< Deuteronomy 28 >

1 Bí ìwọ bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní kíkún kí o sì kíyèsára láti tẹ̀lé gbogbo ohun tí ó pàṣẹ tí mo fi fún ọ lónìí, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé ọ lékè ju gbogbo orílẹ̀-èdè ayé lọ.
Kata Musa selanjutnya, “Jika setiap orang di antara kalian menaati dengan cermat semua perintah TUHAN Allah yang saya sampaikan hari ini, TUHAN akan membuat Israel menjadi bangsa yang paling terpuji dan terhormat melebihi semua bangsa di bumi.
2 Gbogbo ìbùkún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ bí o bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
“Semua berkat ini akan mengalir kepadamu jika kalian taat kepada TUHAN Allahmu:
3 Ìbùkún ni fún ọ ni ìlú, ìbùkún ni fún ọ ní oko.
Kalian akan diberkati dalam berbagai hal, baik di kota maupun di ladang.
4 Ìbùkún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, àti irú ohun ọ̀sìn rẹ àti ìbísí i màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
Kalian akan diberkati dengan banyak anak. Hasil panenmu akan berlimpah, dan segala jenis ternakmu akan berkembang biak.
5 Ìbùkún ni fún agbọ̀n rẹ àti fún ọpọ́n ipò ìyẹ̀fun rẹ.
Persediaan makananmu akan diberkati.
6 Ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá wọlé, ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
Semua usahamu di mana saja akan diberkati.
7 Olúwa yóò gbà fún ọ pé gbogbo ọ̀tá tí ó dìde sí ọ yóò bì ṣubú níwájú rẹ. Wọn yóò tọ̀ ọ́ wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n wọn yóò sá fún ọ ní ọ̀nà méje.
“Setiap kali musuh-musuh menyerang kalian, TUHAN akan menolongmu mengalahkan mereka. Mereka datang menyerang kalian dari satu arah, tetapi tercerai-berai mereka melarikan diri dari hadapanmu.
8 Olúwa yóò rán ìbùkún sí ọ àti sí ohun gbogbo tí o bá dáwọ́ rẹ lé. Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún un fún ọ nínú ilẹ̀ tí ó ń fi fún ọ.
“TUHAN akan memberkatimu sehingga lumbung-lumbungmu penuh dengan hasil bumi. Dia juga akan memberkati semua usahamu yang lain. Dia akan memberkatimu di negeri yang sebentar lagi Dia bagikan kepadamu.
9 Olúwa yóò fi ọ́ múlẹ̀ bí ènìyàn mímọ́, bí ó ti ṣe ìlérí fún ọ lórí ìbúra, bí o bá pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ mọ́ tí o sì ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
“Jika kalian taat kepada perintah TUHAN dan hidup sesuai kehendak-Nya, Dia akan menepati perjanjian-Nya dengan mengkhususkan kalian sebagai umat yang disucikan oleh-Nya.
10 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ayé yóò rí i pé a pè ọ́ ní orúkọ Olúwa, wọn yóò sì bẹ̀rù rẹ.
Semua bangsa di bumi akan melihat bahwa kalian adalah bangsa milik TUHAN, dan mereka akan takut kepada kalian.
11 Olúwa yóò fi àlàáfíà fún ọ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́, fún ọmọ inú rẹ, irú ohun ọ̀sìn rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá rẹ láti fún ọ.
“TUHAN akan membuat kalian makmur di negeri yang Dia janjikan kepada nenek moyang kita untuk diberikan kepada kita. Dia akan memberkati kalian dengan banyak anak, banyak ternak, dan hasil panen yang melimpah.
12 Olúwa yóò ṣí ọ̀run sílẹ̀, ìṣúra rere rẹ̀ fún ọ, láti rọ òjò sórí ilẹ̀ rẹ ní àsìkò rẹ àti láti bùkún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ. Ìwọ yóò yá ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n ìwọ kò ní í yá lọ́wọ́ ẹnìkankan.
