< Deuteronomy 25 >
1 Nígbà tí àwọn ènìyàn méjì bá ń jà, kí wọn kó ẹjọ́ lọ sí ilé ìdájọ́, kí àwọn onídàájọ́ dá ẹjọ́ náà, kí wọn dá àre fún aláre àti ẹ̀bi fún ẹlẹ́bi.
Ha per támad férfiak között, és törvény elé mennek, és megítélik őket, és igazat adnak az igaznak és bűnösnek mondják a bűnöst:
2 Bí ó bá tọ́ láti na ẹlẹ́bi, kí onídàájọ́ dá a dọ̀bálẹ̀ kí a sì nà án ní ojú u rẹ̀ ní iye pàṣán tí ó tọ́ sí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀.
Akkor, ha a bűnös ütleget érdemel, vonassa le azt a bíró, és üttessen arra maga előtt annak bűnössége szerint való számban.
3 Ṣùgbọ́n kò gbọdọ̀ fún un ju ogójì pàṣán lọ. Bí ó bá nà án ju bẹ́ẹ̀ lọ, arákùnrin rẹ̀ yóò di ẹni ìrẹ̀sílẹ̀ ní ojú rẹ̀.
Negyvenet üttessen rá, ne többet, hogy netalán, ha ennél több ütést üttet reá, alávalóvá legyen előtted a te atyádfia.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń tẹ ọkà lẹ́nu.
Ne kösd be az ökörnek száját, mikor nyomtat!
5 Bí àwọn arákùnrin bá ń gbé pọ̀, tí ọ̀kan nínú wọn bá sì kú, tí kò sí ní ọmọkùnrin, kí aya òkú má ṣe ní àlejò ará òde ní ọkọ rẹ̀. Arákùnrin ọkọ rẹ̀ ni kí ó wọlé tọ̀ ọ́, kí ó fi ṣe aya, kí ó sì ṣe iṣẹ́ arákùnrin ọkọ fún un.
Ha testvérek laknak együtt, és meghal egy közülök, és nincs annak fia: a megholtnak felesége ne menjen ki a háztól idegen férfiúhoz; hanem a sógora menjen be hozzá, és vegye el őt magának feleségül, és éljen vele sógorsági házasságban.
6 Ọmọkùnrin tí ó bá kọ́ bí ni yóò máa jẹ́ orúkọ arákùnrin rẹ̀ tí ó kú náà, kí orúkọ rẹ̀ má ba á parẹ́ ní Israẹli.
És majd az elsőszülött, a kit szülni fog, a megholt testvér nevét kapja, hogy annak neve ki ne töröltessék Izráelből.
7 Ṣùgbọ́n bí ọkùnrin náà kò bá fẹ́ fi aya arákùnrin rẹ̀ ṣe aya rẹ̀, obìnrin náà yóò lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú láti sọ pé, “Arákùnrin ọkọ ọ̀ mi kọ̀ láti gbé orúkọ arákùnrin rẹ̀ ró ní Israẹli. Kò ní ṣe ojúṣe rẹ̀ bí arákùnrin ọkọ mi sí mi.”
Hogyha a férfinak nincs kedve elvenni az ő ángyát, menjen el az ő ángya a kapuba a vénekhez, és mondja: Sógorom vonakodik fentartani az ő testvérének nevét Izráelben, nem akar velem sógorsági házasságban élni.
8 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀ yóò pè é, wọn yóò sì bá sọ̀rọ̀. Bí ó bá sì kọ̀ jálẹ̀ tí ó bá sọ pé, “Èmi kò fẹ́ láti fẹ́ ẹ,”
Akkor hívják azt az ő városának vénei, és beszéljenek vele; és ha megáll és ezt mondja: nincs kedvem őt elvenni:
9 opó arákùnrin rẹ̀ yìí yóò lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ní ojú àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀, yóò yọ bàtà ẹsẹ̀ rẹ̀ kan, yóò sì tu itọ́ sí ọkùnrin náà lójú, yóò sì wí pé, “Èyí ni ohun tí a ṣe sí ọkùnrin tí kò jẹ́ kí ìdílé arákùnrin rẹ̀ wà títí ayé.”
