< Deuteronomy 28 >

1 Bí ìwọ bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní kíkún kí o sì kíyèsára láti tẹ̀lé gbogbo ohun tí ó pàṣẹ tí mo fi fún ọ lónìí, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé ọ lékè ju gbogbo orílẹ̀-èdè ayé lọ.
Og det skal ske, om du flitteligen hører paa Herren din Guds Røst, saa at du tager Vare paa at gøre alle hans Bud, som jeg byder dig i Dag, da skal Herren din Gud sætte dig højt over alle Folk paa Jorden.
2 Gbogbo ìbùkún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ bí o bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Og alle disse Velsignelser skulle komme over dig og vederfares dig, naar du hører paa Herren din Guds Røst:
3 Ìbùkún ni fún ọ ni ìlú, ìbùkún ni fún ọ ní oko.
Velsignet skal du være i Staden, og velsignet skal du være paa Marken.
4 Ìbùkún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, àti irú ohun ọ̀sìn rẹ àti ìbísí i màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
Velsignet skal dit Livs Frugt være og dit Lands Frugt og dit Kvægs Frugt, dine Øksnes Affødning og dit smaa Kvægs Yngel.
5 Ìbùkún ni fún agbọ̀n rẹ àti fún ọpọ́n ipò ìyẹ̀fun rẹ.
Velsignet skal din Kurv være og dit Dejgtrug.
6 Ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá wọlé, ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
Velsignet skal du være, naar du gaar ind, og velsignet skal du være, naar du gaar ud.
7 Olúwa yóò gbà fún ọ pé gbogbo ọ̀tá tí ó dìde sí ọ yóò bì ṣubú níwájú rẹ. Wọn yóò tọ̀ ọ́ wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n wọn yóò sá fún ọ ní ọ̀nà méje.
Herren skal give dine Fjender, som rejse sig imod dig, slagne for dit Ansigt; ad een Vej skulle de drage ud imod dig, og ad syv Veje skulle de fly for dit Ansigt.
8 Olúwa yóò rán ìbùkún sí ọ àti sí ohun gbogbo tí o bá dáwọ́ rẹ lé. Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún un fún ọ nínú ilẹ̀ tí ó ń fi fún ọ.
Herren skal byde Velsignelsen at være hos dig i dine Lader og i alt det, som du udrækker din Haand til; og han skal velsigne dig i det Land, som Herren din Gud giver dig.
9 Olúwa yóò fi ọ́ múlẹ̀ bí ènìyàn mímọ́, bí ó ti ṣe ìlérí fún ọ lórí ìbúra, bí o bá pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ mọ́ tí o sì ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Herren skal oprejse dig til et helligt Folk for sig, som han har tilsvoret dig, naar du holder Herren din Guds Bud og vandrer i hans Veje.
10 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ayé yóò rí i pé a pè ọ́ ní orúkọ Olúwa, wọn yóò sì bẹ̀rù rẹ.
Og alle Folk paa Jorden skulle se, at du er kaldet efter Herrens Navn, og de skulle frygte for dig.
11 Olúwa yóò fi àlàáfíà fún ọ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́, fún ọmọ inú rẹ, irú ohun ọ̀sìn rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá rẹ láti fún ọ.
Og Herren skal give Overflod, dig til Gode, af dit Livs Frugt og af dit Kvægs Frugt og af dit Lands Frugt i det Land, som Herren tilsvor dine Fædre at give dig.
12 Olúwa yóò ṣí ọ̀run sílẹ̀, ìṣúra rere rẹ̀ fún ọ, láti rọ òjò sórí ilẹ̀ rẹ ní àsìkò rẹ àti láti bùkún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ. Ìwọ yóò yá ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n ìwọ kò ní í yá lọ́wọ́ ẹnìkankan.
Herren skal oplade for dig sit gode Forraadskammer, Himmelen, for at give dit Land Regn i sin Tid og at velsigne al din Haands Gerning, og du skal laane ud til mange Folk, og du skal ikke tage til Laans.
13 Olúwa yóò fi ọ́ ṣe orí, ìwọ kì yóò sì jẹ́ ìrù. Bí o bá fi etí sílẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ tí mo fi fún ọ kí o sì máa rọra tẹ̀lé wọn, ìwọ yóò máa wà lókè, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò wà ní ìsàlẹ̀ láé.