TUHAN akan menurunkan hujan bagi ladang-ladangmu pada musimnya dan memberkati semua usahamu. Utusan-utusan dari bangsa lain akan sering meminta pinjaman kepada kalian, tetapi kalian tidak akan perlu meminjam dari mereka.
13 Olúwa yóò fi ọ́ ṣe orí, ìwọ kì yóò sì jẹ́ ìrù. Bí o bá fi etí sílẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ tí mo fi fún ọ kí o sì máa rọra tẹ̀lé wọn, ìwọ yóò máa wà lókè, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò wà ní ìsàlẹ̀ láé.
Apabila kalian menaati semua perintah TUHAN yang saya sampaikan hari ini, TUHAN akan membuat bangsa Israel senantiasa memimpin dan menguasai bangsa-bangsa lain, bukan dipimpin dan dikuasai oleh mereka.
14 Má ṣe yà sọ́tùn tàbí sósì kúrò, nínú èyíkéyìí àwọn àṣẹ tí mo fi fún ọ ní òní yìí, kí o má ṣe tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti máa sìn wọ́n.
Oleh karena itu, janganlah menyimpang dari perintah-perintah yang saya sampaikan kepada kalian hari ini, dan jangan menyembah dewa-dewa.”
15 Ṣùgbọ́n bí o kò bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì rọra máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí, gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ.
“Tetapi jika kalian tidak mematuhi semua perintah dan ketetapan TUHAN Allah yang saya sampaikan hari ini, maka semua kutuk ini akan menimpa kalian:
16 Ègún ni fún ọ ní ìlú, ègún ni fún ọ ní oko.
Kalian akan dikutuk dalam berbagai hal, baik di kota maupun di ladang.
17 Ègún ni fún agbọ̀n rẹ àti ọpọ́n ìpo-fúláwà rẹ.
Persediaan makananmu akan dikutuk.
18 Ègún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, ìbísí màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
Kalian akan dikutuk sehingga sulit memiliki anak, hasil panenmu buruk, dan segala jenis ternakmu tidak berkembang biak.
19 Ègún ni fún ọ nígbà tí o bá wọlé ègún sì ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
Semua usahamu di mana saja akan dikutuk.
20 Olúwa yóò rán ègún sórí rẹ, rúdurùdu àti ìfibú nínú gbogbo ohun tí o bá dáwọ́ rẹ lé, títí ìwọ yóò fi parun àti wá sí ìparun lójijì nítorí búburú tí o ti ṣe ní kíkọ̀ mi sílẹ̀.
“Jika kalian berbuat jahat dengan meninggalkan TUHAN, maka Dia akan mengutuk, mengacaukan, dan menggagalkan semua yang kalian lakukan sehingga kalian segera binasa.
21 Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn bá ọ jà títí tí yóò fi pa ọ́ run kúrò ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
TUHAN juga akan menimpa kalian dengan wabah penyakit, sehingga tidak seorang pun di antara kalian akan tersisa di negeri yang sebentar lagi kalian duduki itu.
22 Olúwa yóò kọlù ọ́ pẹ̀lú ààrùn ìgbẹ́, pẹ̀lú ibà àti àìsàn wíwú, pẹ̀lú ìjóni ńlá àti idà, pẹ̀lú ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù tí yóò yọ ọ́ lẹ́nu títí ìwọ yóò fi parun.
TUHAN akan menghajar kalian dengan penyakit paru-paru, demam, dan sakit radang. Dia akan mengutuk cuaca sehingga terjadi panas terik, kekeringan, dan penyakit tanaman sehingga panen kalian akan gagal. Bencana-bencana ini akan melanda kalian sampai kalian binasa!
23 Ojú ọ̀run tí ó wà lórí rẹ yóò jẹ́ idẹ, ilẹ̀ tí ń bẹ níṣàlẹ̀ rẹ yóò sì jẹ́ irin.
Langit di atas kalian akan menjadi seperti atap tembaga yang mencegah turunnya hujan, dan tanah di bawah kalian akan menjadi begitu keras seperti besi.
