< Deuteronomy 26 >

1 Nígbà tí ìwọ bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìní tí ìwọ sì ti jogún, tí ìwọ sì ti ń gbé níbẹ̀,
And whanne thou hast entrid in to the lond which thi Lord God schal yyue to thee to welde, and thou hast gete it, and hast dwellid therynne,
2 mú díẹ̀ nínú ohun tí o pèsè láti inú erùpẹ̀ ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ, kó wọn sínú agbọ̀n. Nígbà náà kí o lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibi tí orúkọ rẹ̀ yóò máa gbé.
thou schalt take the firste fruytis of alle thi fruytis, and thou schalt putte in a panyere; and thou schalt go to the place which thi Lord God chees, that his name be inwardly clepid there.
3 Kí o sì sọ fun àlùfáà tí ó wà ní ibi iṣẹ́ ní àsìkò náà, pé, “Mo sọ ọ́ di mí mọ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé mo ti wá sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba wa.”
And thou schalt go to the preest, that schal be in tho daies, and thou schalt seie to hym, Y knowleche to dai bifor thi Lord God, that Y entride in to the lond, for which he swoor to oure fadris, that he schulde yyue it to vs.
4 Àlùfáà yóò gbé agbọ̀n náà kúrò ní ọwọ́ rẹ, yóò sì gbé e kalẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ.
And the preest schal take the panyere of thin hond, and schal sette bifor the auter of thi Lord God.
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní iwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Baba mi jẹ́ alárìnkiri ará Aramu, ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti pẹ̀lú ènìyàn díẹ̀, ó sì ń gbé níbẹ̀, ó sì wá di orílẹ̀-èdè olókìkí, alágbára, tí ó kún fún ọ̀pọ̀ ènìyàn.
And thou schalt speke in the siyt of thi Lord God, Sirus pursuede my fadir, `which fadir yede doun in to Egipt, and was a pilgrym there in feweste noumbre; and he encreesside in to a greet folk, and strong, and of multitude without noumbre.
6 Ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti ṣe àìdára sí wa, wọ́n jẹ wá ní yà, wọ́n fún wa ní iṣẹ́ líle ṣe.
And Egipcians turmentiden vs, and pursueden, and puttiden greuouseste birthuns.
7 Nígbà náà ni a kégbe pe Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wa, Olúwa sì gbọ́ ohùn wa, ó sì rí ìrora, làálàá àti ìnira wa.
And we crieden to the Lord God of oure fadris, which herde vs, and bihelde oure mekenesse, and trauel, and angwischis;
8 Nígbà náà ni Olúwa mú wa jáde wá láti Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà, pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá àti iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu.
and he ledde vs out of Egipt in myyti hond, and arm holdun forth, in grete drede, in myraclis, and grete wondris,
9 Ó mú wa wá síbí, ó sì fún wa ní ilẹ̀ yìí, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin;
and ledde vs in to this place; and yaf to vs a lond flowynge with mylk and hony.
10 àti pé ní báyìí, mo mú àkọ́so ilẹ̀ tí ìwọ Olúwa ti fún mi wá.” Ìwọ yóò gbé agbọ̀n náà síwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì wólẹ̀ níwájú u rẹ̀.
And therfor Y offre now to thee the fyrste fruytis of the fruitis of the lond which the Lord yaf to me. And thou schalt leeue tho in the siyt of thi Lord God. And whanne thi Lord God is worchipid,
11 Ìwọ àti àwọn ọmọ Lefi àti àjèjì láàrín yín yóò máa yọ̀ nínú gbogbo oore tí Olúwa ti fi fún ọ àti fún àwọn ará ilé rẹ.
thou schalt ete in alle the goodis whiche thi Lord God yaf to thee and to thin hows, thou, and the dekene, and the comelyng which is with thee.
