bâjbâie orbul în întuneric, şi nu vei prospera în căile tale şi vei fi mereu oprimat şi prădat în toate zilele, şi nimeni nu te va salva.
30 Ìwọ yóò gba ògo láti fẹ́ obìnrin kan ṣùgbọ́n ẹlòmíràn yóò gbà á yóò sì tẹ́ ẹ́ ní ògo. Ìwọ yóò kọ́ ilé, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò gbé ibẹ̀. Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kò tilẹ̀ ní gbádùn èso rẹ.
Te vei logodi cu o femeie şi un alt bărbat se va culca cu ea, vei zidi o casă şi nu vei locui în ea, vei sădi o vie şi nu vei aduna strugurii din ea.
31 Màlúù rẹ yóò di pípa níwájú rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò jẹ nǹkan kan nínú rẹ̀. Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ yóò sì di mímú pẹ̀lú agbára kúrò lọ́dọ̀ rẹ, a kì yóò sì da padà. Àgùntàn rẹ yóò di mímú fún àwọn ọ̀tá rẹ, ẹnìkankan kò sì ní gbà á.
Boul tău va fi înjunghiat înaintea ochilor tăi şi nu vei mânca din el, măgarul tău va fi luat dinaintea feţei tale cu violenţă şi nu îţi va fi înapoiat; oile tale vor fi date duşmanilor tăi şi nu vei avea pe nimeni ca să le salveze.
32 Àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ yóò di mímú fún àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, ìwọ yóò sì fi ojú rẹ ṣọ́nà dúró dè wọ́n láti ọjọ́ dé ọjọ́, ìwọ yóò sì jẹ́ aláìlágbára láti gbé ọwọ́.
Fiii tăi şi fiicele tale vor fi daţi altui popor şi ochii tăi vor privi şi se vor topi de dor după ei toată ziua şi nu va fi nicio putere în mâna ta.
33 Èso ilẹ̀ rẹ àti gbogbo iṣẹ́ làálàá rẹ ni orílẹ̀-èdè mìíràn tí ìwọ kò mọ̀ yóò sì jẹ, ìwọ yóò jẹ́ kìkì ẹni ìnilára àti ẹni ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
O naţiune, pe care nu o cunoşti, va mânca rodul ţării tale şi toate muncile tale; şi vei fi doar oprimat şi zdrobit întotdeauna;
34 Ìran tí ojú rẹ yóò rí, yóò sọ ọ́ di òmùgọ̀.
Astfel că vei înnebuni la priveliştea pe care ochii tăi o vor vedea.
35 Olúwa yóò lu eékún àti ẹsẹ̀ rẹ pẹ̀lú oówo dídùn tí kò le san tán láti àtẹ̀lé méjèèjì rẹ lọ sí òkè orí rẹ.
DOMNUL te va lovi la genunchi şi la picioare, de la talpa piciorului tău până în creştetul capului tău, cu un ulcer rău care nu poate fi vindecat.
36 Olúwa yóò lé ọ àti ọba tí ó yàn lórí rẹ lọ sí orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ tàbí ti àwọn baba rẹ kò mọ̀. Ibẹ̀ ni ìwọ̀ yóò sì sin ọlọ́run mìíràn, ọlọ́run igi àti òkúta.
DOMNUL te va duce pe tine şi pe împăratul tău, pe care îl vei pune peste tine, la o naţiune pe care nu ai cunoscut-o nici tu nici părinţii tăi şi acolo vei servi altor dumnezei, lemn şi piatră.
37 Ìwọ yóò di ẹni ìyanu, àti ẹni òwe, àti ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ nínú gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò darí rẹ sí.
Şi vei deveni o înmărmurire, un proverb şi o zicătoare, între toate naţiunile unde te va conduce DOMNUL.
38 Ìwọ yóò gbin irúgbìn púpọ̀ ṣùgbọ́n ìwọ yóò kórè kékeré, nítorí eṣú yóò jẹ ẹ́ run.
Vei duce multă sămânţă la câmp şi vei strânge puţin, pentru că o va mistui lăcusta.
39 Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà púpọ̀ ìwọ yóò sì ro wọ́n ṣùgbọ́n kò ní mú wáìnì náà tàbí kó àwọn èso jọ, nítorí kòkòrò yóò jẹ wọ́n run.