24 Olúwa yóò yí òjò ilẹ̀ rẹ sí eruku àti ẹ̀tù; láti ọ̀run ni yóò ti máa sọ̀kalẹ̀ sí ọ, títí tí ìwọ yóò fi run.
TUHAN tidak akan menurunkan hujan air, melainkan hujan debu dari langit sampai kalian binasa.
25 Olúwa yóò fi ọ́ gégùn ún láti ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá rẹ. Ìwọ yóò tọ̀ wọ́n wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá fún wọn ní ọ̀nà méje, ìwọ yóò sì padà di ohun ìbẹ̀rù fún gbogbo ìjọba lórí ayé.
“Setiap kali musuh-musuh menyerang kalian, TUHAN akan membuat kalian kalah. Pasukan kalian menyerang musuh dari satu arah, tetapi justru kalian akan tercerai-berai dan melarikan diri dari hadapan mereka. Melihat apa yang terjadi kepada kalian, semua bangsa lain akan merasa ngeri dan menganggap kalian bangsa yang paling malang di dunia.
26 Òkú rẹ yóò jẹ́ oúnjẹ fún gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko ayé, àti pé kò ní sí ẹnikẹ́ni tí yóò lé wọn kúrò.
Mayat kalian akan berserakan begitu saja sehingga dimakan burung-burung dan binatang-binatang liar. Saat itu terjadi, tidak seorang pun dari kalian yang masih hidup untuk mengusir burung dan binatang itu.
27 Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú oówo, Ejibiti àti pẹ̀lú kókó, ojú egbò kíkẹ̀ àti ìhúnra.
“TUHAN akan membuat kalian menderita bisul-bisul bernanah, seperti yang ditimpakan-Nya pada orang Mesir. Seluruh badanmu akan gatal-gatal dan penuh dengan benjol-benjol dan kudis tanpa ada yang bisa menyembuhkanmu.
28 Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú ìsínwín, ojú fífọ́ àti rúdurùdu àyà.
TUHAN akan membuat kalian gila, buta, dan selalu ketakutan.
29 Ní ọ̀sán gangan ìwọ yóò fi ọwọ́ tálẹ̀ kiri bí ọkùnrin afọ́jú nínú òkùnkùn ìwọ kì yóò ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí o bá ń ṣe, ojoojúmọ́ ni wọn yóò máa ni ọ́ lára àti jà ọ́ ní olè, tí kò sì ní í sí ẹnìkan láti gbà ọ́.
Meskipun kalian berjalan pada siang hari yang terang, kalian akan meraba-raba dalam kegelapan seperti orang buta, sehingga kalian tidak akan berhasil dalam segala hal. Kalian akan terus-menerus ditindas dan dirampok, tetapi tidak seorang pun akan menolongmu.
30 Ìwọ yóò gba ògo láti fẹ́ obìnrin kan ṣùgbọ́n ẹlòmíràn yóò gbà á yóò sì tẹ́ ẹ́ ní ògo. Ìwọ yóò kọ́ ilé, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò gbé ibẹ̀. Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kò tilẹ̀ ní gbádùn èso rẹ.
“Kalau kalian bertunangan, laki-laki lain akan memperkosa tunanganmu. Kalau kalian membangun rumah, kalian tidak akan sempat tinggal di dalamnya. Kalau kalian menanami kebun anggur, kalian tidak akan menikmati hasilnya.
31 Màlúù rẹ yóò di pípa níwájú rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò jẹ nǹkan kan nínú rẹ̀. Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ yóò sì di mímú pẹ̀lú agbára kúrò lọ́dọ̀ rẹ, a kì yóò sì da padà. Àgùntàn rẹ yóò di mímú fún àwọn ọ̀tá rẹ, ẹnìkankan kò sì ní gbà á.
Ternak sapimu akan disembelih di depan matamu, tetapi kalian tidak akan makan sedikit pun dari dagingnya. Kawanan keledaimu akan dirampas dan tidak pernah dikembalikan. Musuh-musuhmu akan mencuri ternak dombamu, dan tidak ada orang yang bisa membela hakmu.
32 Àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ yóò di mímú fún àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, ìwọ yóò sì fi ojú rẹ ṣọ́nà dúró dè wọ́n láti ọjọ́ dé ọjọ́, ìwọ yóò sì jẹ́ aláìlágbára láti gbé ọwọ́.
