< Deuteronomy 25 >

1 Nígbà tí àwọn ènìyàn méjì bá ń jà, kí wọn kó ẹjọ́ lọ sí ilé ìdájọ́, kí àwọn onídàájọ́ dá ẹjọ́ náà, kí wọn dá àre fún aláre àti ẹ̀bi fún ẹlẹ́bi.
Dacă este o neînţelegere între oameni şi ei vin la judecată, ca judecătorii să îi judece, atunci să declare drept pe cel drept şi să condamne pe cel stricat.
2 Bí ó bá tọ́ láti na ẹlẹ́bi, kí onídàájọ́ dá a dọ̀bálẹ̀ kí a sì nà án ní ojú u rẹ̀ ní iye pàṣán tí ó tọ́ sí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀.
Şi se va întâmpla, dacă omul stricat este demn să fie bătut, judecătorul să îl facă să se întindă şi să fie bătut, în faţa lui, cu un număr de lovituri conform greşelii lui.
3 Ṣùgbọ́n kò gbọdọ̀ fún un ju ogójì pàṣán lọ. Bí ó bá nà án ju bẹ́ẹ̀ lọ, arákùnrin rẹ̀ yóò di ẹni ìrẹ̀sílẹ̀ ní ojú rẹ̀.
Patruzeci de lovituri poate să îi dea şi să nu le întreacă, pentru ca nu cumva, dacă le întrece şi îl bat peste acestea cu multe lovituri, fratele tău ţi-ar părea nemernic.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń tẹ ọkà lẹ́nu.
Să nu legi gura boului când treieră grâne.
5 Bí àwọn arákùnrin bá ń gbé pọ̀, tí ọ̀kan nínú wọn bá sì kú, tí kò sí ní ọmọkùnrin, kí aya òkú má ṣe ní àlejò ará òde ní ọkọ rẹ̀. Arákùnrin ọkọ rẹ̀ ni kí ó wọlé tọ̀ ọ́, kí ó fi ṣe aya, kí ó sì ṣe iṣẹ́ arákùnrin ọkọ fún un.
Când fraţii locuiesc împreună şi unul dintre ei moare şi nu are copil, soţia mortului să nu se căsătorească în afară, cu un străin; fratele soţului ei să intre la ea şi să şi-o ia de soţie şi să împlinească faţă de ea datoria de frate al soţului.
6 Ọmọkùnrin tí ó bá kọ́ bí ni yóò máa jẹ́ orúkọ arákùnrin rẹ̀ tí ó kú náà, kí orúkọ rẹ̀ má ba á parẹ́ ní Israẹli.
Şi se va întâmpla că, întâiul-născut pe care îl naşte ea să poarte numele fratelui său mort, ca să nu i se şteargă numele din Israel.
7 Ṣùgbọ́n bí ọkùnrin náà kò bá fẹ́ fi aya arákùnrin rẹ̀ ṣe aya rẹ̀, obìnrin náà yóò lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú láti sọ pé, “Arákùnrin ọkọ ọ̀ mi kọ̀ láti gbé orúkọ arákùnrin rẹ̀ ró ní Israẹli. Kò ní ṣe ojúṣe rẹ̀ bí arákùnrin ọkọ mi sí mi.”
Şi dacă omului nu îi place să ia pe soţia fratelui său, atunci soţia fratelui său să se urce la poartă, la bătrâni şi să spună: Fratele soţului meu refuză să ridice nume fratelui său în Israel, refuză să împlinească datoria de frate al soţului meu.
8 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀ yóò pè é, wọn yóò sì bá sọ̀rọ̀. Bí ó bá sì kọ̀ jálẹ̀ tí ó bá sọ pé, “Èmi kò fẹ́ láti fẹ́ ẹ,”
Atunci bătrânii cetăţii sale să îl cheme şi să îi vorbească şi dacă el stăruie şi spune: Nu îmi place să o iau,
9 opó arákùnrin rẹ̀ yìí yóò lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ní ojú àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀, yóò yọ bàtà ẹsẹ̀ rẹ̀ kan, yóò sì tu itọ́ sí ọkùnrin náà lójú, yóò sì wí pé, “Èyí ni ohun tí a ṣe sí ọkùnrin tí kò jẹ́ kí ìdílé arákùnrin rẹ̀ wà títí ayé.”
