< Deuteronomy 28 >

1 Bí ìwọ bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní kíkún kí o sì kíyèsára láti tẹ̀lé gbogbo ohun tí ó pàṣẹ tí mo fi fún ọ lónìí, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé ọ lékè ju gbogbo orílẹ̀-èdè ayé lọ.
Acontecerá, se você ouvir diligentemente a voz de Javé seu Deus, observar para cumprir todos os seus mandamentos que eu lhe ordeno hoje, que Javé seu Deus o elevará acima de todas as nações da terra.
2 Gbogbo ìbùkún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ bí o bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Todas estas bênçãos virão sobre você, e o alcançarão, se você ouvir a voz de Yahweh, seu Deus.
3 Ìbùkún ni fún ọ ni ìlú, ìbùkún ni fún ọ ní oko.
Você será abençoado na cidade, e você será abençoado no campo.
4 Ìbùkún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, àti irú ohun ọ̀sìn rẹ àti ìbísí i màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
Você será abençoado no fruto de seu corpo, no fruto de sua terra, no fruto de seus animais, no aumento de seu gado e nos filhotes de seu rebanho.
5 Ìbùkún ni fún agbọ̀n rẹ àti fún ọpọ́n ipò ìyẹ̀fun rẹ.
Sua cesta e seu cocho de amassar serão abençoados.
6 Ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá wọlé, ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
Serás abençoado quando entrares e serás abençoado quando saíres.
7 Olúwa yóò gbà fún ọ pé gbogbo ọ̀tá tí ó dìde sí ọ yóò bì ṣubú níwájú rẹ. Wọn yóò tọ̀ ọ́ wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n wọn yóò sá fún ọ ní ọ̀nà méje.
Yahweh fará com que seus inimigos que se levantam contra você sejam atingidos antes de você. Eles sairão contra você de uma maneira, e fugirão diante de você de sete maneiras.
8 Olúwa yóò rán ìbùkún sí ọ àti sí ohun gbogbo tí o bá dáwọ́ rẹ lé. Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún un fún ọ nínú ilẹ̀ tí ó ń fi fún ọ.
Yahweh ordenará a bênção sobre você em seus celeiros, e em tudo a que você colocar sua mão. Ele o abençoará na terra que Yahweh seu Deus lhe dá.
9 Olúwa yóò fi ọ́ múlẹ̀ bí ènìyàn mímọ́, bí ó ti ṣe ìlérí fún ọ lórí ìbúra, bí o bá pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ mọ́ tí o sì ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Javé vos estabelecerá para um povo santo para si mesmo, como ele vos jurou, se guardardes os mandamentos de Javé vosso Deus, e andardes nos seus caminhos.
10 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ayé yóò rí i pé a pè ọ́ ní orúkọ Olúwa, wọn yóò sì bẹ̀rù rẹ.
Todos os povos da terra verão que você é chamado pelo nome de Iavé, e terão medo de você.
11 Olúwa yóò fi àlàáfíà fún ọ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́, fún ọmọ inú rẹ, irú ohun ọ̀sìn rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá rẹ láti fún ọ.
Javé te concederá abundante prosperidade no fruto de teu corpo, no fruto de teu gado e no fruto de tua terra, na terra que Javé jurou a teus pais te dar.
12 Olúwa yóò ṣí ọ̀run sílẹ̀, ìṣúra rere rẹ̀ fún ọ, láti rọ òjò sórí ilẹ̀ rẹ ní àsìkò rẹ àti láti bùkún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ. Ìwọ yóò yá ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n ìwọ kò ní í yá lọ́wọ́ ẹnìkankan.
Yahweh lhe abrirá seu bom tesouro no céu, para dar a chuva de sua terra em sua estação e para abençoar todo o trabalho de sua mão. Você emprestará a muitas nações, e não tomará emprestado.
13 Olúwa yóò fi ọ́ ṣe orí, ìwọ kì yóò sì jẹ́ ìrù. Bí o bá fi etí sílẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ tí mo fi fún ọ kí o sì máa rọra tẹ̀lé wọn, ìwọ yóò máa wà lókè, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò wà ní ìsàlẹ̀ láé.
