< Deuteronomy 26 >

1 Nígbà tí ìwọ bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìní tí ìwọ sì ti jogún, tí ìwọ sì ti ń gbé níbẹ̀,
Şi va fi astfel, când vei intra în ţara, pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău ca moştenire, şi o vei stăpâni şi vei locui în ea,
2 mú díẹ̀ nínú ohun tí o pèsè láti inú erùpẹ̀ ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ, kó wọn sínú agbọ̀n. Nígbà náà kí o lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibi tí orúkọ rẹ̀ yóò máa gbé.
Să iei din primele roade ale pământului, pe care le vei aduce din ţara ta, pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău, şi să le pui într-un coş şi să mergi la locul pe care îl va alege DOMNUL Dumnezeul tău să îşi pună numele acolo.
3 Kí o sì sọ fun àlùfáà tí ó wà ní ibi iṣẹ́ ní àsìkò náà, pé, “Mo sọ ọ́ di mí mọ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé mo ti wá sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba wa.”
Şi să mergi la preotul care va fi în zilele acelea şi să îi spui: Mărturisesc astăzi DOMNULUI Dumnezeul tău, că am intrat în ţara, pe care DOMNUL a jurat părinţilor noştri, că ne-o va da.
4 Àlùfáà yóò gbé agbọ̀n náà kúrò ní ọwọ́ rẹ, yóò sì gbé e kalẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Şi preotul să ia coşul din mâna ta şi să îl pună jos înaintea altarului DOMNULUI Dumnezeul tău.
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní iwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Baba mi jẹ́ alárìnkiri ará Aramu, ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti pẹ̀lú ènìyàn díẹ̀, ó sì ń gbé níbẹ̀, ó sì wá di orílẹ̀-èdè olókìkí, alágbára, tí ó kún fún ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Şi să vorbeşti şi să spui înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău: Tatăl meu era un sirian gata să piară şi a coborât în Egipt, cu puţini oameni, şi acolo a locuit temporar şi acolo a devenit o naţiune mare, puternică şi numeroasă,
6 Ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti ṣe àìdára sí wa, wọ́n jẹ wá ní yà, wọ́n fún wa ní iṣẹ́ líle ṣe.
Şi egiptenii s-au purtat rău cu noi şi ne-au chinuit şi au pus robie grea peste noi,
7 Nígbà náà ni a kégbe pe Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wa, Olúwa sì gbọ́ ohùn wa, ó sì rí ìrora, làálàá àti ìnira wa.
Şi când noi am strigat către DOMNUL Dumnezeul părinţilor noştri, DOMNUL a auzit vocea noastră şi a văzut necazul nostru şi osteneala noastră şi oprimarea noastră,
8 Nígbà náà ni Olúwa mú wa jáde wá láti Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà, pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá àti iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu.
Şi DOMNUL ne-a scos din Egipt cu mână tare şi cu braţ întins şi cu groază mare şi cu semne şi cu minuni,
9 Ó mú wa wá síbí, ó sì fún wa ní ilẹ̀ yìí, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin;
Şi ne-a adus în locul acesta şi ne-a dat ţara aceasta, ţară în care curge lapte şi miere.
10 àti pé ní báyìí, mo mú àkọ́so ilẹ̀ tí ìwọ Olúwa ti fún mi wá.” Ìwọ yóò gbé agbọ̀n náà síwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì wólẹ̀ níwájú u rẹ̀.
Şi acum, iată, am adus primele roade ale ţării, pe care tu, DOAMNE, mi-ai dat-o. Şi să le pui înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău şi să te închini înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău.
11 Ìwọ àti àwọn ọmọ Lefi àti àjèjì láàrín yín yóò máa yọ̀ nínú gbogbo oore tí Olúwa ti fi fún ọ àti fún àwọn ará ilé rẹ.
Şi să te bucuri în fiecare lucru bun, pe care ţi l-a dat DOMNUL Dumnezeul tău, ţie şi casei tale, tu şi levitul şi străinul care este printre voi.