Atunci soţia fratelui său să vină la el în prezenţa bătrânilor şi să îi scoată încălţămintea din picior şi să îl scuipe în faţă şi să răspundă şi să spună: Astfel să se facă bărbatului care nu va înălţa casa fratelui său.
10 A ó sì mọ ìdílé arákùnrin yìí ní Israẹli gẹ́gẹ́ bí “Ìdílé tí a yọ bàtà rẹ̀.”
Şi în Israel îi va fi pus numele: Casa celui descălţat.
11 Bí ọkùnrin méjì bá ń jà, tí ìyàwó ọ̀kan nínú wọn bá sì wá láti gbèjà ọkọ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin tí ń lù ú, tí ó sì nawọ́ di nǹkan ọkùnrin abẹ́ ẹ rẹ̀ mú.
Dacă doi bărbaţi se ceartă unul cu altul şi soţia unuia se apropie ca să elibereze pe soţul ei din mâna celui care îl loveşte şi îşi întinde mâna şi îl apucă de părţile ascunse,
12 Ìwọ yóò gé ọwọ́ rẹ̀ náà kúrò. Má ṣe ṣàánú fún un.
Atunci să îi tai mâna, ochiul tău să nu o cruţe.
13 Má ṣe ní oríṣìí ìtẹ̀wọ̀n méjì tó yàtọ̀ sí ara wọn nínú àpò rẹ, ọ̀kan wúwo àti ọ̀kan fífúyẹ́.
Să nu ai la tine în sacul tău greutăţi diferite, una mare şi una mică.
14 Má ṣe ní oríṣìí ìwọ̀n méjì tí ó yàtọ̀ sí ara wọn ní ilé è rẹ: ọ̀kan fífẹ̀, ọ̀kan kékeré.
Să nu ai în casa ta măsuri diferite, una mare şi una mică.
15 O gbọdọ̀ ní ìtẹ̀wọ̀n àti òsùwọ̀n pípé àti ti òtítọ́ nítorí náà kí ìwọ kí ó lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ.
Ci să ai o greutate întreagă şi dreaptă; să ai o măsură întreagă şi dreaptă, ca să ţi se lungească zilele în ţara pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău.
16 Nítorí Olúwa Ọlọ́run kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí, àní ẹnikẹ́ni tí ń ṣe àìṣòdodo.
Pentru că toţi cei ce fac astfel de lucruri şi toţi cei ce fac nedreptate, sunt o urâciune înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău.
17 Rántí ohun tí àwọn ará Amaleki ṣe sí i yín ní ọ̀nà nígbà tí ẹ̀ ń jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Aminteşte-ţi de ce ţi-a făcut Amalec pe cale, când aţi ieşit din Egipt;
18 Nígbà tí àárẹ̀ mú un yín tí agara sì dá a yín, wọ́n pàdé e yín ní ọ̀nà àjò o yín, wọ́n gé àwọn tí ó rẹ̀yìn kúrò, wọn kò ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
Cum te-a întâmpinat pe cale şi ţi-a lovit spatele, pe toţi cei slabi din spatele tău, când tu erai obosit şi trudit şi el nu s-a temut de Dumnezeu.
19 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá fún un yín ní ìsinmi lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá yín tí ó yí i yín ká ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run ń fi fún yín láti ni ní ìní, ẹ̀yin yóò sì pa ìrántí Amaleki rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Má ṣe gbàgbé.
De aceea se va întâmpla, când DOMNUL Dumnezeul tău îţi va fi dat odihnă din partea tuturor duşmanilor tăi de jur împrejur, în ţara pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău ca moştenire să o stăpâneşti, că tu să ştergi amintirea lui Amalec de sub cer, să nu uiţi.

< Deuteronomy 25 >