Yahweh fará de você a cabeça, e não a cauda. Você estará somente acima, e não estará abaixo, se escutar os mandamentos de Javé seu Deus que eu lhe ordeno hoje, para observar e fazer,
14 Má ṣe yà sọ́tùn tàbí sósì kúrò, nínú èyíkéyìí àwọn àṣẹ tí mo fi fún ọ ní òní yìí, kí o má ṣe tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti máa sìn wọ́n.
e não se afastará de nenhuma das palavras que eu lhe ordeno hoje, para a mão direita ou para a esquerda, para ir atrás de outros deuses para servi-los.
15 Ṣùgbọ́n bí o kò bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì rọra máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí, gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ.
Mas acontecerá, se você não ouvir a voz de Javé, seu Deus, para cumprir todos os seus mandamentos e seus estatutos que eu lhe ordeno hoje, que todas estas maldições virão sobre você e o ultrapassarão.
16 Ègún ni fún ọ ní ìlú, ègún ni fún ọ ní oko.
Você será amaldiçoado na cidade, e você será amaldiçoado no campo.
17 Ègún ni fún agbọ̀n rẹ àti ọpọ́n ìpo-fúláwà rẹ.
Sua cesta e seu cocho de amassar serão amaldiçoados.
18 Ègún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, ìbísí màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
O fruto de seu corpo, o fruto de seu solo, o aumento de seu gado e os filhotes de seu rebanho serão amaldiçoados.
19 Ègún ni fún ọ nígbà tí o bá wọlé ègún sì ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
Você será amaldiçoado quando entrar, e será amaldiçoado quando sair.
20 Olúwa yóò rán ègún sórí rẹ, rúdurùdu àti ìfibú nínú gbogbo ohun tí o bá dáwọ́ rẹ lé, títí ìwọ yóò fi parun àti wá sí ìparun lójijì nítorí búburú tí o ti ṣe ní kíkọ̀ mi sílẹ̀.
Yahweh enviará sobre você maldição, confusão e repreensão em tudo o que você colocar sua mão para fazer, até que você seja destruído e até que pereça rapidamente, por causa do mal de seus atos, pelos quais você me abandonou.
21 Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn bá ọ jà títí tí yóò fi pa ọ́ run kúrò ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
Yahweh fará com que a pestilência se agarre a você, até que ele o tenha consumido de fora da terra onde você entra para possuí-la.
22 Olúwa yóò kọlù ọ́ pẹ̀lú ààrùn ìgbẹ́, pẹ̀lú ibà àti àìsàn wíwú, pẹ̀lú ìjóni ńlá àti idà, pẹ̀lú ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù tí yóò yọ ọ́ lẹ́nu títí ìwọ yóò fi parun.
Yahweh irá golpeá-lo com consumo, com febre, com inflamação, com calor ardente, com a espada, com a ferrugem e com o míldio. Eles o perseguirão até que você pereça.
23 Ojú ọ̀run tí ó wà lórí rẹ yóò jẹ́ idẹ, ilẹ̀ tí ń bẹ níṣàlẹ̀ rẹ yóò sì jẹ́ irin.
Seu céu que está sobre sua cabeça será de bronze, e a terra que está sob você será de ferro.
24 Olúwa yóò yí òjò ilẹ̀ rẹ sí eruku àti ẹ̀tù; láti ọ̀run ni yóò ti máa sọ̀kalẹ̀ sí ọ, títí tí ìwọ yóò fi run.
Yahweh fará a chuva de sua terra pó e poeira. Ela cairá sobre você do céu, até que você seja destruído.
25 Olúwa yóò fi ọ́ gégùn ún láti ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá rẹ. Ìwọ yóò tọ̀ wọ́n wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá fún wọn ní ọ̀nà méje, ìwọ yóò sì padà di ohun ìbẹ̀rù fún gbogbo ìjọba lórí ayé.
Yahweh fará com que você seja atingido antes de seus inimigos. Você sairá um caminho contra eles, e fugirá sete caminhos antes deles. Você será jogado para frente e para trás entre todos os reinos da terra.
26 Òkú rẹ yóò jẹ́ oúnjẹ fún gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko ayé, àti pé kò ní sí ẹnikẹ́ni tí yóò lé wọn kúrò.