Anak-anakmu laki-laki dan perempuan akan menjadi tawanan perang, lalu dijadikan budak di negeri lain. Setiap hari kalian akan merindukan mereka, tetapi kalian tidak bisa berbuat apa-apa kecuali terdiam menatap kosong tanpa harapan.
33 Èso ilẹ̀ rẹ àti gbogbo iṣẹ́ làálàá rẹ ni orílẹ̀-èdè mìíràn tí ìwọ kò mọ̀ yóò sì jẹ, ìwọ yóò jẹ́ kìkì ẹni ìnilára àti ẹni ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
Suatu bangsa musuh yang namanya belum pernah kalian dengar akan datang dari negeri yang jauh, lalu menjarah semua hasil panenmu dan segala hasil kerja kerasmu. Kalian akan terus-menerus ditindas dan diperlakukan dengan kejam.
34 Ìran tí ojú rẹ yóò rí, yóò sọ ọ́ di òmùgọ̀.
Kalian akan menjadi gila melihat kengerian yang terjadi.
35 Olúwa yóò lu eékún àti ẹsẹ̀ rẹ pẹ̀lú oówo dídùn tí kò le san tán láti àtẹ̀lé méjèèjì rẹ lọ sí òkè orí rẹ.
TUHAN akan membuat lutut dan pahamu sakit bisul yang tidak bisa disembuhkan. Bisul-bisul itu akan menyebar ke seluruh tubuhmu, dari telapak kaki sampai ke kulit kepala.
36 Olúwa yóò lé ọ àti ọba tí ó yàn lórí rẹ lọ sí orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ tàbí ti àwọn baba rẹ kò mọ̀. Ibẹ̀ ni ìwọ̀ yóò sì sin ọlọ́run mìíràn, ọlọ́run igi àti òkúta.
“TUHAN akan membiarkan Israel beserta raja yang kalian pilih ditawan ke negeri musuh yang jauh, yaitu bangsa yang tidak dikenal oleh kalian ataupun nenek moyang kalian. Di negeri itu, kalian akan menyembah dewa-dewa buatan tangan manusia dari kayu dan batu.
37 Ìwọ yóò di ẹni ìyanu, àti ẹni òwe, àti ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ nínú gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò darí rẹ sí.
Di antara segala bangsa ke mana TUHAN mencerai-beraikan kalian, orang-orang akan ngeri melihat apa yang sudah terjadi kepada kalian, sehingga kalian menjadi bahan olokan mereka.
38 Ìwọ yóò gbin irúgbìn púpọ̀ ṣùgbọ́n ìwọ yóò kórè kékeré, nítorí eṣú yóò jẹ ẹ́ run.
Kalian akan menanam banyak benih di ladang, tetapi hasil panennya hanya sedikit karena dimakan belalang.
39 Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà púpọ̀ ìwọ yóò sì ro wọ́n ṣùgbọ́n kò ní mú wáìnì náà tàbí kó àwọn èso jọ, nítorí kòkòrò yóò jẹ wọ́n run.
Kalian akan menanam dan merawat kebun anggur, tetapi tidak akan memanen buahnya apalagi meminum air anggurnya, karena sudah habis dimakan ulat.
40 Ìwọ yóò ní igi olifi jákèjádò ilẹ̀ rẹ ṣùgbọ́n ìwọ kò ní lo òróró náà, nítorí olifi náà yóò rẹ̀ dànù.
Banyak pohon zaitun akan tumbuh di seluruh wilayah kalian, tetapi kalian tidak akan bisa mengambil dan menikmati minyaknya, karena buah-buahnya akan gugur sebelum matang.
41 Ìwọ yóò ní àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin ṣùgbọ́n ìwọ kò nípa wọ́n mọ́, nítorí wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
Kalian akan memiliki anak-anak laki-laki dan perempuan, tetapi mereka akan dirampas darimu dan menjadi tawanan musuh.
42 Ọ̀wọ́ eṣú yóò gba gbogbo àwọn igi rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ.
