< Deuteronomy 26 >

1 Nígbà tí ìwọ bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìní tí ìwọ sì ti jogún, tí ìwọ sì ti ń gbé níbẹ̀,
Naar du kommer ind i det Land, HERREN din Gud giver dig til Arv, og tager det i Besiddelse og bosætter dig deri,
2 mú díẹ̀ nínú ohun tí o pèsè láti inú erùpẹ̀ ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ, kó wọn sínú agbọ̀n. Nígbà náà kí o lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibi tí orúkọ rẹ̀ yóò máa gbé.
skal du tage en Del af Førstegrøden af alle de Jordens Frugter, som du høster af det Land, HERREN din Gud giver dig, og lægge dem i en Kurv og begive dig til det Sted, HERREN din Gud udvælger til Bolig for sit Navn.
3 Kí o sì sọ fun àlùfáà tí ó wà ní ibi iṣẹ́ ní àsìkò náà, pé, “Mo sọ ọ́ di mí mọ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé mo ti wá sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba wa.”
Naar du saa kommer til den Præst, som er der paa den Tid, skal du sige til ham: »Jeg vidner i Dag for HERREN din Gud, at jeg er kommet ind i det Land, HERREN tilsvor vore Fædre at ville give os.«
4 Àlùfáà yóò gbé agbọ̀n náà kúrò ní ọwọ́ rẹ, yóò sì gbé e kalẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Saa skal Præsten tage Kurven af din Haand og sætte den hen foran HERREN din Guds Alter.
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní iwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Baba mi jẹ́ alárìnkiri ará Aramu, ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti pẹ̀lú ènìyàn díẹ̀, ó sì ń gbé níbẹ̀, ó sì wá di orílẹ̀-èdè olókìkí, alágbára, tí ó kún fún ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Derpaa skal du tage til Orde og sige for HERREN din Guds Aasyn: »En omvankende Aramæer var min Stamfader; han drog ned til Ægypten og boede der som fremmed med nogle faa Mænd, men der blev han til et stort, mægtigt og talrigt Folk.
6 Ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti ṣe àìdára sí wa, wọ́n jẹ wá ní yà, wọ́n fún wa ní iṣẹ́ líle ṣe.
Men Ægypterne mishandlede og plagede os og paalagde os haardt Trællearbejde;
7 Nígbà náà ni a kégbe pe Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wa, Olúwa sì gbọ́ ohùn wa, ó sì rí ìrora, làálàá àti ìnira wa.
da raabte vi til HERREN, vore Fædres Gud, og HERREN hørte vor Røst og saa til vor Elendighed, Møje og Trængsel;
8 Nígbà náà ni Olúwa mú wa jáde wá láti Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà, pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá àti iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu.
og HERREN førte os ud af Ægypten med stærk Haand og udstrakt Arm, med store, forfærdelige Gerninger og med Tegn og Undere;
9 Ó mú wa wá síbí, ó sì fún wa ní ilẹ̀ yìí, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin;
og han førte os til dette Sted og gav os dette Land, et Land, der flyder med Mælk og Honning.
10 àti pé ní báyìí, mo mú àkọ́so ilẹ̀ tí ìwọ Olúwa ti fún mi wá.” Ìwọ yóò gbé agbọ̀n náà síwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì wólẹ̀ níwájú u rẹ̀.
Og her bringer jeg nu Førstegrøden af Frugterne af den Jord, du har givet mig, HERRE!« Derpaa skal du stille Kurven hen for HERREN din Guds Aasyn og tilbede for HERREN din Guds Aasyn
11 Ìwọ àti àwọn ọmọ Lefi àti àjèjì láàrín yín yóò máa yọ̀ nínú gbogbo oore tí Olúwa ti fi fún ọ àti fún àwọn ará ilé rẹ.
og saa være glad over alt det gode, HERREN din Gud giver dig, sammen med din Husstand, Leviten og den fremmede, der bor i din Midte.