12 Nígbà tí ìwọ bá ṣetán láti ya ìdámẹ́wàá gbogbo ohun tí o ti mú jáde ní ọdún kẹta sọ́tọ̀ sí apá kan. Ọdún ìdámẹ́wàá, ìwọ yóò fi fún ọmọ Lefi, àjèjì, aláìní baba àti opó, kí wọn kí ó lè jẹ ní àwọn ìlú rẹ, kí wọn sì yó.
Când vei termina de strâns toate zeciuielile din venitul tău în anul al treilea, anul zeciuielii, şi le vei da levitului, străinului, celui fără tată şi văduvei, ca ei să mănânce înăuntrul porţilor tale şi să fie săturaţi,
13 Nígbà náà ní kí o wí fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Èmi ti mú ohun mímọ́ kúrò nínú ilé mi, èmi sì ti fi fún àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó, gẹ́gẹ́ bí ohun gbogbo tí ìwọ ti pàṣẹ. Èmi kò yípadà kúrò nínú àṣẹ rẹ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbàgbé ọ̀kankan nínú wọn.
Atunci să spui înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău: Am scos din casă lucrurile sfinte şi le-am dat şi levitului şi străinului, celui fără tată şi văduvei, conform cu toate poruncile tale, pe care mi le-ai poruncit; nu am încălcat nici nu am uitat vreuna din poruncile tale.
14 Èmi kò jẹ lára ohun mímọ́ ní ìgbà tí mo ń ṣọ̀fọ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu nínú wọn ní ìgbà tí mo wà ní àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi nínú wọn fún òkú. Èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run mi, èmi sì ti ṣe gbogbo ohun tí ó pàṣẹ fún mi.
Nu am mâncat din ele în jalea mea, nici nu am îndepărtat din ele pentru vreo folosire necurată, nici nu am dat din ele pentru morţi, ci am dat ascultare vocii DOMNULUI Dumnezeul meu şi am făcut conform cu tot ce mi-ai poruncit.
15 Wo ilẹ̀ láti ọ̀run wá, ibùgbé mímọ́ rẹ, kí o sì bùkún fún àwọn ènìyàn Israẹli, àti fún ilẹ̀ náà tí ìwọ ti fi fún wa, bí ìwọ ti búra fún àwọn baba ńlá wa, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin.”
Priveşte jos din locuinţa ta cea sfântă, din cer, şi binecuvântează pe poporul tău Israel şi ţara pe care ne-ai dat-o, precum ai jurat părinţilor noştri, o ţară în care curge lapte şi miere.
16 Olúwa Ọlọ́run rẹ pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa tẹ̀lé àwọn ìlànà àti òfin, kí o sì máa ṣe wọ́n pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo àyà rẹ.
Astăzi DOMNUL Dumnezeul tău ţi-a poruncit să împlineşti aceste statute şi judecăţi şi să le ţii de aceea şi să le împlineşti cu toată inima ta şi cu tot sufletul tău.
17 Ìwọ jẹ́wọ́ Olúwa ní òní pé Olúwa ni Ọlọ́run rẹ, àti pé ìwọ yóò máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, àti pé ìwọ yóò máa pa ìlànà rẹ̀, àṣẹ rẹ̀ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti pé ìwọ yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí i.
Tu ai declarat astăzi pe DOMNUL ca Dumnezeu al tău, şi că vei umbla în căile lui şi vei ţine statutele lui şi poruncile lui şi judecăţile lui şi că vei da ascultare vocii lui,
18 Ní òní ni Olúwa jẹ́wọ́ rẹ pé ìwọ ni ènìyàn òun, ilé ìṣúra rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí, àti pé ìwọ yóò máa pa gbogbo àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Şi DOMNUL te-a declarat astăzi a fi poporul lui deosebit, precum ţi-a promis; şi tu să ţii toate poruncile lui;
19 Òun sì jẹ́wọ́ pé, òun yóò gbé ọ sókè ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí òun ti dá lọ, ní ìyìn, ní òkìkí àti ní ọlá; kí ìwọ kí ó le jẹ́ ènìyàn mímọ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí.
Şi că te va înălţa, mai presus de toate naţiunile pe care le-a făcut el, în laudă şi în renume şi în onoare; şi că tu vei fi un popor sfânt DOMNULUI Dumnezeul tău, precum a vorbit el.

< Deuteronomy 26 >