Serangan serangga akan memakan habis segala yang tumbuh, sehingga tidak ada apa pun yang bisa kalian panen.
43 Àjèjì tí ń gbé láàrín rẹ yóò gbé sókè gíga jù ọ́ lọ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò máa di ìrẹ̀sílẹ̀.
“Pendatang yang tinggal di antara kalian akan semakin berkuasa atas kalian, sedangkan kalian semakin tidak berdaya.
44 Yóò yà ọ́, ṣùgbọ́n o kì yóò yà á, òun ni yóò jẹ́ orí, ìwọ yóò jẹ́ ìrù.
Mereka akan memberi pinjaman kepada kalian, tetapi kalian tidak akan memberi pinjaman kepada mereka. Mereka akan memimpin kalian, dan kalian akan tunduk kepada mereka.
45 Gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ, wọn yóò lé ọ wọn yóò sì bá ọ títí tí ìwọ yóò fi parun, nítorí ìwọ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ kò sì kíyèsi àṣẹ àti òfin tí ó fi fún ọ.
“Jika kalian tidak taat kepada TUHAN Allahmu dan tidak melakukan perintah-perintah-Nya yang sudah Dia berikan, semua kutuk tersebut akan terus menimpa kalian sampai binasa.
46 Wọn yóò jẹ́ àmì àti ìyanu fún ọ àti fún irú-ọmọ rẹ títí láé.
Bencana-bencana itu akan menjadi bukti dari TUHAN bagi kalian dan keturunan kalian selamanya, bahwa semua itu merupakan hukuman dari-Nya.
47 Nítorí ìwọ kò sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ní ayọ̀ àti inú dídùn ní àkókò àlàáfíà.
Sewaktu kalian hidup dalam kemakmuran dari TUHAN Allahmu di negerimu sendiri, kalian tidak mau berterima kasih dan melayani Dia dengan senang hati.
48 Nítorí náà nínú ebi àti òǹgbẹ, nínú ìhòhò àti àìní búburú, ìwọ yóò sin àwọn ọ̀tá à rẹ tí Olúwa rán sí ọ. Yóò sì fi àjàgà irin bọ̀ ọ́ ní ọrùn, títí yóò fi run ọ́.
Karena itu, TUHAN akan mendatangkan musuh-musuh untuk melawan kalian, sehingga kalian terpaksa melayani mereka dalam keadaan lapar, haus, tak berpakaian, dan kekurangan segala hal. TUHAN akan membiarkan mereka memperbudak dan menindas kalian sampai binasa.
49 Olúwa yóò mú àwọn orílẹ̀-èdè wá sí ọ láti ọ̀nà jíjìn, bí òpin ayé, bí idì ti ń bẹ́ láti orí òkè sílẹ̀, orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò gbọ́ èdè wọn.
“TUHAN akan mendatangkan pasukan mereka dari negeri yang jauh, dan mereka akan menyergap kalian seperti seekor elang menerkam mangsanya secepat kilat. Bangsa itu kuat dan kejam, dan bahasa mereka tidak bisa kalian mengerti. Mereka tidak akan punya rasa hormat kepada orang yang tua maupun belas kasihan kepada anak-anak.
50 Orílẹ̀-èdè tí ó rorò tí kò ní ojúrere fún àgbà tàbí àánú fún ọmọdé.
51 Wọn yóò jẹ ohun ọ̀sìn rẹ run àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ títí tí ìwọ yóò fi parun. Wọn kì yóò fi hóró irúgbìn kan fún ọ, wáìnì tuntun tàbí òróró, tàbí agbo ẹran màlúù rẹ kankan tàbí ọ̀wọ́ ẹran àgùntàn rẹ títí ìwọ yóò fi run.
Pasukan bangsa itu akan memakan ternak mudamu dan seluruh hasil panenmu sampai kalian mati kelaparan. Tidak akan tersisa sedikit pun gandum, air anggur, minyak zaitun, anak sapi, dan anak domba bagi kalian, sehingga kalian habis binasa.
52 Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ títí tí odi ìdáàbòbò gíga yẹn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé yóò fi wó lulẹ̀. Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ jákèjádò ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ.