Vei sădi vii şi le vei lucra, dar nu vei bea nici din vin, nici nu vei strânge strugurii, pentru că viermii îi vor mânca.
40 Ìwọ yóò ní igi olifi jákèjádò ilẹ̀ rẹ ṣùgbọ́n ìwọ kò ní lo òróró náà, nítorí olifi náà yóò rẹ̀ dànù.
Vei avea măslini în toate ţinuturile tale, dar nu te vei unge cu untdelemn, pentru că măslinul tău îşi va lepăda rodul său.
41 Ìwọ yóò ní àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin ṣùgbọ́n ìwọ kò nípa wọ́n mọ́, nítorí wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
Vei naşte fii şi fiice, dar nu te vei bucura de ei, pentru că vor merge în captivitate.
42 Ọ̀wọ́ eṣú yóò gba gbogbo àwọn igi rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ.
Lăcusta va mistui toţi copacii tăi şi rodul ţării tale.
43 Àjèjì tí ń gbé láàrín rẹ yóò gbé sókè gíga jù ọ́ lọ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò máa di ìrẹ̀sílẹ̀.
Străinul care este la tine se va înălţa peste tine foarte sus; şi tu vei coborî foarte jos.
44 Yóò yà ọ́, ṣùgbọ́n o kì yóò yà á, òun ni yóò jẹ́ orí, ìwọ yóò jẹ́ ìrù.
El îţi va împrumuta şi tu nu îi vei împrumuta, el va fi capul, iar tu vei fi coada.
45 Gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ, wọn yóò lé ọ wọn yóò sì bá ọ títí tí ìwọ yóò fi parun, nítorí ìwọ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ kò sì kíyèsi àṣẹ àti òfin tí ó fi fún ọ.
Mai mult, toate aceste blesteme vor veni peste tine şi te vor urmări şi te vor ajunge, până vei fi nimicit, pentru că nu ai dat ascultare vocii DOMNULUI Dumnezeul tău, ca să păzeşti poruncile lui şi statutele lui, pe care ţi le-a poruncit.
46 Wọn yóò jẹ́ àmì àti ìyanu fún ọ àti fún irú-ọmọ rẹ títí láé.
Şi ele vor fi peste tine şi peste sămânţa ta pentru totdeauna, ca un semn şi ca o minune.
47 Nítorí ìwọ kò sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ní ayọ̀ àti inú dídùn ní àkókò àlàáfíà.
Pentru că nu ai servit DOMNULUI Dumnezeul tău cu bucurie şi cu veselie a inimii, pentru abundenţa în toate;
48 Nítorí náà nínú ebi àti òǹgbẹ, nínú ìhòhò àti àìní búburú, ìwọ yóò sin àwọn ọ̀tá à rẹ tí Olúwa rán sí ọ. Yóò sì fi àjàgà irin bọ̀ ọ́ ní ọrùn, títí yóò fi run ọ́.
De aceea vei servi pe duşmanii tăi, pe care îi va trimite DOMNUL împotriva ta, în foame şi în sete şi în goliciune şi în lipsă de toate, şi el va pune un jug de fier pe grumazul tău, până te va nimici.
49 Olúwa yóò mú àwọn orílẹ̀-èdè wá sí ọ láti ọ̀nà jíjìn, bí òpin ayé, bí idì ti ń bẹ́ láti orí òkè sílẹ̀, orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò gbọ́ èdè wọn.
DOMNUL va aduce împotriva ta o naţiune de departe, de la marginea pământului, precum zboară acvila; o naţiune a cărei limbă nu o vei înţelege;
50 Orílẹ̀-èdè tí ó rorò tí kò ní ojúrere fún àgbà tàbí àánú fún ọmọdé.
O naţiune aspră la înfăţişare, care nu se uită la faţa bătrânilor, nici nu arată favoare tânărului,
51 Wọn yóò jẹ ohun ọ̀sìn rẹ run àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ títí tí ìwọ yóò fi parun. Wọn kì yóò fi hóró irúgbìn kan fún ọ, wáìnì tuntun tàbí òróró, tàbí agbo ẹran màlúù rẹ kankan tàbí ọ̀wọ́ ẹran àgùntàn rẹ títí ìwọ yóò fi run.
