< Deuteronomy 25 >

1 Nígbà tí àwọn ènìyàn méjì bá ń jà, kí wọn kó ẹjọ́ lọ sí ilé ìdájọ́, kí àwọn onídàájọ́ dá ẹjọ́ náà, kí wọn dá àre fún aláre àti ẹ̀bi fún ẹlẹ́bi.
“Fin pa mwet Israel luo som nu ke acn in nununku in aksuwosye sie alein inmasrloltal, na akkalemyeyuk lah sie seltal wangin mwatal, ac sie oasr mwata.
2 Bí ó bá tọ́ láti na ẹlẹ́bi, kí onídàájọ́ dá a dọ̀bálẹ̀ kí a sì nà án ní ojú u rẹ̀ ní iye pàṣán tí ó tọ́ sí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀.
Na fin fal mwet se ma sutuela in kaiyuk ke sringsring, mwet nununku sac fah sap elan oankiyuki in sringsring el. Pisen sringsring nu sel enenu in fal nu ke lupan ma koluk el orala.
3 Ṣùgbọ́n kò gbọdọ̀ fún un ju ogójì pàṣán lọ. Bí ó bá nà án ju bẹ́ẹ̀ lọ, arákùnrin rẹ̀ yóò di ẹni ìrẹ̀sílẹ̀ ní ojú rẹ̀.
Ku in sringsring el pacl angngaul, tuh in tia alukela. Fin pus liki, na ac fah arulana mwe akmwekinyal.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń tẹ ọkà lẹ́nu.
“Nik kom kapriya oalin soko cow mukul ke kom orekmakunul in lolongya wheat uh.
5 Bí àwọn arákùnrin bá ń gbé pọ̀, tí ọ̀kan nínú wọn bá sì kú, tí kò sí ní ọmọkùnrin, kí aya òkú má ṣe ní àlejò ará òde ní ọkọ rẹ̀. Arákùnrin ọkọ rẹ̀ ni kí ó wọlé tọ̀ ọ́, kí ó fi ṣe aya, kí ó sì ṣe iṣẹ́ arákùnrin ọkọ fún un.
“Tamulel se fin tukeni muta ke acn sefanna, ac sie seltal misa a wangin wen natul, na katinmas sac fah tia payuk nu sin mwet sayen sou sac. Ma kunen tamulel lun mwet misa sac in payuk sel.
6 Ọmọkùnrin tí ó bá kọ́ bí ni yóò máa jẹ́ orúkọ arákùnrin rẹ̀ tí ó kú náà, kí orúkọ rẹ̀ má ba á parẹ́ ní Israẹli.
Wen se emeet natultal ac fah oaoa mu ma nutin tamulel misa sac, tuh takin sou lal fah tutaflana in Israel.
7 Ṣùgbọ́n bí ọkùnrin náà kò bá fẹ́ fi aya arákùnrin rẹ̀ ṣe aya rẹ̀, obìnrin náà yóò lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú láti sọ pé, “Arákùnrin ọkọ ọ̀ mi kọ̀ láti gbé orúkọ arákùnrin rẹ̀ ró ní Israẹli. Kò ní ṣe ojúṣe rẹ̀ bí arákùnrin ọkọ mi sí mi.”
Tusruktu tamulel lun mukul misa sac fin tia lungse payuk sel, na mutan sac fah som nu ye mutun mwet kol lun siti sac ke nien nununku ac fahk, ‘Tamulel lun mukul tumuk el tia akfalye ma kunal; el srunga in sang tuh in oasr fita lun tamulel lal inmasrlon mwet Israel.’