Seus corpos mortos serão alimento para todas as aves do céu, e para os animais da terra; e não haverá ninguém que os afugente.
27 Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú oówo, Ejibiti àti pẹ̀lú kókó, ojú egbò kíkẹ̀ àti ìhúnra.
Yahweh vos atingirá com os furúnculos do Egito, com os tumores, com o escorbuto, e com a coceira, da qual não podereis ser curados.
28 Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú ìsínwín, ojú fífọ́ àti rúdurùdu àyà.
Yahweh irá golpeá-lo com loucura, com cegueira e com espanto do coração.
29 Ní ọ̀sán gangan ìwọ yóò fi ọwọ́ tálẹ̀ kiri bí ọkùnrin afọ́jú nínú òkùnkùn ìwọ kì yóò ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí o bá ń ṣe, ojoojúmọ́ ni wọn yóò máa ni ọ́ lára àti jà ọ́ ní olè, tí kò sì ní í sí ẹnìkan láti gbà ọ́.
Você vai apalpar ao meio-dia, como os apalpões cegos na escuridão, e não prosperará em seus caminhos. Vocês só serão oprimidos e roubados sempre, e não haverá ninguém para salvá-los.
30 Ìwọ yóò gba ògo láti fẹ́ obìnrin kan ṣùgbọ́n ẹlòmíràn yóò gbà á yóò sì tẹ́ ẹ́ ní ògo. Ìwọ yóò kọ́ ilé, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò gbé ibẹ̀. Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kò tilẹ̀ ní gbádùn èso rẹ.
Você desposará uma esposa, e outro homem se deitará com ela. Construirás uma casa, e não morarás nela. Você plantará uma vinha, e não usará seus frutos.
31 Màlúù rẹ yóò di pípa níwájú rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò jẹ nǹkan kan nínú rẹ̀. Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ yóò sì di mímú pẹ̀lú agbára kúrò lọ́dọ̀ rẹ, a kì yóò sì da padà. Àgùntàn rẹ yóò di mímú fún àwọn ọ̀tá rẹ, ẹnìkankan kò sì ní gbà á.
Seu boi será morto diante de seus olhos, e você não comerá nada dele. Seu burro será violentamente retirado de diante de seu rosto, e não será restaurado a você. Suas ovelhas serão entregues a seus inimigos, e você não terá ninguém para salvá-lo.
32 Àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ yóò di mímú fún àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, ìwọ yóò sì fi ojú rẹ ṣọ́nà dúró dè wọ́n láti ọjọ́ dé ọjọ́, ìwọ yóò sì jẹ́ aláìlágbára láti gbé ọwọ́.
Seus filhos e suas filhas serão dados a outro povo. Seus olhos olharão e falharão com saudade deles durante todo o dia. Não haverá poder em sua mão.
33 Èso ilẹ̀ rẹ àti gbogbo iṣẹ́ làálàá rẹ ni orílẹ̀-èdè mìíràn tí ìwọ kò mọ̀ yóò sì jẹ, ìwọ yóò jẹ́ kìkì ẹni ìnilára àti ẹni ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
Uma nação que você não conhece comerá o fruto de sua terra e todo o seu trabalho. Você só será oprimido e esmagado sempre,
34 Ìran tí ojú rẹ yóò rí, yóò sọ ọ́ di òmùgọ̀.
para que as vistas que você vê com seus olhos o deixem louco.
35 Olúwa yóò lu eékún àti ẹsẹ̀ rẹ pẹ̀lú oówo dídùn tí kò le san tán láti àtẹ̀lé méjèèjì rẹ lọ sí òkè orí rẹ.
Yahweh lhe acertará nos joelhos e nas pernas com uma ferida que não poderá ser curada, desde a sola do pé até a coroa da cabeça.
36 Olúwa yóò lé ọ àti ọba tí ó yàn lórí rẹ lọ sí orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ tàbí ti àwọn baba rẹ kò mọ̀. Ibẹ̀ ni ìwọ̀ yóò sì sin ọlọ́run mìíràn, ọlọ́run igi àti òkúta.
