< Deuteronomy 25 >
1 Nígbà tí àwọn ènìyàn méjì bá ń jà, kí wọn kó ẹjọ́ lọ sí ilé ìdájọ́, kí àwọn onídàájọ́ dá ẹjọ́ náà, kí wọn dá àre fún aláre àti ẹ̀bi fún ẹlẹ́bi.
I NA he mea e hakaka ai iwaena o na kanaka, a hele mai lakou ma kahi hookolokolo, i hooponopono ai na lunakanawai ia lakou; alaila e hoapono aku lakou i ka mea i pono, a e hoahewa aku i ka mea i hewa.
2 Bí ó bá tọ́ láti na ẹlẹ́bi, kí onídàájọ́ dá a dọ̀bálẹ̀ kí a sì nà án ní ojú u rẹ̀ ní iye pàṣán tí ó tọ́ sí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀.
Ina he pono e lilo ka mea i hewa i ka hahauia, e hoomoe ka lunakanawai ia ia malalo, a e hahauia oia imua o kona maka, e like me ke ano o kona hewa, ma ka helu ana.
3 Ṣùgbọ́n kò gbọdọ̀ fún un ju ogójì pàṣán lọ. Bí ó bá nà án ju bẹ́ẹ̀ lọ, arákùnrin rẹ̀ yóò di ẹni ìrẹ̀sílẹ̀ ní ojú rẹ̀.
Hookahi kanaha ia e hahau ai ia ia, aole keu aku: ina e hahau hou ia ia, a nai ka hahau ana, e lilo auanei kou hoahanau i mea hoowahawahaia i kou maka.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń tẹ ọkà lẹ́nu.
Mai hoopaa aku oe i ka waha o ka bipi e hehi ana i ka palaoa.
5 Bí àwọn arákùnrin bá ń gbé pọ̀, tí ọ̀kan nínú wọn bá sì kú, tí kò sí ní ọmọkùnrin, kí aya òkú má ṣe ní àlejò ará òde ní ọkọ rẹ̀. Arákùnrin ọkọ rẹ̀ ni kí ó wọlé tọ̀ ọ́, kí ó fi ṣe aya, kí ó sì ṣe iṣẹ́ arákùnrin ọkọ fún un.
Ina e noho pu na hoahanau kane, a make kekahi o lakou, aohe ana keiki, mai mare ka wahine a ka mea i make i ka malihini mawaho: na ka hoahanau o kana kane e hele iloko io na la, a e lawe ia ia i wahine nana, a e malama aka i ka oihana o ka hoahanau o kana kane.
6 Ọmọkùnrin tí ó bá kọ́ bí ni yóò máa jẹ́ orúkọ arákùnrin rẹ̀ tí ó kú náà, kí orúkọ rẹ̀ má ba á parẹ́ ní Israẹli.
A o ka hanau mua ana e hanau ai, e lawe no ia i ka inoa o kona hoahanau i make, i nalowale ole ai kona inoa mai ka Iseraela aku.
7 Ṣùgbọ́n bí ọkùnrin náà kò bá fẹ́ fi aya arákùnrin rẹ̀ ṣe aya rẹ̀, obìnrin náà yóò lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú láti sọ pé, “Arákùnrin ọkọ ọ̀ mi kọ̀ láti gbé orúkọ arákùnrin rẹ̀ ró ní Israẹli. Kò ní ṣe ojúṣe rẹ̀ bí arákùnrin ọkọ mi sí mi.”
Ina makemake ole ke kanaka e lawe i ka wahine a kona hoahanau, alaila e pii ka wahine a kona hoahanau ma ka ipaka i na lunakahiko, a e i aku, Ua hoole ka hoahanau o kuu kane e hooku i ka inoa no kona hoahanau iloko o ka Iseraela, aole ia i haliu mai e malama i ka oihana o ka hoahanau o kuu kane.
8 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀ yóò pè é, wọn yóò sì bá sọ̀rọ̀. Bí ó bá sì kọ̀ jálẹ̀ tí ó bá sọ pé, “Èmi kò fẹ́ láti fẹ́ ẹ,”
Alaila e kahea aku na lunakahiko o kona kulanakauhale ia ia, a e olelo aku ia ia; a i kupaa ia, a e i mai, Aole o'u makemake e lawe ia ia;
9 opó arákùnrin rẹ̀ yìí yóò lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ní ojú àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀, yóò yọ bàtà ẹsẹ̀ rẹ̀ kan, yóò sì tu itọ́ sí ọkùnrin náà lójú, yóò sì wí pé, “Èyí ni ohun tí a ṣe sí ọkùnrin tí kò jẹ́ kí ìdílé arákùnrin rẹ̀ wà títí ayé.”