8 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀ yóò pè é, wọn yóò sì bá sọ̀rọ̀. Bí ó bá sì kọ̀ jálẹ̀ tí ó bá sọ pé, “Èmi kò fẹ́ láti fẹ́ ẹ,”
Na mwet kol lun siti sac fah solama mukul sac ac sramsram nu sel. El fin srakna srunga payuk sel,
9 opó arákùnrin rẹ̀ yìí yóò lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ní ojú àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀, yóò yọ bàtà ẹsẹ̀ rẹ̀ kan, yóò sì tu itọ́ sí ọkùnrin náà lójú, yóò sì wí pé, “Èyí ni ohun tí a ṣe sí ọkùnrin tí kò jẹ́ kí ìdílé arákùnrin rẹ̀ wà títí ayé.”
na katinmas kien tamulel lal fah kalukyang nu yorol ye mutun mwet kol lun siti uh, sarukla la fahluk lun mukul sac, aniya mutal ac fahk, ‘Pa inge ma sikyak nu sin sie mukul su tia lungse sang fita lun tamulel lal.’
10 A ó sì mọ ìdílé arákùnrin yìí ní Israẹli gẹ́gẹ́ bí “Ìdílé tí a yọ bàtà rẹ̀.”
Sou lal fah eteyuk yurin mwet Israel mu ‘sou lun mukul se su sarukyukla fahluk lal.’
11 Bí ọkùnrin méjì bá ń jà, tí ìyàwó ọ̀kan nínú wọn bá sì wá láti gbèjà ọkọ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin tí ń lù ú, tí ó sì nawọ́ di nǹkan ọkùnrin abẹ́ ẹ rẹ̀ mú.
“Mukul luo fin anwuk, ac mutan kien sie srike in kasru mukul tumal ke el iseya ma mukul lun mwet se ngia,
12 Ìwọ yóò gé ọwọ́ rẹ̀ náà kúrò. Má ṣe ṣàánú fún un.
nimet pakomutun mutan sac. Pakela la paol.
13 Má ṣe ní oríṣìí ìtẹ̀wọ̀n méjì tó yàtọ̀ sí ara wọn nínú àpò rẹ, ọ̀kan wúwo àti ọ̀kan fífúyẹ́.
“Kowos in tia kiapu mwet ke kowos orekmakin kain in mwe paun luo — sie nu ke moli ma sin mwet, ac sie nu ke kukakunla ma nu sin mwet.
14 Má ṣe ní oríṣìí ìwọ̀n méjì tí ó yàtọ̀ sí ara wọn ní ilé è rẹ: ọ̀kan fífẹ̀, ọ̀kan kékeré.
Ac kowos in tia pac orekmakin mwe srikasrak luo ma tia oana sie — sie nu ke ma kom moli, ac sie nu ke ma kom kukakunla.
15 O gbọdọ̀ ní ìtẹ̀wọ̀n àti òsùwọ̀n pípé àti ti òtítọ́ nítorí náà kí ìwọ kí ó lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ.
Orekmakin mwe paun ac mwe srikasrak suwohs ac pwaye, tuh kowos in moul paht fin facl se LEUM GOD lowos El asot nu suwos.
16 Nítorí Olúwa Ọlọ́run kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí, àní ẹnikẹ́ni tí ń ṣe àìṣòdodo.
LEUM GOD El kwase kutena mwet su kutasrik ac sesuwos.
17 Rántí ohun tí àwọn ará Amaleki ṣe sí i yín ní ọ̀nà nígbà tí ẹ̀ ń jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
“Esam ma mwet Amalek tuh oru nu suwos ke kowos tuku Egypt me.
18 Nígbà tí àárẹ̀ mú un yín tí agara sì dá a yín, wọ́n pàdé e yín ní ọ̀nà àjò o yín, wọ́n gé àwọn tí ó rẹ̀yìn kúrò, wọn kò ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
Elos tiana sangeng sin God, ac elos tuku tukuwos ke pacl kowos totola ac munasla, ac onela mwet nukewa su fahsr tok ah.
19 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá fún un yín ní ìsinmi lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá yín tí ó yí i yín ká ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run ń fi fún yín láti ni ní ìní, ẹ̀yin yóò sì pa ìrántí Amaleki rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Má ṣe gbàgbé.
Na ke LEUM GOD lowos El asot nu suwos facl sac, ac oru kowos moulla liki mwet lokoalok lowos nukewa su muta raunikowosla, kowos in onela mwet Amalek nukewa, tuh in wangin mwet sifil esamulos. Nik kowos mulkunla!

< Deuteronomy 25 >