Yahweh vos levará, e a vosso rei que colocareis sobre vós, a uma nação que não conheceis, nem vós nem vossos pais. Ali servireis a outros deuses da madeira e da pedra.
37 Ìwọ yóò di ẹni ìyanu, àti ẹni òwe, àti ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ nínú gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò darí rẹ sí.
Vós vos tornareis um espanto, um provérbio e uma palavra de ordem entre todos os povos onde Iavé vos conduzirá.
38 Ìwọ yóò gbin irúgbìn púpọ̀ ṣùgbọ́n ìwọ yóò kórè kékeré, nítorí eṣú yóò jẹ ẹ́ run.
Você levará muitas sementes para o campo e pouco se reunirá, pois o gafanhoto as consumirá.
39 Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà púpọ̀ ìwọ yóò sì ro wọ́n ṣùgbọ́n kò ní mú wáìnì náà tàbí kó àwọn èso jọ, nítorí kòkòrò yóò jẹ wọ́n run.
Vocês plantarão vinhedos e os vestirão, mas não beberão do vinho, nem colherão, pois os vermes os comerão.
40 Ìwọ yóò ní igi olifi jákèjádò ilẹ̀ rẹ ṣùgbọ́n ìwọ kò ní lo òróró náà, nítorí olifi náà yóò rẹ̀ dànù.
Você terá oliveiras em todas as suas bordas, mas não se ungirá com o azeite, pois suas azeitonas cairão.
41 Ìwọ yóò ní àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin ṣùgbọ́n ìwọ kò nípa wọ́n mọ́, nítorí wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
Você será pai de filhos e filhas, mas eles não serão seus, pois eles irão para o cativeiro.
42 Ọ̀wọ́ eṣú yóò gba gbogbo àwọn igi rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ.
Locusts consumirá todas as suas árvores e os frutos do seu solo.
43 Àjèjì tí ń gbé láàrín rẹ yóò gbé sókè gíga jù ọ́ lọ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò máa di ìrẹ̀sílẹ̀.
O estrangeiro que estiver entre vocês subirá acima de vocês cada vez mais alto, e vocês descerão cada vez mais baixo.
44 Yóò yà ọ́, ṣùgbọ́n o kì yóò yà á, òun ni yóò jẹ́ orí, ìwọ yóò jẹ́ ìrù.
Ele emprestará a vocês e vocês não emprestarão a ele. Ele será a cabeça, e vocês serão a cauda.
45 Gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ, wọn yóò lé ọ wọn yóò sì bá ọ títí tí ìwọ yóò fi parun, nítorí ìwọ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ kò sì kíyèsi àṣẹ àti òfin tí ó fi fún ọ.
Todas estas maldições virão sobre você, e o perseguirão e o ultrapassarão, até que seja destruído, porque você não ouviu a voz de Javé, seu Deus, para cumprir seus mandamentos e seus estatutos que ele lhe ordenou.
46 Wọn yóò jẹ́ àmì àti ìyanu fún ọ àti fún irú-ọmọ rẹ títí láé.
Eles serão por um sinal e por uma maravilha para você e para sua prole para sempre.
47 Nítorí ìwọ kò sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ní ayọ̀ àti inú dídùn ní àkókò àlàáfíà.
Porque não serviste a Javé teu Deus com alegria e com alegria de coração, em razão da abundância de todas as coisas;
48 Nítorí náà nínú ebi àti òǹgbẹ, nínú ìhòhò àti àìní búburú, ìwọ yóò sin àwọn ọ̀tá à rẹ tí Olúwa rán sí ọ. Yóò sì fi àjàgà irin bọ̀ ọ́ ní ọrùn, títí yóò fi run ọ́.
portanto, servirás a teus inimigos que Javé envia contra ti, na fome, na sede, na nudez e na falta de todas as coisas. Ele colocará um jugo de ferro no seu pescoço até que ele o tenha destruído.
49 Olúwa yóò mú àwọn orílẹ̀-èdè wá sí ọ láti ọ̀nà jíjìn, bí òpin ayé, bí idì ti ń bẹ́ láti orí òkè sílẹ̀, orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò gbọ́ èdè wọn.