12 Nígbà tí ìwọ bá ṣetán láti ya ìdámẹ́wàá gbogbo ohun tí o ti mú jáde ní ọdún kẹta sọ́tọ̀ sí apá kan. Ọdún ìdámẹ́wàá, ìwọ yóò fi fún ọmọ Lefi, àjèjì, aláìní baba àti opó, kí wọn kí ó lè jẹ ní àwọn ìlú rẹ, kí wọn sì yó.
Whanne thou hast fillid the tithe of alle thi fruytis, in the thridde yeer of tithis, thou schalt yyue to the dekene, and to the comelyng, and to the fadirles, ether modirles child, and to widewe, that thei ete with ynne thi yatis, and be fillid.
13 Nígbà náà ní kí o wí fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Èmi ti mú ohun mímọ́ kúrò nínú ilé mi, èmi sì ti fi fún àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó, gẹ́gẹ́ bí ohun gbogbo tí ìwọ ti pàṣẹ. Èmi kò yípadà kúrò nínú àṣẹ rẹ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbàgbé ọ̀kankan nínú wọn.
And thou schalt speke in the siyt of thi Lord God, Y haue take awai that that is halewid of myn hows, and Y yaf it to the dekene, and to the comelyng, to the fadirles, ethir modirles child, and to the widewe, as thou comaundidist to me; Y passide not thi comaundementis, Y foryat not thin heest.
14 Èmi kò jẹ lára ohun mímọ́ ní ìgbà tí mo ń ṣọ̀fọ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu nínú wọn ní ìgbà tí mo wà ní àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi nínú wọn fún òkú. Èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run mi, èmi sì ti ṣe gbogbo ohun tí ó pàṣẹ fún mi.
Y ete not of tho thingis in my morenyng, nether Y departide tho in ony vnclennesse, nethir Y spendide of tho ony thing in biriyng of deed body, `that is, in makynge feestis therof in biryynge of deed men. Y obeiede to the vois of my Lord God, and Y dide alle thingis as thou comaundidist to me.
15 Wo ilẹ̀ láti ọ̀run wá, ibùgbé mímọ́ rẹ, kí o sì bùkún fún àwọn ènìyàn Israẹli, àti fún ilẹ̀ náà tí ìwọ ti fi fún wa, bí ìwọ ti búra fún àwọn baba ńlá wa, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin.”
Bihold thou fro thi seyntuarie, fro the hiy dwellyng place of heuene, and blesse thou thi puple Israel, and the lond which thou hast youe to vs, as thou `hast swoore to oure fadris; the lond flowynge with mylk and hony.
16 Olúwa Ọlọ́run rẹ pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa tẹ̀lé àwọn ìlànà àti òfin, kí o sì máa ṣe wọ́n pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo àyà rẹ.
To dai thi Lord God comaundide to thee, that thou do these comaundementis and domes, that thou kepe and fille of al thin herte, and of al thi soule.
17 Ìwọ jẹ́wọ́ Olúwa ní òní pé Olúwa ni Ọlọ́run rẹ, àti pé ìwọ yóò máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, àti pé ìwọ yóò máa pa ìlànà rẹ̀, àṣẹ rẹ̀ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti pé ìwọ yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí i.
Thou hast chose the Lord to day, that he be God to thee, and thou go in hise weies, and thou kepe hise cerymonyes, and heestis, and domes, and obeie to his comaundement.
18 Ní òní ni Olúwa jẹ́wọ́ rẹ pé ìwọ ni ènìyàn òun, ilé ìṣúra rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí, àti pé ìwọ yóò máa pa gbogbo àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Lo! the Lord chees thee to day, that thou be a special puple to hym, as he spak to thee, and that thou kepe alle hise comaundementis;
19 Òun sì jẹ́wọ́ pé, òun yóò gbé ọ sókè ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí òun ti dá lọ, ní ìyìn, ní òkìkí àti ní ọlá; kí ìwọ kí ó le jẹ́ ènìyàn mímọ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí.
and he schal make thee hiyere than alle folkis, whiche he made in to his preisyng, and name, and glorie; that thou be an holi puple of thi Lord God, as he spak to thee.

< Deuteronomy 26 >