< Deuteronomy 28 >
1 Bí ìwọ bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní kíkún kí o sì kíyèsára láti tẹ̀lé gbogbo ohun tí ó pàṣẹ tí mo fi fún ọ lónìí, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé ọ lékè ju gbogbo orílẹ̀-èdè ayé lọ.
Ha pedig szorgalmatosan hallgatsz az Úrnak, a te Istenednek szavára, és megtartod és teljesíted minden ő parancsolatát, a melyeket én parancsolok ma néked: akkor e földnek minden népénél feljebbvalóvá tesz téged az Úr, a te Istened;
2 Gbogbo ìbùkún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ bí o bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
És reád szállanak mind ez áldások, és megteljesednek rajtad, ha hallgatsz az Úrnak, a te Istenednek szavára.
3 Ìbùkún ni fún ọ ni ìlú, ìbùkún ni fún ọ ní oko.
Áldott leszesz a városban, és áldott leszesz a mezőben.
4 Ìbùkún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, àti irú ohun ọ̀sìn rẹ àti ìbísí i màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
Áldott lesz a te méhednek gyümölcse és a te földednek gyümölcse, és a te barmodnak gyümölcse, a te teheneidnek fajzása és a te juhaidnak ellése.
5 Ìbùkún ni fún agbọ̀n rẹ àti fún ọpọ́n ipò ìyẹ̀fun rẹ.
Áldott lesz a te kosarad és a te sütő tekenőd.
6 Ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá wọlé, ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
Áldott leszesz bejöttödben, és áldott leszesz kimentedben.
7 Olúwa yóò gbà fún ọ pé gbogbo ọ̀tá tí ó dìde sí ọ yóò bì ṣubú níwájú rẹ. Wọn yóò tọ̀ ọ́ wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n wọn yóò sá fún ọ ní ọ̀nà méje.
Az Úr megszalasztja előtted a te ellenségeidet, a kik reád támadnak; egy úton jőnek ki reád, és hét úton futnak előled.
8 Olúwa yóò rán ìbùkún sí ọ àti sí ohun gbogbo tí o bá dáwọ́ rẹ lé. Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún un fún ọ nínú ilẹ̀ tí ó ń fi fún ọ.
Áldást parancsol melléd az Úr a te csűreidben és mindenben, a mire ráteszed kezedet; és megáld téged azon a földön, a melyet az Úr, a te Istened ád néked.
9 Olúwa yóò fi ọ́ múlẹ̀ bí ènìyàn mímọ́, bí ó ti ṣe ìlérí fún ọ lórí ìbúra, bí o bá pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ mọ́ tí o sì ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Az Úr felkészít téged magának szent néppé, a miképen megesküdt néked, ha megtartod az Úrnak, a te Istenednek parancsolatait, és az ő útain jársz.
10 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ayé yóò rí i pé a pè ọ́ ní orúkọ Olúwa, wọn yóò sì bẹ̀rù rẹ.
És megérti majd a földnek minden népe, hogy az Úrnak nevéről neveztetel, és félnek tőled.
11 Olúwa yóò fi àlàáfíà fún ọ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́, fún ọmọ inú rẹ, irú ohun ọ̀sìn rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá rẹ láti fún ọ.
És bővölködővé tesz téged az Úr minden jóban: a te méhednek gyümölcsében, a te barmodnak gyümölcsében és a te földednek gyümölcsében, azon a földön, a mely felől megesküdt az Úr a te atyáidnak, hogy néked adja azt.
12 Olúwa yóò ṣí ọ̀run sílẹ̀, ìṣúra rere rẹ̀ fún ọ, láti rọ òjò sórí ilẹ̀ rẹ ní àsìkò rẹ àti láti bùkún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ. Ìwọ yóò yá ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n ìwọ kò ní í yá lọ́wọ́ ẹnìkankan.
Megnyitja néked az Úr az ő drága kincsesházát, az eget, hogy esőt adjon a te földednek alkalmas időben, és megáldja kezednek minden munkáját, és kölcsönt adsz sok népnek, te pedig nem veszesz kölcsönt.
13 Olúwa yóò fi ọ́ ṣe orí, ìwọ kì yóò sì jẹ́ ìrù. Bí o bá fi etí sílẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ tí mo fi fún ọ kí o sì máa rọra tẹ̀lé wọn, ìwọ yóò máa wà lókè, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò wà ní ìsàlẹ̀ láé.