Şi va mânca rodul vitelor tale şi rodul ţării tale, până vei fi nimicit, care nu îţi va lăsa nici grâu, nici vin, nici untdelemn, nici fătul vacilor tale, nici turmele oilor tale, până te va nimici.
52 Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ títí tí odi ìdáàbòbò gíga yẹn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé yóò fi wó lulẹ̀. Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ jákèjádò ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ.
Şi te va asedia în toate porţile tale în toată ţara ta, până se vor prăbuşi zidurile tale înalte şi întărite, în care te-ai încrezut; şi te va asedia în toate porţile tale în toată ţara ta, pe care ţi-a dat-o DOMNUL Dumnezeul tău.
53 Ìwọ ó sì jẹ èso ọmọ inú rẹ̀, ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti ti àwọn ọmọ rẹ obìnrin tí Olúwa Ọlọ́run ti fi fún ọ; nínú ìdótì náà àti nínú ìhámọ́ náà tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò há ọ mọ́.
Şi, în asediul şi în strâmtorarea cu care te vor chinui duşmanii tăi, vei mânca rodul propriului tău trup, carnea fiilor tăi şi a fiicelor tale pe care ţi-i va da DOMNUL Dumnezeul tău,
54 Ọkùnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, ojú rẹ̀ yóò korò sí arákùnrin rẹ̀ àti sí aya oókan àyà rẹ̀, àti sí ìyókù ọmọ rẹ̀ tí òun jẹ kù.
Astfel încât ochiul bărbatului plăpând şi foarte delicat printre voi, va fi rău faţă de fratele său şi faţă de soţia sânului său şi faţă de rămăşiţa copiilor săi, pe care îi va lăsa,
55 Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fún ẹnikẹ́ni nínú ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ̀ tí ó ń jẹ, nítorí kò sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún un nínú ìdótì náà àti ìhámọ́, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ gbogbo.
Astfel încât nu va da niciunuia dintre ei din carnea copiilor săi, pe care o va mânca el, pentru că nu i-a rămas nimic în asediul şi în strâmtorarea cu care te vor chinui duşmanii tăi, în toate porţile tale.
56 Obìnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, tí kò jẹ́ dáṣà láti fi àtẹ́lẹsẹ̀ ẹ rẹ̀ kan ilẹ̀ nítorí ìkẹ́ra àti ìwà ẹlẹgẹ́, ojú u rẹ̀ yóò korò sí ọkọ oókan àyà rẹ̀, àti sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ rẹ̀ obìnrin,
Femeia plăpândă şi delicată dintre voi, care nu ar fi cutezat să pună talpa piciorului ei pe pământ, din delicateţe şi sensibilitate, ochiul ei va fi rău faţă de soţul sânului ei şi faţă de fiul ei şi faţă de fiica ei,
57 àti sí ọmọ rẹ̀ tí ó ti agbede-méjì ẹsẹ̀ rẹ̀ jáde, àti sí àwọn ọmọ rẹ̀ tí yóò bí. Nítorí òun ó jẹ wọ́n ní ìkọ̀kọ̀, nítorí àìní ohunkóhun nínú ìdótì àti ìhámọ́ náà, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ.
Şi faţă de fătul ei, care iese dintre picioarele ei, şi faţă de copiii ei, pe care îi va naşte, pentru că în lipsă de toate îi va mânca în ascuns, în asediul şi în strâmtorarea cu care te va chinui dușmanul tău în porţile tale.
58 Bí ìwọ kò bá rọra tẹ̀lé gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí, tí a kọ sínú ìwé yìí, tí ìwọ kò sì bu ọlá fún ògo yìí àti orúkọ dáradára: orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ,
Dacă nu vei lua seama să împlineşti toate cuvintele acestei legi, care sunt scrise în această carte, ca să te temi de numele acesta glorios şi înspăimântător, DOMNUL DUMNEZEUL TĂU,
59 Olúwa yóò sọ ìyọnu rẹ di ìyanu, àti ìyọnu irú-ọmọ ọ̀ rẹ, àní àwọn ìyọnu ńlá èyí tí yóò pẹ́, àti ààrùn búburú èyí tí yóò pẹ́.
Atunci DOMNUL va face îngrozitoare plăgile tale şi plăgile seminţei tale, plăgi mari şi îndelungate, cu boli rele şi îndelungate.
