< Deuteronomy 27 >
1 Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Pa gbogbo àṣẹ tí mo fún ọ lónìí mọ́.
Moses [Drawn out] and the elders of Israel [God prevails] enjoined the people, saying, “Keep all the mitzvot ·instructions· and statutes which I enjoin you today.
2 Nígbà tí o bá ti kọjá a Jordani sí inú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ, gbé kalẹ̀ lára àwọn òkúta ńlá àti aṣọ ìlekè rẹ pẹ̀lú ẹfun.
It shall be on the day when you shall pass over the Jordan [Descender] to the land which Adonai your God gives you, that you shall set yourself up great stones, and coat them with plaster.
3 Kí ìwọ kí ó kọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí sára wọn nígbà tí ìwọ bá ti ń rékọjá láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti ṣèlérí fún ọ.
You shall write on them all the words of this Torah ·Teaching·, when you have passed over; that you may go in to the land which Adonai your God gives you, a land flowing with milk and honey, as Adonai, the God of your fathers, has promised you.
4 Àti nígbà tí o bá ti kọjá a Jordani, kí o gbé òkúta yìí kalẹ̀ sórí i Ebali, bí mo ti pa à láṣẹ fún ọ lónìí, kí o sì wọ̀ wọ́n pẹ̀lú ẹfun.
It shall be, when you have crossed over the Jordan [Descender], that you shall set up these stones, which I enjoin you today, on Mount Ebal, and you shall coat them with plaster.
5 Kọ́ pẹpẹ síbẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, pẹpẹ òkúta. Má ṣe lo ohun èlò irin lórí wọn.
There you shall build an altar to Adonai your God, an altar of stones. You shall not use any iron tool on them.
6 Kí ìwọ kí ó mọ pẹpẹ pẹ̀lú òkúta àìgbẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí ìwọ kí ó sì máa rú ẹbọ sísun ni orí rẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.
You shall build Adonai your God’s altar of uncut stones. You shall offer burnt offerings on it to Adonai your God.
7 Rú ẹbọ àlàáfíà níbẹ̀ kí o jẹ wọ́n, kí o sì yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
You shall sacrifice peace offerings, and shall eat there. You shall rejoice before Adonai your God.
8 Kí o sì kọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí ketekete sórí òkúta tí ó ti gbé kalẹ̀.”
You shall write on the stones all the words of this Torah ·Teaching· very plainly.”
9 Nígbà náà ni Mose àti àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi, sọ fún Israẹli pé, “Ẹ dákẹ́ ẹ̀yin Israẹli, kí ẹ sì fetísílẹ̀! O ti wá di ènìyàn Olúwa Ọlọ́run rẹ báyìí.
Moses [Drawn out] and the priests the Levites [Descendants of United with] spoke to all Israel [God prevails], saying, “Be silent, and sh'ma ·hear obey·, Israel [God prevails]! Today you have become the people of Adonai your God.
10 Gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì tẹ̀lé àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mo ń fi fún ọ lónìí.”
You shall therefore sh'ma ·hear obey· Adonai your God’s voice, and do his instructions and his statutes, which I enjoin you today.”
11 Ní ọjọ́ kan náà Mose pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé.
Moses [Drawn out] enjoined the people the same day, saying,
12 Nígbà tí ìwọ bá ti kọjá a Jordani, àwọn ẹ̀yà yìí yóò dúró lórí òkè Gerisimu láti súre fún àwọn ènìyàn: Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Josẹfu àti Benjamini.
“These shall stand on Mount Gerizim to bless the people, when you have crossed over the Jordan [Descender]: Simeon [Hearing], Levi [United with], Judah [Praised], Issachar [Hire, Reward], Joseph [May he add], and Benjamin [Son of right hand, Son of south].
13 Àwọn ẹ̀yà yìí yóò dúró lórí òkè Ebali láti gé ègún: Reubeni, Gadi, àti Aṣeri, àti Sebuluni, Dani, àti Naftali.
These shall stand on Mount Ebal for the curse: Reuben [See, a son!], Gad [Good fortune], Asher [Happy], Zebulun [Living together], Dan [He judged], and Naphtali [My wrestling].
14 Àwọn ẹ̀yà Lefi yóò ké sí gbogbo ènìyàn Israẹli ní ohùn òkè:
With a loud voice, the Levites [Descendants of United with] shall say to all the men of Israel [God prevails],
15 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó fín ère tàbí gbẹ́ òrìṣà ohun tí ó jẹ́ ìríra níwájú Olúwa, iṣẹ́ ọwọ́ oníṣọ̀nà tí ó gbé kalẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
‘Cursed is the man who makes an engraved or molten image, an abomination to Adonai, the work of the hands of the craftsman, and sets it up in secret.’ All the people shall answer and say, ‘Amen ·So be it·.’
16 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dójútì baba tàbí ìyá rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
‘Cursed is he who dishonors his father or his mother.’ All the people shall say, ‘Amen ·So be it·.’
17 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó yí òkúta ààlà aládùúgbò o rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
‘Cursed is he who removes his neighbor’s landmark.’ All the people shall say, ‘Amen ·So be it·.’
18 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣi afọ́jú lọ́nà ní ojú ọ̀nà.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
‘Cursed is he who leads the blind astray, intoxicated, unintentional sin ·error· on the road.’ All the people shall say, ‘Amen ·So be it·.’
19 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó yí ìdájọ́ po fún àlejò, aláìní baba tàbí opó.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
‘Cursed is he who withholds mishpat ·justice· from the foreigner, orphan, and widow.’ All the people shall say, ‘Amen ·So be it·.’
20 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ìyàwó baba rẹ̀, nítorí ó ti dójúti ibùsùn baba rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
‘Cursed is he who lies with his father’s wife, because he dishonors his father’s bed.’ ‘All the people shall say, ‘Amen ·So be it·.’
21 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ẹranko.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
‘Cursed is he who lies with any kind of animal.’ ‘All the people shall say, ‘Amen ·So be it·.’
22 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú arábìnrin rẹ̀, ọmọbìnrin baba rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin ìyá rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
‘Cursed is he who lies with his sister, his father’s daughter or his mother’s daughter.’ ‘All the people shall say, ‘Amen ·So be it·.’
23 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ìyá ìyàwó o rẹ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
‘Cursed is he who lies with his mother-in-law.’ ‘All the people shall say, ‘Amen ·So be it·.’
24 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
‘Cursed is he who secretly kills his neighbor.’ ‘All the people shall say, ‘Amen ·So be it·.’
25 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí ó gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti pa ènìyàn láìjẹ̀bi.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
‘Cursed is he who takes a bribe to kill an innocent person.’ All the people shall say, ‘Amen ·So be it·.’
26 “Ègún ni fún ọkùnrin náà tí kò gbé ọ̀rọ̀ òfin yìí ró nípa ṣíṣe wọ́n.” Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn wọ̀nyí yóò wí pé, “Àmín!”
‘Cursed is he who does not uphold the words of this Torah ·Teaching· by doing them.’ ‘All the people shall say, “Amen ·So be it·.’”