És fejjé tesz téged az Úr és nem farkká, és mindinkább feljebbvaló leszesz és nem alábbvaló, ha hallgatsz az Úrnak, a te Istenednek parancsolataira, a melyeket én parancsolok ma néked, hogy tartsd meg és teljesítsd azokat;
14 Má ṣe yà sọ́tùn tàbí sósì kúrò, nínú èyíkéyìí àwọn àṣẹ tí mo fi fún ọ ní òní yìí, kí o má ṣe tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti máa sìn wọ́n.
És ha el nem térsz egyetlen ígétől sem, a melyeket én parancsolok néktek, se jobbra, se balra, járván idegen istenek után, hogy azokat tiszteljétek.
15 Ṣùgbọ́n bí o kò bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì rọra máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí, gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ.
Ha pedig nem hallgatsz az Úrnak, a te Istenednek szavára, hogy megtartsad és teljesítsed minden parancsolatát és rendelését, a melyeket én parancsolok ma néked: reád jőnek mind ez átkok, és megteljesednek rajtad:
16 Ègún ni fún ọ ní ìlú, ègún ni fún ọ ní oko.
Átkozott leszesz a városban, és átkozott a mezőn.
17 Ègún ni fún agbọ̀n rẹ àti ọpọ́n ìpo-fúláwà rẹ.
Átkozott lesz a te kosarad és a te sütő tekenőd.
18 Ègún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, ìbísí màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
Átkozott lesz a te méhednek gyümölcse és a te földednek gyümölcse, a te teheneidnek fajzása és a te juhaidnak ellése.
19 Ègún ni fún ọ nígbà tí o bá wọlé ègún sì ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
Átkozott leszesz bejöttödben, és átkozott leszesz kimentedben.
20 Olúwa yóò rán ègún sórí rẹ, rúdurùdu àti ìfibú nínú gbogbo ohun tí o bá dáwọ́ rẹ lé, títí ìwọ yóò fi parun àti wá sí ìparun lójijì nítorí búburú tí o ti ṣe ní kíkọ̀ mi sílẹ̀.
Bocsát az Úr te reád átkot, bomlást és romlást mindenben, a mit kezdesz vagy cselekszel; mígnem eltöröltetel és mígnem gyorsasággal elveszesz a te cselekedeteidnek gonoszsága miatt, a melyekkel elhagytál engem.
21 Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn bá ọ jà títí tí yóò fi pa ọ́ run kúrò ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
Hozzád ragasztja az Úr a döghalált, mígnem elemészt téged arról a földről, a melyre bemégy, hogy bírjad azt.
22 Olúwa yóò kọlù ọ́ pẹ̀lú ààrùn ìgbẹ́, pẹ̀lú ibà àti àìsàn wíwú, pẹ̀lú ìjóni ńlá àti idà, pẹ̀lú ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù tí yóò yọ ọ́ lẹ́nu títí ìwọ yóò fi parun.
Megver téged az Úr szárazbetegséggel hidegleléssel, gyulasztó és izzasztó betegséggel, aszálylyal, szárazsággal és ragyával; és üldöznek téged, mígnem elveszesz.
23 Ojú ọ̀run tí ó wà lórí rẹ yóò jẹ́ idẹ, ilẹ̀ tí ń bẹ níṣàlẹ̀ rẹ yóò sì jẹ́ irin.
Eged, a mely fejed felett van, rézzé, a föld pedig, a mely lábad alatt van, vassá válik.
24 Olúwa yóò yí òjò ilẹ̀ rẹ sí eruku àti ẹ̀tù; láti ọ̀run ni yóò ti máa sọ̀kalẹ̀ sí ọ, títí tí ìwọ yóò fi run.
Az Úr eső helyett port és hamut ád a te földedre; az égből száll reád, mígnem elpusztulsz.
25 Olúwa yóò fi ọ́ gégùn ún láti ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá rẹ. Ìwọ yóò tọ̀ wọ́n wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá fún wọn ní ọ̀nà méje, ìwọ yóò sì padà di ohun ìbẹ̀rù fún gbogbo ìjọba lórí ayé.
Az Úr megszalaszt téged a te ellenségeid előtt; egy úton mégy ki ő reá, és hét úton futsz előtte, és a föld minden országának rettentésére leszel.
26 Òkú rẹ yóò jẹ́ oúnjẹ fún gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko ayé, àti pé kò ní sí ẹnikẹ́ni tí yóò lé wọn kúrò.