60 Olúwa yóò mú gbogbo ààrùn Ejibiti tí ó mú ẹ̀rù bà ọ́ wá padà bá ọ, wọn yóò sì lẹ̀ mọ́ ọ.
Mai mult, el va aduce asupra ta toate bolile Egiptului, de care te-ai temut; şi ele se vor lipi de tine.
61 Olúwa yóò tún mú onírúurú àìsàn àti ìpọ́njú tí a kò kọ sínú ìwé òfin yìí wá sórí rẹ, títí ìwọ yóò fi run.
De asemenea, fiecare boală şi fiecare plagă, care nu este scrisă în cartea acestei legi, pe ele DOMNUL le va aduce asupra ta, până vei fi nimicit.
62 Ìwọ tí ó dàbí àìmoye bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò ṣẹ́ku kékeré níye, nítorí tí o kò ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Şi veţi fi lăsaţi puţini la număr, deşi eraţi mulţi ca stelele cerului, pentru că ai refuzat să asculţi de vocea DOMNULUI Dumnezeul tău.
63 Gẹ́gẹ́ bí ó ti dùn mọ́ Olúwa nínú láti mú ọ ṣe rere àti láti pọ̀ si ní iye, bẹ́ẹ̀ ni yóò dùn mọ́ ọ nínú láti bì ọ́ ṣubú kí ó sì pa ọ́ run. Ìwọ yóò di fífà tu kúrò lórí ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
Şi se va întâmpla, precum DOMNUL s-a bucurat de voi să vă facă bine şi să vă înmulţească, tot astfel DOMNUL se va bucura de voi să vă nimicească şi să vă facă de nimic; şi veţi fi smulşi din ţara în care intri ca să o stăpâneşti.
64 Nígbà náà ni Olúwa yóò fọ́n ọ ká láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, láti òpin kan ní ayé sí òmíràn. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò ti sin ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run igi àti ti òkúta. Èyí tí ìwọ àti àwọn baba rẹ kò mọ̀.
Şi DOMNUL te va împrăştia printre toate popoarele, de la o margine a pământului până la cealaltă; şi acolo vei servi altor dumnezei, pe care nu i-ai cunoscut, nici tu, nici părinţii tăi, lemn şi piatră.
65 Ìwọ kì yóò sinmi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà, kò sí ibi ìsinmi fún àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti fún ọ ní ọkàn ìnàngà, àárẹ̀ ojú, àti àìnírètí àyà.
Şi printre aceste naţiuni nu vei avea linişte, nici talpa piciorului tău nu va avea odihnă, ci DOMNUL îţi va da acolo o inimă cutremurată şi ochi care se topesc şi tristeţe a minţii,
66 Ìwọ yóò gbé ní ìdádúró ṣinṣin, kún fún ìbẹ̀rùbojo lọ́sàn án àti lóru, bẹ́ẹ̀ kọ́ láé ni ìwọ yóò rí i ní àrídájú wíwà láyé rẹ.
Şi viaţa ta va atârna în îndoială înaintea ta, şi te vei teme noaptea şi ziua şi nu vei avea siguranţă pentru viaţa ta,
67 Ìwọ yóò wí ní òwúrọ̀ pé, “Bí ó tilẹ̀ lè jẹ́ pé ìrọ̀lẹ́ nìkan ni!” Nítorí ẹ̀rù tí yóò gba ọkàn rẹ àti ìran tí ojú rẹ yóò máa rí.
Dimineaţa vei spune: De ar fi seară! Şi seara vei spune: De ar voi Dumnezeu să fie dimineaţă! De teama inimii tale, de care te vei teme, şi de priveliştea, pe care ochii tăi o vor vedea.
68 Olúwa yóò rán ọ padà nínú ọkọ̀ sí Ejibiti sí ìrìnàjò tí mo ní ìwọ kì yóò lọ mọ́. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò tún fi ara rẹ fún àwọn ọ̀tá à rẹ gẹ́gẹ́ bí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò rà ọ́.
Şi DOMNUL te va întoarce în Egipt cu corăbii, pe calea despre care ţi-am vorbit: Să nu o mai vezi; şi acolo veţi fi vânduţi duşmanilor voştri ca robi şi roabe şi nimeni nu vă va cumpăra.

< Deuteronomy 28 >