Mereka akan mengepung kota-kota di seluruh negeri pemberian TUHAN kepada kalian. Biarpun kalian merasa aman berlindung di kota yang dibentengi tembok yang tinggi, mereka akan meruntuhkan benteng itu.
53 Ìwọ ó sì jẹ èso ọmọ inú rẹ̀, ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti ti àwọn ọmọ rẹ obìnrin tí Olúwa Ọlọ́run ti fi fún ọ; nínú ìdótì náà àti nínú ìhámọ́ náà tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò há ọ mọ́.
“Selama kotamu dikepung, kalian akan merasa begitu sengsara dan kehabisan makanan, sampai kalian memakan anak-anakmu, darah dagingmu sendiri yang diberikan TUHAN kepadamu. Kalian akan sangat kelaparan, sehingga laki-laki yang paling lembut dan peka di antara kalian pun tega memakan daging anaknya sendiri. Bahkan dia tidak akan mau membagi sedikit pun daging itu kepada saudaranya, istrinya yang sangat dicintainya, dan satu-satunya anak yang masih hidup.
54 Ọkùnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, ojú rẹ̀ yóò korò sí arákùnrin rẹ̀ àti sí aya oókan àyà rẹ̀, àti sí ìyókù ọmọ rẹ̀ tí òun jẹ kù.
55 Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fún ẹnikẹ́ni nínú ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ̀ tí ó ń jẹ, nítorí kò sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún un nínú ìdótì náà àti ìhámọ́, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ gbogbo.
56 Obìnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, tí kò jẹ́ dáṣà láti fi àtẹ́lẹsẹ̀ ẹ rẹ̀ kan ilẹ̀ nítorí ìkẹ́ra àti ìwà ẹlẹgẹ́, ojú u rẹ̀ yóò korò sí ọkọ oókan àyà rẹ̀, àti sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ rẹ̀ obìnrin,
Demikian juga perempuan yang paling lembut dan peka di antara kalian— begitu lembutnya bagaikan tuan putri yang seolah tidak pernah menjejakkan kakinya ke tanah— akan tega menyembunyikan bayi yang baru saja dia lahirkan beserta dengan ari-arinya, lalu diam-diam memakannya, sebab tidak ada apa pun lagi yang bisa dimakan. Dia bahkan tidak akan mau membagi sedikit pun daging itu kepada suami dan anaknya yang lain.
57 àti sí ọmọ rẹ̀ tí ó ti agbede-méjì ẹsẹ̀ rẹ̀ jáde, àti sí àwọn ọmọ rẹ̀ tí yóò bí. Nítorí òun ó jẹ wọ́n ní ìkọ̀kọ̀, nítorí àìní ohunkóhun nínú ìdótì àti ìhámọ́ náà, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ.
58 Bí ìwọ kò bá rọra tẹ̀lé gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí, tí a kọ sínú ìwé yìí, tí ìwọ kò sì bu ọlá fún ògo yìí àti orúkọ dáradára: orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ,
“Jika kamu sekalian tidak menaati semua hukum yang tertulis dalam kitab Taurat ini, dan tidak takut dan hormat terhadap TUHAN Allah Yang Mahamulia,
59 Olúwa yóò sọ ìyọnu rẹ di ìyanu, àti ìyọnu irú-ọmọ ọ̀ rẹ, àní àwọn ìyọnu ńlá èyí tí yóò pẹ́, àti ààrùn búburú èyí tí yóò pẹ́.
maka TUHAN akan mendatangkan bencana-bencana dan berbagai wabah penyakit kepada kamu dan keturunanmu, yaitu penyakit mengerikan seperti yang kalian saksikan ketika TUHAN menghukum orang Mesir. Kalian akan menderita sakit parah itu bertahun-tahun tanpa bisa sembuh.