És eledelévé lesz a te holttested az ég minden madarának és a föld vadainak, és nem lesz, a ki elűzze azokat.
27 Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú oówo, Ejibiti àti pẹ̀lú kókó, ojú egbò kíkẹ̀ àti ìhúnra.
Megver téged az Isten Égyiptomnak fekélyével, és sülylyel, varral és viszketegséggel, a melyekből ki nem gyógyíttathatol.
28 Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú ìsínwín, ojú fífọ́ àti rúdurùdu àyà.
Megver téged az Úr tébolyodással, vaksággal és elme-zavarodással;
29 Ní ọ̀sán gangan ìwọ yóò fi ọwọ́ tálẹ̀ kiri bí ọkùnrin afọ́jú nínú òkùnkùn ìwọ kì yóò ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí o bá ń ṣe, ojoojúmọ́ ni wọn yóò máa ni ọ́ lára àti jà ọ́ ní olè, tí kò sì ní í sí ẹnìkan láti gbà ọ́.
És tapogatni fogsz délben, a mint tapogat a vak a setétségben; és szerencsétlen leszel a te útaidban, sőt elnyomott és kifosztott leszel minden időben, és nem lesz, a ki megszabadítson.
30 Ìwọ yóò gba ògo láti fẹ́ obìnrin kan ṣùgbọ́n ẹlòmíràn yóò gbà á yóò sì tẹ́ ẹ́ ní ògo. Ìwọ yóò kọ́ ilé, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò gbé ibẹ̀. Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kò tilẹ̀ ní gbádùn èso rẹ.
Feleséget jegyzesz magadnak, de más férfi hál azzal; házat építesz, de nem lakol benne; szőlőt ültetsz, de nem veszed annak hasznát.
31 Màlúù rẹ yóò di pípa níwájú rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò jẹ nǹkan kan nínú rẹ̀. Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ yóò sì di mímú pẹ̀lú agbára kúrò lọ́dọ̀ rẹ, a kì yóò sì da padà. Àgùntàn rẹ yóò di mímú fún àwọn ọ̀tá rẹ, ẹnìkankan kò sì ní gbà á.
A te ökröd szemed előtt vágatik le, és nem eszel abból; a te szamarad elragadtatik előled, és nem tér vissza hozzád; a te juhaid ellenségeidnek adatnak, és nem lesz, a ki megszabadítson.
32 Àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ yóò di mímú fún àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, ìwọ yóò sì fi ojú rẹ ṣọ́nà dúró dè wọ́n láti ọjọ́ dé ọjọ́, ìwọ yóò sì jẹ́ aláìlágbára láti gbé ọwọ́.
A te fiaid és leányaid más népnek adatnak, és a te szemeid néznek és epekednek utánok egész napon, és nem lesz erő a te kezedben.
33 Èso ilẹ̀ rẹ àti gbogbo iṣẹ́ làálàá rẹ ni orílẹ̀-èdè mìíràn tí ìwọ kò mọ̀ yóò sì jẹ, ìwọ yóò jẹ́ kìkì ẹni ìnilára àti ẹni ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
A te földednek gyümölcsét, és minden fáradságos szerzeményedet oly nép emészti fel, a melyet nem ismertél, sőt elnyomott és megnyomorított leszel minden időben.
34 Ìran tí ojú rẹ yóò rí, yóò sọ ọ́ di òmùgọ̀.
És megtébolyodol a látványtól, a melyet látni fognak a te szemeid.
35 Olúwa yóò lu eékún àti ẹsẹ̀ rẹ pẹ̀lú oówo dídùn tí kò le san tán láti àtẹ̀lé méjèèjì rẹ lọ sí òkè orí rẹ.
Megver téged az Úr gonosz kelésekkel a te térdeiden és czombjaidon, a melyekből ki nem gyógyíttathatol, talpadtól fogva a koponyádig.
36 Olúwa yóò lé ọ àti ọba tí ó yàn lórí rẹ lọ sí orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ tàbí ti àwọn baba rẹ kò mọ̀. Ibẹ̀ ni ìwọ̀ yóò sì sin ọlọ́run mìíràn, ọlọ́run igi àti òkúta.
Az Úr elvisz téged és a te királyodat, a kit magad fölé emelsz, oly nép közé, a melyet nem ismertél sem te, sem a te atyáid; és szolgálni fogsz ott idegen isteneket: fát és követ.