Og Herren skal sætte dig til Hoved og ikke til Hale, og du skal kun gaa opad og ikke nedad, dersom du vil høre Herren din Guds Bud, hvilke jeg byder dig i Dag at holde og at gøre efter dem,
14 Má ṣe yà sọ́tùn tàbí sósì kúrò, nínú èyíkéyìí àwọn àṣẹ tí mo fi fún ọ ní òní yìí, kí o má ṣe tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti máa sìn wọ́n.
og du ikke viger fra noget af disse Ord, som jeg byder eder i Dag, til højre eller venstre Side, ved at gaa efter andre Guder og tjene dem.
15 Ṣùgbọ́n bí o kò bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì rọra máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí, gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ.
Og det skal ske, dersom du ikke hører Herren din Guds Røst om at holde og at gøre efter alle hans Bud og hans Skikke, som jeg byder dig i Dag, da skulle alle disse Forbandelser komme over dig og vederfares dig:
16 Ègún ni fún ọ ní ìlú, ègún ni fún ọ ní oko.
Forbandet skal du være i Staden, og forbandet skal du være paa Marken.
17 Ègún ni fún agbọ̀n rẹ àti ọpọ́n ìpo-fúláwà rẹ.
Forbandet skal din Kurv være og dit Dejgtrug.
18 Ègún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, ìbísí màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
Forbandet skal dit Livs Frugt være og dit Lands Frugt, dine Øksnes Affødning og dit smaa Kvægs Yngel.
19 Ègún ni fún ọ nígbà tí o bá wọlé ègún sì ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
Forbandet skal du være, naar du gaar ind, og forbandet skal du være, naar du gaar ud.
20 Olúwa yóò rán ègún sórí rẹ, rúdurùdu àti ìfibú nínú gbogbo ohun tí o bá dáwọ́ rẹ lé, títí ìwọ yóò fi parun àti wá sí ìparun lójijì nítorí búburú tí o ti ṣe ní kíkọ̀ mi sílẹ̀.
Herren skal sende Forbandelsen, Forstyrrelsen og Tugtelsen over dig i alt det, du udrækker din Haand til, som du vil gøre, indtil du bliver ødelagt, og indtil du hastigen gaar til Grunde for dine Gerningers Ondskabs Skyld, fordi du forlod mig.
21 Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn bá ọ jà títí tí yóò fi pa ọ́ run kúrò ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
Herren skal lade Pest hænge ved dig, indtil han fuldkommen udsletter dig af Landet, som du drager hen til for at eje det.
22 Olúwa yóò kọlù ọ́ pẹ̀lú ààrùn ìgbẹ́, pẹ̀lú ibà àti àìsàn wíwú, pẹ̀lú ìjóni ńlá àti idà, pẹ̀lú ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù tí yóò yọ ọ́ lẹ́nu títí ìwọ yóò fi parun.
Herren skal slaa dig med Svindsot og med Feber og med hidsig Sygdom og med Betændelse og med Sværd og med Brand og Rust i Kornet, og de skulle forfølge dig, indtil du omkommer.
23 Ojú ọ̀run tí ó wà lórí rẹ yóò jẹ́ idẹ, ilẹ̀ tí ń bẹ níṣàlẹ̀ rẹ yóò sì jẹ́ irin.
Og din Himmel, som er over dit Hoved, skal være som Kobber, og Jorden, som er under dig, som Jern.
24 Olúwa yóò yí òjò ilẹ̀ rẹ sí eruku àti ẹ̀tù; láti ọ̀run ni yóò ti máa sọ̀kalẹ̀ sí ọ, títí tí ìwọ yóò fi run.
Herren skal gøre dit Lands Regn til Sand og Støv; af Himmelen skal det falde ned over dig, indtil du bliver ødelagt.
25 Olúwa yóò fi ọ́ gégùn ún láti ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá rẹ. Ìwọ yóò tọ̀ wọ́n wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá fún wọn ní ọ̀nà méje, ìwọ yóò sì padà di ohun ìbẹ̀rù fún gbogbo ìjọba lórí ayé.
Herren skal lade dig slaas for dine Fjenders Ansigt; ad een Vej skal du drage ud imod ham, og ad syv Veje skal du fly for hans Ansigt; og du skal være i Ustadighed iblandt alle Riger paa Jorden.
26 Òkú rẹ yóò jẹ́ oúnjẹ fún gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko ayé, àti pé kò ní sí ẹnikẹ́ni tí yóò lé wọn kúrò.
