< Deuteronomy 27 >

1 Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Pa gbogbo àṣẹ tí mo fún ọ lónìí mọ́.
UMozisi labadala bakoIsrayeli basebelaya abantu besithi: Gcina yonke imithetho engililaya yona lamuhla.
2 Nígbà tí o bá ti kọjá a Jordani sí inú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ, gbé kalẹ̀ lára àwọn òkúta ńlá àti aṣọ ìlekè rẹ pẹ̀lú ẹfun.
Kuzakuthi-ke mhla lichapha iJordani lisiya elizweni iNkosi uNkulunkulu wakho ekunika lona, uzazimisela amatshe amakhulu, uwahuqe ngekalaga,
3 Kí ìwọ kí ó kọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí sára wọn nígbà tí ìwọ bá ti ń rékọjá láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti ṣèlérí fún ọ.
ubhale kuwo wonke amazwi alumlayo nxa usuchaphile, ukuze ungene elizweni iNkosi uNkulunkulu wakho ekunika lona, ilizwe eligeleza uchago loluju, njengalokho iNkosi uNkulunkulu waboyihlo ikhulumile kuwe.
4 Àti nígbà tí o bá ti kọjá a Jordani, kí o gbé òkúta yìí kalẹ̀ sórí i Ebali, bí mo ti pa à láṣẹ fún ọ lónìí, kí o sì wọ̀ wọ́n pẹ̀lú ẹfun.
Kuzakuthi-ke selichaphile iJordani, limise lamatshe engililaya ngawo lamuhla, entabeni yeEbhali, liwahuqe ngekalaga.
5 Kọ́ pẹpẹ síbẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, pẹpẹ òkúta. Má ṣe lo ohun èlò irin lórí wọn.
Wakhele khona iNkosi uNkulunkulu wakho ilathi, ilathi lamatshe. Ungasebenzisi insimbi phezu kwawo.
6 Kí ìwọ kí ó mọ pẹpẹ pẹ̀lú òkúta àìgbẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí ìwọ kí ó sì máa rú ẹbọ sísun ni orí rẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Wakhele iNkosi uNkulunkulu wakho ilathi ngamatshe apheleleyo. Unikele phezu kwalo iminikelo yokutshiswa eNkosini uNkulunkulu wakho,
7 Rú ẹbọ àlàáfíà níbẹ̀ kí o jẹ wọ́n, kí o sì yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
uhlabe iminikelo yokuthula, udle lapho, uthokoze phambi kweNkosi uNkulunkulu wakho.
8 Kí o sì kọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí ketekete sórí òkúta tí ó ti gbé kalẹ̀.”
Futhi ubhale phezu kwamatshe wonke amazwi alumlayo, kukhanye kuhle.
9 Nígbà náà ni Mose àti àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi, sọ fún Israẹli pé, “Ẹ dákẹ́ ẹ̀yin Israẹli, kí ẹ sì fetísílẹ̀! O ti wá di ènìyàn Olúwa Ọlọ́run rẹ báyìí.
UMozisi labapristi abangamaLevi basebekhuluma kuIsrayeli wonke besithi: Thula ulalele, Israyeli; lamuhla usuyisizwe seNkosi uNkulunkulu wakho.
10 Gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì tẹ̀lé àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mo ń fi fún ọ lónìí.”
Ngakho uzalalela ilizwi leNkosi uNkulunkulu wakho, wenze imilayo yayo lezimiso zayo engikulaya zona lamuhla.
11 Ní ọjọ́ kan náà Mose pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé.
UMozisi wasebalaya abantu ngalolosuku esithi:
12 Nígbà tí ìwọ bá ti kọjá a Jordani, àwọn ẹ̀yà yìí yóò dúró lórí òkè Gerisimu láti súre fún àwọn ènìyàn: Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Josẹfu àti Benjamini.
Laba bazakuma entabeni yeGerizimi ukubusisa abantu nxa selichaphe iJordani: OSimeyoni, loLevi, loJuda, loIsakari, loJosefa, loBhenjamini.
13 Àwọn ẹ̀yà yìí yóò dúró lórí òkè Ebali láti gé ègún: Reubeni, Gadi, àti Aṣeri, àti Sebuluni, Dani, àti Naftali.
Lalaba bazakuma entabeni yeEbhali phezu kwesiqalekiso: ORubeni, uGadi, loAsheri, loZebuluni, uDani, loNafithali.
14 Àwọn ẹ̀yà Lefi yóò ké sí gbogbo ènìyàn Israẹli ní ohùn òkè:
LamaLevi azaphendula athi kuwo wonke amadoda akoIsrayeli ngelizwi eliphakemeyo:
15 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó fín ère tàbí gbẹ́ òrìṣà ohun tí ó jẹ́ ìríra níwájú Olúwa, iṣẹ́ ọwọ́ oníṣọ̀nà tí ó gbé kalẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kaqalekiswe umuntu owenza isithombe esibaziweyo lesibunjwe ngokuncibilikisa, isinengiso eNkosini, umsebenzi wezandla zomuntu oyingcitshi, asibeke ensitha. Labo bonke abantu bazaphendula bathi: Ameni.
16 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dójútì baba tàbí ìyá rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kaqalekiswe odelela uyise lonina. Labo bonke abantu bazakuthi: Ameni.
17 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó yí òkúta ààlà aládùúgbò o rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kaqalekiswe otshedisa isikhonkwane somngcele kamakhelwane wakhe. Labo bonke abantu bazakuthi: Ameni.
18 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣi afọ́jú lọ́nà ní ojú ọ̀nà.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kaqalekiswe oduhisa isiphofu endleleni. Labo bonke abantu bazakuthi: Ameni.
19 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó yí ìdájọ́ po fún àlejò, aláìní baba tàbí opó.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kaqalekiswe ophambula isahlulelo sowemzini, intandane, lomfelokazi. Labo bonke abantu bazakuthi: Ameni.
20 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ìyàwó baba rẹ̀, nítorí ó ti dójúti ibùsùn baba rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kaqalekiswe olala lomkayise, ngoba embule umphetho wesembatho sikayise. Labo bonke abantu bazakuthi: Ameni.
21 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ẹranko.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kaqalekiswe olala laloba yiyiphi inyamazana. Labo bonke abantu bazakuthi: Ameni.
22 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú arábìnrin rẹ̀, ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kaqalekiswe olala lodadewabo, indodakazi kayise loba indodakazi kanina. Labo bonke abantu bazakuthi: Ameni.
23 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ìyá ìyàwó o rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kaqalekiswe olala loninazala. Labo bonke abantu bazakuthi: Ameni.
24 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kaqalekiswe otshaya umakhelwane wakhe ensitha. Labo bonke abantu bazakuthi: Ameni.
25 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti pa ènìyàn láìjẹ̀bi.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kaqalekiswe owemukela isivalamlomo sokutshaya umuntu, igazi elingelacala. Labo bonke abantu bazakuthi: Ameni.
26 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí kò gbé ọ̀rọ̀ òfin yìí ró nípa ṣíṣe wọ́n.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kaqalekiswe ongaqinisi amazwi alumlayo ukuwenza. Labo bonke abantu bazakuthi: Ameni.

< Deuteronomy 27 >