37 Ìwọ yóò di ẹni ìyanu, àti ẹni òwe, àti ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ nínú gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò darí rẹ sí.
És iszonyattá, példabeszéddé és gúnynyá leszel minden népnél, a melyek közé elűz téged az Úr.
38 Ìwọ yóò gbin irúgbìn púpọ̀ ṣùgbọ́n ìwọ yóò kórè kékeré, nítorí eṣú yóò jẹ ẹ́ run.
Sok magot viszel ki a mezőre, de keveset takarsz be, mert felemészti azt a sáska.
39 Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà púpọ̀ ìwọ yóò sì ro wọ́n ṣùgbọ́n kò ní mú wáìnì náà tàbí kó àwọn èso jọ, nítorí kòkòrò yóò jẹ wọ́n run.
Szőlőket ültetsz és míveled azokat, de bort nem iszol, meg sem szeded, mert elemészti azokat a féreg.
40 Ìwọ yóò ní igi olifi jákèjádò ilẹ̀ rẹ ṣùgbọ́n ìwọ kò ní lo òróró náà, nítorí olifi náà yóò rẹ̀ dànù.
Olajfáid lesznek minden határodban, de nem kened magadat olajjal, mert olajfádnak gyümölcse lehull.
41 Ìwọ yóò ní àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin ṣùgbọ́n ìwọ kò nípa wọ́n mọ́, nítorí wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
Fiakat és leányokat nemzesz, de nem lesznek tiéid; mert fogságra jutnak.
42 Ọ̀wọ́ eṣú yóò gba gbogbo àwọn igi rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ.
Minden fádat és földednek minden gyümölcsét megemészti a sáska.
43 Àjèjì tí ń gbé láàrín rẹ yóò gbé sókè gíga jù ọ́ lọ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò máa di ìrẹ̀sílẹ̀.
A jövevény, a ki közötted van, feljebb-feljebb emelkedik feletted, te pedig alább-alább szállasz.
44 Yóò yà ọ́, ṣùgbọ́n o kì yóò yà á, òun ni yóò jẹ́ orí, ìwọ yóò jẹ́ ìrù.
Ő fog néked kölcsönt adni, és nem te kölcsönzöl néki; ő fej lesz, te pedig fark leszel.
45 Gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ, wọn yóò lé ọ wọn yóò sì bá ọ títí tí ìwọ yóò fi parun, nítorí ìwọ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ kò sì kíyèsi àṣẹ àti òfin tí ó fi fún ọ.
És ez átkok mind reád szállanak, és üldöznek téged és megteljesednek rajtad, míglen elpusztulsz; mert nem hallgattál az Úrnak, a te Istenednek szavára, hogy megtartottad volna az ő parancsolatait és rendeléseit, a melyeket parancsolt néked;
46 Wọn yóò jẹ́ àmì àti ìyanu fún ọ àti fún irú-ọmọ rẹ títí láé.
És rajtad lesznek jelül és csudául, és a te magodon mind örökké.
47 Nítorí ìwọ kò sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ní ayọ̀ àti inú dídùn ní àkókò àlàáfíà.
A miatt, hogy nem szolgáltad az Urat, a te Istenedet örömmel és jó szívvel, mindennel bővölködvén:
48 Nítorí náà nínú ebi àti òǹgbẹ, nínú ìhòhò àti àìní búburú, ìwọ yóò sin àwọn ọ̀tá à rẹ tí Olúwa rán sí ọ. Yóò sì fi àjàgà irin bọ̀ ọ́ ní ọrùn, títí yóò fi run ọ́.
Szolgálod majd a te ellenségeidet, a kiket reád bocsát az Úr, éhen és szomjan, mezítelen és mindennek szűkiben; és vasigát vet a te nyakadra, míglen elpusztít téged.
49 Olúwa yóò mú àwọn orílẹ̀-èdè wá sí ọ láti ọ̀nà jíjìn, bí òpin ayé, bí idì ti ń bẹ́ láti orí òkè sílẹ̀, orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò gbọ́ èdè wọn.