Og din døde Krop skal blive alle Fugle under Himmelen og Dyr paa Jorden til Føde, og der skal ingen være, som skræmmer dem.
27 Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú oówo, Ejibiti àti pẹ̀lú kókó, ojú egbò kíkẹ̀ àti ìhúnra.
Herren skal slaa dig med ægyptiske Bylder og med Hævelser og med Skurv og med Udslet, for hvilke du ikke skal kunne læges.
28 Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú ìsínwín, ojú fífọ́ àti rúdurùdu àyà.
Herren skal slaa dig med Vanvid og med Blindhed og med Sindsforvirring.
29 Ní ọ̀sán gangan ìwọ yóò fi ọwọ́ tálẹ̀ kiri bí ọkùnrin afọ́jú nínú òkùnkùn ìwọ kì yóò ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí o bá ń ṣe, ojoojúmọ́ ni wọn yóò máa ni ọ́ lára àti jà ọ́ ní olè, tí kò sì ní í sí ẹnìkan láti gbà ọ́.
Og du skal føle dig for om Middagen, ligesom den blinde føler sig for i Mørket, og du skal ingen Lykke have paa dine Veje, og du skal lide idel Vold og vorde til Rov alle Dage, og ingen skal frelse dig.
30 Ìwọ yóò gba ògo láti fẹ́ obìnrin kan ṣùgbọ́n ẹlòmíràn yóò gbà á yóò sì tẹ́ ẹ́ ní ògo. Ìwọ yóò kọ́ ilé, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò gbé ibẹ̀. Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kò tilẹ̀ ní gbádùn èso rẹ.
Du skal trolove dig en Hustru, og en anden Mand skal ligge hos hende; du skal bygge et Hus, men du skal ikke bo derudi; du skal plante en Vingaard, men du skal ikke nyde Frugten af den.
31 Màlúù rẹ yóò di pípa níwájú rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò jẹ nǹkan kan nínú rẹ̀. Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ yóò sì di mímú pẹ̀lú agbára kúrò lọ́dọ̀ rẹ, a kì yóò sì da padà. Àgùntàn rẹ yóò di mímú fún àwọn ọ̀tá rẹ, ẹnìkankan kò sì ní gbà á.
Din Okse skal slagtes for dine Øjne, og du skal ikke æde deraf; dit Asen skal røves for dit Ansigt og ikke komme tilbage til dig; dit smaa Kvæg skal gives dine Fjender, og du skal ingen have, som frelser dig.
32 Àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ yóò di mímú fún àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, ìwọ yóò sì fi ojú rẹ ṣọ́nà dúró dè wọ́n láti ọjọ́ dé ọjọ́, ìwọ yóò sì jẹ́ aláìlágbára láti gbé ọwọ́.
Dine Sønner og dine Døtre skulle gives til et andet Folk, og dine Øjne skulle se derpaa og hentæres over dem hver Dag; men der skal intet være i din Haands Magt.
33 Èso ilẹ̀ rẹ àti gbogbo iṣẹ́ làálàá rẹ ni orílẹ̀-èdè mìíràn tí ìwọ kò mọ̀ yóò sì jẹ, ìwọ yóò jẹ́ kìkì ẹni ìnilára àti ẹni ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
Dit Lands Frugt og alt, hvad du har arbejdet for, skal et Folk fortære, som du ikke kender, og du skal lide idel Vold og blive knust alle Dage.
34 Ìran tí ojú rẹ yóò rí, yóò sọ ọ́ di òmùgọ̀.
Og du skal blive rasende over det Syn, som dine Øjne skulle se.
35 Olúwa yóò lu eékún àti ẹsẹ̀ rẹ pẹ̀lú oówo dídùn tí kò le san tán láti àtẹ̀lé méjèèjì rẹ lọ sí òkè orí rẹ.
Herren skal slaa dig med onde Bylder paa Knæerne og paa Laarene, saa at du ikke skal kunne læges fra din Fodsaale og til din Hovedisse.
36 Olúwa yóò lé ọ àti ọba tí ó yàn lórí rẹ lọ sí orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ tàbí ti àwọn baba rẹ kò mọ̀. Ibẹ̀ ni ìwọ̀ yóò sì sin ọlọ́run mìíràn, ọlọ́run igi àti òkúta.
Herren skal føre dig og din Konge, som du skal sætte over dig, til et Folk, som hverken du, ej heller dine Fædre have kendt, og der skal du tjene andre Guder, Træ og Sten.