Javé trará uma nação contra você de longe, do fim da terra, como a águia voa: uma nação cuja língua você não entenderá,
50 Orílẹ̀-èdè tí ó rorò tí kò ní ojúrere fún àgbà tàbí àánú fún ọmọdé.
uma nação de expressões faciais ferozes, que não respeita os idosos, nem mostra favor aos jovens.
51 Wọn yóò jẹ ohun ọ̀sìn rẹ run àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ títí tí ìwọ yóò fi parun. Wọn kì yóò fi hóró irúgbìn kan fún ọ, wáìnì tuntun tàbí òróró, tàbí agbo ẹran màlúù rẹ kankan tàbí ọ̀wọ́ ẹran àgùntàn rẹ títí ìwọ yóò fi run.
eles comerão o fruto de seu gado e o fruto de sua terra, até que você seja destruído. Eles também não lhe deixarão grãos, vinho novo, azeite, o aumento de seu gado, ou os filhotes de seu rebanho, até que eles tenham causado a sua perecimento.
52 Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ títí tí odi ìdáàbòbò gíga yẹn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé yóò fi wó lulẹ̀. Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ jákèjádò ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ.
Eles o sitiarão em todos os seus portões até que seus muros altos e fortificados, nos quais você confiou, desçam por toda a sua terra. Eles o cercarão em todos os seus portões em toda a sua terra que Yahweh seu Deus lhe deu.
53 Ìwọ ó sì jẹ èso ọmọ inú rẹ̀, ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti ti àwọn ọmọ rẹ obìnrin tí Olúwa Ọlọ́run ti fi fún ọ; nínú ìdótì náà àti nínú ìhámọ́ náà tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò há ọ mọ́.
Você comerá o fruto de seu próprio corpo, a carne de seus filhos e de suas filhas, que Yavé seu Deus lhe deu, no cerco e na angústia com que seus inimigos o afligirão.
54 Ọkùnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, ojú rẹ̀ yóò korò sí arákùnrin rẹ̀ àti sí aya oókan àyà rẹ̀, àti sí ìyókù ọmọ rẹ̀ tí òun jẹ kù.
O homem que for terno entre vós, e muito delicado, seu olho será mau para seu irmão, para a esposa que ama, e para o resto de seus filhos que lhe resta,
55 Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fún ẹnikẹ́ni nínú ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ̀ tí ó ń jẹ, nítorí kò sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún un nínú ìdótì náà àti ìhámọ́, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ gbogbo.
para que não dê a nenhum deles a carne de seus filhos que comerá, porque nada lhe resta, no cerco e na angústia com que vosso inimigo vos angustiará em todos os vossos portões.
56 Obìnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, tí kò jẹ́ dáṣà láti fi àtẹ́lẹsẹ̀ ẹ rẹ̀ kan ilẹ̀ nítorí ìkẹ́ra àti ìwà ẹlẹgẹ́, ojú u rẹ̀ yóò korò sí ọkọ oókan àyà rẹ̀, àti sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ rẹ̀ obìnrin,
A mulher terna e delicada entre vocês, que não se atreveria a colocar a planta de seu pé no chão por delicadeza e ternura, seu olho será maligno para o marido que ama, para seu filho, para sua filha,
57 àti sí ọmọ rẹ̀ tí ó ti agbede-méjì ẹsẹ̀ rẹ̀ jáde, àti sí àwọn ọmọ rẹ̀ tí yóò bí. Nítorí òun ó jẹ wọ́n ní ìkọ̀kọ̀, nítorí àìní ohunkóhun nínú ìdótì àti ìhámọ́ náà, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ.
toward sua jovem que sai de entre seus pés, e para seus filhos que ela carrega; pois ela os comerá secretamente por falta de todas as coisas no cerco e na angústia com que seu inimigo os angustiará em seus portões.
58 Bí ìwọ kò bá rọra tẹ̀lé gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí, tí a kọ sínú ìwé yìí, tí ìwọ kò sì bu ọlá fún ògo yìí àti orúkọ dáradára: orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ,
Se você não observar fazer todas as palavras desta lei que estão escritas neste livro, para que você possa temer este nome glorioso e temível, YAHWEH seu Deus,
59 Olúwa yóò sọ ìyọnu rẹ di ìyanu, àti ìyọnu irú-ọmọ ọ̀ rẹ, àní àwọn ìyọnu ńlá èyí tí yóò pẹ́, àti ààrùn búburú èyí tí yóò pẹ́.
então Yahweh fará suas pragas e as pragas de sua prole temerem, mesmo grandes pragas, e de longa duração, e de doenças severas, e de longa duração.