Hoz az Úr ellened népet meszszünnen, a földnek széléről, nem különben, a mint repül a sas; oly népet, a melynek nyelvét nem érted;
50 Orílẹ̀-èdè tí ó rorò tí kò ní ojúrere fún àgbà tàbí àánú fún ọmọdé.
Vad tekintetű népet, a mely nem tiszteli a vén embert, és a gyermeknek nem kedvez:
51 Wọn yóò jẹ ohun ọ̀sìn rẹ run àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ títí tí ìwọ yóò fi parun. Wọn kì yóò fi hóró irúgbìn kan fún ọ, wáìnì tuntun tàbí òróró, tàbí agbo ẹran màlúù rẹ kankan tàbí ọ̀wọ́ ẹran àgùntàn rẹ títí ìwọ yóò fi run.
És felemészti a te barmodnak tenyészését és a te földednek gyümölcsét, mígnem kipusztulsz; a mely nem hágy néked a te gabonádból, borodból, olajodból, és a te teheneidnek fajzásából, juhaidnak elléséből, mígnem kiveszít téged.
52 Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ títí tí odi ìdáàbòbò gíga yẹn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé yóò fi wó lulẹ̀. Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ jákèjádò ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ.
És megszáll téged minden városodban, míglen leomolnak a te magas és erős kőfalaid, a melyekben bízol, minden te földeden: megszáll téged minden városodban, minden te földeden, a melyet az Úr, a te Istened ád néked.
53 Ìwọ ó sì jẹ èso ọmọ inú rẹ̀, ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti ti àwọn ọmọ rẹ obìnrin tí Olúwa Ọlọ́run ti fi fún ọ; nínú ìdótì náà àti nínú ìhámọ́ náà tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò há ọ mọ́.
És megeszed a te méhednek gyümölcsét, a te fiaidnak és leányidnak húsát, a kiket ád néked az Úr, a te Istened – a megszállás és szorongattatás alatt, a melylyel megszorongat téged a te ellenséged.
54 Ọkùnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, ojú rẹ̀ yóò korò sí arákùnrin rẹ̀ àti sí aya oókan àyà rẹ̀, àti sí ìyókù ọmọ rẹ̀ tí òun jẹ kù.
A te közötted való finnyás és igen kedvére nevekedett férfi is irígy szemmel tekint az ő atyjafiára, az ő szeretett feleségére és fiainak maradékrészére, a kik megmaradtak még.
55 Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fún ẹnikẹ́ni nínú ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ̀ tí ó ń jẹ, nítorí kò sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún un nínú ìdótì náà àti ìhámọ́, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ gbogbo.
Hogy ne kelljen adnia azok közül senkinek az ő fiainak húsából, a mit eszik, mivelhogy semmi egyebe nem marad a megszállás és szorongattatás alatt, a melylyel megszorongat téged a te ellenséged minden városodban.
56 Obìnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, tí kò jẹ́ dáṣà láti fi àtẹ́lẹsẹ̀ ẹ rẹ̀ kan ilẹ̀ nítorí ìkẹ́ra àti ìwà ẹlẹgẹ́, ojú u rẹ̀ yóò korò sí ọkọ oókan àyà rẹ̀, àti sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ rẹ̀ obìnrin,
A közötted való finnyás és kedvére nevekedett asszony (a ki meg se próbálta talpát a földre bocsátani az elkényesedés és finnyásság miatt) irígy szemmel tekint az ő szeretett férjére, fiára, leányára.
57 àti sí ọmọ rẹ̀ tí ó ti agbede-méjì ẹsẹ̀ rẹ̀ jáde, àti sí àwọn ọmọ rẹ̀ tí yóò bí. Nítorí òun ó jẹ wọ́n ní ìkọ̀kọ̀, nítorí àìní ohunkóhun nínú ìdótì àti ìhámọ́ náà, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ.
Az ő mássa miatt, a mely elmegy tőle és gyermekei miatt, a kiket megszül; mert megeszi ezeket titkon, mikor mindenből kifogy, a megszállás és szorongattatás alatt, a melylyel megszorongat téged a te ellenséged a te városaidban.
58 Bí ìwọ kò bá rọra tẹ̀lé gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí, tí a kọ sínú ìwé yìí, tí ìwọ kò sì bu ọlá fún ògo yìí àti orúkọ dáradára: orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ,
Hogyha meg nem tartod és nem teljesíted e törvény minden ígéjét, a melyek meg vannak írva e könyvben, hogy féljed e dicsőséges és rettenetes nevet, az Úrét, a te Istenedét:
59 Olúwa yóò sọ ìyọnu rẹ di ìyanu, àti ìyọnu irú-ọmọ ọ̀ rẹ, àní àwọn ìyọnu ńlá èyí tí yóò pẹ́, àti ààrùn búburú èyí tí yóò pẹ́.