37 Ìwọ yóò di ẹni ìyanu, àti ẹni òwe, àti ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ nínú gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò darí rẹ sí.
Og du skal blive til en Skræk, til et Ordsprog og til Spot iblandt alle de Folk, til hvilke Herren skal føre dig hen.
38 Ìwọ yóò gbin irúgbìn púpọ̀ ṣùgbọ́n ìwọ yóò kórè kékeré, nítorí eṣú yóò jẹ ẹ́ run.
Du skal udføre megen Sæd paa Marken, men du skal samle lidet ind; thi Græshoppen skal opæde den.
39 Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà púpọ̀ ìwọ yóò sì ro wọ́n ṣùgbọ́n kò ní mú wáìnì náà tàbí kó àwọn èso jọ, nítorí kòkòrò yóò jẹ wọ́n run.
Du skal plante og dyrke Vingaarde, men ikke drikke Vinen og ikke indsamle; thi Ormen skal fortære den.
40 Ìwọ yóò ní igi olifi jákèjádò ilẹ̀ rẹ ṣùgbọ́n ìwọ kò ní lo òróró náà, nítorí olifi náà yóò rẹ̀ dànù.
Du skal have Olietræer inden alle dine Landemærker, men ikke salve dig med Olien; thi dit Olietræ skal oprykkes.
41 Ìwọ yóò ní àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin ṣùgbọ́n ìwọ kò nípa wọ́n mọ́, nítorí wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
Du skal avle Sønner og Døtre, men de skulle ikke blive hos dig; thi de skulle gaa i Fangenskab.
42 Ọ̀wọ́ eṣú yóò gba gbogbo àwọn igi rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ.
Alle dine Træer og dit Lands Frugt skal Græshoppen eje.
43 Àjèjì tí ń gbé láàrín rẹ yóò gbé sókè gíga jù ọ́ lọ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò máa di ìrẹ̀sílẹ̀.
Den fremmede, som er midt iblandt dig, skal stige højere og højere op over dig; men du skal stige dybere og dybere ned.
44 Yóò yà ọ́, ṣùgbọ́n o kì yóò yà á, òun ni yóò jẹ́ orí, ìwọ yóò jẹ́ ìrù.
Han skal laane dig, og du skal ikke laane ham; han skal være Hoved og du skal være Hale.
45 Gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ, wọn yóò lé ọ wọn yóò sì bá ọ títí tí ìwọ yóò fi parun, nítorí ìwọ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ kò sì kíyèsi àṣẹ àti òfin tí ó fi fún ọ.
Saa skulle alle disse Forbandelser komme over dig og forfølge dig og ramme dig, indtil du bliver ødelagt, fordi du ikke hørte Herren din Guds Røst, saa at du holdt hans Bud og hans Skikke, som han havde budet dig.
46 Wọn yóò jẹ́ àmì àti ìyanu fún ọ àti fún irú-ọmọ rẹ títí láé.
Og de skulle være til et Tegn og til et Vidunder paa dig og paa din Sæd evindeligen,
47 Nítorí ìwọ kò sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ní ayọ̀ àti inú dídùn ní àkókò àlàáfíà.
efterdi du ikke tjente Herren din Gud i Glæde og med Hjertens Lyst, fordi du havde alting i Overflod.
48 Nítorí náà nínú ebi àti òǹgbẹ, nínú ìhòhò àti àìní búburú, ìwọ yóò sin àwọn ọ̀tá à rẹ tí Olúwa rán sí ọ. Yóò sì fi àjàgà irin bọ̀ ọ́ ní ọrùn, títí yóò fi run ọ́.
Og du skal tjene dine Fjender, som Herren skal udsende imod dig, i Hunger og i Tørst, i Nøgenhed og i alle Haande Mangel; og han skal lægge et Jernaag paa din Hals, indtil han ødelægger dig.
49 Olúwa yóò mú àwọn orílẹ̀-èdè wá sí ọ láti ọ̀nà jíjìn, bí òpin ayé, bí idì ti ń bẹ́ láti orí òkè sílẹ̀, orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò gbọ́ èdè wọn.
Herren skal føre et Folk op over dig langt fra, fra Jordens Ende, som Ørnen i Flugt, et Folk, hvis Tungemaal du ikke forstaar,
50 Orílẹ̀-èdè tí ó rorò tí kò ní ojúrere fún àgbà tàbí àánú fún ọmọdé.
et ublu Folk, som ikke skal agte den gamles Person og ej være den unge naadig.