12 Nígbà tí ìwọ bá ṣetán láti ya ìdámẹ́wàá gbogbo ohun tí o ti mú jáde ní ọdún kẹta sọ́tọ̀ sí apá kan. Ọdún ìdámẹ́wàá, ìwọ yóò fi fún ọmọ Lefi, àjèjì, aláìní baba àti opó, kí wọn kí ó lè jẹ ní àwọn ìlú rẹ, kí wọn sì yó.
Naar du det tredje Aar, Tiendeaaret, er færdig med at aflevere hele Tienden af din Afgrøde og har givet Leviten, den fremmede, den faderløse og Enken den, saa de kan spise sig mætte inden dine Porte,
13 Nígbà náà ní kí o wí fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Èmi ti mú ohun mímọ́ kúrò nínú ilé mi, èmi sì ti fi fún àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó, gẹ́gẹ́ bí ohun gbogbo tí ìwọ ti pàṣẹ. Èmi kò yípadà kúrò nínú àṣẹ rẹ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbàgbé ọ̀kankan nínú wọn.
da skal du sige for HERREN din Guds Aasyn: »Jeg har leveret det hellige ud fra mit Hus, jeg har ogsaa givet Leviten, den fremmede, den faderløse og Enken det efter alt dit Bud, som du har givet os; jeg har ikke overtraadt noget af dine Bud og intet glemt.
14 Èmi kò jẹ lára ohun mímọ́ ní ìgbà tí mo ń ṣọ̀fọ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu nínú wọn ní ìgbà tí mo wà ní àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi nínú wọn fún òkú. Èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run mi, èmi sì ti ṣe gbogbo ohun tí ó pàṣẹ fún mi.
Jeg har ikke spist deraf, medens jeg havde Sorg, jeg har ikke været uren, da jeg afleverede det, og jeg har ikke givet en død noget deraf, jeg har adlydt HERREN min Guds Røst, jeg har handlet nøje efter dit Bud.
15 Wo ilẹ̀ láti ọ̀run wá, ibùgbé mímọ́ rẹ, kí o sì bùkún fún àwọn ènìyàn Israẹli, àti fún ilẹ̀ náà tí ìwọ ti fi fún wa, bí ìwọ ti búra fún àwọn baba ńlá wa, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin.”
Se derfor ned fra din hellige Bolig, fra Himmelen, og velsign dit Folk Israel og den Jord, du gav os, som du tilsvor vore Fædre, et Land, der flyder med Mælk og Honning!«
16 Olúwa Ọlọ́run rẹ pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa tẹ̀lé àwọn ìlànà àti òfin, kí o sì máa ṣe wọ́n pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo àyà rẹ.
I Dag byder HERREN din Gud dig at handle efter disse Anordninger og Lovbud; hold dem derfor omhyggeligt af hele dit Hjerte og hele din Sjæl!
17 Ìwọ jẹ́wọ́ Olúwa ní òní pé Olúwa ni Ọlọ́run rẹ, àti pé ìwọ yóò máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, àti pé ìwọ yóò máa pa ìlànà rẹ̀, àṣẹ rẹ̀ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti pé ìwọ yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí i.
Du har i Dag ladet HERREN tilsige dig, at han vil være din Gud, og at han vil sætte dig højt over alle Folk, som han har skabt, til Pris og Berømmelse og Ære.
18 Ní òní ni Olúwa jẹ́wọ́ rẹ pé ìwọ ni ènìyàn òun, ilé ìṣúra rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí, àti pé ìwọ yóò máa pa gbogbo àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Og HERREN har i Dag ladet dig tilsige ham, at du vil være hans Ejendomsfolk, som han har sagt dig, og tage Vare paa alle hans Bud,
19 Òun sì jẹ́wọ́ pé, òun yóò gbé ọ sókè ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí òun ti dá lọ, ní ìyìn, ní òkìkí àti ní ọlá; kí ìwọ kí ó le jẹ́ ènìyàn mímọ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí.
og at du vil gaa paa hans Veje og holde hans Anordninger, Bud og Lovbud og høre hans Røst, og at du vil være HERREN din Gud et helligt Folk, som han har sagt.

< Deuteronomy 26 >