Csudálatosakká teszi az Úr a te csapásaidat, és a te magodnak csapásait: nagy és maradandó csapásokká, gonosz és maradandó betegségekké.
60 Olúwa yóò mú gbogbo ààrùn Ejibiti tí ó mú ẹ̀rù bà ọ́ wá padà bá ọ, wọn yóò sì lẹ̀ mọ́ ọ.
És reád fordítja Égyiptomnak minden nyavalyáját, a melyektől irtóztál vala, és hozzád ragadnak azok.
61 Olúwa yóò tún mú onírúurú àìsàn àti ìpọ́njú tí a kò kọ sínú ìwé òfin yìí wá sórí rẹ, títí ìwọ yóò fi run.
Mindazt a betegséget és mindazt a csapást is, a melyek nincsenek megírva e törvénynek könyvében, reád rakja az Úr, míglen kipusztulsz.
62 Ìwọ tí ó dàbí àìmoye bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò ṣẹ́ku kékeré níye, nítorí tí o kò ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
És kevesen maradtok meg, a kik annak előtte oly sokan voltatok, mint az égnek csillagai; mivelhogy nem hallgattál az Úrnak, a te Istenednek szavára.
63 Gẹ́gẹ́ bí ó ti dùn mọ́ Olúwa nínú láti mú ọ ṣe rere àti láti pọ̀ si ní iye, bẹ́ẹ̀ ni yóò dùn mọ́ ọ nínú láti bì ọ́ ṣubú kí ó sì pa ọ́ run. Ìwọ yóò di fífà tu kúrò lórí ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
És a miképen örvendezett az Úr rajtatok, hogy jót tett veletek és megsokasított titeket: akképen fog örvendezni az Úr rajtatok, hogy kiveszt és kipusztít titeket; és ki fogtok gyomláltatni arról a földről, a melyre te bemégy, hogy bírjad azt.
64 Nígbà náà ni Olúwa yóò fọ́n ọ ká láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, láti òpin kan ní ayé sí òmíràn. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò ti sin ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run igi àti ti òkúta. Èyí tí ìwọ àti àwọn baba rẹ kò mọ̀.
És szétszór téged az Úr minden nép közé, a földnek egyik végétől a földnek másik végéig; és szolgálni fogsz ott idegen isteneket, a kiket sem te nem ismertél, sem a te atyáid: fát és követ.
65 Ìwọ kì yóò sinmi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà, kò sí ibi ìsinmi fún àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti fún ọ ní ọkàn ìnàngà, àárẹ̀ ojú, àti àìnírètí àyà.
De e nemzetek között sem pihensz meg, és nem lesz a te talpadnak nyugodalma; mert rettegő szívet, epedő szemeket és sóvárgó lelket ád ott néked az Úr.
66 Ìwọ yóò gbé ní ìdádúró ṣinṣin, kún fún ìbẹ̀rùbojo lọ́sàn án àti lóru, bẹ́ẹ̀ kọ́ láé ni ìwọ yóò rí i ní àrídájú wíwà láyé rẹ.
És a te életed kétséges lesz majd előtted: és rettegni fogsz éjjel és nappal, és nem bízol életedben.
67 Ìwọ yóò wí ní òwúrọ̀ pé, “Bí ó tilẹ̀ lè jẹ́ pé ìrọ̀lẹ́ nìkan ni!” Nítorí ẹ̀rù tí yóò gba ọkàn rẹ àti ìran tí ojú rẹ yóò máa rí.
Reggel azt mondod: Bárcsak estve volna! estve pedig azt mondod: Bárcsak reggel volna! – a te szívednek rettegései miatt, a melylyel rettegsz, és a te szemeidnek látása miatt, a melyet látsz.
68 Olúwa yóò rán ọ padà nínú ọkọ̀ sí Ejibiti sí ìrìnàjò tí mo ní ìwọ kì yóò lọ mọ́. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò tún fi ara rẹ fún àwọn ọ̀tá à rẹ gẹ́gẹ́ bí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò rà ọ́.
És visszavisz téged az Úr Égyiptomba hajókon, azon az úton, a melyről azt mondtam néked, hogy nem fogod azt többé meglátni! És áruljátok ott magatokat a ti ellenségeiteknek szolgákul és szolgálóleányokul, de nem lesz, a ki megvegyen.