< Deuteronomy 27 >

1 Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Pa gbogbo àṣẹ tí mo fún ọ lónìí mọ́.
Niin Mooses ja Israelin vanhimmat käskivät kansaa sanoen: "Noudattakaa kaikkia niitä käskyjä, jotka minä tänä päivänä teille annan.
2 Nígbà tí o bá ti kọjá a Jordani sí inú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ, gbé kalẹ̀ lára àwọn òkúta ńlá àti aṣọ ìlekè rẹ pẹ̀lú ẹfun.
Ja kun menette Jordanin yli siihen maahan, jonka Herra, sinun Jumalasi, sinulle antaa, pystytä itsellesi suuria kiviä ja sivele ne kalkilla.
3 Kí ìwọ kí ó kọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí sára wọn nígbà tí ìwọ bá ti ń rékọjá láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti ṣèlérí fún ọ.
Ja kirjoita niihin kaikki tämän lain sanat, kun menet joen yli siihen maahan, jonka Herra, sinun Jumalasi, sinulle antaa, maahan, joka vuotaa maitoa ja mettä, niinkuin Herra, sinun isiesi Jumala, on sinulle puhunut.
4 Àti nígbà tí o bá ti kọjá a Jordani, kí o gbé òkúta yìí kalẹ̀ sórí i Ebali, bí mo ti pa à láṣẹ fún ọ lónìí, kí o sì wọ̀ wọ́n pẹ̀lú ẹfun.
Ja kun olette menneet Jordanin yli, niin pystyttäkää Eebalin vuorelle ne kivet, joista minä tänä päivänä annan teille käskyn, ja sivele ne kalkilla.
5 Kọ́ pẹpẹ síbẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, pẹpẹ òkúta. Má ṣe lo ohun èlò irin lórí wọn.
Ja rakenna siihen alttari Herralle, sinun Jumalallesi, alttari kivistä, joihin et saa rauta-aseella koskea.
6 Kí ìwọ kí ó mọ pẹpẹ pẹ̀lú òkúta àìgbẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí ìwọ kí ó sì máa rú ẹbọ sísun ni orí rẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Hakkaamattomista kivistä rakenna Herran, Jumalasi, alttari; uhraa sen päällä polttouhreja Herralle, Jumalallesi,
7 Rú ẹbọ àlàáfíà níbẹ̀ kí o jẹ wọ́n, kí o sì yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
ja teurasta teuraita yhteysuhriksi ja syö siellä ja iloitse Herran, Jumalasi, edessä.
8 Kí o sì kọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí ketekete sórí òkúta tí ó ti gbé kalẹ̀.”
Ja kirjoita kiviin kaikki tämän lain sanat hyvin selkeästi."
9 Nígbà náà ni Mose àti àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi, sọ fún Israẹli pé, “Ẹ dákẹ́ ẹ̀yin Israẹli, kí ẹ sì fetísílẹ̀! O ti wá di ènìyàn Olúwa Ọlọ́run rẹ báyìí.
Ja Mooses ja leeviläiset papit puhuivat kaikelle Israelille sanoen: "Ole hiljaa ja kuule, Israel! Tänä päivänä on sinusta tullut Herran, Jumalasi, kansa.
10 Gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì tẹ̀lé àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mo ń fi fún ọ lónìí.”
Kuule siis Herraa, Jumalaasi, ja noudata hänen käskyjänsä ja ohjeitansa, jotka minä tänä päivänä sinulle annan."
11 Ní ọjọ́ kan náà Mose pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé.
Ja Mooses käski kansaa sinä päivänä sanoen:
12 Nígbà tí ìwọ bá ti kọjá a Jordani, àwọn ẹ̀yà yìí yóò dúró lórí òkè Gerisimu láti súre fún àwọn ènìyàn: Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Josẹfu àti Benjamini.
"Kun te olette menneet Jordanin yli, asettukoot nämä Garissimin vuorelle siunaamaan kansaa: Simeon, Leevi, Juuda, Isaskar, Joosef ja Benjamin.
13 Àwọn ẹ̀yà yìí yóò dúró lórí òkè Ebali láti gé ègún: Reubeni, Gadi, àti Aṣeri, àti Sebuluni, Dani, àti Naftali.
Nämä taas asettukoot Eebalin vuorelle lausumaan kirouksen: Ruuben, Gaad, Asser, Sebulon, Daan ja Naftali.
14 Àwọn ẹ̀yà Lefi yóò ké sí gbogbo ènìyàn Israẹli ní ohùn òkè:
Ja leeviläiset lausukoot ja sanokoot kovalla äänellä kaikille Israelin miehille:
15 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó fín ère tàbí gbẹ́ òrìṣà ohun tí ó jẹ́ ìríra níwájú Olúwa, iṣẹ́ ọwọ́ oníṣọ̀nà tí ó gbé kalẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
'Kirottu olkoon se, joka tekee jumalankuvan, veistetyn tai valetun, taitajan käden tekemän, kauhistukseksi Herralle, ja joka salaa sen pystyttää'. Ja kaikki kansa vastatkoon ja sanokoon: 'Amen'.
16 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dójútì baba tàbí ìyá rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kirottu olkoon se, joka häpäisee isäänsä tai äitiänsä. Ja kaikki kansa sanokoon: 'Amen'.
17 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó yí òkúta ààlà aládùúgbò o rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kirottu olkoon se, joka siirtää lähimmäisensä rajan. Ja kaikki kansa sanokoon: 'Amen'.
18 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣi afọ́jú lọ́nà ní ojú ọ̀nà.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kirottu olkoon se, joka vie sokean harhaan tieltä. Ja kaikki kansa sanokoon: 'Amen'.
19 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó yí ìdájọ́ po fún àlejò, aláìní baba tàbí opó.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kirottu olkoon se, joka vääristää muukalaisen, orvon tai lesken oikeuden. Ja kaikki kansa sanokoon: 'Amen'.
20 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ìyàwó baba rẹ̀, nítorí ó ti dójúti ibùsùn baba rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kirottu olkoon se, joka makaa äitipuolensa kanssa, sillä hän nostaa isänsä peitteen. Ja kaikki kansa sanokoon: 'Amen'.
21 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ẹranko.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kirottu olkoon se, joka sekaantuu eläimeen. Ja kaikki kansa sanokoon: 'Amen'.
22 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú arábìnrin rẹ̀, ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kirottu olkoon se, joka makaa sisarensa, isänsä tyttären tai äitinsä tyttären, kanssa. Ja kaikki kansa sanokoon: 'Amen'.
23 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ìyá ìyàwó o rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kirottu olkoon se, joka makaa anoppinsa kanssa. Ja kaikki kansa sanokoon: 'Amen'.
24 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kirottu olkoon se, joka salaa murhaa lähimmäisensä. Ja kaikki kansa sanokoon: 'Amen'.
25 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti pa ènìyàn láìjẹ̀bi.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kirottu olkoon se, joka ottaa lahjuksen surmatakseen viattoman. Ja kaikki kansa sanokoon: 'Amen'.
26 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí kò gbé ọ̀rọ̀ òfin yìí ró nípa ṣíṣe wọ́n.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
Kirottu olkoon se, joka ei pidä tämän lain sanoja eikä täytä niitä. Ja kaikki kansa sanokoon: 'Amen'."

< Deuteronomy 27 >