51 Wọn yóò jẹ ohun ọ̀sìn rẹ run àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ títí tí ìwọ yóò fi parun. Wọn kì yóò fi hóró irúgbìn kan fún ọ, wáìnì tuntun tàbí òróró, tàbí agbo ẹran màlúù rẹ kankan tàbí ọ̀wọ́ ẹran àgùntàn rẹ títí ìwọ yóò fi run.
Og det skal fortære dit Kvægs Frugt og dit Lands Frugt, indtil du bliver ødelagt, og det skal ikke efterlade dig Korn, ny Vin eller Olie, dine Øksnes Affødning eller dit smaa Kvægs Yngel, indtil det faar dig tilintetgjort.
52 Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ títí tí odi ìdáàbòbò gíga yẹn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé yóò fi wó lulẹ̀. Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ jákèjádò ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ.
Og det skal ængste dig inden alle dine Porte, indtil dine høje og befæstede Mure falde ned, som du forlader dig paa i hele dit Land; ja det skal ængste dig inden alle dine Porte i dit ganske Land, som Herren din Gud har givet dig.
53 Ìwọ ó sì jẹ èso ọmọ inú rẹ̀, ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti ti àwọn ọmọ rẹ obìnrin tí Olúwa Ọlọ́run ti fi fún ọ; nínú ìdótì náà àti nínú ìhámọ́ náà tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò há ọ mọ́.
Og du skal æde dit Livs Frugt, Kødet af dine Sønner og af dine Døtre, som Herren din Gud har givet dig, i Belejring og i Trang, hvormed din Fjende skal trænge dig.
54 Ọkùnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, ojú rẹ̀ yóò korò sí arákùnrin rẹ̀ àti sí aya oókan àyà rẹ̀, àti sí ìyókù ọmọ rẹ̀ tí òun jẹ kù.
Den Mand, som var blødagtig hos dig og saare kræsen, han skal ikke unde sin Broder eller Hustruen i sin Arm eller sine øvrige Sønner, som han har tilbage,
55 Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fún ẹnikẹ́ni nínú ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ̀ tí ó ń jẹ, nítorí kò sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún un nínú ìdótì náà àti ìhámọ́, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ gbogbo.
at give en af dem af sine Sønners Kød, hvilket han æder, fordi intet er levnet ham i den Belejring og Trang, hvormed din Fjende skal trænge dig inden dine Porte.
56 Obìnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, tí kò jẹ́ dáṣà láti fi àtẹ́lẹsẹ̀ ẹ rẹ̀ kan ilẹ̀ nítorí ìkẹ́ra àti ìwà ẹlẹgẹ́, ojú u rẹ̀ yóò korò sí ọkọ oókan àyà rẹ̀, àti sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ rẹ̀ obìnrin,
Hun, som har været saa blødagtig og kræsen hos dig, at hun ikke har forsøgt at sætte sin Fodsaale paa Jorden for Kræsenhed og Blødagtighed, skal ikke unde sin Mand i sin Arm eller sin Søn eller sin Datter
57 àti sí ọmọ rẹ̀ tí ó ti agbede-méjì ẹsẹ̀ rẹ̀ jáde, àti sí àwọn ọmọ rẹ̀ tí yóò bí. Nítorí òun ó jẹ wọ́n ní ìkọ̀kọ̀, nítorí àìní ohunkóhun nínú ìdótì àti ìhámọ́ náà, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ.
end ikke sit Efterbyrd, som er gaaet fra hende, eller sine Børn, som hun skal føde; thi hun skal æde dem i Skjul af Mangel paa alt, i Belejring og i Trang, hvormed din Fjende skal trænge dig inden dine Porte.
58 Bí ìwọ kò bá rọra tẹ̀lé gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí, tí a kọ sínú ìwé yìí, tí ìwọ kò sì bu ọlá fún ògo yìí àti orúkọ dáradára: orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ,
Dersom du ikke tager Vare paa at gøre efter alle denne Lovs Ord, som ere skrevne i denne Bog, saa at du frygter dette herlige og forfærdelige Navn, Herren din Gud:
59 Olúwa yóò sọ ìyọnu rẹ di ìyanu, àti ìyọnu irú-ọmọ ọ̀ rẹ, àní àwọn ìyọnu ńlá èyí tí yóò pẹ́, àti ààrùn búburú èyí tí yóò pẹ́.