60 Olúwa yóò mú gbogbo ààrùn Ejibiti tí ó mú ẹ̀rù bà ọ́ wá padà bá ọ, wọn yóò sì lẹ̀ mọ́ ọ.
Ele trará novamente sobre você todas as doenças do Egito, das quais você tinha medo; e elas se apegarão a você.
61 Olúwa yóò tún mú onírúurú àìsàn àti ìpọ́njú tí a kò kọ sínú ìwé òfin yìí wá sórí rẹ, títí ìwọ yóò fi run.
Também toda doença e toda peste que não estiver escrita no livro desta lei, Javé as trará sobre você até que você seja destruído.
62 Ìwọ tí ó dàbí àìmoye bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò ṣẹ́ku kékeré níye, nítorí tí o kò ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Vocês serão poucos em número, apesar de terem sido as estrelas do céu para a multidão, porque não ouviram a voz de Javé, seu Deus.
63 Gẹ́gẹ́ bí ó ti dùn mọ́ Olúwa nínú láti mú ọ ṣe rere àti láti pọ̀ si ní iye, bẹ́ẹ̀ ni yóò dùn mọ́ ọ nínú láti bì ọ́ ṣubú kí ó sì pa ọ́ run. Ìwọ yóò di fífà tu kúrò lórí ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
Acontecerá que, enquanto Javé se alegrou por você para fazer-lhe o bem e multiplicá-lo, assim Javé se alegrará por você para fazê-lo perecer e destruí-lo. Você será arrancado da terra que você vai possuir.
64 Nígbà náà ni Olúwa yóò fọ́n ọ ká láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, láti òpin kan ní ayé sí òmíràn. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò ti sin ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run igi àti ti òkúta. Èyí tí ìwọ àti àwọn baba rẹ kò mọ̀.
Yahweh o espalhará entre todos os povos, de um extremo ao outro da terra. Ali servireis a outros deuses que não conheceis, nem vós nem vossos pais, nem mesmo madeira e pedra.
65 Ìwọ kì yóò sinmi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà, kò sí ibi ìsinmi fún àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti fún ọ ní ọkàn ìnàngà, àárẹ̀ ojú, àti àìnírètí àyà.
Entre estas nações não encontrarás facilidade, e não haverá descanso para a planta de teu pé; mas Javé te dará ali um coração trêmulo, uma falha de olhos e um pingo de alma.
66 Ìwọ yóò gbé ní ìdádúró ṣinṣin, kún fún ìbẹ̀rùbojo lọ́sàn án àti lóru, bẹ́ẹ̀ kọ́ láé ni ìwọ yóò rí i ní àrídájú wíwà láyé rẹ.
Sua vida ficará em dúvida diante de você. Você terá medo noite e dia, e não terá nenhuma garantia de sua vida.
67 Ìwọ yóò wí ní òwúrọ̀ pé, “Bí ó tilẹ̀ lè jẹ́ pé ìrọ̀lẹ́ nìkan ni!” Nítorí ẹ̀rù tí yóò gba ọkàn rẹ àti ìran tí ojú rẹ yóò máa rí.
De manhã você dirá: “Gostaria que fosse de noite” e à noite você dirá: “Gostaria que fosse de manhã”, pelo medo de seu coração que você temerá, e pelas visões que seus olhos verão.
68 Olúwa yóò rán ọ padà nínú ọkọ̀ sí Ejibiti sí ìrìnàjò tí mo ní ìwọ kì yóò lọ mọ́. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò tún fi ara rẹ fún àwọn ọ̀tá à rẹ gẹ́gẹ́ bí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò rà ọ́.
Yahweh o trará novamente ao Egito com navios, pelo qual eu lhe disse que nunca mais o veria novamente. Lá vocês se oferecerão a seus inimigos para escravos e escravas, e ninguém os comprará.

< Deuteronomy 28 >