Alaila e hele mai ka wahine a kona hoahanau ia ia imua o na lunakahiko, a e kala ae i kona kamaa mai kona wawae, a e kuha aku i kona maka, me ka olelo aku, Pela e hanaia'ku ai i ke kanaka, i ka mea kukulu ole i ka hale o kona hoahanau.
10 A ó sì mọ ìdílé arákùnrin yìí ní Israẹli gẹ́gẹ́ bí “Ìdílé tí a yọ bàtà rẹ̀.”
A e kapaia kona inoa iloko o ka Iseraela, O ka hale o ka mea i kalaia kona kamaa.
11 Bí ọkùnrin méjì bá ń jà, tí ìyàwó ọ̀kan nínú wọn bá sì wá láti gbèjà ọkọ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin tí ń lù ú, tí ó sì nawọ́ di nǹkan ọkùnrin abẹ́ ẹ rẹ̀ mú.
A i hakaka pu na kanaka, kekahi kanaka a me kona hoahanau, a hookokoke mai ka wahine a kekahi e hoopakele i kana kane i ka lima o ka mea i pepehi mai ia ia, a hoopaa aku ia ia ma kona wahi hilahila:
12 Ìwọ yóò gé ọwọ́ rẹ̀ náà kúrò. Má ṣe ṣàánú fún un.
E oki ae i kona lima, mai minamina koa maka.
13 Má ṣe ní oríṣìí ìtẹ̀wọ̀n méjì tó yàtọ̀ sí ara wọn nínú àpò rẹ, ọ̀kan wúwo àti ọ̀kan fífúyẹ́.
Mai waiho iloko o kou aa i na mea kaupouna ano lua, i ka mea nui a me ka mea uuku.
14 Má ṣe ní oríṣìí ìwọ̀n méjì tí ó yàtọ̀ sí ara wọn ní ilé è rẹ: ọ̀kan fífẹ̀, ọ̀kan kékeré.
Aole hoi ma kou hale na ana elua, o ka mea nui, a me ka mea uuku.
15 O gbọdọ̀ ní ìtẹ̀wọ̀n àti òsùwọ̀n pípé àti ti òtítọ́ nítorí náà kí ìwọ kí ó lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ.
E malama oe i ka pouna pono, a me ka pololei, a me ke ana pono a me ka pololei; i loihi ai koa mau la ma ka aina a Iehova kou Akua i haawi mai ai ia oe.
16 Nítorí Olúwa Ọlọ́run kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí, àní ẹnikẹ́ni tí ń ṣe àìṣòdodo.
No ka mea, ua hoowahawahaia e Iehova na mea a pau e hana ana i keia mau mea, a me ka poe a pau e hana ana i ka mea pono ole.
17 Rántí ohun tí àwọn ará Amaleki ṣe sí i yín ní ọ̀nà nígbà tí ẹ̀ ń jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
E hoomanao i ka mea a ka Amaleka i hana mai ai ia oe ma ke ala i ko oakoa hele ana, mai Aigupita mai.
18 Nígbà tí àárẹ̀ mú un yín tí agara sì dá a yín, wọ́n pàdé e yín ní ọ̀nà àjò o yín, wọ́n gé àwọn tí ó rẹ̀yìn kúrò, wọn kò ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
I ko lakou halawai ana me oe ma ke ala, a pepehi mai ma kou hope i na mea nawaliwali a pau mahope ou ia oe i nawaliwali ai, a i maloeloe ai; aole lakou i makau i ke Akua.
19 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá fún un yín ní ìsinmi lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá yín tí ó yí i yín ká ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run ń fi fún yín láti ni ní ìní, ẹ̀yin yóò sì pa ìrántí Amaleki rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Má ṣe gbàgbé.
No ia mea, aia hoomaha mai o Iehova kou Akua ia oe mai kou poe enemi a puni, ma ka aina a Ienova kou Akua i hoolilo mai ai nou, e hokai loa aku oe i ka Amaleka malalo ae o ka lani; mai hoopoina oe.