Da skal Herren vidunderligen sende Plager paa dig og Plager paa din Sæd, store og vedvarende Plager, og onde og vedvarende Sygdomme.
60 Olúwa yóò mú gbogbo ààrùn Ejibiti tí ó mú ẹ̀rù bà ọ́ wá padà bá ọ, wọn yóò sì lẹ̀ mọ́ ọ.
Og han skal gentage alle de ægyptiske Sygdomme over dig, hvilke du gruer for, og de skulle hænge ved dig.
61 Olúwa yóò tún mú onírúurú àìsàn àti ìpọ́njú tí a kò kọ sínú ìwé òfin yìí wá sórí rẹ, títí ìwọ yóò fi run.
Ja, al Sygdom og al Plage, som ikke er skreven i denne Lovs Bog, den skal Herren lade komme over dig, indtil du ødelægges.
62 Ìwọ tí ó dàbí àìmoye bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò ṣẹ́ku kékeré níye, nítorí tí o kò ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Og I skulle blive tilovers som en liden Hob, i det Sted, at I vare som Stjernerne paa Himmelen i Mangfoldighed, fordi du ikke hørte paa Herren din Guds Røst.
63 Gẹ́gẹ́ bí ó ti dùn mọ́ Olúwa nínú láti mú ọ ṣe rere àti láti pọ̀ si ní iye, bẹ́ẹ̀ ni yóò dùn mọ́ ọ nínú láti bì ọ́ ṣubú kí ó sì pa ọ́ run. Ìwọ yóò di fífà tu kúrò lórí ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
Og det skal ske, at ligesom Herren glædede sig over eder, ved at gøre vel imod eder og at formere eder, saaledes skal Herren glæde sig over eder, ved at fordærve eder og ødelægge eder; og I skulle udryddes af Landet, som du kommer hen til for at eje det.
64 Nígbà náà ni Olúwa yóò fọ́n ọ ká láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, láti òpin kan ní ayé sí òmíràn. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò ti sin ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run igi àti ti òkúta. Èyí tí ìwọ àti àwọn baba rẹ kò mọ̀.
Og Herren skal adsprede dig iblandt alle Folk fra den ene Ende af Jorden til den anden Ende af Jorden; og der skal du tjene andre Guder, som hverken du eller dine Fædre kendte, Træ og Sten.
65 Ìwọ kì yóò sinmi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà, kò sí ibi ìsinmi fún àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti fún ọ ní ọkàn ìnàngà, àárẹ̀ ojú, àti àìnírètí àyà.
Og du skal ingen Rolighed have iblandt disse Folk, og din Fodsaale skal ingen Hvile have; og Herren skal give dig der et bævende Hjerte og hentærede Øjne og en bedrøvet Sjæl.
66 Ìwọ yóò gbé ní ìdádúró ṣinṣin, kún fún ìbẹ̀rùbojo lọ́sàn án àti lóru, bẹ́ẹ̀ kọ́ láé ni ìwọ yóò rí i ní àrídájú wíwà láyé rẹ.
Og dit Liv skal hænge i et Haar for dig, og du skal ræddes Dag og Nat og ikke være sikker paa dit Liv.
67 Ìwọ yóò wí ní òwúrọ̀ pé, “Bí ó tilẹ̀ lè jẹ́ pé ìrọ̀lẹ́ nìkan ni!” Nítorí ẹ̀rù tí yóò gba ọkàn rẹ àti ìran tí ojú rẹ yóò máa rí.
Om Morgenen skal du sige: Gid det var Aften! og om Aftenen skal du sige: Gid det var Morgen! for dit Hjertes Rædsel, som du skal ræddes med, og for det Syn, dine Øjne skulle se.
68 Olúwa yóò rán ọ padà nínú ọkọ̀ sí Ejibiti sí ìrìnàjò tí mo ní ìwọ kì yóò lọ mọ́. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò tún fi ara rẹ fún àwọn ọ̀tá à rẹ gẹ́gẹ́ bí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò rà ọ́.
Og Herren skal føre dig tilbage til Ægypten igen paa Skibe ad den Vej, om hvilken jeg sagde dig: Du skal ikke ydermere se den; og der skulle I sælge eder selv til dine Fjender som Trælle og som Trælkvinder, og der skal ingen være, som vil købe.

< Deuteronomy 28 >