60 Olúwa yóò mú gbogbo ààrùn Ejibiti tí ó mú ẹ̀rù bà ọ́ wá padà bá ọ, wọn yóò sì lẹ̀ mọ́ ọ.
61 Olúwa yóò tún mú onírúurú àìsàn àti ìpọ́njú tí a kò kọ sínú ìwé òfin yìí wá sórí rẹ, títí ìwọ yóò fi run.
TUHAN juga akan mendatangkan segala macam wabah dan penyakit lain yang tidak tertulis dalam kitab Taurat ini, sampai kalian binasa.
62 Ìwọ tí ó dàbí àìmoye bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò ṣẹ́ku kékeré níye, nítorí tí o kò ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
“Sebagaimana TUHAN tadinya senang berbuat baik kepada kalian dan menambah jumlah kalian, Dia pun akan senang menghancurkan dan membinasakan kalian jika kalian tidak menaati-Nya. Sekali pun awalnya jumlah kalian banyak seperti bintang di langit, hanya sedikit yang akan dibiarkan hidup sesudah TUHAN menghukum kalian. Dan kalian akan disingkirkan dari negeri subur yang sebentar lagi kalian duduki karena kalian tidak menaati perintah-perintah TUHAN.
63 Gẹ́gẹ́ bí ó ti dùn mọ́ Olúwa nínú láti mú ọ ṣe rere àti láti pọ̀ si ní iye, bẹ́ẹ̀ ni yóò dùn mọ́ ọ nínú láti bì ọ́ ṣubú kí ó sì pa ọ́ run. Ìwọ yóò di fífà tu kúrò lórí ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
64 Nígbà náà ni Olúwa yóò fọ́n ọ ká láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, láti òpin kan ní ayé sí òmíràn. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò ti sin ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run igi àti ti òkúta. Èyí tí ìwọ àti àwọn baba rẹ kò mọ̀.
TUHAN akan mencerai-beraikan kalian ke antara bangsa-bangsa lain di seluruh bumi. Di sana kalian akan menyembah dewa-dewa yang terbuat dari kayu dan batu, yang tidak dikenal olehmu ataupun nenek moyangmu.
65 Ìwọ kì yóò sinmi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà, kò sí ibi ìsinmi fún àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti fún ọ ní ọkàn ìnàngà, àárẹ̀ ojú, àti àìnírètí àyà.
Di antara bangsa-bangsa itu, kalian tidak akan pernah mempunyai tempat tinggalmu sendiri dan tidak akan merasa tenang. TUHAN akan membuat hatimu gelisah, mukamu suram, dan perasaanmu tertekan.
66 Ìwọ yóò gbé ní ìdádúró ṣinṣin, kún fún ìbẹ̀rùbojo lọ́sàn án àti lóru, bẹ́ẹ̀ kọ́ láé ni ìwọ yóò rí i ní àrídájú wíwà láyé rẹ.
Hidupmu akan selalu terancam bahaya. Siang dan malam kalian merasa ngeri dan kuatir apakah bisa tetap hidup.
67 Ìwọ yóò wí ní òwúrọ̀ pé, “Bí ó tilẹ̀ lè jẹ́ pé ìrọ̀lẹ́ nìkan ni!” Nítorí ẹ̀rù tí yóò gba ọkàn rẹ àti ìran tí ojú rẹ yóò máa rí.
Karena sering melihat hal-hal yang mengerikan, kalian akan hidup dalam ketakutan setiap saat, sehingga di pagi hari kalian berkata, ‘Andaikan sekarang sudah malam!’ Dan di malam hari kalian berkata, ‘Andaikan sekarang sudah pagi!’
68 Olúwa yóò rán ọ padà nínú ọkọ̀ sí Ejibiti sí ìrìnàjò tí mo ní ìwọ kì yóò lọ mọ́. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò tún fi ara rẹ fún àwọn ọ̀tá à rẹ gẹ́gẹ́ bí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò rà ọ́.
TUHAN juga akan mengirim sebagian dari kalian ke Mesir dengan kapal, meskipun Dia pernah mengatakan bahwa kalian tidak akan melihat negeri itu lagi. Di sana kalian akan begitu melarat sampai berusaha menawarkan diri sebagai budak lagi kepada orang Mesir, tetapi tidak akan ada yang mau membelimu.”

< Deuteronomy 28 >