Akkor járuljon hozzá az ő ángya a vének szemei előtt, és húzza le saruját annak lábáról, és köpjön az arczába, és szóljon, és ezt mondja: Így kell cselekedni azzal a férfival, a ki nem építi az ő testvérének házát.
10 A ó sì mọ ìdílé arákùnrin yìí ní Israẹli gẹ́gẹ́ bí “Ìdílé tí a yọ bàtà rẹ̀.”
És „lehúzott sarujú háznép”-nek nevezzék az ő nevét Izráelben.
11 Bí ọkùnrin méjì bá ń jà, tí ìyàwó ọ̀kan nínú wọn bá sì wá láti gbèjà ọkọ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin tí ń lù ú, tí ó sì nawọ́ di nǹkan ọkùnrin abẹ́ ẹ rẹ̀ mú.
Ha két férfi összevesz egymással, és az egyiknek felesége oda járul, hogy megszabadítsa az ő férjét annak kezéből, a ki veri azt, és kinyujtja kezét, és megfogja annak szeméremtestét:
12 Ìwọ yóò gé ọwọ́ rẹ̀ náà kúrò. Má ṣe ṣàánú fún un.
Vágd el annak kezét, meg ne szánja szemed.
13 Má ṣe ní oríṣìí ìtẹ̀wọ̀n méjì tó yàtọ̀ sí ara wọn nínú àpò rẹ, ọ̀kan wúwo àti ọ̀kan fífúyẹ́.
Ne legyen a te zsákodban kétféle font: nagyobb és kisebb.
14 Má ṣe ní oríṣìí ìwọ̀n méjì tí ó yàtọ̀ sí ara wọn ní ilé è rẹ: ọ̀kan fífẹ̀, ọ̀kan kékeré.
Ne legyen a te házadban kétféle éfa: nagyobb és kisebb.
15 O gbọdọ̀ ní ìtẹ̀wọ̀n àti òsùwọ̀n pípé àti ti òtítọ́ nítorí náà kí ìwọ kí ó lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ.
Teljes és igaz fontod legyen néked; teljes és igaz éfád legyen néked; hogy hosszú ideig élj azon a földön, a melyet az Úr, a te Istened ád néked.
16 Nítorí Olúwa Ọlọ́run kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí, àní ẹnikẹ́ni tí ń ṣe àìṣòdodo.
Mert az Úr előtt, a te Istened előtt útálni való mindaz, a ki ezeket cselekszi; és mindaz, a ki hamisságot mível.
17 Rántí ohun tí àwọn ará Amaleki ṣe sí i yín ní ọ̀nà nígbà tí ẹ̀ ń jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Megemlékezzél arról, a mit Amálek cselekedett rajtad az úton, a mikor Égyiptomból kijöttetek:
18 Nígbà tí àárẹ̀ mú un yín tí agara sì dá a yín, wọ́n pàdé e yín ní ọ̀nà àjò o yín, wọ́n gé àwọn tí ó rẹ̀yìn kúrò, wọn kò ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
Hogy reád támadt az úton, és megverte a seregnek utolsó részét, mind az erőtleneket, a kik hátul valának, a mikor magad is fáradt és lankadt voltál, és nem félte az Istent.
19 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá fún un yín ní ìsinmi lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá yín tí ó yí i yín ká ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run ń fi fún yín láti ni ní ìní, ẹ̀yin yóò sì pa ìrántí Amaleki rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Má ṣe gbàgbé.
Mikor azért megnyugtat majd téged az Úr, a te Istened, minden te köröskörül lévő ellenségedtől azon a földön, a melyet az Úr, a te Istened ád néked örökségül, hogy bírjad azt: töröld el Amálek emlékezetét az ég alól; el ne felejtsd!